< Revelation 2 >

1 Unto the messenger of the congregacion of Ephesus wryte: These thynges sayth he that holdeth the vii. starres in his right honde and walketh in the myddes of the vii. golden candlestyckes
“Sí angẹli ìjọ ní Efesu kọ̀wé: Nǹkan wọ̀nyí ní ẹni tí ó mú ìràwọ̀ méje náà ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ wí, ẹni tí ń rìn ní àárín ọ̀pá wúrà fìtílà méje.
2 I knowe thy workes and thy labour and thy pacience and howe thou cannest not forbeare the which are evyll: and examinedst them which saye they are Apostles and are not: and hast founde them lyars
Èmi mọ iṣẹ́ rẹ, àti làálàá rẹ, àti ìfaradà rẹ, àti bí ara rẹ kò ti gba àwọn ẹni búburú, àti bí ìwọ sì ti dán àwọn tí ń pe ara wọn ní aposteli, tí wọ́n kì í sì í ṣe bẹ́ẹ̀ wo, tí ìwọ sì rí pé èké ni wọ́n,
3 and dydest wasshe thy self. And hast pacience: and for my names sake hast labored and hast not faynted.
tí ìwọ sì faradà ìyà, àti nítorí orúkọ mi tí ó sì rọ́jú, tí àárẹ̀ kò sì mú ọ.
4 Neverthelesse I have sumwhat agaynst the for thou haste lefte thy fyrst love.
Síbẹ̀ èyí ni mo rí wí sí ọ, pé, ìwọ ti fi ìfẹ́ ìṣáájú rẹ sílẹ̀.
5 Remember therfore from whence thou art fallen and repent and do the fyrst workes. Or elles I wyll come vnto the shortly and will remove thy candlestyke out of his place excepte thou repent.
Rántí ibi tí ìwọ ti gbé ṣubú! Ronúpìwàdà, kí ó sì ṣe iṣẹ́ ìṣáájú; bí kò sì ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó sì tọ̀ ọ́ wá, èmi ó sì ṣí ọ̀pá fìtílà rẹ̀ kúrò ní ipò rẹ̀, bí kò ṣe bí ìwọ bá ronúpìwàdà.
6 But this thou haste because thou hatest ye dedes of the Nicolaitans which dedes I also hate.
Ṣùgbọ́n èyí ni ìwọ ní, pé ìwọ kórìíra ìṣe àwọn Nikolatani, èyí tí èmi pẹ̀lú sì kórìíra.
7 Lett him yt hath eares heare what ye sprete sayth vnto the congregacions. To him that overcometh will I geve to eate of the tree of lyfe which is in the myddes of ye paradice of god.
Ẹni tí ó bá ní etí kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ. Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun ni èmi yóò fi èso igi ìyè nì fún jẹ, tí ń bẹ láàrín Paradise Ọlọ́run.
8 And vnto the angell of the congregacion of Smyrna wryte: These thynges sayth he that is fyrst and the laste which was deed and is alive.
“Àti sí angẹli ìjọ ní Smirna kọ̀wé. Nǹkan wọ̀nyí ni ẹni tí í ṣe ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn wí, ẹni tí ó ti kú, tí ó sì tún yè.
9 I knowe thy workes and tribulacion and poverte but thou art ryche: And I knowe the blaspemy of them whiche call them selves Iewes and are not: but are the congregacio of sathan.
Èmi mọ iṣẹ́ rẹ, àti ìpọ́njú, àti àìní rẹ—ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ ni ọ́, èmi sì mọ ọ̀rọ̀-òdì tí àwọn tí ń wí pé, Júù ni àwọn tìkára wọn, tí wọn kì sì í ṣe bẹ́ẹ̀, ṣùgbọ́n tí wọ́n jẹ́ Sinagọgu ti Satani.
10 Feare none of thoo thynges which thou shalt soffre. Beholde the devyll shall caste of you into preson to tempte you and ye shall have tribulacion. x. dayes. Be faythfull vnto the deeth and I will geve the a croune of lyfe.
