< 2 Rois 23 >

1 Et ils rapportèrent au roi ces paroles; et il envoya des messagers, et il assembla autour de lui tous les anciens de Juda et de Jérusalem.
Nígbà náà ọba pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda àti Jerusalẹmu jọ.
2 Et le roi monta au temple du Seigneur avec tout Juda, tous les habitants de Jérusalem, les prêtres, les prophètes, tout le peuple, depuis le petit jusqu'au grand, et il lut à leurs oreilles toutes les paroles du livre de l'alliance trouvé dans le temple du Seigneur.
Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
3 Ensuite, le roi, debout sur le piédestal, renouvela l'alliance devant le Seigneur, afin de suivre le Seigneur, de garder ses commandements, ses témoignages et ses justices, de tout son cœur, dans la plénitude de son âme; et enfin, de faire revivre toutes les paroles de l'alliance écrite dans le livre; or, tout le peuple acquiesça à l'alliance.
Ọba sì dúró lẹ́bàá òpó, ó sì sọ májẹ̀mú di tuntun níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, ìlànà àti òfin pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo ẹ̀mí rẹ̀, àti láti ṣe ìwádìí àwọn ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sínú ìwé yìí. Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn sì ṣèlérí fúnra wọn sí májẹ̀mú náà.
4 Et le roi prescrivit à Helcias le grand prêtre, aux prêtres du second rang et aux gardiens de la porte, d'enlever du temple du Seigneur tous les vases faits pour Baal, pour le bois sacré et pour l'armée du ciel; il les brûla hors de Jérusalem dans la vallée de Cédron, et il en fit porter les cendres à Béthel.
Ọba sì pàṣẹ fún Hilkiah olórí àlùfáà àti àwọn, àlùfáà tí ó tẹ̀lé e ní ipò àti àwọn olùṣọ́nà láti yọ kúrò nínú ilé Olúwa gbogbo ohun èlò tí a ṣe fún Baali àti Aṣerah àti gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run. Ó sì sun wọ́n ní ìta Jerusalẹmu ní pápá àfonífojì Kidironi. Ó sì kó eérú wọn jọ sí Beteli.
5 Puis, il brûla vifs les prêtres idolâtres qu'avaient institués les rois de Juda et qui encensaient sur les hauts lieux, soit dans les villes de Juda, soit autour de Jérusalem, et aussi ceux qui encensaient Baal, le soleil, la lune, les douze signes et toute l'armée du ciel.
Ó sì kúrò pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà tí a yàn láti ọwọ́ ọba Juda láti sun tùràrí ní ibi gíga ti ìlú Juda àti àwọn tí ó yí Jerusalẹmu ká. Àwọn tí ó ń sun tùràrí sí Baali, sí oòrùn àti òṣùpá, sí àwọn àmì ìràwọ̀ àti sí gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run.
6 Et il emporta l'idole des bois sacrés hors du temple, hors de Jérusalem dans le torrent de Cédron; il la réduisit en cendres qu'il dispersa sur la sépulture des fils du peuple.
Ó mú ère òrìṣà Aṣerah láti ilé Olúwa sí àfonífojì Kidironi ní ìta Jerusalẹmu, ó sì sun wọ́n níbẹ̀. Ó lọ̀ ọ́ bí àtíkè ó sì fọ́n eruku náà sórí isà òkú àwọn ènìyàn tí ó wọ́pọ̀.
7 Il démolit la demeure des initiés qu'on avait construite dans le temple, et où les femmes tissaient des tentes pour le bois sacré.
Ó sì wó ibùgbé àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà lulẹ̀. Tí ó wà nínú ilé Olúwa àti ibi tí àwọn obìnrin tí ń ṣe iṣẹ́ aṣọ híhun fún òrìṣà Aṣerah.
8 Il assembla ensuite tous les prêtres des villes de Juda; et il souilla les hauts lieux, où les prêtres avaient brûlé de l'encens, depuis Gebal jusqu'à Bersabée; puis, il abattit la maison des portes, à côté de la demeure de de Josué, prince de Jérusalem, à gauche, en sortant de la ville.
Josiah kó gbogbo àwọn àlùfáà láti àwọn ìlú Juda ó sì ba ibi mímọ́ wọ̀n-ọn-nì jẹ́ láti Geba sí Beerṣeba, níbi tí àwọn àlùfáà ti sun tùràrí. Ó wó àwọn ojúbọ lulẹ̀ ní ẹnu ìlẹ̀kùn—ní ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ti Joṣua, baálẹ̀ ìlú ńlá tí ó wà ní apá òsì ẹnu ìlẹ̀kùn ìlú ńlá.
