< Romans 7 >

1 Remember ye not brethren (I speake to them yt know the lawe) how that the lawe hath power over a man as longe as it endureth?
Ẹ̀yin kò ha mọ̀, ara: nítorí èmí bá àwọn tí ó mọ òfin sọ̀rọ̀ pé, òfin ní ipá lórí ènìyàn níwọ̀n ìgbà tí ó bá wà láààyè nìkan?
2 For the woman which is in subieccion to a man is bounde by the lawe to the man as longe as he liveth. Yf the man be deed she is lowsed from the lawe of the man.
Fún àpẹẹrẹ, nípa òfin ní a de obìnrin mọ́ ọkọ rẹ̀ níwọ̀n ìgbà tí ọkọ náà wà láààyè, ṣùgbọ́n bí ọkọ rẹ̀ bá kú, a tú u sílẹ̀ kúrò nínú òfin ìgbéyàwó náà.
3 So then yf whill the man liveth she couple her selfe with another man she shalbe counted a wedlocke breaker. But yf the man be deed she is fre fro the lawe: so that she is no wedlocke breaker though she couple her selfe with another man.
Nígbà náà, bí ó bá fẹ́ ọkùnrin mìíràn nígbà tí ọkọ rẹ̀ wà láààyè, panṣágà ní a ó pè é. Ṣùgbọ́n bí ọkọ rẹ̀ bá kú, ó bọ́ lọ́wọ́ òfin náà, kí yóò sì jẹ́ panṣágà bí ó bá ní ọkọ mìíràn.
4 Even so ye my brethren are deed concerninge the lawe by the body of Christ yt ye shuld be coupled to another (I meane to him that is rysen agayne fro deeth) that we shuld bringe forth frute vnto God.
Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ará mi, ẹ̀yin pẹ̀lú ti di òkú sí òfin nípa ara Kristi, kí ẹ̀yin kí ó lè ní ẹlòmíràn, àní ẹni náà tí a jí dìde kúrò nínú òkú, kí àwa kí ó lè so èso fún Ọlọ́run.
5 For when we were in the flesshe the lustes of synne which were stered vppe by ye lawe raygned in oure membres to bringe forth frute vnto deeth.
Nítorí ìgbà tí a wa nípa ti ara, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ nípa ti òfin, ma ń ṣiṣẹ́ nínú wa, tí a sì ń so èso tí ó yẹ fún ikú.
6 But now are we delivered fro the lawe and deed fro that whervnto we werein bondage that we shuld serve in a newe conversacion of ye sprete and not in ye olde conversacion of the letter.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nípa kíkú ohun tó so wá pọ̀ tẹ́lẹ̀ rí, a ti tú wa sílẹ̀ kúrò nínú òfin, kí a lè sin ín ní ìlànà tuntun ti Ẹ̀mí, kì í ṣe ní ìlànà àtijọ́ tí ìwé òfin gùnlé.
7 What shall we saye then? is ye lawe synne? God forbid: but I knewe not what synne meant but by the lawe. For I had not knowne what lust had meant excepte the lawe had sayde thou shalt not lust.
Ǹjẹ́ àwa o ha ti wí, nígbà náà? Òfin ha ń ṣe ẹ̀ṣẹ̀ bí? Kí a má rí i! Ṣùgbọ́n èmi kì bá tí mọ ohun tí ẹ̀ṣẹ̀ jẹ́, bí kò ṣe nípa òfin. Èmi kì bá tí mọ ojúkòkòrò, bí kò ṣe bí òfin ti wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò.”
8 But synne toke an occasion by the meanes of the commaundement and wrought in me all manner of concupiscece. For with out the lawe synne was deed.
Ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ sì ti ipa òfin rí ààyè ṣiṣẹ́ onírúurú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ nínú mi. Nítorí láìsí òfin, ẹ̀ṣẹ̀ jẹ́ ikú.
9 I once lived with out lawe. But when the commaundement came synne revyved and I was deed.
Èmi sì ti wà láààyè láìsí òfin nígbà kan rí; ṣùgbọ́n nígbà tí òfin dé, ẹ̀ṣẹ̀ sọjí èmi sì kú.
10 And the very same comaundement which was ordeyned vnto lyfe was founde to be vnto me an occasion of deeth.
Mo ṣàkíyèsí pé òfin tí ó yẹ kí ó mú ìyè wá ni ó padà mú ikú wá.
11 For synne toke occasion by the meanes of the comaundement and so disceaved me and by the selfe commaundement slewe we.
Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ti ipa òfin rí ààyè láti tàn mí jẹ, ó sì ti ipa òfin ṣe ikú pa mi.
