< 1 Samuel 1 >

1 Il y avait dans les montagnes d'Ephraïm un homme d'Armathaïm-Sipha; il se nommait Elcana, fils de Jéréméel, fils d'Eliu, fils de Thocé, l'un des Nasib d'Ephraïm.
Ọkùnrin kan wà, láti Ramataimu-Sofimu, láti ìlú olókè Efraimu, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elihu, ọmọ Tohu, ọmọ Sufu, ará Efrata.
2 Il avait deux femmes: le nom de la première était Anne; le nom de la seconde, Phenenna; or, Phenenna avait des enfants, et Anne n'en avait point.
Ó sì ní ìyàwó méjì, orúkọ wọn ni Hana àti Penina: Penina ní ọmọ, ṣùgbọ́n Hana kò ní.
3 Les jours s'écoulèrent, et l'homme partit de la ville d'Armathaïm pour adorer le Seigneur Dieu sabaoth, et lui sacrifier en Silo; Héli et ses deux fils Ophni et Phinéès étaient alors prêtres du Seigneur.
Ní ọdọọdún, ọkùnrin yìí máa ń gòkè láti ìlú rẹ̀ láti lọ sìn àti láti ṣe ìrúbọ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ ní Ṣilo, níbi tí àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì, Hofini àti Finehasi ti jẹ́ àlùfáà Olúwa.
4 Le jour venu, Elcana sacrifia; puis, il donna des parts à Phenenna, sa femme, et à ses fils.
Nígbàkígbà tí ó bá kan Elkana láti ṣe ìrúbọ, òun yóò bù lára ẹran fún aya rẹ̀ Penina àti fún gbogbo àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin.
5 Mais il ne donna qu'une part à Anne, parce qu'elle n'avait pas d'enfants. Cependant, Elcana aimait Anne plus que la première; et le Seigneur avait clos ses entrailles;
Ṣùgbọ́n ó máa ń pín ìlọ́po fun Hana nítorí pé ó fẹ́ràn rẹ̀ àti pé Olúwa ti sé e nínú.
6 Car le Seigneur, quels que fussent son affliction et l'abattement causé par son affliction, ne lui avait point donné d'enfants. Elle était découragée, parce que le Seigneur avait clos ses entrailles, et ne lui avait point donné d'enfants.
Nítorí pé Olúwa ti sé e nínú, orogún rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní fín níràn láti lè mú kí ó bínú.
7 Les choses se passaient de la sorte tous les ans lorsqu'elle montait à la maison du Seigneur; elle était abattue, et elle pleurait, et elle ne mangeait point.
Eléyìí sì máa ń ṣẹlẹ̀ ní ọdọọdún. Nígbàkígbà tí Hana bá gòkè lọ sí ilé Olúwa, orogún rẹ̀ a máa fín níràn títí tí yóò fi máa sọkún tí kò sì ní lè jẹun.
8 Et son époux Elcana lui dit: Anne; et elle répondit: Me voici, seigneur; et il reprit: Qu'as-tu à pleurer? Pourquoi ne manges-tu point? Pourquoi ton cœur te fait-il souffrir? Ne suis-je pas pour toi meilleur que dix enfants?
Elkana ọkọ rẹ̀ yóò sọ fún un pé, “Hana èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Èéṣe tí ìwọ kò fi jẹun? Èéṣe tí ìwọ fi ń ba ọkàn jẹ́? Èmi kò ha ju ọmọ mẹ́wàá lọ fún ọ bí?”
9 Et, après qu'ils eurent mangé à Silo, Anne se leva, puis elle alla se placer devant le Seigneur, pendant qu'Héli le prêtre était sur son siège, devant le seuil du temple du Seigneur.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹ, tí wọ́n tún mu tán ní Ṣilo, Hana dìde wá síwájú Olúwa. Nígbà náà, Eli àlùfáà wà lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ní ibi tí ó máa ń jókòó.
