< Philippians 3 >

1 [Now there are] other things [that I want to write about]. My fellow believers, continue to rejoice because [you belong to] the Lord. [Though] I will [now] write to you about those same matters [that I mentioned to you before, this is] not tiresome for me, and it will protect you [from those who would harm you spiritually].
Ní àkótán ará, ẹ máa yọ̀ nínú Olúwa wa. Kì í ṣe ìnira fún mi láti kọ̀wé ohun kan náà sí yín, ṣùgbọ́n fún yín ó jẹ́ ohun ààbò.
2 Beware of those [people who are dangerous] [MET] [like wild] dogs. They are [dangerous] evildoers [DOU]. Beware of them [since they are like people who] cut [other people’s] bodies [MET]. [They will harm you spiritually by insisting that you must let someone circumcise you in order for you to become God’s people] [MTY, MET].
Ẹ kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn ajá, ẹ kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn oníṣẹ́ búburú, ẹ sì kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn onílà.
3 [Those people think that they are God’s people because someone has circumcised them]. But we, [not they], are [truly God’s people] [MET], [whether or not someone has] circumcised [us]. God’s Spirit [enables us to] [MTY] worship [God]; we praise Christ Jesus [because he has enabled us to become the people of God]. We do not believe [that God will consider/make us his people as a result of what someone has done to our] bodies [MTY, SYN].
Nítorí àwa ni onílà, tí ń sin Ọlọ́run nípa ti Ẹ̀mí, àwa sì ń ṣògo nínú Kristi Jesu, àwa kò sí ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ẹran-ara.
4 [We do not trust in those rituals to make us acceptable to God], although I could very well do that [if it would be useful for me]. Philippians 3:4b-6 [In fact], [if I could benefit from it for my salvation], I could rely upon what I have done and who I am [MTY, SYN] more than anyone else could! I will tell you why.
Bí èmi tìkára mi pẹ̀lú ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ara. Bí ẹnikẹ́ni bá rò pé òun ni ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ara, tèmi tilẹ̀ pọ̀,
5 I [was circumcised] {[Someone] circumcised me} when I was one week old. I am from the people of Israel. I am from the tribe of Benjamin. I am completely Hebrew in every way. [While I was] a member of the Pharisee [sect], I [strictly obeyed] the laws [that God gave Moses].
ẹni tí a kọ nílà ní ọjọ́ kẹjọ, láti inú kùkùté Israẹli wá, láti inú ẹ̀yà Benjamini, Heberu láti inú Heberu wá; nítorí, ní ti òfin Farisi ni èmi;
6 I was [so] zealous [to make people obey those laws that] I caused the people who believe in Christ to suffer [because I thought they were trying to abolish those laws. Indeed], as far as my obeying those laws is concerned, no [one could] have accused [me by] saying that I had disobeyed any of those laws.
ní ti ìtara, èmi ń ṣe inúnibíni sí ìjọ; ní ti òdodo tí ó wà nínú òfin, mo jẹ́ aláìlẹ́gàn.
7 Nevertheless, all such things as those, which I used to [consider to] be useful to me, those [very] things I now consider worthless, because I [want to know] Christ (OR, in order that I [may know] Christ).
Ṣùgbọ́n ohunkóhun tí ó ti jásí èrè fún mi, àwọn ni mo ti kà sí òfo nítorí Kristi.
8 More than that, I consider all things to be worthless, compared to how great it is to know Christ Jesus my Lord. Because I [want to know] him [better] (OR, In order that I [may know] him [better]), I have rejected all things as worthless. I consider them [as useless as] [MET] rubbish, in order that I may have [a close relationship with] Christ [MET],
Nítòótọ́ láìṣe àní àní mo sì ka ohun gbogbo sí òfo nítorí ìtayọ ìmọ̀ Kristi Jesu Olúwa mi; nítorí ẹni ti mo ti ṣòfò ohun gbogbo, mo si kà wọn sí ohun tí kò ní èrè, kí èmi lè jèrè Kristi,
9 and in order that I may completely belong to him. It was not as a result of [my obeying] the laws [he gave Moses] that God erased the record of my sins. Instead, it is because I have trusted in Christ [that God] has declared that I am no longer guilty for my sins, and he enables me to act righteously. [It is] God [himself who] has erased the record of my sins, and he enables me to act righteously, [only] because I have trusted [in Christ].
kí a sì lè bá mi nínú rẹ̀, láìní òdodo tí èmi tìkára mi, tí ó ti inú òfin wá, ṣùgbọ́n èyí tí ó ti inú ìgbàgbọ́ wá nínú Kristi, òdodo láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run nípasẹ̀ ìgbàgbọ́.
