< Nehemiah 7 >

1 Now when the wall was built and I had set up the doors, and the gatekeepers and the singers and the Levites were appointed,
Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
2 I put my brother Hanani, and Hananiah the governor of the fortress, in charge of Jerusalem; for he was a faithful man and feared God above many.
Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
3 I said to them, “Don’t let the gates of Jerusalem be opened until the sun is hot; and while they stand guard, let them shut the doors, and you bar them; and appoint watches of the inhabitants of Jerusalem, everyone in his watch, with everyone near his house.”
Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
4 Now the city was wide and large; but the people were few therein, and the houses were not built.
Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
5 My God put into my heart to gather together the nobles, and the rulers, and the people, that they might be listed by genealogy. I found the book of the genealogy of those who came up at the first, and I found this written in it:
Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
6 These are the children of the province who went up out of the captivity of those who had been carried away, whom Nebuchadnezzar the king of Babylon had carried away, and who returned to Jerusalem and to Judah, everyone to his city,
Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
7 who came with Zerubbabel, Yeshua, Nehemiah, Azariah, Raamiah, Nahamani, Mordecai, Bilshan, Mispereth, Bigvai, Nehum, and Baanah. The number of the men of the people of Israel:
Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
8 The children of Parosh: two thousand and one hundred and seventy-two.
àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
9 The children of Shephatiah: three hundred and seventy-two.
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
10 The children of Arah: six hundred and fifty-two.
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
11 The children of Pahathmoab, of the children of Yeshua and Joab: two thousand and eight hundred and eighteen.
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
12 The children of Elam: one thousand and two hundred and fifty-four.
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
13 The children of Zattu: eight hundred and forty-five.
Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
14 The children of Zaccai: seven hundred and sixty.
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
15 The children of Binnui: six hundred and forty-eight.
Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
16 The children of Bebai: six hundred and twenty-eight.
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
17 The children of Azgad: two thousand and three hundred and twenty-two.
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
18 The children of Adonikam: six hundred and sixty-seven.
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
19 The children of Bigvai: two thousand and sixty-seven.
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
20 The children of Adin: six hundred and fifty-five.
Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
21 The children of Ater: of Hezekiah, ninety-eight.
Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
22 The children of Hashum: three hundred and twenty-eight.
Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
23 The children of Bezai: three hundred and twenty-four.
Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
24 The children of Hariph: one hundred and twelve.
Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
25 The children of Gibeon: ninety-five.
Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
26 The men of Bethlehem and Netophah: one hundred and eighty-eight.
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
27 The men of Anathoth: one hundred and twenty-eight.
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
28 The men of Beth Azmaveth: forty-two.
Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
29 The men of Kiriath Jearim, Chephirah, and Beeroth: seven hundred and forty-three.
Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
30 The men of Ramah and Geba: six hundred and twenty-one.
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
31 The men of Michmas: one hundred and twenty-two.
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
32 The men of Bethel and Ai: one hundred and twenty-three.
Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
33 The men of the other Nebo: fifty-two.
Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
34 The children of the other Elam: one thousand and two hundred and fifty-four.
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
35 The children of Harim: three hundred and twenty.
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
36 The children of Jericho: three hundred and forty-five.
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
37 The children of Lod, Hadid, and Ono: seven hundred and twenty-one.
Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
38 The children of Senaah: three thousand and nine hundred and thirty.
Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
39 The priests: The children of Jedaiah, of the house of Yeshua: nine hundred and seventy-three.
Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
40 The children of Immer: one thousand and fifty-two.
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
41 The children of Pashhur: one thousand and two hundred and forty-seven.
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
42 The children of Harim: one thousand and seventeen.
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
43 The Levites: the children of Yeshua, of Kadmiel, of the children of Hodevah: seventy-four.
Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
44 The singers: the children of Asaph: one hundred and forty-eight.
Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
45 The gatekeepers: the children of Shallum, the children of Ater, the children of Talmon, the children of Akkub, the children of Hatita, the children of Shobai: one hundred and thirty-eight.
Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
46 The temple servants: the children of Ziha, the children of Hasupha, the children of Tabbaoth,
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
47 the children of Keros, the children of Sia, the children of Padon,
Kerosi, Sia, Padoni,
48 the children of Lebana, the children of Hagaba, the children of Salmai,
Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
49 the children of Hanan, the children of Giddel, the children of Gahar,
Hanani, Giddeli, Gahari,
50 the children of Reaiah, the children of Rezin, the children of Nekoda,
Reaiah, Resini, Nekoda,
51 the children of Gazzam, the children of Uzza, the children of Paseah,
Gassamu, Ussa, Pasea,
52 the children of Besai, the children of Meunim, the children of Nephushesim,
Besai, Mehuni, Nefisimu,
53 the children of Bakbuk, the children of Hakupha, the children of Harhur,
Bakbu, Hakufa, Harhuri,
54 the children of Bazlith, the children of Mehida, the children of Harsha,
Basluti, Mehida, Harṣa,
55 the children of Barkos, the children of Sisera, the children of Temah,
Barkosi, Sisera, Tema,
56 the children of Neziah, and the children of Hatipha.
Nesia, àti Hatifa.
57 The children of Solomon’s servants: the children of Sotai, the children of Sophereth, the children of Perida,
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
58 the children of Jaala, the children of Darkon, the children of Giddel,
Jaala, Darkoni, Giddeli,
59 the children of Shephatiah, the children of Hattil, the children of Pochereth Hazzebaim, and the children of Amon.
Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
60 All the temple servants and the children of Solomon’s servants were three hundred and ninety-two.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
61 These were those who went up from Tel Melah, Tel Harsha, Cherub, Addon, and Immer; but they could not show their fathers’ houses, nor their offspring, whether they were of Israel:
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
62 The children of Delaiah, the children of Tobiah, the children of Nekoda: six hundred and forty-two.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
63 Of the priests: the children of Hobaiah, the children of Hakkoz, the children of Barzillai, who took a wife of the daughters of Barzillai the Gileadite, and was called after their name.
Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
64 These searched for their genealogical records, but couldn’t find them. Therefore they were deemed disqualified and removed from the priesthood.
Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
65 The governor told them not to eat of the most holy things until a priest stood up to minister with Urim and Thummim.
Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
66 The whole assembly together was forty-two thousand and three hundred and sixty,
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
67 in addition to their male servants and their female servants, of whom there were seven thousand and three hundred and thirty-seven. They had two hundred and forty-five singing men and singing women.
yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
68 Their horses were seven hundred and thirty-six; their mules, two hundred and forty-five;
Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
69 their camels, four hundred and thirty-five; their donkeys, six thousand and seven hundred and twenty.
ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
70 Some from amongst the heads of fathers’ households gave to the work. The governor gave to the treasury one thousand darics of gold, fifty basins, and five hundred and thirty priests’ garments.
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
71 Some of the heads of fathers’ households gave into the treasury of the work twenty thousand darics of gold, and two thousand and two hundred minas of silver.
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
72 That which the rest of the people gave was twenty thousand darics of gold, plus two thousand minas of silver, and sixty-seven priests’ garments.
Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
73 So the priests, the Levites, the gatekeepers, the singers, some of the people, the temple servants, and all Israel lived in their cities. When the seventh month had come, the children of Israel were in their cities.
Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,

< Nehemiah 7 >