< Psalms 86 >

1 A Prayer by David. Hear, LORD, and answer me, for I am poor and needy.
Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, kí o sì dá mi lóhùn, nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní.
2 Preserve my soul, for I am godly. You, my God, save your servant who trusts in you.
Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ: ìwọ ni Ọlọ́run mi, gbà ìránṣẹ́ rẹ là tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
3 Be merciful to me, Lord, for I call to you all day long.
Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́.
4 Bring joy to the soul of your servant, for to you, Lord, do I lift up my soul.
Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa, ni mo gbé ọkàn mí sókè sí.
5 For you, Lord, are good, and ready to forgive, abundant in loving kindness to all those who call on you.
Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, Olúwa, ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.
6 Hear, LORD, my prayer. Listen to the voice of my petitions.
Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa; tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú.
7 In the day of my trouble I will call on you, for you will answer me.
Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́, nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn.
8 There is no one like you among the gods, Lord, nor any deeds like your deeds.
Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, Olúwa: kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ.
9 All nations you have made will come and worship before you, Lord. They shall glorify your name.
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá yóò wá láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, Olúwa; wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀.
10 For you are great, and do wondrous things. You are God alone.
Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu; ìwọ nìkan ni Ọlọ́run.
11 Teach me your way, LORD. I will walk in your truth. Make my heart undivided to fear your name.
Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ; fún mi ní ọkàn tí kì í yapa, kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ.
12 I will praise you, Lord my God, with my whole heart. I will glorify your name forever more.
Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé.
13 For your loving kindness is great toward me. You have delivered my soul from the lowest Sheol. (Sheol h7585)
Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi; ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú. (Sheol h7585)
14 God, the proud have risen up against me. A company of violent men have sought after my soul, and they don’t hold regard for you before them.
Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run; àti ìjọ àwọn alágbára ń wá ọkàn mi kiri, wọn kò sì fi ọ́ pè.
15 But you, Lord, are a merciful and gracious God, slow to anger, and abundant in loving kindness and truth.
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere, Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́.
16 Turn to me, and have mercy on me! Give your strength to your servant. Save the son of your servant.
Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi; fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là.
17 Show me a sign of your goodness, that those who hate me may see it, and be shamed, because you, LORD, have helped me, and comforted me.
Fi àmì hàn mí fún rere, kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri, kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ Olúwa ni ó ti tù mí nínú.

< Psalms 86 >