9 Cependant, les prêtres des hauts lieux ne montèrent plus à l'autel du Seigneur à Jérusalem, à moins qu'ils n'eussent mangé des azymes au milieu de leurs frères.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, àwọn àlùfáà ibi gíga kò jọ́sìn ní ibi pẹpẹ Olúwa ní Jerusalẹmu, wọ́n jẹ nínú àkàrà aláìwú pẹ̀lú àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn.
10 Josias souilla encore Tapheth dans le val des fils d'Ennom, où ils faisaient passer dans la flamme de Moloch, les uns leurs fils, les autres leurs filles.
Ó sì ba ohun mímọ́ Tofeti jẹ́, tí ó wà ní àfonífojì Beni-Hinnomu, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkan tí ó lè lò ó fún ẹbọ rírú fún ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin nínú iná sí Moleki.
11 Il brûla les chevaux que les rois de Juda avaient consacrés au soleil, à l'entrée du temple, dans le trésor de Nathan, eunuque du roi, à Pharurim; il brûla en outre le char du soleil,
Ó sì kúrò láti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí ilé Olúwa, àwọn ẹṣin tí àwọn ọba Juda ti yà sọ́tọ̀ sí oòrùn náà. Wọ́n wà nínú ilé ẹjọ́ lẹ́bàá yàrá oníṣẹ́ tí orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Natani-Meleki. Josiah sì sun àwọn kẹ̀kẹ́ tí a yà sọ́tọ̀ fún oòrùn.
12 Et les autels que les rois de Juda avaient élevés sur la terrasse au- dessus de la chambre d'Achaz, et ceux que Manassé avait construits dans les deux parvis du temple; il en fit jeter les cendres dans le torrent de Cédron.
Ó wó o palẹ̀ pẹpẹ tí àwọn ọba Juda ti wọ́n gbé dúró ní orí òrùlé lẹ́bàá yàrá òkè ti Ahasi pẹ̀lú àwọn pẹpẹ tí Manase ti kọ́ nínú ilé ẹjọ́ méjèèjì sí ilé Olúwa. Ó ṣí wọn kúrò níbẹ̀, ó fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́. Ó sì da ekuru wọn sínú àfonífojì Kidironi.
13 Le roi souilla aussi le temple que Salomon, roi d'Israël, avait érigé en face de Jérusalem, à droite du chemin de la montagne de Mosthath, en l'honneur d'Astarté, abomination des Sidoniens et de Chamos, abomination de Moab et de Moloch, abomination des Ammonites.
Ọba pẹ̀lú ba ohun mímọ́ àwọn ibi gíga jẹ́ tí ó wà ní ìhà ìlà-oòrùn Jerusalẹmu ní ìhà gúúsù ti òkè ìbàjẹ́—èyí tí Solomoni ọba Israẹli ti kọ́ fún Aṣtoreti ọlọ́run ìríra àwọn ará Sidoni, fún Kemoṣi ọlọ́run ìríra àwọn ará Moabu àti fún Moleki, ọlọ́run ìríra àwọn ènìyàn Ammoni.
14 Il mit en pièces leurs colonnes, détruisit leurs bois sacrés, et remplit d'ossements humains le lieu où on les adorait.
Josiah fọ́ òkúta yíyà sọ́tọ̀, ó sì gé ère Aṣerah lulẹ̀. Ó sì bo ẹ̀gbẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pẹ̀lú egungun ènìyàn.
15 Puis, il abattit l'autel qu'en Béthel, sur le haut lieu, Jéroboam, fils de Nabat, avait élevé et où il avait fait tomber tout le peuple dans le péché; il le démolit. Il en broya les pierres, il les réduisit en poudre, et il brûla le bois sacré.
Àní pẹpẹ tí ó wà ní Beteli ibi gíga tí Jeroboamu ọmọ Nebati dá. Tí ó ti fa Israẹli láti ṣẹ̀, àní pẹpẹ náà àti ibi gíga tí ó fọ́ túútúú. Ó jó àwọn ibi gíga, ó sì lọ̀ ọ́ sí ẹ̀tù, ó sì sun ère Aṣerah pẹ̀lú.
16 Et Josias, se détournant, vit les sépulcres de cette ville; aussitôt, il donna ses ordres: il en fit extraire les ossements, et il les brûla sur l'autel pour le souiller, selon la parole du Seigneur qu'avait dite l'homme de Dieu quand Jéroboam avait célébré la fête de l'autel; puis, se retournant encore, il leva les yeux et il vit la sépulture de cet homme de Dieu qui avait dit ces paroles.
