< Romans 3 >

1 [Someone may object to this, saying], “[If being circumcised does not cause God to accept us Jews], (there is no advantage in being a Jew [over being a non-Jew]./is there any advantage in being a Jew [over being a non-Jew]?) [RHQ] Being circumcised does not benefit [us Jews at all]!”
Ǹjẹ́ àǹfààní wo ní Júù ní? Tàbí kín ni èrè ilà kíkọ?
2 [I would reply that being Jews] benefits [us] in many ways [HYP]. First of all, it benefits us because it was to [our ancestors] that God’s words, [words that contain his promises], were given {that [God] gave his words, [words that contain his promises]}.
Púpọ̀ lọ́nà gbogbo; pàtàkì jùlọ ni pé àwọn ni a fi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lé lọ́wọ́.
3 Many [Jews did not obey God as they promised that they would. So someone might ask], “Does their not being faithful mean that God will not [bless us Jews] as he promised [that he would]?”
Ǹjẹ́ kí ha ni bí àwọn kan jẹ́ aláìgbàgbọ́? Àìgbàgbọ́ wọn yóò ha sọ òtítọ́ Ọlọ́run di asán bí?
4 [I would reply], “No, it certainly does not mean that! God always does [what he has promised], even though [people do not]. All those who accuse God [of not keeping his promises to us Jews] are very mistaken.” [What King David wrote about God’s justly saying that he would punish him for his sins is also true of those who accuse God of not keeping his promises. What he said to God was], “So everyone must acknowledge that what you [(sg)] have said [about them] (OR, [their sin]) is true, and you will always win the case when you are accused {when [people] accuse you}.”
Kí a má rí! Kí Ọlọ́run jẹ́ olóòtítọ́, àti olúkúlùkù ènìyàn jẹ́ èké; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Kí a lè dá ọ láre nínú ọ̀rọ̀ rẹ, ṣùgbọ́n kí ìwọ lè borí nígbà tí ìwọ bá wá sí ìdájọ́.”
5 So if we [Jews’] being wicked [PRS] shows that it is right that God [does not bless us], what shall we say/conclude? Shall we conclude that it is not right for God to be angry [and punish us Jews] [MTY]? I [should not be saying these things], [but] I am speaking as ordinary humans [speak].
Ṣùgbọ́n bí àìṣòdodo wa bá fi òdodo Ọlọ́run hàn, kín ni àwa ó wí? Ọlọ́run ha jẹ́ àìṣòdodo bí, nígbà tí ó bá ń fi ìbínú rẹ̀ hàn? (Mo fi ṣe àkàwé bí ènìyàn.)
6 We should certainly not [conclude that God should not judge us], because if God [did not judge us Jews], (it would not possibly be right for him to judge [anyone in] the world [MTY]!/how could he judge [anyone in] the world?) [MTY, RHQ]
Kí a má rí i. Bí bẹ́ẹ̀ bá ni, Ọlọ́run yóò ha ṣe lè dájọ́ aráyé?
7 But [someone might object and say to me], “The fact that God truly [keeps his promises] becomes very clear/evident because of my not doing [what God has commanded]. But the result is that people praise God! So (God should no longer say that I should be punished {that [he] should punish me} on account of my having sinned!/why should God still say that I should be punished {that [he] should punish me} on account of my having sinned?) [RHQ]
Nítorí bí òtítọ́ Ọlọ́run bá di púpọ̀ sí ìyìn rẹ̀ nítorí èké mi, èéṣe tí a fi ń dá mi lẹ́jọ́ bí ẹlẹ́ṣẹ̀?
8 [If what you, Paul, say is true], then (we might as well/it is all right for us to) do evil things in order that good things [like that] will result! For example, [then people will praise God]!” Some people speak evil about me by their [falsely] saying that I say [such things. God] will fairly/justly punish [people who say such things about me]!
Èéṣe tí a kò fi ṣe búburú kí rere lè jáde wá? Bí àwọn kan tí ń fi ẹnu àtẹ́ sọ wí pé a ń sọ bẹ́ẹ̀; ti àwọn kan sì ń tẹnumọ́ ọn pé a sọ; àwọn ẹni tí ìdálẹ́bi wọn tọ́.
