< 1 Samuel 15 >

1 Et Samuel dit à Saül: Le Seigneur m'a jadis envoyé pour t'oindre roi d'Israël; maintenant, écoute la voix du Seigneur.
Samuẹli wí fún Saulu pé, “Èmi ni Olúwa rán láti fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli; fetísílẹ̀ láti gbọ́ iṣẹ́ tí Olúwa rán mi sí ọ́.
2 Voici ce que dit le Seigneur sabaoth: Je veux tirer vengeance de ce qu'a fait Amalec contre Israël lorsqu'il est venu à sa rencontre sur sa voie, comme il revenait d'Égypte.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi yóò jẹ àwọn Amaleki ní yà fún ohun tí wọ́n ti ṣe sí Israẹli nígbà tí wọn dè wọn lọ́nà nígbà tí wọn ń bọ̀ láti Ejibiti.
3 Marche donc, et tu frapperas Amalec et Hiérim, et ce qui lui appartient; tu ne t'en approprieras rien, tu extermineras tout. Amalec sera anathème avec tout ce qui lui appartient; tu n'en épargneras aucune chose. Tu mettras à mort hommes et femmes, nourrissons et nourrices, bœufs et brebis, chamelles et ânesses.
Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọlu Amaleki, kí o sì pa gbogbo ohun tí ó bá jẹ́ tiwọn ní à parun. Má ṣe dá wọn sí, pa ọkùnrin àti obìnrin wọn, ọmọ kékeré àti ọmọ ọmú, màlúù àti àgùntàn, ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.’”
4 Et Saül convoqua le peuple, et il passa en revue, à Galgala, quatre cent mille combattants, outre trente mille hommes de Juda.
Bẹ́ẹ̀ ni Saulu kó àwọn ènìyàn jọ, ó sì ka iye wọn ní Talaemu, wọ́n sì jẹ́ ogún ọ̀kẹ́ àwọn ológun ẹlẹ́ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Juda.
5 Puis, Saül marcha sur la ville d'Amalec, et il se mit en embuscade dans le torrent.
Saulu sì lọ sí ìlú Amaleki ó sì gọ dè wọ́n ní àfonífojì kan.
6 Et Saül dit au Cénéen: Éloigne-toi et te sépare des Amalécites, de peur que je ne te confonde avec eux, car tu as été miséricordieux pour les fils d'Israël quand ils revenaient d'Égypte. Et le Cénéen se sépara d'Amalec.
Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ará Keni pé, “Ẹ lọ, kúrò ní Amaleki kí èmi má ba à run yín pẹ̀lú wọn; nítorí ẹ̀yin fi àánú hàn fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n gòkè ti Ejibiti wá.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Kenaiti lọ kúrò láàrín àwọn Amaleki.
7 Et Saül battit Amalec, depuis Evilat jusqu'à Sur, en face de l'Égypte.
Nígbà náà ni Saulu kọlu àwọn Amaleki láti Hafila dé Ṣuri, tí ó fi dé ìlà-oòrùn Ejibiti.
8 Il prit vivant Agag, roi d'Amalec, et il passa au fil de l'épée tout le peuple, tout Hiérim.
Ó sì mú Agagi ọba Amaleki láààyè, ó sì fi idà rẹ̀ kọlù gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀.
9 Mais Saül et tout le peuple laissèrent vivre Agag; ils épargnèrent ce qu'il y avait de meilleur parmi ses brebis, ses bœufs, ses vivres, le vin de ses vignes, tous ses biens; ils résolurent de ne les point détruire, et ils détruisirent toutes les choses viles ou de peu de valeur.
Ṣùgbọ́n Saulu àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ dá Agagi sí àti èyí tí ó dára jùlọ nínú àgùntàn àti màlúù àti ọ̀dọ́-àgùntàn àbọ́pa àti gbogbo nǹkan tó dára. Wọ́n kò sì fẹ́ pa àwọn wọ̀nyí run pátápátá ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan tí kò dára tí kò sì níláárí ni wọ́n parun pátápátá.
10 Et la parole du Seigneur vint à Samuel, disant:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Samuẹli wá pé,
11 Je me reproche d'avoir fait roi Saül, parce qu'il a cessé de me suivre, et qu'il n'a point observé mes ordres; Samuel en fut abattu, et il cria toute la nuit au Seigneur.
“Èmi káàánú gidigidi pé mo fi Saulu jẹ ọba, nítorí pé ó ti yípadà kúrò lẹ́yìn mi, kò sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́.” Inú Samuẹli sì bàjẹ́ gidigidi, ó sì ké pe Olúwa ní gbogbo òru náà.
