< 2 Chroniques 28 >

1 Achaz avait vingt-cinq ans lorsqu'il monta sur le trône, et il régna seize ans à Jérusalem; et il ne fit point ce qui est droit devant le Seigneur, comme David, son aïeul.
Ahasi sì jẹ́ ẹni ogún ọdún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́rìndínlógún. Gẹ́gẹ́ bí i Dafidi baba rẹ̀ kò sì ṣe ohun rere ní ojú Olúwa.
2 Mais il marcha dans les voies des rois d'Israël, car il fit des sculptures,
Ó sì rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli ó sì ṣe ère dídá fún ìsìn Baali
3 Et il sacrifia à leurs idoles dans le val de Benennom, et il fit passer ses enfants à travers la flamme; selon les abominations des peuples que le Seigneur avait exterminés devant les fils d'Israël.
Ó sì sun ẹbọ ní àfonífojì Hinnomu, ó sì sun àwọn ọmọ rẹ̀ nínú iná, gẹ́gẹ́ bí ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli
4 Et il brûla de l'encens sur les hauts lieux, et sur les terrasses des maisons, et sous les arbres touffus.
Ó sì rú ẹbọ, ó sì sun tùràrí ní ibi gíga wọ́n nì lórí òkè kékeré àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
5 Alors le Seigneur Dieu le livra au roi de Syrie; il le frappa par ses mains, en permettant aux Syriens d'emmener à Damas une multitude de captifs; il le livra aussi au roi d'Israël, et de ses propres mains, il le frappa d'une grande plaie.
Nítorí náà, Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fi lé ọba Siria lọ́wọ́. Àwọn ará Siria sì pa á run, wọ́n sì kó púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́wọ̀n, wọ́n sì kó wọn wá sí Damasku. Ó sì tún fi lé ọwọ́ ọba Israẹli pẹ̀lú, ẹni tí ó kó wọn ní ìgbèkùn púpọ̀ tí ó sì pa wọ́n ní ìpakúpa.
6 Phacée, fils de Romélie, roi d'Israël, tua, en un seul jour, cent vingt mille hommes de Juda, forts et vaillants, parce qu'ils avaient abandonné le Seigneur Dieu de leurs pères.
Ní ọjọ́ kan Peka, ọmọ Remaliah, pa ọ̀kẹ́ mẹ́fà àwọn ọmọ-ogun ní Juda nítorí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀.
7 Et Zéchri, homme vaillant d'Ephraïm, tua Maasias, fils du roi; Esrican, son grand maître du palais, et Elcana, son lieutenant.
Sikri àti Efraimu alágbára sì pa Maaseiah ọmọ ọba, Aṣrikamu ìjòyè tí ó wà ní ìkáwọ́ ilé ọba, àti Elkana igbákejì ọba.
8 Et les fils d'Israël firent parmi leurs frères trois cent mille captifs: femmes, fils et filles; et ils leur enlevèrent un immense butin, et emportèrent les dépouilles à Samarie.
Àwọn ọmọ Israẹli sì kó ní ìgbèkùn lára àwọn arákùnrin wọn ọ̀kẹ́ mẹ́wàá àwọn aya wọn, àwọn ọmọkùnrin àti obìnrin wọn sì tún kó ọ̀pọ̀ ìkógun, èyí tí wọn kó padà lọ sí Samaria.
9 Or, il y avait là un prophète du Seigneur nommé Obed, qui sortit à la rencontre de l'armée pendant qu'elle revenait à Samarie, et il leur dit: Voilà que la colère du Seigneur Dieu de vos pères est sur Juda; il vous les a livrés, et vous les avez massacrés avec fureur, et le bruit en est monté jusqu'au ciel.
Ṣùgbọ́n wòlíì Olúwa tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Odedi wà níbẹ̀, ó sì jáde lọ láti lọ pàdé ogun nígbà tí ó padà sí Samaria. Ó sì wí fún wọn pé, “Nítorí Olúwa, Ọlọ́run baba yín bínú sí Juda ó sì fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin pa wọ́n ní ìpa oró tí ó de òkè ọ̀run.