9 [If someone would ask], “[Shall we conclude that God] will treat us [Jews] more favorably [and will treat] the non-Jews less [favorably] [RHQ]?” [I would reply that we can] certainly not [conclude that]! I have already shown you that all people, the Jews and also the non-Jews, have sinned and [so they deserve to be punished] {[that God will punish them]} [PRS].
Ǹjẹ́ kí ha ni? Àwa ha sàn ju wọn lọ bí? Kò rí bẹ́ẹ̀ rárá, nítorí a fihàn ṣáájú pé àti àwọn Júù àti àwọn Giriki, gbogbo wọn ni ó wà lábẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
10 [The following words] that are written {prophets have written} [in the Scriptures support this], No person is righteous. There is not even one righteous person!
Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Kò sí ẹni tí í ṣe olódodo, kò sí ẹnìkan,
11 There is no one who understands [how to live properly] (OR, [about God]). There is no one who seeks/desires [to know] God!
kò sí ẹni tí òye yé, kò sí ẹni tí ó ń wá Ọlọ́run.
12 Absolutely everyone has turned away [MET] [from God]. God considers them depraved (OR, Everyone has become useless [to God]). There is no one who acts righteously; no, there is not even one!
Gbogbo wọn ni ó ti yapa, wọ́n jùmọ̀ di aláìlérè; kò sí ẹni tí ń ṣe rere, kò tilẹ̀ sí ẹnìkan.”
13 What people say [MTY] [is foul/bad, like the smell that comes from] a grave that has been {that [people] have} opened [MET]. [By what people say] [MTY], they deceive people. [By what they say] [MTY] [they injure people, just like] the poison of snakes [injures people] [MET].
“Ibojì tí ó ṣí sílẹ̀ ní ọ̀fun wọn: ahọ́n wọn n sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.” “Oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ lábẹ́ ètè wọn.”
14 They are continually (cursing/asking God to do harmful things to) others and saying (cruel/harsh/hateful) things [MTY].
“Ẹnu ẹni tí ó kún fún èpè àti fún oró kíkorò.”
15 They (go quickly/are eager) to murder people [MTY].
“Ẹsẹ̀ wọn yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀,
16 Wherever they go, they ruin everything and make [people] miserable [MTY].
ìparun àti ìpọ́njú wà lọ́nà wọn.
17 They have not/never known how [to live] peacefully [with other people].
Ọ̀nà àlàáfíà ni wọn kò sì mọ̀,”
18 They absolutely refuse to fear/reverence God [SYN]!
“Ìbẹ̀rù Ọlọ́run kò sí níwájú wọn.”
19 Furthermore, we know that it is to [Jewish] people, [who are] required to obey [God’s] laws, that Moses wrote those laws [PRS]. [We can infer from this that] there are no [Jews or non-Jews] [SYN] who are able to say anything [in reply to God’s saying that he will punish them for having sinned]. God has declared everyone in the world [MTY] guilty!
Àwa sì mọ̀ pé ohunkóhun tí òfin bá wí, ó ń wí fún àwọn tí ó wà lábẹ́ òfin: kí gbogbo ẹnu bá à lè dákẹ́ àti kí a lè mú gbogbo aráyé wá sábẹ́ ìdájọ́ Ọlọ́run.
20 It is not because people have done the things that God’s laws [require] that [God] will (erase the record of their sins/declare them no longer guilty for sin), [because no one has done those things completely]. In fact, the result of [our knowing God’s] laws is that we know clearly that we have sinned (OR, are sinful).
Nítorí pé nípa iṣẹ́ òfin, a kì yóò dá ẹnikẹ́ni láre níwájú rẹ̀: nítorí nípa òfin ni ìmọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ ti wá.
21 But God’s (erasing the record of our sins/declaring us no longer guilty) does not depend on [our obeying] the laws [that he gave Moses]. It has now been {[God] has now} revealed [to us] how he erases the record of our sins [by a different way]. It was written about [by Moses] {[Moses] wrote about it} in the laws [PRS] [God gave] him, and it was also written about by the prophets {the prophets also wrote about it}.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, a ti fi òdodo Ọlọ́run hàn láìsí òfin, tí a ti ń jẹ́rìí sí nípa òfin àti nípa àwọn wòlíì,
22 God erases the record of our sins because we trust in [what] Jesus Christ [has done for us]. God does this for every person who trusts [in Christ], because [he considers] that there is no difference [between Jews and non-Jews].
