< Romans 8 >

1 Because [God has erased the record of our sins because we trust in what Christ has done for us], now [God will] not condemn and punish those/us who have a relationship with (OR, are united to) Christ Jesus.
Nítorí náà, kò sí ìdálẹ́bi nísinsin yìí fún àwọn tí ó wà nínú Kristi Jesu, àwọn tí kò rìn nípa ti ara, bí kò ṣe nípa ti Ẹ̀mí.
2 [God’s] Spirit causes us to live [in a new way] [PRS] as a result of what Christ Jesus [did for us]. And he has set up a way by which he frees [each of] us from continually being forced to sin (OR, to obey our self-directed natures) and from being separated from God.
Nítorí nípasẹ̀ òfin ti ẹ̀mí ìyè nínú Kristi Jesu ti sọ mí di òmìnira kúrò lọ́wọ́ òfin ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú.
3 What [we] could not do [by trying to obey] the laws [of God] [PRS], because our self-directed nature was too weak [to obey them], God did. He sent his own Son [into the world in order that his Son might atone] for our sin. His Son came having a body (OR, human nature) that was like [the body] (OR, the [human nature]) of us people who sin. [By sending his Son in this way], he condemned and punished [his Son, who never sinned, instead of punishing us, who] sinned [MTY]. He did that [by making his Son’s] body [a sacrifice] (OR, [by causing his Son’s] body [to suffer/die]) for [all our] sin.
Nítorí ohun tí òfin kò lè ṣe, bí ó ti jẹ aláìlera nítorí ara, Ọlọ́run rán ọmọ òun tìkára rẹ̀ ní àwòrán ara ẹ̀ṣẹ̀, ó sì di ẹ̀ṣẹ̀; àti bi ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀, ó sì dá ẹ̀ṣẹ̀ lẹ́bi nínú ara,
4 So we can [now] fulfill all that God required in his laws. We do this, not by our acting the way our sinful human nature [desires], but instead by living as [God’s] Spirit [desires us to live].
kí a lè mú òdodo òfin ṣẹ, nínú wa, nítorí tí àwa yé gẹ́gẹ́ bí ohun ti ara, bí kò ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun ti Ẹ̀mí.
5 People who live according to what their self-directed nature [desires] think about and are concerned about what their self-directed nature [desires]. But people who [live] according to what [God’s] Spirit [desires think about and are concerned about] what [God’s] Spirit [desires].
Àwọn tí ń gbe nípa ti ara, wọn a máa ronú ohun ti ara; ṣùgbọ́n àwọn ti ń gbe nípa ti Ẹ̀mí, wọn a máa ronú ohun ti Ẹ̀mí.
6 Those people who [PRS] think about and are concerned about what their self-directed nature [desires] will not live eternally (OR, will be separated from God). But those people who think about and are concerned about what [God’s] Spirit [desires] will live [eternally] and have [inner] peace.
Nítorí èrò ti ara ikú ni; ṣùgbọ́n èrò ti ẹ̀mí ni ìyè àti àlàáfíà.
7 Let me explain this. [To the extent that] people [PRS] think about and are concerned about what their self-directed nature [desires], they are acting contrary to God. They do not obey the laws of God. In fact, they are not even able [to obey his laws].
Nítorí èrò ti ara ọ̀tá ni sí Ọlọ́run, nítorí kì í tẹríba fún òfin Ọlọ́run, òun kò tilẹ̀ le ṣe e.
8 The people who let their self-directed nature [control them] cannot do what pleases God.
Ìdí nìyìí tí àwọn tí ó wà lábẹ́ àkóso ara ẹ̀ṣẹ̀, kò le è tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn.
9 But we do not have to let our self-directed nature [control us]. Instead, we can [let] God’s Spirit [control us], because he lives within us. If people do not have [living in them] the Spirit [who comes from] Christ, they do not belong to Christ.
Ṣùgbọ́n ẹyin kò sí nínú ti ara, bí kò ṣe nínú ti Ẹ̀mí, bí ó bá ṣe pé Ẹ̀mí Ọlọ́run ń gbé inú yín. Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni kò bá ní Ẹ̀mí Kristi, òun kò sí nínú ẹni tirẹ̀.
10 But since Christ [is living in you/us by his Spirit, although] your/our bodies [are certain to] die because you/we sin, your/our spirits are alive because God has erased the record of your/our sins.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Kristi ń gbé inú yín síbẹ̀síbẹ̀, ara yín jẹ́ òkú nítorí ẹ̀ṣẹ̀; ṣùgbọ́n ẹ̀mí mímọ́ tí ń gbé inú yín yóò fún yín ní ìyè, nítorí ó ti fún un yín ní òdodo.
