< Nehemiah 5 >

1 [Later, ] many of the men and their wives protested loudly about what [some of] the [other] Jews were doing.
Nísinsin yìí àwọn ènìyàn àti àwọn ìyàwó wọn kígbe ńlá sókè sí àwọn Júù arákùnrin wọn.
2 Some/One of them said, “We have many children. So we need a lot of grain to be able to eat and continue to live.”
Àwọn kan ń wí pé, “Àwa àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa pọ̀; kí àwa kí ó le è jẹ, kí a sì wà láààyè, a gbọdọ̀ rí oúnjẹ.”
3 Others said, “The fields and vineyards and houses that we own, it has been necessary for us to (mortgage them/promise to give them to someone if we do not pay back to him the money he has loaned us) in order to get money to buy grain, during this (famine/time where there is not much food).”
Àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ti fi oko wa ọgbà àjàrà wa àti ilé wa dógò kí àwa kí ó lè rí oúnjẹ ní àkókò ìyàn.”
4 Others said, “We have [needed to] borrow money to pay the taxes that the king [commanded us to pay] on our fields and our vineyards.
Síbẹ̀ àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ní láti yá owó láti san ìṣákọ́lẹ̀ fún ọba lórí àwọn oko wa àti àwọn ọgbà àjàrà wa.
5 We are Jews just like [IDM] they are. Our children are ([just as good as/equal with)] their children. But we have needed to sell some of our children to become slaves [in order to pay what we owe]. We have already sold some of our daughters to become slaves. Our fields and vineyards have been taken away from us, so now we do not have [the money to pay what we owe, and we are forced to sell our children to get money to pay those debts].”
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a jẹ́ ẹran-ara kan àti ẹ̀jẹ̀ kan gẹ́gẹ́ bí àwọn ará ìlú wa tí àwọn ọmọkùnrin wa sì dára bí í tiwọn, síbẹ̀ àwa ní láti fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa sí oko ẹrú. Díẹ̀ nínú àwọn ọmọbìnrin wa ti wà lóko ẹrú náà, ṣùgbọ́n àwa kò ní agbára, nítorí àwọn oko àti ọgbà àjàrà wa ti di ti ẹlòmíràn.”
6 I was very angry when I heard these things that they were complaining about.
Èmi bínú gidigidi nígbà tí mo gbọ́ igbe wọn àti àwọn ẹ̀sùn wọ̀nyí.
7 So I thought about what I could do about it. I told the leaders and officials [who were responsible for this work], “You are charging interest to your own relatives [when they borrow money from you]!” Then I called together a large group of people,
Mo rò wọ́n wò ní ọkàn mi mo sì fi ẹ̀sùn kan ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè. Mo sọ fún wọn pé, ẹ̀yin ń gba owó èlé lọ́wọ́ àwọn ará ìlú u yín! Nítorí náà mo pe àpéjọ ńlá láti bá wọn wí.
8 and I said to their [leaders], “Some of our Jewish relatives have been forced to sell themselves to become slaves of people who have come from other countries. As much as we have been able to, we have been buying them back [out of slavery]. But now you are forcing your own relatives to sell themselves to you, their fellow Jews, as slaves!” [When I said that to them, ] they were silent. There was nothing that they could say [because they knew that what I said was true].
Mo sì wí fún wọn pé, “Níbi tí àwa ní agbára mọ, àwa ti ra àwọn Júù arákùnrin wa tí a ti tà fún àwọn tí kì í ṣe Júù padà. Nísinsin yìí ẹ̀yìn ń ta àwọn arákùnrin yín, tí àwa sì tún ní láti rà wọ́n padà!” Wọ́n dákẹ́, nítorí wọn kò rí ohunkóhun sọ.
9 Then I said to them, “What you are doing is terrible [EUP]! You certainly ought to [RHQ] obey God and do what is right! If you did that, our enemies who do not revere Yahweh [would see that we are doing what is right and] would not ridicule us.
Nítorí náà, mo tẹ̀síwájú pé, “Ohun tí ẹ̀ ń ṣe kò dára. Kò ha yẹ kí ẹ máa rìn nínú ìbẹ̀rù Ọlọ́run bí, láti yẹra fún ẹ̀gàn àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn tí í ṣe ọ̀tá wa?
10 My fellow Jews and I and my servants have lent money and grain to people [without charging interest]. So you all should stop charging interest on these loans.
Èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi, pẹ̀lú ń yá àwọn ènìyàn lówó àti oúnjẹ. Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí a dáwọ́ owó èlé gbígbà yìí dúró!
11 Also, you must give back to them their fields, their vineyards, their olive tree orchards, and their houses that you have taken from them. You must also give back to them the interest that you charged them when they borrowed money, grain, wine, and [olive] oil from you, and you must do it today!”