12 Et Samuel se leva de grand matin; dès l'aurore, il partit à la rencontre d'Israël. On l'alla rapporter à Saül, disant: Samuel est arrivé au mont Carmel; il a levé une poignée d'hommes. A ce moment, Samuel tourna son char, et il descendit à Galgala vers Saül, comme celui-ci offrait en holocauste au Seigneur les prémices des dépouilles qu'il avait amenées d'Amalec.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Samuẹli sì dìde láti lọ pàdé Saulu, ṣùgbọ́n wọ́n sọ fún un pé, “Saulu ti wá sí Karmeli. Ó ti kọ́ ibìkan fún ara rẹ̀ níbẹ̀, ó sì ti yípadà, ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Gilgali.”
13 Samuel s'approcha de Saül, et Saül lui dit: Béni sois-tu au nom du Seigneur, j'ai fait tout ce qu'a ordonné le Seigneur.
Nígbà tí Samuẹli sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Saulu sì wí fún un pé, “Olúwa bùkún fún ọ, mo ti ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ.”
14 Mais Samuel dit à Saül: Quels sont donc ces bêlements de brebis qui parviennent à mes oreilles, et ces mugissements de bœufs que je viens d'entendre?
Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Èwo wá ni igbe àgùntàn tí mo ń gbọ́ ní etí mi? Kí ni igbe màlúù ti mo ń gbọ́ yìí?”
15 Et Saül lui dit: J'ai amené ce bétail d'Amalec; le peuple a épargné les plus belles têtes pour les sacrifier au Seigneur; j'ai détruit tout le reste.
Saulu sì dáhùn pé, “Àwọn ọmọ-ogun ní o mú wọn láti Amaleki wá, wọ́n dá àwọn àgùntàn, àti màlúù tí ó dára jùlọ sí láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ṣùgbọ́n a pa àwọn tókù run pátápátá.”
16 Alors, Samuel dit à Saül: Permets, je vais te dévoiler ce que cette nuit m'a dit le Seigneur. Et Saül répondit: Parle.
Samuẹli sí wí fún Saulu pé, “Dákẹ́ ná, jẹ́ kí èmi kí ó sọ ohun tí Olúwa wí fún mi ní alẹ́ àná fún ọ.” Saulu sì wí pé, “Sọ fún mi.”
17 Et Samuel dit à Saül: N'es-tu point petit à ses yeux, toi qui règnes sur les tribus d'Israël? C'est le Seigneur qui t'a sacré roi.
Samuẹli sì wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ fi ìgbà kan kéré lójú ara rẹ, ǹjẹ́ ìwọ kò ha di olórí ẹ̀yà Israẹli? Olúwa fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.
18 Et le Seigneur t'a envoyé contre Amalec, et il t'a dit: Marche, et extermine. Mets à mort ce peuple qui a péché contre moi; fais-lui la guerre jusqu'à ce que tu l'aies détruit.
Olúwa sì rán ọ níṣẹ́ wí pé, ‘Lọ, kí o sì pa àwọn ènìyàn búburú ará Amaleki run pátápátá; gbóguntì wọ́n títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’
19 Pourquoi donc n'as-tu pas été docile à la voix du Seigneur? Pourquoi as- tu pris sur toi de disposer du butin? Pourquoi as-tu fait le mal devant le Seigneur?
Èéṣe tí ìwọ kò fi gbọ́ ti Olúwa? Èéṣe tí ìwọ fi sáré sí ìkógun tí o sì ṣe búburú níwájú Olúwa?”
20 C'est, reprit Saül, pour avoir écouté la clameur du peuple; je suivais la voie que m'avait indiquée le Seigneur; j'avais fait prisonnier Agag, et exterminé Amalec;
Saulu sì wí fún Samuẹli pé, “Ṣùgbọ́n èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa, èmi sì ti lọ ní ọ̀nà tí Olúwa rán mi. Mo sì ti pa àwọn ará Amaleki run pátápátá, mo sì ti mú Agagi ọba wọn padà wá.
21 Mais le peuple prit des dépouilles ce qu'il y avait de meilleur, parmi les brebis et les bœufs, pour les sacrifier, en Galgala, au Seigneur notre Dieu.
Àwọn ọmọ-ogun ti mú àgùntàn àti màlúù lára ìkógun èyí tí ó dára láti fi fún Olúwa láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Gilgali.”
22 Les holocaustes, dit Samuel, et les victimes sont-ils plus agréables au Seigneur que l'obéissance à sa voix? La docilité vaut mieux que les offrandes; l'obéissance vaut mieux que la graisse des béliers.
Ṣùgbọ́n Samuẹli dáhùn pé, “Olúwa ha ní inú dídùn sí ẹbọ sísun àti ẹbọ ju kí a gba ohùn Olúwa gbọ́? Ìgbọ́ràn sàn ju ẹbọ lọ, ìfetísílẹ̀ sì sàn ju ọ̀rá àgbò lọ.
23 La désobéissance est un péché comme la divination; les theraphim amènent peines et douleurs. Parce que tu as dédaigné la parole du Seigneur, le Seigneur te rejettera du trône d'Israël.