11 [God] caused Jesus to live again after he died. And because his Spirit lives in you/us, [God] will also make your/our bodies, which [now] are sure to die, live [again after you/we die]. God, who caused Christ to live again after he died, will make you/us live again by [causing] his Spirit, who lives within you/us, [to do it].
Àti pé, bí ẹ̀mí Ọlọ́run, ẹni tí ó jí Jesu kúrò nínú òkú bá ń gbé inú yín, ẹni tí ó jí Kristi Jesu dìde kúrò nínú òkú, yóò fi ẹ̀mí rẹ̀ tí ń gbé inú yín sọ ara kíkú yín di ààyè pẹ̀lú.
12 Therefore, my fellow believers, we must [live as the Spirit directs us]. What we do not have to do is to live as our self-directed nature [guides us].
Nítorí náà ará a ni ojúṣe láti ṣe, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa nǹkan tí ara, tí a ó fi máa gbé nípa ti ara.
13 If you live the way your self-directed nature [directs], you will surely not live [eternally] (OR, will surely be eternally separated from God). But if by [the power of God’s] Spirit you quit doing the [sinful] things that your bodies [desire] [MET], you will live eternally.
Nítorí pé bí ẹ̀yin bá ń tẹ̀lé, ẹ̀ṣẹ̀ ti ara ẹ̀yin yóò sọnù, ẹ ó sì ṣègbé, ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ ń gbé nípa ti ara, ẹ̀yin yóò kú, ṣùgbọ́n bí ẹ̀yín bá ń gbé nípa ti Ẹ̀mí, ẹ ó pa iṣẹ́ ti ara run, ẹ̀yin yóò yè.
14 We who are guided by the Spirit of God {allow the Spirit of God to guide us} are God’s children.
Nítorí pé, iye àwọn tí Ẹ̀mí Ọlọ́run bá ń darí ni ọmọ Ọlọ́run.
15 [You have showed that this is true], because you received [from God] a Spirit that is not one that makes you fear [God] again. You are not like slaves who [fear their masters] [MET]. On the contrary, we have received a Spirit by whose [work in our hearts God] has adopted us. The Spirit now enables us to cry out [to God], “[You(sg) are my] Father [DOU]!”
Nítorí ẹ̀yin kò tún gba ẹ̀mí ẹrú láti máa bẹ̀rù mọ́; ṣùgbọ́n ẹ̀yin gba ẹ̀mí ìsọdọmọ, nípa èyí tí àwa fi ń ké pé “Ábbà, Baba.”
16 The Spirit himself confirms what our spirits [say], that we are God’s children.
Nítorí Ẹ̀mí mímọ́ ń sọ̀rọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú ọkàn wa, ó sì ń sọ fún wa pé, nítòótọ́, àwa jẹ́ ọmọ Ọlọ́run.
17 Because we are [God’s] children, we also will some day receive/inherit [eternal blessings/privileges]. We will receive/inherit them from God, and we will [also] receive/inherit [them] just like Christ has [inherited them]. But we must suffer [for doing good] as Christ did, in order to receive splendor as he did.
Níwọ́n ìgbà tí a jẹ́ ọmọ rẹ̀, ǹjẹ́ ajogún ni àwa, ajogún Ọlọ́run, àti àjùmọ̀jogún pẹ̀lú Kristi, bí ó bá ṣe àwa jìyà, kí a sì le ṣe wá lógo pẹ̀lú rẹ̀.
18 I consider that what we suffer during the present time is not worth [paying attention to, because] the future splendor/glory that will be revealed {that [God] will reveal} to us [is so great].
Síbẹ̀síbẹ̀, ìyà tí a ń jẹ nísinsin yìí kò jámọ́ nǹkan nígbà tí a bá fiwé ògo tí yóò fún wa ní ìkẹyìn.
19 The [things that God has] created are very eagerly waiting for [the time] [PRS, DOU] when God will reveal who his [true] children are.
Nítorí ẹ̀dá ń dúró ní ìfojúsọ́nà de ìfihàn àwọn ọmọ Ọlọ́run.
20 [God] caused the things that he created to be unable to achieve [what he had purposed. That was] not because they wanted to [be unable to do that]. On the contrary, [God] made them that way because he wanted them to keep confidently expecting
Nítorí a tẹrí ẹ̀dá ba fún asán, kì í ṣe bí òun ti fẹ́, ṣùgbọ́n nípa ìfẹ́ ẹni tí ó tẹ orí rẹ̀ ba ní ìrètí.
21 that the things that [he] created will be freed {that [he] will free the things that [he] created} from their sure decay [MET]. [He] will free them in order that [he can give them] the same glory that belongs to his children.
