< 2 Rois 9 >

1 Alors, le prophète Elisée appela l'un des fils des prophètes, et il lui dit Ceins-toi les reins; prends en tes mains cette fiole d'huile, et va à Ramoth- Galaad.
Wòlíì Eliṣa fi àṣẹ pe ọkùnrin kan láti ẹgbẹ́ àwọn wòlíì, ó sì wí fún un pé, “Ki agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè rẹ, gba ṣágo kékeré òróró yìí pẹ̀lú rẹ, kí o sì lọ sí Ramoti Gileadi.
2 Entre, et tu verras Jéhu, fils de Josaphat fils de Namsi; tu iras auprès de lui et tu l'emmèneras du milieu de ses frères, en un lieu retiré de ses appartements.
Nígbà tí o bá dé bẹ̀, wá Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi kiri. Lọ sí ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀, mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀, kí o sì mú un wọ inú yàrá lọ́hùn ún lọ.
3 Et tu prendras la fiole d'huile; tu la lui verseras sur la tête, et tu diras: Voici ce que dit le Seigneur: Je t'ai sacré roi d'Israël; cela dit, tu ouvriras la porte, et tu partiras rapidement sans t'arrêter.
Nígbà náà, mú ṣágo kékeré yìí, kí o sì da òróró náà lé e lórí, kí o sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’ Nígbà náà, ṣí ìlẹ̀kùn, kí o sì sáré, má ṣe jáfara!”
4 Et le jeune prophète alla en Ramoth-Galaad.
Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wòlíì náà lọ sí Ramoti Gileadi.
5 Il entra, il vit les chefs de l'armée assis ensemble, et il dit: Un mot à toi, chef. Jéhu demanda: Auquel de nous? Il répondit: A toi, chef,
Nígbà tí ó dé, ó rí àwọn olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí wọ́n jókòó papọ̀. “Èmi ní iṣẹ́ fún ọ, olórí,” Ó wí. “Sí ta ni nínú wa?” Jehu béèrè. Òun sì wí pé, “Sí ọ, balógun,” Ó dáhùn.
6 Et Jéhu se leva, et ils allèrent à l'intérieur de la maison; là, le prophète lui versa l'huile sur la tête, et lui dit: Voici ce que dit le Seigneur Dieu d'Israël: Je t'ai sacré roi du peuple du Seigneur, roi d'Israël.
Jehu dìde sókè, ó sì wọ inú ilé lọ. Nígbà náà, wòlíì náà da òróró náà sórí Jehu; ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn Olúwa Israẹli.
7 Et tu extermineras de devant ma face la maison d'Achab, ton maître; tu vengeras le sang des prophètes, mes serviteurs, et le sang de tous mes serviteurs qu'a répandu la main de Jézabel,
Kí ìwọ kí ó pa ilé Ahabu ọ̀gá à rẹ̀ run, Èmi yóò sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Olúwa tí a ta sílẹ̀ látọwọ́ ọ Jesebeli.
8 Et celui qu'a répandu toute la maison d'Achab; tu extermineras tout mâle de la maison d'Achab, tout ce qui se tient enfermé et survit en Israël.
Gbogbo ilé Ahabu yóò ṣègbé. Èmi yóò gé e kúrò láti orí Ahabu gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó gbẹ̀yìn ni Israẹli, ẹrú tàbí òmìnira.
9 Et je traiterai la maison d'Achab comme celle de Jéroboam, fils de Nabat, comme celle de Baasa, fils d'Achias,
Èmi yóò ṣe ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati àti ilé Baaṣa ọmọ Ahijah.
10 Et les chiens dévoreront Jézabel dans le champ de Jezraël, et il n'y aura personne qui l'ensevelisse. Puis, le prophète ouvrit la porte et s'enfuit.
Fún Jesebeli, ajá ni yóò jẹ ẹ́ ní oko Jesreeli, kò sì sí ẹni tí yóò sin òkú rẹ̀.’” Nígbà náà ó ṣí ìlẹ̀kùn, ó sì sálọ.
11 Jéhu revint auprès des serviteurs de son maître, et ils lui dirent: Tout va bien. Pourquoi cet épileptique est-il venu te trouver? Il leur répondit: Vous connaissez l'homme et son bavardage?