10 I [want] to know Christ [better and better]. Particularly, I [want] to continually experience [his working] powerfully in my life, [just like God worked powerfully when he] caused Christ to become alive after he died. I [also want to be continually willing] to suffer [in order that I may obey God], just like Christ suffered [in order that he might obey God. I also want] to be completely willing to die for [Christ], even as he died for me,
Èmi mọ̀ ọ́n, àti agbára àjíǹde rẹ̀, àti láti jẹ́ alábápín nínú ìyà rẹ̀ nígbà tí mo bá fi ara mọ́ ọn nínú ikú rẹ̀;
11 [because I expect that, as a result of God’s goodness], he will cause me to live again after I have died.
nípasẹ̀ bẹ́ẹ̀ kí èmi lè ní àjíǹde kúrò nínú òkú.
12 I do not claim that I have already become completely like Christ Jesus; that is, I have not already become all that God intends me to be [DOU]. But I earnestly try to become [more and more like Christ], because he chose me [in order that I might become like him].
Kì í ṣe pé ọwọ́ mi ti tẹ̀ ẹ́ ná, tàbí mo ti di pípé, ṣùgbọ́n èmi ń lépa sí i, bí ọwọ́ mi yóò lè tẹ èrè náà nítorí èyí tí a ti dì mímú pẹ̀lú, láti ọ̀dọ̀ Kristi Jesu wá.
13 My fellow believers, I certainly do not consider that I have already become completely like Christ. But I [am like a runner. A runner does not look backward] [MET]. Instead, he leans/stretches forward as he runs straight toward the goal [in order that he might win the race and get the prize. Similarly], I do not think about what I have already done.
Ará, èmi kò kara mi sí ẹni ti ọwọ́ rẹ̀ ti tẹ̀ ẹ́ ná, ṣùgbọ́n ohun kan yìí ni èmi ń ṣe, èmi ń gbàgbé àwọn nǹkan tí ó ti kọjá. Lẹ́yìn náà mo ń nàgà wo àwọn nǹkan tí ó wà níwájú.
14 Instead, I concentrate only on [continuing to become more and more like Christ right up to the end of my life] [MET]. As a result, because of my relationship with Christ Jesus, God will call/summon me to receive a reward from him [in heaven].
Èmi ń lépa láti dé òpin eré ìje náà fún èrè ìpè gíga Ọlọ́run nínú Kristi Jesu.
15 So, all of us who are [spiritually] mature should think this [same way]. If any [of you] do not think this same way regarding what I [have written here], God will reveal that to you.
Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí àwa tí a dàgbà nípa ti ẹ̀mí ni èrò yìí; bí ẹ̀yin bá sì ní èrò mìíràn nínú ohunkóhun, èyí náà pẹ̀lú ni Ọlọ́run yóò fihàn yín.
16 What is important is that we must conduct our lives according to what [God has already revealed to] us.
Kìkì pé, ki a ma gbe ìgbé ayé gẹ́gẹ́ bi èyí ti a ri gba.
17 My fellow believers, [all of] you should follow my example, and observe those people who act as I do, [in order that you may imitate them also].
Ará, ẹ jùmọ̀ ṣe àfarawé mi, ẹ ṣe àkíyèsí àwọn tí ń rìn bẹ́ẹ̀, àní bí ẹ ti ní wa fún àpẹẹrẹ.
18 [Keep in mind that] there are many people [who say that they believe in Christ, but] who act [in such a way that shows] that they are opposed to [the teaching about] Christ [dying on] the cross [MTY]. I have told you about those people many times [before], and now I am sad, even crying, as I tell you [about them again].
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ní ń rìn, nípasẹ̀ àwọn ẹni tí mo ti ń wí fún yín nígbàkígbà, àní, tí mo sì ń sọkún bí mo ti ń wí fún yín nísinsin yìí, pé, ọ̀tá àgbélébùú Kristi ni wọ́n.
19 [God] will severely punish them. The things their bodies desire [MTY] have become [like] gods to them [MET]. They are proud of the things they should be ashamed of. They think only about what unbelievers [MTY] think about.
Ìgbẹ̀yìn wọn ni ìparun, ikùn wọn sì ni Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń ṣògo nínú ìtìjú wọn, àwọn ẹni tí ń tọ́jú ohun ti ayé.
20 [But remember] that we are citizens of heaven. And we eagerly wait for our Savior, the Lord Jesus Christ, [to return] from there.
Nítorí ìlú ìbílẹ̀ wá ń bẹ̀ ní ọ̀run, láti ibi ti àwa pẹ̀lú gbé ń fojúsọ́nà fún Olùgbàlà, Jesu Kristi Olúwa.
21 By the power that enables him to put everything under his own control, he will change our weak bodies to become like his glorious body.
Ẹni tí yóò sọ ara ìrẹ̀lẹ̀ wa di ọ̀tún kí ó lè bá ara ògo rẹ̀ mu, nípa agbára tí ó mú kí ó ṣe é ṣe fún un láti tẹ orí ohun gbogbo bá fún ara rẹ̀.

< Philippians 3 >