10 Là, tout affligée en son cœur, elle fit au Seigneur une prière, et elle se prit à pleurer amèrement.
Pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn Hana sọkún gidigidi, ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
11 Et elle fit un vœu au Seigneur, disant: Adonaï, Seigneur, Eloé sabaoth, si vous jetez les yeux sur l'humiliation de votre servante, si vous vous souvenez de moi, si vous donnez à votre servante un fils, je vous le consacrerai jusqu'au jour de sa mort; il ne boira ni vin ni boisson enivrante, et le fer ne passera jamais sur sa tête.
Ó sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, jùlọ tí ìwọ bá le bojú wo ìránṣẹ́bìnrin rẹ kí ìwọ sì rántí rẹ̀, tí ìwọ kò sì gbàgbé ìránṣẹ́ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ yóò fún un ní ọmọkùnrin, nígbà náà èmi yóò sì fi fún Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ a kì yóò sì fi abẹ kàn án ní orí.”
12 Et pendant qu'elle prolongeait sa prière devant le Seigneur, Héli le prêtre était attentif au mouvement de ses lèvres,
Bí ó sì ṣe ń gbàdúrà sí Olúwa, Eli sì kíyèsi ẹnu rẹ̀.
13 Car elle parlait en son cœur, et elle remuait les lèvres, mais on n'entendait point sa voix; or, Héli la crut ivre.
Hana ń gbàdúrà láti inú ọkàn rẹ̀, ṣùgbọ́n ètè rẹ̀ ni ó ń mì, a kò gbọ́ ohùn rẹ̀. Eli rò wí pé ó ti mu ọtí yó.
14 Et le serviteur d'Héli alla lui dire: Jusqu'à quand seras-tu donc ivre? Va-t'en avec ton vin; retire-toi de devant le Seigneur.
Eli sì wí fún un pé, “Yóò ti pẹ́ fún ọ tó tí ìwọ yóò máa yó? Mú ọtí wáìnì rẹ̀ kúrò.”
15 Anne répondit, et elle dit au prêtre: Non, seigneur, je suis aujourd'hui une femme pleine d'affliction, je n'ai bu ni vin ni boisson enivrante, et je répands mon âme devant le Seigneur.
Hana dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, Olúwa mi, èmi ni obìnrin oníròbìnújẹ́. Èmi kò mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle; èmi ń tú ọkàn mi jáde sí Olúwa ni.
16 Ne prends pas ta servante pour une fille de pestilence; c'est à cause de l'abondance de mes méditations que j'ai prolongé jusqu'à ce moment ma prière.
Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí obìnrin búburú. Èmi ti ń gbàdúrà níhìn-ín nínú ìrora ọkàn àti ìbànújẹ́ mi.”
17 Héli reprenant, lui dit: Va en paix, que le Dieu d'Israël t'accorde toute ta prière, tout ce que tu lui as demandé.
Eli dáhùn pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, kí Ọlọ́run Israẹli fi ohun tí ìwọ ti béèrè ní ọwọ́ rẹ̀ fún ọ.”
18 Alors, elle dit: Ta servante a trouvé grâce devant tes yeux. Et la femme s'en alla, elle rentra à son logis, elle mangea et but avec son mari, et son visage cessa d'être abattu.
Ó wí pé, “Kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà bá tirẹ̀ lọ, ó sì jẹun, kò sì fa ojú ro mọ́.
19 Ensuite, s'étant levés de grand matin, ils adorèrent le Seigneur, et reprirent leur chemin; Elcana rentra dans sa maison d'Armathaïm, et il connut Anne; or, le Seigneur se souvint d'elle, et elle conçut.
Wọ́n sì dìde ni kùtùkùtù òwúrọ̀, wọn wólẹ̀ sìn níwájú Olúwa, wọn padà wa sí ilé wọn ni Rama: Elkana si mọ Hana aya rẹ̀: Olúwa sì rántí rẹ̀.
20 Le temps révolu, elle enfanta un fils, et elle l'appela Samuel, parce que, dit-elle, je l'avais demandé au Seigneur Dieu sabaoth.
Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ rẹ̀ pé, lẹ́yìn ìgbà tí Hana lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Samuẹli, pé, “Nítorí tí mo béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ Olúwa.”
21 Or, son époux Elcana, avec toute sa famille, monta à Silo pour offrir au Seigneur le sacrifice de la saison, ses oblations votives, et la dîme de tous les fruits de ses champs.
Ọkùnrin náà Elkana, àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, gòkè lọ láti rú ẹbọ ọdún sí Olúwa, àti láti sán ẹ̀jẹ́ rẹ̀.
22 Mais Anne ne partit pas avec lui, et elle dit à son époux: J'irai quand l'enfant ira, quand je l'aurai sevré, et qu'il sera présenté au Seigneur pour y rester toujours.
Ṣùgbọ́n Hana kò gòkè lọ; nítorí tí ó sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ó di ìgbà tí mo bá gba ọmú lẹ́nu ọmọ náà, nígbà náà ni èmi yóò mú un lọ, kí òun lè fi ara hàn níwájú Olúwa, kí ó sí máa gbé ibẹ̀ títí láé.”
23 Son époux Elcana lui répondit: Fais ce que bon te semble, demeure ici jusqu'à ce que tu l'aies sevré; que le Seigneur accomplisse toutes les paroles qui sont sorties de ta bouche. Et la femme ne bougea pas, et elle allaita son fils jusqu'à ce qu'elle le sevrât.
Elkana ọkọ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ. Dúró títí ìwọ yóò fi gba ọmú lẹ́nu rẹ̀; ṣùgbọ́n kí Olúwa sá à mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà sì jókòó, ó sì fi ọmú fún ọmọ rẹ̀ títí ó fi gbà á lẹ́nu rẹ̀.
24 Alors, elle partit avec Elcana pour Silo; ils avaient un bœuf de trois ans, des pains, un éphi de fleur de farine et un nébel de vin; elle entra à Silo dans la maison du Seigneur, et son enfant était avec eux.
Nígbà tí ó sì gba ọmú lẹ́nu rẹ̀, ó sì mú un gòkè lọ pẹ̀lú ara rẹ̀. Pẹ̀lú ẹgbọrọ màlúù mẹ́ta, àti ìyẹ̀fun efa kan, àti ìgò ọtí wáìnì kan, ó sì mú un wá sí ilé Olúwa ní Ṣilo: ọmọ náà sì wà ní ọmọdé.
25 Et ils le conduisirent devant le Seigneur; son père égorgea la victime que de saison en saison il sacrifiait au Seigneur; il présenta l'enfant après avoir égorgé le bœuf; et Anne, la mère de l'enfant, le conduisit à Héli,
Wọ́n pa ẹgbọrọ màlúù, wọ́n sì mú ọmọ náà tọ Eli wá.
26 Et elle dit: Je te prie, seigneur, aussi vrai que tu vis, je suis la femme que tu as vue assise devant toi, priant le Seigneur.
Hana sì wí pé, “Olúwa mi, bí ọkàn rẹ ti wà láààyè, Olúwa mi, èmi ni obìnrin náà tí ó dúró lẹ́bàá ọ̀dọ̀ rẹ níhìn-ín tí ń tọrọ lọ́dọ̀ Olúwa.
27 J'ai prié pour obtenir cet enfant, et le Seigneur a exaucé la prière que je lui avais faite.
Ọmọ yìí ni mo ń tọrọ; Olúwa sì fi ìdáhùn ìbéèrè tí mo béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ fún mi.
28 Cet enfant, je le donne au Seigneur pour être tous les jours de sa vie au service du Seigneur; puis, elle dit:
Nítorí náà pẹ̀lú, èmi fi í fún Olúwa; ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀: nítorí tí mo ti béèrè rẹ̀ fún Olúwa.” Wọn si wólẹ̀ sin Olúwa níbẹ̀.

< 1 Samuel 1 >