12 Wherfore the lawe is holy and the commaundement holy iust and good.
Bẹ́ẹ̀ ni mímọ́ ni òfin, mímọ́ sì ni àṣẹ, àti òdodo, àti dídára.
13 Was that then which is good made deeth vnto me? God forbyd. Naye synne was deeth vnto me that it myght appere how that synne by the meanes of that which is good had wrought deeth in me: that synne which is vnder the commandemet myght be out of measure synfull.
Ǹjẹ́ ohun tí ó dára ha di ikú fún mi bí? Kí a má rí i! Ṣùgbọ́n kí ẹ̀ṣẹ̀, kí ó lè farahàn bí ẹ̀ṣẹ̀, ó ń ti ipa ohun tí ó dára ṣiṣẹ́ ikú nínú mi, kí ẹ̀ṣẹ̀ lè ti ipa òfin di búburú rékọjá.
14 For we knowe that the lawe is spirituall: but I am carnall solde vnder synne
Nítorí àwa mọ̀ pé ohun ẹ̀mí ni òfin, ṣùgbọ́n ẹni ti ara ni èmi, tí a ti tà sábẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
15 because I wote not what I doo. For what I wold that do I not: but what I hate that do I.
Èmi pàápàá, kò mọ̀ ohun tí èmi ń ṣe. Nítorí pé, ohun tí mo fẹ́ ṣe gan an n kò ṣe é, ṣùgbọ́n ohun tí mo kórìíra ni mo ń ṣe.
16 Yf I do now that which I wolde not I graute to the lawe that it is good.
Ṣùgbọ́n bí mo bá ṣe ohun tí èmi kò fẹ́, mo gbà pé òfin dára.
17 So then nowe it is not I that do it but synne that dwelleth in me.
Ṣùgbọ́n bí ọ̀rọ̀ ṣe rí yìí kì í ṣe èmi ni ó ṣe é bí kò ṣe ẹ̀ṣẹ̀ tí ń gbé inú mi.
18 For I knowe that in me (that is to saye in my flesshe) dwelleth no good thinge. To will is present with me: but I fynde no meanes to performe that which is good.
Èmi mọ̀ dájú pé kò sí ohun tí ó dára kan tí ń gbé inú mi, àní, nínú ara ẹ̀ṣẹ̀ mi. Èmi fẹ́ ṣe èyí tí ó dára, ṣùgbọ́n kò sé é ṣe.
19 For I doo not yt good thinge which I wold: but that evill do I which I wolde not.
Nítorí ohun tí èmi ṣe kì í ṣe ohun rere tí èmi fẹ́ láti ṣe; rárá, ṣùgbọ́n búburú tí èmi kò fẹ́, èyí nì ni èmi ń ṣe.
20 Finally yf I do that I wolde not then is it not I that doo it but synne that dwelleth in me doeth it.
Nísinsin yìí, bí mo bá ń ṣe nǹkan tí n kò fẹ́ láti ṣe, kì í ṣe èmí fúnra mi ni ó ṣe é, bí kò ṣe ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ nínú ni ó ṣe é.
21 I fynde then by the lawe that when I wolde do good evyll is present with me.
Nítorí náà, èmi kíyèsi pé òfin ní ń ṣiṣẹ́ nínú mi, nígbà tí èmi bá fẹ́ ṣe rere, búburú wà níbẹ̀ pẹ̀lú mi.
22 I delite in the lawe of God concerninge the inner man.
Nínú ìjìnlẹ̀ ọkàn mi mo ní inú dídùn sí òfin Ọlọ́run;
23 But I se another lawe in my membres rebellinge agaynst the lawe of my mynde and subduynge me vnto the lawe of synne which is in my membres.
mo rí òfin mìíràn tó ń ṣiṣẹ́ nínú ẹ̀yà ara mi, èyí tí ń gbógun ti òfin tó tinú ọkàn mi wá, èyí tí ó sọ mi di ẹrú òfin ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ń ṣiṣẹ́ nínú ẹ̀yà ara mi.
24 O wretched man yt I am: who shall delyver me fro this body of deeth?
Èmi ẹni òsì! Ta ni yóò ha gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ara kíkú yìí?
25 I thanke God thorow Iesus Christ oure Lorde. So then I my silfe in my mynde serve the lawe of God and in my flesshe the lawe of synne.
Ọpẹ́ ni fún Ọlọ́run nípasẹ̀ Jesu Kristi Olúwa wa! Ǹjẹ́ nítorí náà, èmi fúnra mi jẹ́ ẹrú sí òfin Ọlọ́run, ṣùgbọ́n nínú ara ẹ̀ṣẹ̀ mo jẹ́ ẹrú fún òfin ẹ̀ṣẹ̀.

< Romans 7 >