< Lamentations 5 >

1 Remember, LORD, what has come on us. Look, and see our reproach.
Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
2 Our inheritance has been turned over to strangers, our houses to aliens.
Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
3 We are orphans and fatherless. Our mothers are as widows.
Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
4 We must pay for water to drink. Our wood is sold to us.
A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
5 Our pursuers are on our necks. We are weary, and have no rest.
Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
6 We have given our hands to the Egyptians, and to the Assyrians, to be satisfied with bread.
Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
7 Our fathers sinned, and are no more. We have borne their iniquities.
Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8 Servants rule over us. There is no one to deliver us out of their hand.
Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9 We get our bread at the peril of our lives, because of the sword in the wilderness.
Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
10 Our skin is black like an oven, because of the burning heat of famine.
Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
11 They ravished the women in Zion, the virgins in the cities of Judah.
Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
12 Princes were hanged up by their hands. The faces of elders were not honored.
Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
13 The young men carry millstones. The children stumbled under loads of wood.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
14 The elders have ceased from the gate, and the young men from their music.
Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
15 The joy of our heart has ceased. Our dance is turned into mourning.
Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
16 The crown has fallen from our head. Woe to us, for we have sinned!
Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
17 For this our heart is faint. For these things our eyes are dim:
Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
18 for the mountain of Zion, which is desolate. The foxes walk on it.
Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
19 You, LORD, remain forever. Your throne is from generation to generation.
Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
20 Why do you forget us forever, and forsake us for so long a time?
Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
21 Turn us to yourself, LORD, and we will be turned. Renew our days as of old.
Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
22 But you have utterly rejected us. You are very angry against us.
àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.

< Lamentations 5 >