Nígbà tí Jehu jáde lọ bá àwọn ọgbà ìjòyè e rẹ̀, ọ̀kan nínú wọn sì bi í pé, “Ṣé gbogbo nǹkan dára?” Kí ni ó dé tí aṣiwèrè fi tọ̀ ọ́ wá, “Ìwọ mọ ọkùnrin náà àti irú nǹkan tí ó ń sọ,” Jehu fèsì.
12 Mais ils dirent: Nullement, raconte-nous-le donc. Alors, Jéhu leur dit: Il m'a parlé de telle et de telle manière, ajoutant: Voici ce que dit le Seigneur: Je t'ai sacré roi d'Israël.
“Ìyẹn kì í ṣe òótọ́!” Wọ́n wí. “Sọ fún wa.” Jehu wí, “Èyí ni ohun tí ó sọ fún mi: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’”
13 Dès qu'ils l'eurent ouï, ils s'empressèrent; chacun ôta son manteau et le mit sous les pieds de Jéhu au faîte des degrés; puis, ils sonnèrent du cor, et ils dirent: Jéhu est roi.
Wọ́n ṣe gírí, wọ́n sì mú agbádá a wọn, wọ́n sì tàn wọ́n sí abẹ́ rẹ̀ ní orí àtẹ̀gùn. Nígbà náà, wọ́n fọn ìpè, wọ́n sì kígbe, “Jehu jẹ ọba!”
14 Ainsi, Jéhu, fils de Josaphat, fils de Namsi, se révolta contre Joram. Alors, Joram défendait Ramoth-Galaad, avec tout Israël, contre Azaël, roi de Syrie.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi, dìtẹ̀ sí Joramu. (Nísinsin yìí Joramu àti gbogbo Israẹli ti ń dáàbò bo Ramoti Gileadi nítorí Hasaeli ọba Aramu.
15 Et le roi Joram était revenu à Jezraël pour se guérir des blessures que les Syriens lui avaient faites quand il avait combattu Azaël, roi de Syrie. Et Jéhu dit aux siens: Si votre âme est avec moi, ne laissez sortir de la ville personne qui puisse aller tout dire à Jezraël.
ṣùgbọ́n ọba Joramu ti padà sí Jesreeli láti lọ sàn nínú ọgbẹ́ tí àwọn ará Aramu ti dá sí i lára nínú ogun pẹ̀lú ọba Hasaeli ti Aramu.) Jehu wí pé, “Tí èyí bá jẹ́ ọ̀nà tí ò ń rò, má ṣe jẹ́ kí ẹnìkankan kí ó yọ jáde nínú ìlú ńlá láti lọ sọ ìròyìn náà ní Jesreeli.”
16 Ensuite, Jéhu monta à cheval, partit, et descendit à Jezraél, où le roi Joram était à panser les blessures que lui avaient faites les flèches des archers syriens quand il avait combattu Azaël, roi de Syrie; car il était vaillant et plein de force. Et Ochozias, roi de Juda, était venu voir Joram.
Nígbà náà Jehu wọ inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó sì gùn ún lọ sí Jesreeli, nítorí Joramu ń sinmi níbẹ̀ àti Ahasiah ọba Juda sì sọ̀kalẹ̀ láti wá wò Joramu.
17 Et une sentinelle montée sur la tour de Jezraël, vit la poussière que soulevait Jéhu en approchant; et elle dit: Je vois de la poussière. A quoi Joram répondit: Prends un cavalier; fais-le partir au-devant d'eux; qu'il demande: Est-ce la paix?
Nígbà tí olùṣọ́ kan tí ó dúró ní ilé ìṣọ́ ní Jesreeli, rí ọ̀wọ́ ogun Jehu tí wọ́n ń súnmọ́ tòsí, ó pè jáde, “Mo rí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí ó ń bọ̀.” “Mú ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kan,” Joramu pa á láṣẹ. “Rán an lọ sí ọ̀dọ̀ wọn kí o sì béèrè pé, ‘Ṣé ẹ̀yin wá pẹ̀lú àlàáfíà?’”
18 Et un cavalier partit à leur rencontre, et il dit: Voici ce que dit le roi: Est-ce la paix? Jéhu répliqua: Qu'y a-t-il entre toi et la paix? Va te joindre à ceux qui me suivent. Cependant, la sentinelle fit ce rapport: Le messager est allé jusqu'à eux, et il n'est point revenu.
