< Psalms 87 >

1 A Psalm by the sons of Korah; a Song. His foundation is in the holy mountains.
Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Orin. Ó ti fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ sórí òkè mímọ́;
2 Yahweh loves the gates of Zion more than all the dwellings of Jacob.
Olúwa fẹ́ràn ẹnu-ọ̀nà Sioni ju gbogbo ibùgbé Jakọbu lọ.
3 Glorious things are spoken about you, city of God. (Selah)
Ohun ológo ni a sọ nípa rẹ̀, ìlú Ọlọ́run,
4 I will record Rahab and Babylon among those who acknowledge me. Behold, Philistia, Tyre, and also Ethiopia: “This one was born there.”
“Èmi ó dárúkọ Rahabu àti Babeli láàrín àwọn tí ó jẹ́wọ́ mi: Filistia pẹ̀lú, àti Tire, pẹ̀lú Kuṣi, yóò sọ pé, ‘Èyí ni a bí ní Sioni.’”
5 Yes, of Zion it will be said, “This one and that one was born in her;” the Most High himself will establish her.
Nítòótọ́, ti Sioni ni a ó sọ, “Eléyìí àti eléyìí ni a bí nínú rẹ̀, àti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo ni yóò fìdí rẹ̀ múlẹ̀.”
6 Yahweh will count, when he writes up the peoples, “This one was born there.” (Selah)
Olúwa yóò kọ nínú àkọsílẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀: “Eléyìí ni a bí ní Sioni.”
7 Those who sing as well as those who dance say, “All my springs are in you.”
Àti àwọn olórin àti àwọn tí ń lu ohun èlò orin yóò wí pé, “Gbogbo orísun mi ń bẹ nínú rẹ.”

< Psalms 87 >