àní òdodo Ọlọ́run nípa ìgbàgbọ́ nínú Jesu Kristi, sí gbogbo ènìyàn àti gbogbo àwọn tí ó gbàgbọ́, nítorí tí kò sí ìyàtọ̀ láàrín Júù àti Helleni.
23 All people have done evil, and all people have failed to accomplish the glorious [goals] that God [set for them].
Gbogbo ènìyàn ni ó ṣá ti ṣẹ̀, tí wọ́n sì kùnà ògo Ọlọ́run,
24 Our record of sins has been erased {God erased the record of our sins} by God acting kindly [to forgive our sins], without our doing anything to earn it. Christ Jesus accomplished this [by dying for us].
àwọn ẹni tí a ń dá láre lọ́fẹ̀ẹ́ nípa oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀, nípa ìdáǹdè tí ó wà nínú Kristi Jesu.
25 God showed that Christ was the one who would atone for (OR, forgive) our sins [with the] blood [that flowed from his body when he died. God redeems/forgives] us because of our trusting [in Christ’s having died for us. God wanted] to show that he acts justly. [He wanted to do that] because, before [Jesus came, God] did not punish [everyone who sinned. So it seemed as though he was not being just]. But he was overlooking people’s sins during [that time],
Ẹni tí Ọlọ́run ti gbé kalẹ̀ láti jẹ́ ètùtù nípa ìgbàgbọ́ nípa ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, láti fi òdodo rẹ̀ hàn nítorí ìdáríjì àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti kọjá, nínú ìpamọ́ra Ọlọ́run,
26 because he is patient. [God arranged for Jesus to die for us]. By doing that, God now shows that he is just, and he shows that he is justly able to erase the record of sins for everyone who trusts/believes in Jesus.
láti fi òdodo rẹ̀ hàn ní ìgbà ìsinsin yìí: kí ó lè jẹ́ olódodo àti olùdáláre ẹni tí ó gba Jesu gbọ́.
27 It is not at all [RHQ] because of [our obeying the] laws [of Moses that God erases the record of our sins]. So, (there is no way that we can boast [that God does that because of our obeying those laws]./how can we boast [about God erasing the record of our sins because of our obeying those laws]?) [RHQ] Instead, [it is because of our] believing/trusting [in Christ that God erases the record of our sins].
Ọ̀nà ìṣògo dà? A ti mú un kúrò. Nípa òfin wo? Nípa iṣẹ́? Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n nípa òfin ìgbàgbọ́.
28 [We cannot boast about that], because we conclude that the record of our sins is erased {God erases the record of our sins} because of our trusting [in Christ]. God does not erase the record of our sins because of our obeying the laws [that he gave to Moses, because it is impossible for us to completely obey them].
Nítorí náà, a parí rẹ̀ sí pé nípa ìgbàgbọ́ ni a ń dá ènìyàn láre láìsí iṣẹ́ òfin.
29 (You who are Jews certainly should not [think that you] are the only ones whom God [will accept]!/Do you Jews [think it is you] alone whom God [will accept]?) [RHQ] You certainly should [realize that he will accept] non-Jews, too. [RHQ] Of course, [he will accept] non-Jews also,
Ọlọ́run àwọn Júù nìkan ha ni bí? Kì í ha ṣe ti àwọn aláìkọlà pẹ̀lú? Bẹ́ẹ̀ ni, ti àwọn aláìkọlà pẹ̀lú.
30 because, [as you firmly believe], there is only one God, who will erase the record of Jews’ [MTY] sins if they trust [in what Christ has done], and who will similarly erase the record of non-Jews’ [MTY] sins if they trust [in Christ].
Bí ó ti jẹ́ pé Ọlọ́run kan ni, yóò dá àwọn akọlà láre nípa ìgbàgbọ́ àti àwọn aláìkọlà nípa ìgbàgbọ́ wọn.
31 So, [if someone should ask concerning the laws that God gave Moses], “By saying [that God erases the record of our sins because of our] trusting [in Christ], does that mean that those laws now are useless?”, [I would reply], “Certainly not. Instead, we truly fulfill the laws [that God gave Moses].”
Àwa ha ń sọ òfin dasán nípa ìgbàgbọ́ bí? Kí a má rí i, ṣùgbọ́n a ń fi òfin múlẹ̀.

< Romans 3 >