< Matthew 4 >

1 Then Jesus was led by the Spirit {[God’s] Spirit led Jesus} into a desolate area to be tempted by the devil {in order that the devil would tempt him}.
Nígbà náà ni Ẹ̀mí Mímọ́ darí Jesu sí ijù láti dán an wò láti ọwọ́ èṣù.
2 After he did not eat food for 40 days, and 40 nights. he was hungry.
Lẹ́yìn tí Òun ti gbààwẹ̀ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, ebi sì ń pa á.
3 [Satan], the tempter, came to him and said, “Because you [claim that you have a relationship with] God [as] a son [has with his father] [MET], [prove it] by commanding these stones to become bread [so that you can eat them]!”
Nígbà náà ni olùdánwò tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, pàṣẹ kí òkúta wọ̀nyí di àkàrà.”
4 But Jesus said [to him], “[No! I will not change stones into bread, because] it is written [in the Scriptures] {in the Scriptures [Moses] wrote}, [‘Eating] food [SYN] [sustains] people [physically, but] it does not sustain them [spiritually] [SYN]. Instead, [paying attention to] everything that God has spoken [to them is what sustains people spiritually].’”
Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn pé, “A ti kọ ìwé rẹ̀ pé: ‘Ènìyàn kì yóò wà láààyè nípa àkàrà nìkan, bí kò ṣe nípa gbogbo ọ̀rọ̀ ti ó ti ẹnu Ọlọ́run jáde wá.’”
5 Then the devil took Jesus to [Jerusalem], the city that is dedicated to God. He set him on the highest part of the Temple,
Lẹ́yìn èyí ni èṣù gbé e lọ sí ìlú mímọ́ náà; ó gbé e lé ibi ṣóńṣó tẹmpili.
6 and said to him, “Because you [claim that you have a relationship with] God [as] a son [has with his father, prove it by] jumping down [to the ground. You will not be hurt], because it is written [in the Scriptures], [‘God] will command his angels to protect you. They will lift you up in their hands [when you are falling], in order that [you will not get hurt]. You will not [even] strike your foot on a stone.’”
Ó wí pé, “Bí ìwọ̀ bá jẹ́ Ọmọ Ọlọ́run, bẹ́ sílẹ̀ fún ara rẹ. A sá à ti kọ̀wé rẹ̀ pé, “‘Yóò pàṣẹ fún àwọn angẹli rẹ̀ nítorí tìrẹ wọn yóò sì gbé ọ sókè ni ọwọ́ wọn kí ìwọ kí ó má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gbún òkúta.’”
7 But Jesus said, “[No! I] will not [jump down, because] in another place [in the Scriptures] it is written {there are these words that [Moses] wrote}: ‘Do not [try to] test the Lord your God [to see if he will prevent something bad from happening to you when you do something foolish!]’”
Jesu sì dalóhùn, “A sá à ti kọ ọ́ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run rẹ wò.’”
8 Then the devil took him on [top of] a very high mountain. There he showed him all the nations in the world and the magnificent things in those nations.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, èṣù gbé e lọ sórí òkè gíga, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ ọba ayé àti gbogbo ògo wọn hàn án.
9 And then he said to him, “I will [let you rule all these nations and] give you the magnificent things in them if you bow down and worship me.”
Ó sì wí fún un pé, “Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi yóò fi fún ọ, bí ìwọ bá foríbalẹ̀ tí o sì sìn mi.”
10 But Jesus said to him, “[No, I will not worship you], Satan, [so] go away! It is written in the Scriptures, ‘It is the Lord your God whom you [(pl)] must worship, and you [(pl)] must serve only him!’”
Jesu wí fún un pé, “Padà kúrò lẹ́yìn mi, Satani! Nítorí a ti kọ ọ́ pé, ‘Olúwa Ọlọ́run rẹ ni kí ìwọ kí ó fi orí balẹ̀ fún, òun nìkan ṣoṣo ni kí ìwọ máa sìn.’”
11 Then the devil went away, and right away, angels came to Jesus and took care of him.
Nígbà náà ni èṣù fi í sílẹ̀ lọ, àwọn angẹli sì tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.
12 [While] Jesus [was in Judea, John the Baptizer’s disciples] told him that John had been put in prison and kept there {that [Herod Antipas] had put John [the Baptizer] in prison [and kept him there]}. [So] Jesus returned to Galilee [District]. While he was in Galilee, he first went to Nazareth [town].
Nígbà tí Jesu gbọ́ wí pé a ti fi Johanu sínú túbú ó padà sí Galili.
13 Then he left Nazareth and went to Capernaum [city in order to live there. Capernaum is located beside Galilee Lake in the region which was formerly] the regions of [the tribes of] Zebulun and Naphtali.
Ó kúrò ní Nasareti, ó sì lọ í gbé Kapernaumu, èyí tí ó wà létí Òkun Sebuluni àti Naftali.