Nítorí pé ìṣọ̀tẹ̀ dàbí ẹ̀ṣẹ̀ àfọ̀ṣẹ, àti ìgbéraga bí ẹ̀ṣẹ̀ ìbọ̀rìṣà. Nítorí tí ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa, Òun sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba.”
24 J'ai péché, répondit Saül, en transgressant l'ordre du Seigneur et le tien; j'ai eu crainte du peuple, et j'ai écouté sa clameur.
Nígbà náà ni Saulu wí fún Samuẹli pé, “Èmi ti ṣẹ̀. Mo ti rú òfin Olúwa àti ọ̀rọ̀ rẹ̀. Èmi sì bẹ̀rù àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni èmi sì gba ohùn wọn gbọ́.
25 Maintenant, ôte-moi mon péché, reviens avec moi, et j'adorerai le Seigneur ton Dieu.
Mo bẹ̀ ọ́ nísinsin yìí, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì, kí ó sì yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè sin Olúwa.”
26 Mais Samuel dit à Saül: Je ne reviendrai plus vers toi; parce que tu as méprisé la parole du Seigneur, le Seigneur te méprisera; tu ne seras plus roi d'Israël.
Ṣùgbọ́n Samuẹli wí fún un pé, “Èmi kò ní bá ọ padà. Ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa sílẹ̀, Olúwa sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba lórí Israẹli!”
27 Et Samuel se retourna pour partir, mais Saül saisit le pan de son double manteau, et il le déchira.
Bí Samuẹli sì ti fẹ́ yípadà láti lọ, Saulu sì di ẹ̀wù ìlekè rẹ̀ mú, ó sì fàya;
28 Et Samuel lui dit: Le Seigneur, par tes mains, a déchiré aujourd'hui ta royauté en Israël; il la donnera à ton prochain qui vaut mieux que toi.
Samuẹli sì wí fún un pé, “Olúwa ti fa ìjọba Israẹli ya kúrò lọ́wọ́ ọ̀ rẹ lónìí, ó sì ti fi fún aládùúgbò rẹ kan tí ó sàn jù ọ́ lọ.
29 Israël aussi sera déchiré en deux parts; le Seigneur ne changera pas, et il ne se repentira pas; car il n'est point comme un homme pour se repentir.
Ẹni tí ó ń ṣe ògo Israẹli, kì í purọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì í yí ọkàn rẹ̀ padà; nítorí kì í ṣe ènìyàn tí yóò yí ọkàn rẹ̀ padà.”
30 Et Saül dit: J'ai péché; mais ne laisse pas de m'honorer devant les anciens d'Israël et devant mon peuple; viens-t'en avec moi, et j'adorerai ton Dieu.
Saulu sì wí pé, “Èmi ti ṣẹ̀, ṣùgbọ́n jọ̀wọ́ bu ọlá fún mi níwájú àwọn àgbàgbà ènìyàn mi, àti níwájú u Israẹli, yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè tẹríba fún Olúwa Ọlọ́run rẹ.”
31 Et Samuel revint auprès de Saül, et celui-ci adora le Seigneur.
Bẹ́ẹ̀ ni Samuẹli sì yípadà pẹ̀lú Saulu, Saulu sì sin Olúwa.
32 Samuel dit ensuite: Amenez-moi Agag, roi d'Amalec; et Agag arriva tout tremblant. Et Agag dit: Faut-il que la mort soit si amère?
Nígbà náà ni Samuẹli wí pé, “Mú Agagi ọba àwọn ará Amaleki wá fún mi.” Agagi sì tọ̀ ọ́ wá ní ìgboyà pẹ̀lú èrò pé, “Nítòótọ́ ìkorò ikú ti kọjá.”
33 Et Samuel dit à Agag: De même que par ton glaive les femmes sont restées sans enfants, ta mère, parmi les femmes, tout à l'heure n'aura plus d'enfant. Et Samuel égorgea Agag devant le Seigneur, à Galgala.
Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Bí idà rẹ ti sọ àwọn obìnrin di aláìní ọmọ bẹ́ẹ̀ ni ìyá rẹ yóò sì di aláìní ọmọ láàrín obìnrin.” Samuẹli sì pa Agagi níwájú Olúwa ni Gilgali.
34 Puis, Samuel retourna en Armathem, et Saül partit pour sa demeure à Gabaa.
Nígbà náà ni Samuẹli lọ sí Rama, Saulu sì gòkè lọ sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah tí Saulu.
35 Et Samuel cessa de visiter Saül jusqu'au jour de sa mort; mais il pleurait sur lui, parce que le Seigneur s'était repenti d'avoir fait Saül roi d'Israël.
Samuẹli kò sì padà wá mọ́ láti wo Saulu títí ó fi di ọjọ́ ikú u rẹ̀, ṣùgbọ́n Samuẹli káàánú fún Saulu. Ó sì dun Olúwa pé ó fi Saulu jẹ ọba lórí Israẹli.

< 1 Samuel 15 >