Ẹ fún wọn ní oko wọn, ọgbà àjàrà wọn, ọgbà olifi wọn àti ilé e wọn pẹ̀lú owó èlé tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn ìdá ọgọ́rùn-ún owó, oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn padà kíákíá.”
12 The leaders replied, “We will do what you have said. We will return to them everything that we forced them to give to us, and we will not require that they give us anything more.” Then I summoned the priests, and I forced the leaders to vow in front of them that they would do what they had promised to do.
Wọ́n wí pé, “Àwa yóò dá a padà. Àwa kì yóò sì béèrè ohunkóhun lọ́wọ́ wọn mọ́. Àwa yóò ṣe bí o ti wí.” Nígbà náà mo pe àwọn àlùfáà, mo sì mú kí àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè búra láti jẹ́ kí wọ́n ṣe ohun tí wọ́n ti ṣe ìlérí.
13 I shook out the folds of my robe and said to them, “If you do not do what you have just now promised to do, I hope/desire that God will shake you like I am shaking my robe. He will take away your homes and everything else that you own.” They all replied, “Amen/May it be so!” And they praised Yahweh. Then they did what they had promised to do.
Mo sì gbọn ìṣẹ́tí aṣọ mi, mo wí pé, “Báyìí ni kí Ọlọ́run gbọn olúkúlùkù ènìyàn tí kò bá pa ìlérí yìí mọ́ jáde kúrò ní ilẹ̀ ìní i rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni kí a gbọn irú ẹni bẹ́ẹ̀ jáde kí ó sì ṣófo!” Gbogbo ìjọ ènìyàn sì wí pé, “Àmín,” wọ́n sì fi ìyìn fún Olúwa. Àwọn ènìyàn náà sì ṣe bí wọ́n ti ṣe ìlérí.
14 I was appointed to be the governor of Judea in the twentieth year that Artaxerxes was the king [of Persia]. For the next twelve years, until he had been ruling for almost 32 years, neither I nor my officials accepted [the money that we were allowed/entitled to receive to buy] food because of my being the governor.
Síwájú sí í, láti ogún ọdún ọba Artasasta, nígbà tí a ti yàn mí láti jẹ́ baálẹ̀ wọn ní ilẹ̀ Juda, títí di ọdún kejìlélọ́gbọ̀n ìjọba rẹ̀—ọdún méjìlá, èmi àti àwọn arákùnrin mi kò jẹ oúnjẹ baálẹ̀.
15 The men who were governors before I became the governor had burdened the people by requiring them to pay a lot of taxes. They had forced each person to pay to them 40 silver coins every day, in addition to giving food and wine to them. Even their servants/officials oppressed the people. But I did not do that, because I revered God.
Ṣùgbọ́n àwọn baálẹ̀ ìṣáájú—tí ó ti wà ṣáájú mi—gbe àjàgà wúwo lé àwọn ènìyàn lórí yàtọ̀ fún oúnjẹ àti wáìnì wọ́n sì tún gba ogójì ṣékélì fàdákà lọ́wọ́ wọn. Kódà àwọn ìránṣẹ́ wọn tún jẹ gàba lórí wọn. Ṣùgbọ́n èmi kò ṣe bẹ́ẹ̀ nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
16 I also continued to work on the wall, and I did not take land from people [who were unable to pay back the money that they had borrowed from me]. All those who worked for me joined me to work on the wall.
Dípò bẹ́ẹ̀, mo fi ara mi jì fún iṣẹ́ lórí odi yìí. Gbogbo àwọn ènìyàn mi péjọ síbẹ̀ fún iṣẹ́ náà; a kò sì gba ilẹ̀ kankan.
17 Also, every day I was responsible to feed 150 Jewish officials, and also [official] visitors who came from nearby countries.
Síwájú sí í, àádọ́jọ àwọn Júù àti àwọn ìjòyè jẹun lórí tábìlì mi, àti pẹ̀lú àwọn tí wọ́n wá bá wa láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká.
18 Each day I [told my servants to] serve [us the meat from] one ox, six very good sheep, and chickens. And every ten days I gave them a large new supply of wine. But I knew that the people were burdened [by paying lots of taxes], so I did not accept [the money that I was entitled/allowed to receive to buy all this] food because of my being the governor.
Ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ni a máa ń pèsè màlúù kan, ààyò àgùntàn mẹ́fà àti adìyẹ fún mi àti lẹ́ẹ̀kan ní ọjọ́ mẹ́wàá ni wọ́n máa ń pèsè onírúurú wáìnì tí ó pọ̀ fún mi. Fún gbogbo èyí, èmi kò béèrè oúnjẹ baálẹ̀, nítorí ohun ti a ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí pọ̀ jọjọ.
19 My God, do not forget me, and reward me because of all that I have done for these people.
Rántí mi, Ọlọ́run mi, fún rere, nítorí fún gbogbo ohun tí mo ti ṣe fún àwọn ènìyàn yìí.

< Nehemiah 5 >