< Psalms 92 >

1 A Psalm. A song for the Sabbath day. It is a good thing to give thanks to the LORD, to sing praises to your name, Most High,
Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
2 to proclaim your loving kindness in the morning, and your faithfulness every night,
láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
3 with the ten-stringed lute, with the harp, and with the melody of the lyre.
lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
4 For you, LORD, have made me glad through your work. I will triumph in the works of your hands.
Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
5 How great are your works, LORD! Your thoughts are very deep.
Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
6 A senseless man doesn’t know, neither does a fool understand this:
Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
7 though the wicked spring up as the grass, and all the evildoers flourish, they will be destroyed forever.
nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
8 But you, LORD, are on high forever more.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
9 For behold, your enemies, LORD, for behold, your enemies shall perish. All the evildoers will be scattered.
Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
10 But you have exalted my horn like that of the wild ox. I am anointed with fresh oil.
Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
11 My eye has also seen my enemies. My ears have heard of the wicked enemies who rise up against me.
Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
12 The righteous shall flourish like the palm tree. He will grow like a cedar in Lebanon.
Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
13 They are planted in the LORD’s house. They will flourish in our God’s courts.
tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
14 They will still produce fruit in old age. They will be full of sap and green,
Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
15 to show that the LORD is upright. He is my rock, and there is no unrighteousness in him.
láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”

< Psalms 92 >