Má ṣe bẹ̀rù ohunkóhun tí ìwọ ń bọ wá jìyà rẹ̀. Kíyèsi i, èṣù yóò gbé nínú yín jù sínú túbú, kí a lè dán yin wò; ẹ̀yin ó sì ní ìpọ́njú ní ọjọ́ mẹ́wàá, ìwọ ṣa ṣe olóòtítọ́ dé ojú ikú, èmi ó sì fi adé ìyè fún ọ.
11 Let him that hath ears heare what the sprete sayth to the congregacions: He that overcometh shall not be hurte of the seconde deeth.
Ẹni tí ó bá ní etí kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ. Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun kì yóò fi ara pa nínú ikú kejì.
12 And to the messenger of the congregacion in Pergamos wryte: This sayth he which hath ye sharpe swearde with two edges.
“Àti sì angẹli ìjọ ni Pargamu kọ̀wé. Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni ẹni tí ó ní idà mímú olójú méjì.
13 I knowe thy workes and where thow dwellest evyn where Sathans seat ys and thou kepest my name and hast not denyed my fayth. And in my dayes Antipas was a faythfull witnes of myne which was slayne amonge you where sathan dwelleth.
Èmí mọ̀ ibi tí ìwọ ń gbé, àní ibi tí ìtẹ́ Satani wà. Síbẹ̀ ìwọ di orúkọ mi mú ṣinṣin. Ìwọ kò sì sẹ́ ìgbàgbọ́ nínú mi, pàápàá jùlọ ni ọjọ́ Antipa ẹlẹ́rìí mi, olóòtítọ́ ènìyàn, ẹni tí wọn pa láàrín yín, níbi tí Satani ń gbé.
14 But I have a fewe thynges agaynst the: yt thou hast there they that mayntayne the doctryne of Balam which taught in balake to put occasion of syn before the chylderne of Israhell that they shulde eate of meate dedicat vnto ydoles and to commyt fornicacion.
Ṣùgbọ́n mo ni nǹkan díẹ̀ wí sí ọ; nítorí tí ìwọ ní àwọn kan tí ó di ẹ̀kọ́ Balaamu mú síbẹ̀, ẹni tí ó kọ́ Balaki láti mú ohun ìkọ̀sẹ̀ wá síwájú àwọn ọmọ Israẹli, láti máa jẹ ohun tí a pa rú ẹbọ sí òrìṣà, àti láti máa ṣe àgbèrè.
15 Even so hast thou them that mayntayne the doctryne of the Nicolaytans which thynge I hate.
Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ní àwọn tí ó gbá ẹ̀kọ́ àwọn Nikolatani pẹ̀lú, ohun tí mo kórìíra.
16 But be converted or elles I will come vnto the shortly and will fyght agaynste the with thes wearde of my mouth
Nítorí náà, ronúpìwàdà; bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó tọ̀ ọ́ wá nísinsin yìí, èmí o sì fi idà ẹnu mi bá wọn jà.
17 Lett him that hath eares heare what the sprete sayth vnto the congregacios: To him that overcommeth will I geve to eate manna that is hyd and will geve him a whyte stone and in the stone a newe name wrytten which no ma knoweth savinge he that receaveth it.
Ẹni tí ó bá létí, kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ. Ẹni tí o bá ṣẹ́gun ni èmi o fi manna tí ó pamọ́ fún, èmi ó sì fún un ni òkúta funfun kan, àti sára òkúta náà ni a kọ orúkọ tuntun kan, tí ẹnìkan kò mọ̀ bí kò ṣe ẹni tí ó gbà á.
18 And vnto the messenger of the congregacion of Theatira write: This sayth the sonne of god which hath his eyes lyke vnto a flame of fyre whose fete are like brasse:
“Àti sí angẹli ìjọ ní Tiatira kọ̀wé. Nǹkan wọ̀nyí ni Ọmọ Ọlọ́run wí, ẹni tí ojú rẹ̀ dàbí ọ̀wọ́-iná, tí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì dàbí idẹ dáradára.