Nítorí a ó sọ ẹ̀dá tìkára rẹ̀ di òmìnira kúrò nínú ẹrú ìdíbàjẹ́, sí òmìnira ògo àwọn ọmọ Ọlọ́run.
22 We know that until now [it is as though] all [things] that God created have been groaning together, [and they long for that glory, just like a mother having the pains before bearing a child] groans [and longs for her baby’s birth] [MET].
Nítorí àwa mọ̀ pé gbogbo ẹ̀dá ni ó jùmọ̀ ń kérora tí ó sì ń rọbí pọ̀ títí di ìsinsin yìí.
23 Not only [do those things groan], but we ourselves also groan inwardly. We who have [God’s] Spirit, who is like a partial gift [MET] we have received as we wait for [the future glory, groan inwardly]. We groan while we wait eagerly for the time when we will receive our [full] rights as God’s adopted children. That [will include] his freeing our bodies [from the things that hinder us on earth. He will do this by giving us new bodies].
Kì í ṣe àwọn nìkan, ṣùgbọ́n àwa tìkára wa pẹ̀lú, a ni àkóso ẹ̀mí, àní àwa tìkára wa ń kérora nínú ara wa, àwa ń dúró de ìsọdọmọ àní ìdáǹdè ara wa.
24 Ever since we were saved {since [God] saved us}, we have continued to confidently expect [that future glory]. If we had what we waited for, we would not [need to] wait for it any longer, because those who have something, certainly do not continue to wait for it! [RHQ]
Nítorí nípa ìrètí ni a fi gbà wá là, ṣùgbọ́n ìrètí tí a bá rí kì í ṣe ìrètí nítorí ta ni ń retí ohun tí ó bá rí?
25 But because we keep waiting expectantly to receive what we do not yet have, we wait for it eagerly and patiently/perseveringly.
Ṣùgbọ́n bí àwa bá ń retí èyí tí àwa kò rí, ǹjẹ́ àwa ń fi sùúrù dúró dè é.
26 Similarly, in addition to our continuing to wait for what God will give us, God’s Spirit helps us when our spirits feel weak. We do not know what is proper/necessary for us to pray. But God’s Spirit knows, and he prays for us when we groan (OR, he groans) in a way that cannot be expressed in words (OR, prays with us, groaning in a way that cannot be expressed in words).
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ẹ̀mí pẹ̀lú sì ń ran àìlera wa lọ́wọ́: nítorí a kò mọ bí a ti ń gbàdúrà gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ, ṣùgbọ́n ẹ̀mí tìkára rẹ̀ ń fi ìrora tí a kò le fi ẹnu sọ bẹ̀bẹ̀ fún wa.
27 God, who examines our inner feelings, understands what his Spirit desires. What God understands is that his Spirit prays for us who belong to God exactly as God wants him to pray.
Ẹni tí ó sì ń wá inú ọkàn wò, ó mọ ohun ti ẹ̀mí, nítorí tí ó ń bẹ̀bẹ̀ fún àwọn ènìyàn mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Ọlọ́run.
28 And we know that to those/us who love God, he works out all things that happen [to them/us] in a way that produces good [spiritual] benefits [for us]. He does these things for those/us whom he has chosen, because that was (OR, was according to) what he planned to do.
Àwa sì mọ̀ pé ohun gbogbo ni ó ń ṣiṣẹ́ pọ̀ sí rere fún àwọn tí ó fẹ́ Ọlọ́run, àní fún àwọn ẹni tí a pè gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ̀.
29 God knew previously [that we would believe] in him (OR, [would be saved]). We are those who God also decided previously would develop a character like his Son’s character. The result of that is that [Christ is like] a firstborn/highest-ranking [son], and [those/we who are God’s children] [MET] are [like] [MET] many [younger] brothers [of Jesus].
Nítorí àwọn ẹni tí ó mọ̀ tẹ́lẹ̀, ni ó sì yàn tẹ́lẹ̀ láti rí bí àwòrán ọmọ rẹ̀, kí òun lè jẹ́ àkọ́bí láàrín àwọn arákùnrin púpọ̀.
30 And us who God decided previously [that we would become like his Son], he also summoned. And for us whom he summoned, he also erased the record of our sins. And for us whose record of sins he has erased, he also will surely give future splendor.
Àti pé lẹ́yìn tí òun ti pè wá wá sọ́dọ̀ ara rẹ̀, ó sọ wá di aláìjẹ̀bi lẹ́yìn èyí, ó fi rere Kristi kún inú ọkàn wa. Lékè gbogbo rẹ̀, ó fún wa ní ìdúró rere pẹ̀lú rẹ̀, ó sì pinu ògo rẹ̀ fún wa.