14 [One reason that he went there] was so that [these words] that were written by the prophet Isaiah might be fulfilled {so that he might fulfill these words that the prophet Isaiah wrote}:
Kí èyí tí a ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu wòlíì Isaiah lè ṣẹ pé,
15 “Zebulun region and Naphtali region [are on] the road [which is] near Galilee [Lake and] on the eastern side of the Jordan [River. They are] the regions in Galilee [District where many] non-Jews [are living].
“Ìwọ Sebuluni àti ilẹ̀ Naftali ọ̀nà tó lọ sí Òkun, ní ọ̀nà Jordani, Galili ti àwọn kèfèrí.
16 [Although the people there will be like] people who sit in a dark place [MET], [they will suddenly perceive clearly a new teaching, as] people who have seen a big light shining on them [MET] perceive everything clearly. [The] people who are located in a dangerous [MET] region [will suddenly perceive clearly what God teaches], as people on whom a light shines perceive things clearly [MET, DOU].
Àwọn ènìyàn tí ń gbé ni òkùnkùn tí ri ìmọ́lẹ̀ ńlá, àti àwọn tó ń gbé nínú ilẹ̀ òjijì ikú ni ìmọ́lẹ̀ tan fún.”
17 From that time, [while] Jesus was [in Capernaum city, he began to preach this to people: “God [MTY/EUP] will very soon begin to rule, and he will judge you when he rules]. So you [(pl)] need to turn from your sinful ways [so that God will not punish you].”
Láti ìgbà náà lọ ni Jesu ti bẹ̀rẹ̀ sí wàásù: “Ẹ ronúpìwàdà, nítorí tí ìjọba ọ̀run kù sí dẹ̀dẹ̀.”
18 [One day] while Jesus was walking by Galilee Lake, he saw two men, Simon, who was [later] called Peter, and Andrew, his [younger] brother. They were casting their [fishing] net into the lake because they [earned money by] catching [and selling] fish.
Bí Jesu ti ń rìn létí Òkun Galili, ó rí àwọn arákùnrin méjì, Simoni, ti à ń pè ní Peteru, àti Anderu arákùnrin rẹ̀. Wọ́n ń sọ àwọ̀n wọn sínú Òkun nítorí apẹja ni wọ́n.
19 He said to them, “[Just like you have been] gathering fish, come with me and I will teach you how to gather people [to become my disciples].” [MET]
Jesu wí fún wọn pé, “Ẹ wá, ẹ máa tọ̀ mí lẹ́yìn èmi yóò sì sọ yín di apẹja ènìyàn.”
20 They immediately left [the work that they were doing with] their [fishing] nets, and they went with him.
Lójúkan náà, wọ́n fi àwọ̀n wọn sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
21 As [the three of them] walked on from there, Jesus saw two other men, James, and John, the [younger] brother of James. [They were] in their boat with Zebedee, their father, mending their [fishing] nets. Jesus told them that [they should leave their work and] go with him.
Bí ó sì ti kúrò ní ibẹ̀, ò rí àwọn arákùnrin méjì mìíràn, Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu, arákùnrin rẹ̀. Wọ́n wà nínú ọkọ̀ ojú omi pẹ̀lú Sebede baba wọn, wọ́n ń di àwọ̀n wọn, Jesu sì pè àwọn náà pẹ̀lú.
22 They immediately left their fishing boat and their father, and they went with Jesus.
Lójúkan náà, wọ́n fi ọkọ̀ ojú omi àti baba wọn sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
23 Jesus went [with those four men] throughout all of Galilee [District]. He was teaching [the people] in the buildings where we Jews worship God. He was preaching the good message that tells how to become members of the group of people whose lives God rules over. He was also healing all [the Galileans] who had diseases or who were sick.
Jesu sì rin káàkiri gbogbo Galili, ó ń kọ́ni ní Sinagọgu, ó ń wàásù ìyìnrere ti ìjọba ọ̀run, ó sì ń ṣe ìwòsàn ààrùn gbogbo àti àìsàn láàrín gbogbo ènìyàn.
24 When people who lived in other parts of Syria [District] heard [PRS] what he was doing, they brought to him people who suffered from illnesses, people who suffered from many kinds of diseases, people who [suffered from] severe pains, people who were controlled by demons {whom demons controlled}, people who were epileptics, and people who were paralyzed. And Jesus healed them all.
Òkìkí rẹ̀ sì kàn yí gbogbo Siria ká; wọ́n sì gbé àwọn aláìsàn tí ó ní onírúurú ààrùn, àwọn tí ó ní ìnira ẹ̀mí èṣù, àti àwọn ti o ní wárápá àti àwọn tí ó ní ẹ̀gbà; ó sì wò wọ́n sàn.
25 Then crowds started to go with him. [They were people from] Galilee [District], (from the Decapolis/from the Ten Towns [area]), from Jerusalem [city], from other [parts of] Judea [district], and from areas east of the Jordan [River].
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn láti Galili, Dekapoli, Jerusalẹmu, Judea, àti láti òkè odò Jordani sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.

< Matthew 4 >