< Hebrews 8 >

1 Of the thynges which we have spoke this is the pyth: that we have soche an hye preste that is sitten on ye right honde of the seate of maieste in heven
Nísinsin yìí, kókó ohun tí à ń sọ nìyí. Àwa ní irú olórí àlùfáà bẹ́ẹ̀, tí ó jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún ìtẹ́ Ọláńlá nínú àwọn ọ̀run,
2 and is a minister of holy thynges and of the very tabernacle which God pyght and not ma.
Ìránṣẹ́ ibi mímọ́, àti ti àgọ́ tòótọ́, tí Olúwa pa, kì í ṣe ènìyàn.
3 For every hye prest is ordeyned to offer gyftes and sacryfises wherfore it is of necessitie that this man have somewhat also to offer.
Nítorí a fi olórí àlùfáà kọ̀ọ̀kan jẹ láti máa mú ẹ̀bùn wá láti máa rú ẹbọ, nítorí náà ó ṣe pàtàkì fún eléyìí náà láti ní nǹkan tí ó máa fi sílẹ̀.
4 For he were not a preste yf he were on ye erth where are prestes that acordynge to ye lawe
Tí ó bá jẹ́ pé ó wà ní ayé ni, òun kì bá ti jẹ́ àlùfáà, nítorí pé àwọn ọkùnrin tí ó ń fi ẹ̀bùn sílẹ̀ ti wà bí òfin ṣe là á sílẹ̀.
5 offer giftes which prestes serve vnto ye ensample and shadowe of hevenly thynges: even as the answer of God was geven vnto Moses when he was about to fynnishe the tabernacle: Take hede (sayde he) that thou make all thynges accordynge to the patrone shewed to the in the mount.
Àwọn ẹni tí ń jọ́sìn nínú pẹpẹ kan tí ó jẹ́ àpẹẹrẹ àti òjìji ohun tí ń bẹ ní ọ̀run. Ìdí abájọ nìyí tí a fi kìlọ̀ fún Mose nígbà tí ó fẹ́ kọ́ àgọ́, nítorí ó wí pé, “Kíyèsí i, kí ìwọ kí ó ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ wọn, ti a fi hàn ọ́ ni orí òkè.”
6 Now hath he obtayned a more excellent office in as moche as he is the mediator of a better testament which was made for better promyses.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí o ti gba iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí ó ni ọlá jù, níwọ̀n bí o ti jẹ pé alárinà májẹ̀mú tí o dára jù ní i ṣe, èyí tí a fi ṣe òfin lórí ìlérí tí o sàn jù bẹ́ẹ̀ lọ.
7 For yf that fyrst testament had bene fautelesse: then shuld no place have bene sought for the seconde.
Nítorí ìbá ṣe pé májẹ̀mú ìṣáájú nì kò ní àbùkù, ǹjẹ́ a kì bá ti wá ààyè fún èkejì.
8 For in rebukynge the he sayth: Beholde the dayes will come (sayth the lorde) and I will fynnyshe apon the housse of Israhel and apon the housse of Iuda
Nítorí tí ó rí àbùkù lára wọn, ó wí pé, “Ìgbà kan ń bọ̀, ni Olúwa wí, tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
9 a newe testament: not lyke the testament that I made with their fathers at that tyme whe I toke them by the hondes to lede them oute of the londe of Egipte for they continued not in my testament and I regarded them not sayth the lorde.
Kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí májẹ̀mú tí mo ti bá àwọn baba baba wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́ láti mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, nítorí wọn kò jẹ́ olóòtítọ́ sí májẹ̀mú mi èmi kò sì ta wọ́n nu, ni Olúwa wí.
10 For this is the testament that I will make with the housse of Israhell: After those dayes sayth the lorde: I will put my lawes in their myndes and in their hertes I will wryte the and I wilbe their God and they shalbe my people.
Nítorí èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, ni Olúwa wí. Èmi ó fi òfin mi sí inú wọn, èmi ó sì kọ wọ́n sí ọkàn wọn, èmi ó sì máa jẹ́ Ọlọ́run fún wọn, wọn ó sì máa jẹ́ ènìyàn fún mi.
11 And they shall not teache every man his neghboure and every man his brother sayinge: knowe the lorde: For they shall knowe me from the lest to the moste of them:
Olúkúlùkù kò ní tún máa kọ́ ara ìlú rẹ̀, tàbí olúkúlùkù arákùnrin rẹ̀, pé, ‘Mọ Olúwa,’ nítorí pé gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí, láti kékeré dé àgbà.
12 For I wilbe mercifull over their vnrightwesnes and on their synnes and on their iniquiries.
Nítorí pé èmi ó ṣàánú fún àìṣòdodo wọn, àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn àti àìṣedéédéé wọn lèmi ki yóò sì rántí mọ́.”
13 In yt he sayth a new testament he hath abrogat the olde. Now that which is disanulled and wexed olde is redy to vannysshe awaye.
Ní èyí tí ó wí pé, májẹ̀mú títún ó ti sọ ti ìṣáájú di ti láéláé. Ṣùgbọ́n èyí tí ó ń di i ti láéláé tí ó sì ń gbó, o múra àti di asán.

< Hebrews 8 >