Ọkùnrin ẹlẹ́ṣin náà, lọ láti lọ bá Jehu ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba wí: ‘Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?’” “Kí ni ìwọ ní ṣe pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu sì dáhùn. “Bọ́ sí ẹ̀yìn mi.” Olùṣọ́ náà sì wí fún un pé, “Ìránṣẹ́ náà ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́.”
19 Et elle envoya un second messager; celui-ci arriva près d'eux, et il dit: Voici ce que dit le roi: Est-ce la paix? Jéhu répliqua: Qu'y a-t-il entre toi et la paix? Va te joindre à ceux qui me suivent.
Bẹ́ẹ̀ ni, ọba rán ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kejì. Nígbà náà ó wá sí ọ̀dọ̀ wọn, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba sọ: “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu dáhùn, “Dúró sí ẹ̀yìn mi.”
20 L'homme en sentinelle fit derechef ce rapport: Il est allé jusqu'à eux, et il n'est point revenu; le chef paraît être Jéhu, fils de Namsi; car il marche comme un furieux.
Olùṣọ́ náà sì fi sùn. “Ó ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́ pẹ̀lú. Wíwá rẹ̀ sì dàbí ti Jehu ọmọ Nimṣi, ó ń wa kẹ̀kẹ́ bí ti aṣiwèrè.”
21 Et Joram dit: Qu'on attelle. On attela son char; et Joram, roi d'Israël, sortit avec Ochozias, roi de Juda, chacun sur son char; ils allèrent à la rencontre de Jéhu, et ils le trouvèrent dans le champ de Naboth le Jezraélite.
“Fi ìwọ̀ kọ́ kẹ̀kẹ́ ogun mi.” Joramu pa á láṣẹ. Àti nígbà tí a fi kọ́, Joramu ọba Israẹli àti Ahasiah ọba Juda, gun kẹ̀kẹ́ lọ, olúkúlùkù nínú kẹ̀kẹ́ ogun tirẹ̀, láti lọ bá Jehu. Wọ́n bá a pàdé ní ibi oko tí ó ti jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli.
22 Dès que Joram vit Jéhu, il s'écria: Est-ce la paix, Jéhu? Jéhu répondit: Quoi! la paix! quand Jézabel, ta mère, multiplie ses débauches et ses sortilèges?
Nígbà tí Joramu rí Jehu, ó béèrè pé, “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà, Jehu?” “Báwo ni àlàáfíà yóò ṣe wà,” Jehu dáhùn, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí gbogbo ìbọ̀rìṣà àti iṣẹ́ àjẹ́ ti màmá rẹ Jesebeli di púpọ̀?”
23 Alors, Joram tourna bride, s'enfuit, et dit au roi de Juda Trahison! Ochozias.
Joramu yí ọwọ́ rẹ̀ padà, ó sì sálọ, ó sì ń pe Ahasiah, “Ọ̀tẹ̀ dé, Ahasiah!”
24 Mais Jéhu tendit son arc avec force, et il atteignit Joram entre les épaules; la flèche lui traversa le cœur, et il s'affaissa sur ses genoux.
Nígbà náà, Jehu fa ọrun rẹ̀, ó sì yin Joramu láàrín èjìká méjèèjì. Ọfà náà sì wọ inú ọkàn rẹ̀, ó sì ṣubú lulẹ̀ láti orí kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
25 Puis, Jéhu dit à Badecar, son lieutenant: Jette-le dans le champ de Naboth le Jezraélite; car je me souviens, et tu te souviens aussi, que, quand nous étions sur un char à la suite d'Achab, son père, le Seigneur a prononcé cette sentence:
Jehu sọ fún Bidikari, balógun kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Gbé e sókè kí ó sì jù ú sí orí oko tí ó jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli. Rántí bí èmi àti ìwọ ti ń gun kẹ̀kẹ́ papọ̀ lẹ́yìn Ahabu baba à rẹ nígbà tí Olúwa sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀,
26 Si je n'avais point vu hier le sang de Naboth et le sang de ses fils! dit le Seigneur; mais je les vengerai dans ce champ même, dit le Seigneur. Maintenant, prends-le et jette-le dans le champ, selon la parole du Seigneur.
‘Ní àná, mo rí ẹ̀jẹ̀ Naboti pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ni Olúwa wí.’ Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ gbé e sókè, kí o sì jù ú sí orí ilẹ̀ oko náà ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa.”
