< Obadiah 1 >

1 This is a message that Yahweh our God gave to me, Obadiah, about the Edom [people-group]. Yahweh our God has told me this about [the people of] Edom: “I, Yahweh, have sent a messenger to other nations, telling them to prepare to go and attack Edom.”
Ìran ti Obadiah. Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu. Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, a sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé, “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”
2 And Yahweh says this to the people of Edom: “I will soon cause you to become the weakest and most despised nation [on the earth].
“Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí; ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
3 Your [capital city] is high in the rocky cliffs, and you are very proud; you think that you are safe from being attacked by your enemies [RHQ], but you [IDM] have deceived yourselves.
Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ, ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta, tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga, ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé, ‘Ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
4 And I tell you that even if [you had wings and] could fly higher than eagles fly, and if you could make your homes among the stars, I would bring you [crashing] down from there.
Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì, bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,” ni Olúwa wí.
5 When thieves break into someone’s house during the night, they certainly [RHQ] steal only the things that they want. And people who pick grapes always [RHQ] leave a few grapes on the vines. But your country will be completely destroyed!
“Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá, bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru, Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́, wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́? Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá, wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
6 Everything that is valuable will be taken away. [Your enemies] will find and take away even the valuable things that you have hidden.
Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau, tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
7 All (your allies/nations who promised to help you) will turn against you, and they will force you to leave your country/land. Those with whom you have peace now will trick/deceive you and defeat you. Those who eat meals with you now are planning to trap you, and [then they will say to you], ‘You are not [RHQ] as clever [as you thought you were]!’
Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ; àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”
8 I, Yahweh, declare that at the time that I destroy Edom, I will punish the men who live in those cliffs who [thought that they] were wise.
Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà, Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run, àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
9 The soldiers from Teman [town] will become terrified; all you people who are descendants of Esau will be (wiped out/killed).
A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, ìwọ Temani, gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
10 You acted cruel in a cruel way toward your relatives who are descendants of Jacob, [the twin brother of your ancestor Esau]. So now you will be disgraced forever; you will be completely destroyed.
Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ, ìtìjú yóò bò ọ, a ó sì pa ọ run títí láé.
11 Foreigners entered the gates of Jerusalem and (cast lots/threw small stones that were marked) to decide what valuable things they would take away; but you were as bad as those foreigners, because you just stood there [and did not help the Israelis].
Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan, ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ, tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ, tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu, ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
12 You should not have (gloated/been happy) about the disaster that the Israelis were experiencing. You should not have been happy when their towns were ruined. You should not have made fun [of them] when they were suffering.
Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ, ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀ ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda, ní ọjọ́ ìparun wọn ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
13 They are my people, so you should not have entered their [city] gates when they were experiencing those disasters and you should not have laughed at them. And you should not have taken away their [valuable] possessions.
Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀ nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó, ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
14 You should not have stood at crossroads to catch those who were [trying to] escape. You should not have [captured them and] put them into the hands of [their enemies] when they were experiencing those disasters.”
Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò. Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
15 “There will soon be the time when I, Yahweh, will judge [and punish] all the nations. And you [people of Edom] will experience the same [disasters] that you caused [others to experience]. The same evil things that you have done to others will happen to you.
“Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé lórí gbogbo àwọn kèfèrí. Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà; ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
16 [My people in Jerusalem have been punished] because I was very angry with them. [It is as though] [MET] they drank [a cup of very bitter liquid] on Zion, my sacred hill. But [I] will punish [MET] all the other nations even more severely, and cause them to disappear completely.
Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí; wọn yóò mu ún ní àmutẹ́rùn wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò mu ún rí.
17 But some [people in Jerusalem will escape], and Jerusalem will become a very holy/sacred place. Then the descendants of Jacob will [conquer and] possess again the land that truly belongs to them.
Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni, wọn yóò sì jẹ́ mímọ́, àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn.
18 The descendants [MTY] of Jacob and his son Joseph will be like [MET] a fire, and the people [MTY] of Edom will be like [MET] stubble that will be completely burned in that fire. Not one person will remain alive. [That will surely happen because] I, Yahweh, have said it.”
Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko wọn yóò fi iná sí i, wọn yóò jo run. Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.” Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
19 The Israeli people [who live] in the southern desert are the ones who will capture Edom. And those [who live in] the western foothills will capture the Phoenicia [region] and the areas of Ephraim and Samaria. And people of the tribe of Benjamin will conquer the Gilead [region].
Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau, àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní. Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria; Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
20 Those who were (exiled in/forced to go to) [Babylon] will [return to their land] [and] capture the Phoenicia [region] as far north as Zarephath [on the coast of the Mediterranean Sea]. People of Jerusalem who were captured and taken to Sardis, [the capital city of the Lydia region], will capture the towns in the southern desert.
Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati; àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní.
21 The army of Jerusalem will attack Edom and conquer it, and Yahweh will be their king.
Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau. Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.

< Obadiah 1 >