< 2 Chroniques 21 >

1 Et Josaphat s'endormit avec ses pères; et il fut enseveli dans la ville de David, et Joram, son fils, régna à sa place.
Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
2 Il avait six frères nés de Josaphat: Azarias, Jehiel, Zacharie, Azarias, Michel et Zaphatias. Tels furent les fils de Josaphat, roi de Juda.
Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
3 Leur père les avait richement dotés d'argent, d'or et d'armes avec des places fortes en Juda; mais il laissa le royaume à Joram, parce qu'il était le premier-né.
Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
4 Et Joram se mit en marche dans son royaume, et il s'affermit, et il fit périr par le glaive tous ses frères avec quelques-uns des chefs d'Israël.
Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
5 Il avait trente-deux ans quand il monta sur le trône, et il régna huit ans à Jérusalem.
Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
6 Et il marcha dans la voie du roi d'Israël, comme avait fait la maison d'Achab, parce que sa femme était fille d'Achab, et il fit le mal devant le Seigneur.
Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
7 Toutefois, le Seigneur ne voulait pas détruire la maison de David, à cause de l'alliance qu'il avait faite avec lui, et parce qu'il avait promis de donner, à lui et à ses fils, un flambeau qui ne s'éteindrait jamais.
Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
8 En ces jours-là, Edom se souleva contre Juda, et mit à sa tête un roi.
Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
9 Et Joram partit avec ses chefs et toute sa cavalerie, et il se leva la nuit, et il tailla en pièces Edom qui l'avait enveloppé; les chefs des chars, le peuple, tout s'enfuit chacun en sa demeure.
Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
10 Or, Edom est resté en révolte contre Juda jusqu'à nos jours. En ce temps- là, Lomna se souleva aussi contre Joram, parce qu'il avait abandonné le Seigneur Dieu de ses pères,
Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
11 Et qu'il avait bâti des hauts lieux dans les villes de Juda, et entraîné les habitants de Jérusalem à se prostituer, et qu'il avait égaré Juda.
Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
12 Alors, il lui vint une lettre du prophète Elie, disant: Voici ce que dit le Seigneur Dieu de David, ton aïeul: En punition de ce que tu n'as point marché dans la voie de Josaphat, ton père, ni dans la voie d'Asa, roi de la Judée;
Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
13 Et de ce que tu as marché dans les voies des rois d'Israël, et de ce que tu as entraîné Juda et les habitants de Jérusalem à se prostituer, comme s'est prostituée la maison d'Achab, et de ce que tu as tué tes frères, fils de ton père, qui valaient mieux que toi,
Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
14 Voilà que le Seigneur va te frapper d'une grande plaie au milieu de ton peuple, de tes fils, de tes femmes, de toutes tes richesses.
Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
15 Tu seras atteint d'une maladie cruelle, d'un mal d'entrailles, et tous tes intestins sortiront de jour en jour par l'effet de cette maladie.
Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
16 Et le Seigneur excita contre Joram les Philistins, les Arabes et les voisins de l'Éthiopie.
Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
17 Et ils marchèrent sur Juda, et furent vainqueurs; ils enlevèrent tout ce qu'ils trouvèrent dans le palais du roi, avec ses fils et ses filles; il ne lui resta pas de fils, hormis Ochozias, le plus jeune de tous.
Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
18 Après cela, le Seigneur le frappa d'un mal d'entrailles incurable;
Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
19 Et les jours s'écoulèrent, et après deux ans accomplis, le mal avait fait sortir tous ses intestins, et il mourut dans une angoisse cruelle. Et son peuple ne lui fit point de funérailles comme il en avait fait à Josaphat, son père.
Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
20 Il était monté sur le trône à trente-deux ans, et il avait régné huit ans à Jérusalem, et il n'avait pas marché d'une manière digne de louange, et il fut enseveli dans la ville de David, mais non dans le sépulcre des rois.
Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.

< 2 Chroniques 21 >