19 I knowe thy workes and thy love service and fayth and thy paciece and thy dedes which are mo at the last then at the fyrste.
Èmi mọ̀ iṣẹ́, ìfẹ́, àti ìgbàgbọ́ àti ìsìn àti sùúrù rẹ̀; àti pé iṣẹ́ rẹ̀ ìkẹyìn ju tí ìṣáájú lọ.
20 Notwitstondinge I have a feawe thynges agaynst the that thou sofferest that woman Iesabell which called her sylfe a prophetes to teache and to deceave my servauntes to make them commyt fornicacion and to eate meates offered vppe vnto ydoles.
Ṣùgbọ́n èyí ni mo rí wí sí ọ, nítorí tí ìwọ fi ààyè sílẹ̀ fún obìnrin Jesebeli tí ó ń pe ara rẹ̀ ní wòlíì. Nípasẹ̀ ẹ̀kọ́ rẹ̀, ó sì ń kọ́ àwọn ìránṣẹ́ mi, ó sì ń tàn wọ́n láti máa ṣe àgbèrè, àti láti máa jẹ ohun tí a pa rú ẹbọ sì òrìṣà.
21 And I gave her space to repent of her fornicacion and she repented not.
Èmi fi àkókò fún un, láti ronúpìwàdà; ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ ronúpìwàdà àgbèrè rẹ̀.
22 Beholde I will caste her into a beed and them yt commyt fornicacion wt her into gret adversite excepte they tourne fro their deades.
Nítorí náà, èmi ó gbé e sọ sí orí àkéte ìpọ́njú, àti àwọn tí ń bá a ṣe panṣágà ni èmi ó fi sínú ìpọ́njú ńlá, bí kò ṣe bí wọ́n bá ronúpìwàdà iṣẹ́ wọn.
23 And I will kyll her children with deeth. And all the congregacions shall knowe that I am he which searcheth ye reynes and hertes. And I will geve vnto evere one of you accordynge vnto youre workes.
Èmi o pa àwọn ọmọ rẹ̀ run; gbogbo ìjọ ni yóò sì mọ̀ pé, èmi ni ẹni tí ń wádìí inú àti ọkàn, èmi ó sì fi fún olúkúlùkù yín gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.
24 Vnto you I saye and vnto other of them of Thiatyra as many as have not this lerninge and which have not knowen the depnes of Satha (as they saye) I will put apo you none other burthe
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni mò ń sọ fún, ẹ̀yin ìyókù tí ń bẹ ní Tiatira, gbogbo ẹ̀yin tí kò ni ẹ̀kọ́ yìí, ti kò ì tí ì mọ̀ ohun tí wọn pè ni ohun ìjìnlẹ̀ Satani, èmi kò di ẹrù mìíràn rù yín,
25 but yt which ye have alreddy. Holde fast tyll I come
ṣùgbọ́n èyí tí ẹ̀yin ní, ẹ di mú ṣinṣin títí èmi ó fi dé.
26 and whosoever overcometh and kepeth my workes vnto the ende to hym will I geve power over nacios
Ẹni tí ó bá sì ṣẹ́gun, àti tí ó sì ṣe ìfẹ́ mi títí dé òpin, èmi ó fún un láṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè:
27 and he shall rule them with a rodde of yron: and as the vessels of a potter shall he breake them to shevers. Eve as I receaved of my father
‘Òun ó sì máa fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn; gẹ́gẹ́ bí a ti ń fọ́ ohun èlò amọ̀kòkò ni a ó fọ́ wọn túútúú,’ gẹ́gẹ́ bí èmi pẹ̀lú tí gbà àṣẹ láti ọ̀dọ̀ Baba mi.
28 eue so will I geve him ye mornynge starre.
Èmi yóò sì fi ìràwọ̀ òwúrọ̀ fún un.
29 Let him yt hath eares heare what the sprete sayth to the congregacions.
Ẹni tí ó bá létí, kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ.

< Revelation 2 >