10 Et maintenant vous pensez garder comme esclaves les fils de Juda et de Jérusalem; mais ne suis-je point parmi vous pour prendre à témoin le Seigneur votre Dieu?
Nísinsin yìí, ẹ̀yin ń pète láti mú ọkùnrin àti obìnrin Juda àti Jerusalẹmu ṣe gẹ́gẹ́ bí ẹrú yín, ẹ̀yin kò ha jẹ̀bi Olúwa Ọlọ́run yín, àní ẹ̀yin?
11 Écoutez-moi donc, et délivrez les captifs que vous avez enlevés chez vos frères; car la colère du Dieu terrible est sur vous.
Nísinsin yìí ẹ gbọ́ tèmi! Ẹ rán àwọn ìgbèkùn tí ẹ̀yin ti mú gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹlẹ́wọ̀n padà nítorí ìbínú kíkan Olúwa ń bẹ lórí yín.”
12 Et les chefs des fils d'Ephraïm: Udie, fils de Jean; Barachias, fils de Mosolmoth; Ezéchias, fils de Sellem; et Amasias, fils d'Eldaï, s'élevèrent pareillement contre ceux qui revenaient du combat.
Lẹ́yìn náà, díẹ̀ nínú àwọn olórí ní Efraimu, Asariah ọmọ Jehohanani, Berekiah ọmọ Meṣilemoti, Jehiskiah ọmọ Ṣallumu, àti Amasa ọmọ Hadlai, dìde sí àwọn tí o ti ogun náà bọ̀.
13 Et ils leur dirent: Vous n'introduirez point ici, chez nous, ces captifs; car, lorsque vous péchez contre le Seigneur, votre péché retombe sur nous; et vous entendez ajouter à vos péchés et à vos délits par ignorance, quand déjà vos fautes sont nombreuses, et quand une terrible colère du Seigneur est sur Israël?
Wọn si wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ mú àwọn ẹlẹ́wọ̀n wá síbí,” “tàbí àwa ti jẹ̀bi níwájú Olúwa, ṣe ẹ̀yin ń gbèrò láti fi kún ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹ̀bi wa ni: nítorí tí ẹ̀bi wa ti tóbi púpọ̀, ìbínú rẹ̀ kíkan sì wà lórí Israẹli.”
14 Et les guerriers mirent en liberté les captifs, et ils leur rendirent les dépouilles, devant les chefs de toute l'Église.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ológun tú àwọn ẹlẹ́wọ̀n àti ìkógun sílẹ̀ níwájú àwọn ìjòyè àti gbogbo ìjọ ènìyàn.
15 Et les hommes qui viennent d'être nominativement désignés, se levèrent, prirent soin des captifs, les vêtirent d'objets compris dans les dépouilles, les habillèrent, les chaussèrent, leur donnèrent des vivres pour manger, de l'huile pour se parfumer, firent monter les infirmes sur des ânes, les menèrent avec leurs frères jusqu'à Jéricho, ville des palmiers, et retournèrent à Samarie.
Àwọn ọkùnrin tí a pè pẹ̀lú orúkọ náà sì dìde, wọn sì mú àwọn ìgbèkùn náà, wọ́n sì fi ìkógun náà wọ̀ gbogbo àwọn tí ó wà ní ìhòhò nínú wọn, wọ́n sì wọ̀ wọ́n ní aṣọ, wọ́n sì bọ̀ wọ́n ní bàtà, wọ́n sì fún wọn ní oúnjẹ àti ohun mímu, wọ́n sì fi òróró kùn wọ́n ní ara, wọ́n sì kó gbogbo àwọn tí ó jẹ́ aláìlera nínú wọ́n sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kó wọn padà sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wọn ní Jeriko, ìlú ọ̀pẹ, wọ́n sì padà sí Samaria.
16 En ce temps-là, le roi Achaz envoya chez le roi assyrien demander son secours,
Ní àkókò ìgbà náà, ọba Ahasi ránṣẹ́ sí ọba Asiria fún ìrànlọ́wọ́.
17 Et voici pourquoi: les Sidoniens faisaient des irruptions; ils frappaient Juda, et lui enlevaient des captifs.
Àwọn ará Edomu sì tún padà wá láti kọlu Juda kí wọn sì kó àwọn ẹlẹ́wọ̀n lọ.
