< Psalms 118 >

1 O give thanks to the LORD; for he is good: because his mercy endureth for ever.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
2 Let Israel now say, that his mercy endureth for ever.
Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
3 Let the house of Aaron now say, that his mercy endureth for ever.
Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
4 Let them now that fear the LORD say, that his mercy endureth for ever.
Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
5 I called upon the LORD in distress: the LORD answered me, and set me in a large place.
Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
6 The LORD is on my side; I will not fear: what can man do to me?
Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
7 The LORD taketh my part with them that help me: therefore shall I see my desire upon them that hate me.
Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
8 It is better to trust in the LORD than to put confidence in man.
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
9 It is better to trust in the LORD than to put confidence in princes.
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
10 All nations surrounded me: but in the name of the LORD will I destroy them.
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
11 They surrounded me; yea, they surrounded me: but in the name of the LORD I will destroy them.
Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
12 They surrounded me like bees; they are quenched as the fire of thorns: for in the name of the LORD I will destroy them.
Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
13 Thou hast violently thrust at me that I might fall: but the LORD helped me.
Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
14 The LORD is my strength and song, and is become my salvation.
Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
15 The voice of rejoicing and salvation is in the tabernacles of the righteous: the right hand of the LORD doeth valiantly.
Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
16 The right hand of the LORD is exalted: the right hand of the LORD doeth valiantly.
Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
17 I shall not die, but live, and declare the works of the LORD.
Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
18 The LORD hath chastened me greatly: but he hath not given me over to death.
Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
19 Open to me the gates of righteousness: I will enter them, and I will praise the LORD:
Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
20 This gate of the LORD, into which the righteous shall enter.
Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
21 I will praise thee: for thou hast heard me, and art become my salvation.
Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
22 The stone which the builders refused is become the head stone of the corner.
Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
23 This is the LORD’S doing; it is marvellous in our eyes.
Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
24 This is the day which the LORD hath made; we will rejoice and be glad in it.
Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
25 Save now, I beseech thee, O LORD: O LORD, I beseech thee, send now prosperity.
Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
26 Blessed be he that cometh in the name of the LORD: we have blessed you out of the house of the LORD.
Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
27 God is the LORD, who hath shown us light: bind the sacrifice with cords, even to the horns of the altar.
Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
28 Thou art my God, and I will praise thee: thou art my God, I will exalt thee.
Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
29 O give thanks to the LORD; for he is good: for his mercy endureth for ever.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

< Psalms 118 >