31 So (I will tell you what we must conclude from [all] these things [that God does for us]./what shall we conclude from [all] these things [that God does for us]?) [RHQ] Because God [is acting] on our behalf, (no one can win against us!/can anyone defeat us? (OR, it does not matter if anyone opposes us)!) [RHQ]
Kí ni àwa yóò wí nísinsin yìí sí nǹkan ìyanu wọ̀nyí? Bí Ọlọ́run bá wà pẹ̀lú wa, ta ni yóò kọjú ìjà sí wa?
32 God did not spare even his very own Son. Instead, he turned him over [to others to cruelly kill him] in order that all we [who believe in him] may benefit [from his dying for us. Therefore, because God did that], (he will also certainly give us freely everything [that we need to live for him], in addition to [giving us] Christ./will he not also certainly give us freely everything [that we need to live for him], in addition to [giving us] Christ?) [RHQ]
Níwọ̀n ìgbà tí Ọlọ́run ti fi Ọmọ rẹ̀ fún wa, ǹjẹ́ ó ha tún le ṣòro fún un láti fún wa ní ohunkóhun bí?
33 It is God himself who erases the record of our sins. So (no one who accuses us [before God will win against us] (OR, [it does not matter] if anyone tries to accuse us) whom God has chosen./is it possible that anyone who accuses us [before God] will win against us (OR, does it matter if anyone tries to accuse us) whom God has chosen?) [RHQ]
Ta ni ẹni náà tí ó lè dá wa lẹ́bi, àwa ẹni tí Ọlọ́run ti yàn fún ara rẹ̀. Ǹjẹ́ Ọlọ́run yóò dá wa lẹ́bi? Bẹ́ẹ̀ kọ́! Òun ni ẹni tí ó dáríjì wá, tí ó sì fi wá sípò tí ó dára lọ́dọ̀ rẹ̀.
34 It is Christ Jesus himself who pleads [with God] for us, so (no one can condemn us (OR, say that we are still guilty for our sin)./can anyone condemn us (OR, say that we are still guilty for our sin)?) [RHQ] Christ died [for us], but he was also brought back to life {[God] also raised him from the dead}, and he is now at the place of honor [ruling] with God [MTY].
Ta ni ẹni náà tí yóò dá wa lẹ́bi? Kò sí. Kristi Jesu tí ó kú, kí a sá à kúkú wí pé tí a ti jí dìde kúrò nínú òkú, ẹni tí ó sì wà ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run, tó sì ń bẹ̀bẹ̀ fún wa?
35 Absolutely no one and nothing can cause Christ to stop loving us! [RHQ] That could not [RHQ] happen [because someone] caused us to have trouble [DOU], or [because someone did things to] harm us, or [because we did] not have anything to eat, or [because we did] not have enough clothes, or [because we lived in a] dangerous situation, or [because someone killed us with] a sword [MTY] (OR, murdered us).
Ta ni yóò ha yà wá kúrò nínú ìfẹ́ Kristi? Ìpọ́njú ni, tàbí wàhálà tàbí inúnibíni tàbí ìyàn, tàbí ìhòhò, tàbí ewu tàbí idà?
36 [Such things may happen to us, just like] it is written {[as David] wrote} [that David said to God], “Because we are your [(sg)] people, [other people repeatedly attempt to] kill us. They consider that we are [only people to be killed], [like a butcher considers] that sheep are [only] animals to be slaughtered [MET].”
Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Nítorí rẹ̀ ni a ṣe ń pa wá kú ní gbogbo ọjọ́; À ń kà wá sí bí àgùntàn fún pípa.”
37 But even though all these bad things [may happen to us], we win a great victory/triumph [over these things because Christ], who loves us, [helps us].
Ṣùgbọ́n nínú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, àwa ju ẹni tí ó ṣẹ́gun lọ nípasẹ̀ Kristi ẹni tí ó fẹ́ wa.
38 I am absolutely certain that neither being dead (OR, being killed), nor [what happens to us while] we live, nor angels, nor demons, nor present events, nor future events, nor powerful [beings/forces],
Nítorí pé ó dá mi lójú gbangba pé, kì í ṣe ikú tàbí ìyè, kì í ṣe àwọn angẹli tàbí ẹ̀mí èṣù, kì í ṣe ohun ìgbà ìsinsin yìí tàbí ohun tí ó ń bọ̀, tàbí àwọn agbára,
39 nor [powerful beings] above [the horizon] or below [the horizon] [MTY], nor anything else that [God has] created can cause God to stop loving us. [God showed us that he loves us by sending] Jesus Christ our Lord [to die for us].
tàbí òkè, tàbí ọ̀gbun, tàbí ohunkóhun nínú ìṣẹ̀dá ni yóò le yà wá kúrò nínú ìfẹ́ Ọlọ́run tí ó ń bẹ nínú Kristi Jesu, Olúwa wa.

< Romans 8 >