18 Les Philistins aussi avaient pris les armes contre les villes de la plaine, au midi de Juda, et s'étaient emparés de Bethsamys, de Galero, de Socho et de ses bourgs, de Thamna et de ses bourgs, de Gamzo et de ses bourgs, et ils s'y étaient établis.
Nígbà tí àwọn ará Filistini sì ti jagun ní ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n nì àti síhà gúúsù Juda. Wọ́n ṣẹ́gun wọ́n sì gba Beti-Ṣemeṣi, Aijaloni àti Gederoti, àti Soko, Timna, a ri Gimiso, pẹ̀lú ìletò wọn.
19 Car le Seigneur avait humilié Juda, à cause du roi Achaz qui s'était détourné du Seigneur.
Olúwa sì rẹ Juda sílẹ̀ nítorí Ahasi ọba Israẹli, nítorí ó sọ Juda di aláìní ìrànlọ́wọ́, ó sì ṣe ìrékọjá gidigidi sí Olúwa.
20 Alors, Thelgath-Phalnasar, roi des Assyriens, intervint, mais contre lui, et il l'opprima.
Tiglat-Pileseri ọba Asiria wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó fún ní ìpọ́njú dípò ìrànlọ́wọ́.
21 Et Achaz prit les richesses du temple du Seigneur, celles du palais du roi, celles des demeures des princes, et il les donna au roi assyrien; or, celui-ci n'était pas venu pour le secourir,
Ahasi mú díẹ̀ nínú ìní ilé Olúwa àti láti ilé ọba àti láti ọ̀dọ̀ ọba ó sì fi wọ́n fún ọba Asiria: ṣùgbọ́n èyí kò ràn wọ́n lọ́wọ́.
22 Mais pour l'écraser; cependant, le roi Achaz continua de se détourner du Seigneur, et il dit:
Ní àkókò ìpọ́njú rẹ̀ ọba Ahasi sì di aláìṣòótọ́ sí Olúwa.
23 Je chercherai les dieux de Damas qui me frappent. Puis, il ajouta: Ce sont les dieux du roi de Syrie qui lui donnent de la force; je leur sacrifierai donc, et ils me protégeront. Et ils furent une cause de chute pour lui et pour Israël.
Ó sì rú ẹbọ sí òrìṣà àwọn Damasku, ẹni tí ó ṣẹ́gun wọn, nítorí ó rò wí pé, “Nítorí àwọn òrìṣà àwọn ọba Siria ti ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọn kí ó bà lè ràn mí lọ́wọ́.” Ṣùgbọ́n àwọn ni ìparun rẹ̀ àti ti gbogbo Israẹli.
24 Achaz retira donc les vases du temple du Seigneur, il les brisa, ferma les portes du temple, et se fit des autels dans tous les carrefours de Jérusalem.
Ahasi sì kó gbogbo ohun èlò láti ilé Olúwa jọ ó sì kó wọn lọ. Ó sì ti ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tẹ́ pẹpẹ fún ara rẹ̀ ní gbogbo igun Jerusalẹmu.
25 Et il établit des hauts lieux dans toutes les villes de Juda pour que l'on y encensât des dieux étrangers; et les fils de Juda excitèrent le courroux du Seigneur Dieu de leurs pères.
Ní gbogbo ìlú Juda ó sì kọ́ ibi gíga láti sun ẹbọ fún àwọn ọlọ́run mìíràn. Kí ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn bínú.
26 Le reste de ses faits et gestes, les premiers et les derniers, sont écrits au livre des Rois de Juda et d'Israël.
Ìyókù iṣẹ́ ìjọba rẹ̀ àti gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sínú ìwé àwọn ọba Juda àti ti Israẹli.
27 Et Achaz s'endormit avec ses pères, et il fut enseveli en la ville de David; mais on ne le transporta pas dans le sépulcre des rois d'Israël, et son fils Ezéchias régna à sa place.
Ahasi sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní ìlú Jerusalẹmu ṣùgbọ́n wọn kò mú un wá sínú àwọn isà òkú àwọn ọba Israẹli. Hesekiah ọmọ rẹ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< 2 Chroniques 28 >