Nígbà náà, Josiah wò yíká, nígbà tí ó sì rí àwọn isà òkú tí ó wà níbẹ̀ ní ẹ̀bá òkè, ó yọ egungun kúrò lára wọn, ó sì jó wọn lórí pẹpẹ láti sọ ọ́ di èérí ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa tí a ti kéde láti ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti àwọn nǹkan wọ̀nyí tẹ́lẹ̀.
17 Et il dit: Quel est ce tombeau que j'aperçois? Et les hommes de la ville lui répondirent: Celui de l'homme de Dieu qui est venu de Juda, et qui a fait les imprécations contre l'autel de Béthel.
Ọba sì béèrè pé, “Kí ni ọwọ̀n isà òkú yẹn tí mo rí?” Àwọn ọkùnrin ìlú ńlá wí pé, “Ó sàmì sí isà òkú ènìyàn Ọlọ́run tí ó wá láti Juda, tí ó sì kéde ìdojúkọ pẹpẹ Beteli, ohun kan wọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe sí wọn.”
18 Et le roi dit: Respectez-le; que nul n'enlève ses ossements. Et ses os furent sauvés avec ceux du prophète qui était venu de Samarie.
“Fi sílẹ̀ nìkan,” Ó wí pé. “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó da àwọn egungun rẹ̀ láàmú.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá egungun rẹ̀ sí àti ti àwọn wòlíì tí ó wá láti Samaria.
19 Josias détruisit donc tous les temples des hauts lieux que les rois d'Israël avaient élevés dans les villes de Samarie, pour y irriter le Seigneur, et il y fit la même chose qu'à Béthel.
Gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Beteli, Josiah sì kúrò, ó sì ba gbogbo ojúbọ òrìṣà ti ibi gíga jẹ́, tí àwọn ọba Israẹli ti kọ́ sí àwọn ìlú ní Samaria, tí ó ti mú Olúwa bínú.
20 Et il sacrifia sur leurs autels tous les prêtres des hauts lieux qui étaient là, il y brûla les os des hommes, et il retourna à Jérusalem.
Josiah dúńbú gbogbo àwọn àlùfáà ibi gíga lórí pẹpẹ. Ó sì sun egungun ènìyàn lórí wọn. Nígbà náà, ó padà lọ sí Jerusalẹmu.
21 Et le roi donna ses ordres à tout le peuple, disant: Immolez la pâque au Seigneur notre Dieu, comme il est écrit au livre de cette alliance.
Ọba pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sí inú ìwé májẹ̀mú yìí.”
22 Car, on n'avait point ainsi célébré cette fête depuis le temps des Juges qui jugeaient Israël; ni sous les rois d'Israël, ni sous les rois de Juda.
Kì í ṣe láti ọjọ́ àwọn Juda tí ó tọ́ Israẹli, ní gbogbo àwọn ọjọ́ àwọn ọba Israẹli àti àwọn ọba Juda. Ṣé wọ́n ti ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá rí.
23 Ce ne fut qu'en la dix-huitième année du règne de Josias, que l'on immola la pâque au Seigneur à Jérusalem
Ṣùgbọ́n ní ọdún kejìdínlógún tí ọba Josiah, àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí sí Olúwa ní Jerusalẹmu.
24 En outre, Josias extermina les initiés et les devins; Il détruisit les idoles, les images et toutes les abominations qui existaient tant à Jérusalem qu'en Juda, afin de respecter les paroles de la Loi écrite dans le livre, que le prêtre Chelsias avait trouvé dans la maison du Seigneur.
Síwájú sí, Josiah sì lé àwọn oṣó àti àwọn ẹ̀mí ní àwọn ìdílé, àti àwọn òrìṣà àti gbogbo àwọn nǹkan ìríra tí a rí ní Juda àti ní Jerusalẹmu. Èyí ni ó ṣe kí ó le è mú ọ̀rọ̀ òfin náà ṣe ní ti òfin tí a kọ sínú ìwé tí Hilkiah àlùfáà ti rí nínú ilé Olúwa.
25 Il n'y avait point eu auparavant de roi qui, comme lui, se convertît à Dieu de tout son cœur, de toute son âme et de toutes ses forces, conformément à la loi de Moïse; et il n'y en eut point après lui.
Kò sì sí ọba kankan níwájú tàbí lẹ́yìn Josiah tí ó dàbí rẹ̀, tí ó yí padà sí olúwa tinútinú àti gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe tọkàntọkàn pẹ̀lú gbogbo ẹ̀mí i rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin Mose.
26 Mais le Seigneur ne détourna point la colère dont il était enflammé contre Juda, à cause des offenses qu'il avait reçues de Manassé.