27 Et Ochozias, roi de Juda, vit tout, et il prit la fuite par le chemin de Bethgan; Jéhu le poursuivit, et il dit: Tuez aussi celui-là. L'un de ses gens le frappa sur son char comme il montait en Haï (la même que Jéblaam). Et Ochozias se réfugia dans Mageddo, où il mourut.
Nígbà tí Ahasiah ọba, Juda rí ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀, ó sálọ sójú ọ̀nà sí Beti-Haggani. Jehu sì lépa rẹ̀, ó ń kígbe, “Pa á pẹ̀lú!” Wọ́n ṣá a ní ọgbẹ́ nínú kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Guri lẹ́bàá a Ibleamu, ṣùgbọ́n ó sálọ sí Megido, ó sì kú síbẹ̀.
28 Ses serviteurs le placèrent sur son char; ils le ramenèrent à Jérusalem, et ils l'ensevelirent dans son sépulcre en la ville de David.
Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì gbé e pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lọ sí Jerusalẹmu, ó sì sin ín pẹ̀lú, baba a rẹ̀ nínú ibojì rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi.
29 Ochozias était devenu roi de Juda, la onzième année du règne de Joram en Israël.
(Ní ọdún kọkànlá ti Joramu ọmọ Ahabu, Ahasiah ti di ọba Juda.)
30 Ensuite, Jéhu entra dans Jezraël; Jézabel l'ouït, elle se farda le tour des yeux, orna sa tête, et se pencha à sa fenêtre.
Nígbà náà Jehu lọ sí Jesreeli. Nígbà tí Jesebeli gbọ́ nípa rẹ̀, ó kun ojú u rẹ̀, ó to irun rẹ̀, ó sì wò jáde láti ojú fèrèsé.
31 Quand Jéhu passa, elle lui cria: Zambri s'est-il bien trouvé d'avoir tué son maître?
Bí Jehu ti wọ ẹnu ìlẹ̀kùn, ó béèrè, “Ṣé ìwọ wá ní àlàáfíà, Simri, ìwọ olùpa ọ̀gá à rẹ?”
32 Il leva les yeux vers sa fenêtre; il la vit, et il dit: Qui es-tu? Descends auprès de moi. Or, il y avait là deux eunuques qui se penchèrent vers lui.
Ó gbójú sókè láti wo fèrèsé, ó sì pè jáde, “Ta ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ mi? Ta ni?” Ìwẹ̀fà méjì tàbí mẹ́ta bojú wò ó nílẹ̀.
33 Jéhu leur dit: Jetez-la par la fenêtre. Et ils la jetèrent; son sang jaillit sur les murs et sur les chevaux, et les chevaux la foulèrent aux pieds.
Jehu sọ wí pé, “Gbé e jù sílẹ̀!” Wọ́n sì jù ú sílẹ̀. Díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì fọ́n sí ara ògiri àti àwọn ẹṣin bí wọ́n ti tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ wọn.
34 Ensuite, Jéhu entra dans le palais; il mangea et il but; puis, il dit: Allez voir cette maudite, et ensevelissez-la, car c'est une fille de roi.
Jehu wọ inú ilé lọ, ó jẹ, ó sì mu. “Tọ́jú obìnrin yẹn tí a fi bú,” Ó wí, “Kí o sì sin ín, nítorí ọmọbìnrin ọba ni ó jẹ́.”
35 Et ses gens sortirent pour l'inhumer; mais ils ne trouvèrent plus rien d'elle que le crâne, les pieds et les paumes des mains.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde lọ láti lọ sin ín, wọn kò rí nǹkan kan àyàfi agbárí i rẹ̀, ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì àti ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì.
36 Ils rentrèrent; ils lui en firent le rapport, et il dit: C'est la parole du Seigneur qu'il a dite par Elie le Thesbite, disant: Dans les champs de Jezraël, les chiens dévoreront les chairs de Jézabel.
Wọ́n padà lọ sọ fún Jehu, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah ará Tiṣibi wí pé, ‘Ní orí oko Jesreeli ni àwọn ajá yóò ti jẹ ẹran-ara Jesebeli.
37 Et son cadavre sera comme du fumier sur la surface du champ de Jezraël, et nul ne pourra dire: C'est Jézabel.
Òkú Jesebeli yóò dàbí ohun ẹ̀gbin ní orí oko Jesreeli, dé bi pé, ẹnikẹ́ni kì yóò lè sọ pé, “Jesebeli ni èyí.”’”

< 2 Rois 9 >