Bí ó ti wù kí ó rí Olúwa kò yípadà kúrò nínú ìmúná ìbínú ńlá rẹ̀ tí ó jó sí Juda, nítorí gbogbo èyí tí Manase ti ṣe láti mú un bínú.
27 Et le Seigneur dit: J'expulserai aussi Juda de devant ma face comme j'ai expulsé Israël; je répudierai cette ville que j'avais choisie, cette Jérusalem, et le temple dont j'avais dit: C'est là que sera mon nom.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí pé, “Èmi yóò mú Juda kúrò pẹ̀lú níwájú mi, bí mo ti mú Israẹli, èmi yóò sì kó Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí mo yàn àti ilé Olúwa yìí, nípa èyí tí mo sọ, ‘Níbẹ̀ ni orúkọ mi yóò wà?’”
28 Quant au reste de l'histoire de Josias, n'est-il pas écrit au livre des Faits et gestes des rois de Juda?
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Josiah, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
29 Sous son règne, le Pharaon d'Égypte Néchao marcha sur le fleuve Euphrate contre le roi des Assyriens; Josias se porta à sa rencontre, et Néchao le tua à Mageddo, au premier choc.
Nígbà tí Josiah jẹ́ ọba, Farao Neko ọba Ejibiti gòkè lọ sí odò Eufurate láti lọ ran ọba Asiria lọ́wọ́. Ọba Josiah jáde lọ láti lọ bá a pàdé lójú ogun ṣùgbọ́n Neko dojúkọ ọ́, ó sì pa á ní Megido.
30 Les serviteurs placèrent son corps sur un char, et le ramenèrent de Mageddo à Jérusalem, et ils l'ensevelirent dans son sépulcre; alors, le peuple de la terre prit Joachaz, fils de Josias; il le sacra, et il le proclama roi la place de son père.
Ìránṣẹ́ Josiah gbé ara rẹ̀ wá nínú kẹ̀kẹ́ láti Megido sí Jerusalẹmu ó sì sin ín sínú isà òkú rẹ̀. Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jehoahasi ọmọ Josiah. Ó fi àmì òróró yàn án, ó sì ṣe é ní ọba ní ipò baba a rẹ̀.
31 Joachaz avait vingt-trois ans quand il monta sur le trône, et il régna trois mois à Jérusalem; le nom de sa mère était Amital, fille de Jérémie de Lebna.
Jehoahasi sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Hamutali ọmọbìnrin Jeremiah; ó wá láti Libina.
32 Et il fit le mal aux yeux du Seigneur, comme l'avaient fait ses pères.
Ó ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.
33 Et le Pharaon Néchao le transporta en Rablaam dans la terre d'Emath, pour qu'il ne régnât point à Jérusalem; puis, il imposa à la terre un tribut de cent talents d'argent et de cent talents d'or.
Farao Neko sì fi sí inú ìdè ní Ribla ní ilẹ̀ Hamati, kí ó má ba à lè jẹ ọba ní Jerusalẹmu. Ó sì tan Juda jẹ fun iye ìwọ̀n ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì wúrà kan.
34 A sa place, le Pharaon Néchao leur donna pour roi Eliacim, fils de Josias, et il changea son nom, et il l'appela Joacin. Et il emmena Joachaz en Égypte, où il mourut.
Farao Neko ṣe Eliakimu ọmọ Josiah ní ọba ní ipò baba rẹ̀ Josiah. Ó sì yí orúkọ Eliakimu padà sí Jehoiakimu. Ṣùgbọ́n ó mú Jehoahasi, ó sì gbé e lọ sí Ejibiti, níbẹ̀ ni ó sì kú.
35 Joacin donna au Pharaon de l'argent et de l'or, mais il taxa la terre pour payer le tribut au Pharaon; chacun donna de l'argent et de l'or selon sa taxe; tout le peuple donna donc le tribut au Pharaon.
Jehoiakimu sì san fún Farao Neko fàdákà àti wúrà tí ó béèrè. Láti ṣe bẹ́ẹ̀, ó bu owó òde fún ilẹ̀ náà láti san, ó fi agbára gba fàdákà àti wúrà láti ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà ní ìbámu pẹ̀lú iye tí a pín.
36 Joacin avait vingt-cinq ans lorsqu'il monta sur le trône, et il régna onze ans à Jérusalem; sa mère se nommait Jeldaph, fille de Phadaël, de Rhuma.
Jehoiakimu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlá orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sebida ọmọbìnrin Pedaiah ó wá láti Ruma.
37 Et il fit le mal aux yeux du Seigneur comme avaient fait tous ses aïeux.
Ó sì ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.

< 2 Rois 23 >