< Matthew 24 >

1 Jesus left the Temple [courtyard]. As he was walking along, [we] disciples came to him to ask him to note [how beautiful] the Temple buildings [were].
Bí Jesu ti ń kúrò ni tẹmpili, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n fẹ́ fi ẹwà tẹmpili náà hàn án.
2 He said to us, “These buildings that you are looking at [RHQ] [are wonderful, but] I want to tell you [something about them. They will soon be completely destroyed] {[Foreign invaders will completely destroy them]}. Every stone [in these buildings] will be thrown down {they will throw down every stone in these buildings}. Not one stone will be left {They will not leave one stone} on top of another stone.”
Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin kò ha rí gbogbo nǹkan wọ̀nyí? Lóòótọ́ ni mo wí fún yín gbogbo ilé yìí ni a yóò wó lulẹ̀, kò ní sí òkúta kan tí a ó fi sílẹ̀ lórí òmíràn, tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
3 [Later], as Jesus was sitting alone on [the slope of] Olive [Tree] Hill, [we] disciples went to him and asked him, “When will this happen [to the buildings of the Temple? Also, tell us what will happen to indicate that you are about to] come again, and [to indicate] that this world is ending?” (aiōn g165)
Bí ó ti jókòó ní orí òkè Olifi, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn tọ̀ ọ́ wá ní ìkọ̀kọ̀, wọ́n wí pé, “Sọ fún wa nígbà wo ni èyí yóò ṣẹlẹ̀? Kí ni yóò jẹ́ àmì ìpadà wá rẹ, àti ti òpin ayé?” (aiōn g165)
4 Jesus replied, “[All that I will say is], be sure that no one deceives you [about what will happen]
Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tàn yín jẹ.
5 Many [people] will come and say (that I sent them/that they have my authority) [MTY]. They will say, ‘I am the Messiah’, and they will deceive many [people].
Nítorí ọ̀pọ̀ yóò wá ní orúkọ mi tí wọn yóò máa pe ara wọn ní Kristi náà. Wọn yóò ṣi ọ̀pọ̀lọpọ̀ lọ́nà.
6 You will hear about wars [that are close] and wars that are far away, but do not let that trouble you. Keep in mind that [God has said that] those things must happen. But [when they happen], it will not mean that the end [of the world] has come!
Ẹ ó máa gbọ́ ìró ogun àti ìdágìrì ogun, kí ẹ̀yin má ṣe jáyà nítorí nǹkan wọ̀nyí kò lè ṣe kí ó ma ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin kì í ṣe àkókò náà.
7 [Groups in various] countries will fight each other, and [various] governments [will also fight] against each other. There will be famines and earthquakes in various places.
Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba. Ìyàn àti ilẹ̀ mímì yóò wà ní ibi púpọ̀.
8 These things will happen first. Then there will be other things that [will happen before I return. What will happen will be like the first pains] of childbirth MET].
Ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan wọ̀nyí sì jẹ́ ìbẹ̀rẹ̀ ìpọ́njú tí ó ń bọ̀.
9 At that time [people who oppose you] will take you to [the authorities, who] will mistreat you and kill you. You will be hated by [people who live in] all nations [PRS] {[People who live in] all nations [PRS] will hate you} because [you believe in me][MTY].
“Nígbà náà ni a ó sì dá a yín lóró. A ó pa yín, a ó sì kórìíra yín ni gbogbo orílẹ̀-èdè, nítorí pé ẹ̀yin jẹ́ tèmi.
10 Also, many [people] will stop believing [in me because of the way they will suffer]. They will betray each other and will hate each other.
Àti pé, ọ̀pọ̀ nínú yín yóò kọsẹ̀, ẹ̀yin yóò ṣòfófó ara yín, ẹ̀yin yóò kórìíra ara yín pẹ̀lú,
11 Many will come saying that they are prophets, but they will be lying, and they will deceive many people.
ọ̀pọ̀ àwọn èké wòlíì yóò farahàn, wọn yóò tan ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn jẹ.
12 Because there will be more and more [people] who will disobey [God’s] laws [PRS], many [people] will no longer [MET] love [their fellow believers] [PRS].
Ẹ̀ṣẹ̀ yóò wà níbi gbogbo, yóò sì sọ ìfẹ́ ọ̀pọ̀ di tútù,
13 But [all] those who keep on [believing in me] to the end [of their lives] will be saved.
ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá forítì í dópin ni a ó gbàlà.
14 Furthermore, the good message about my ruling over people’s lives will be preached in every part of the world, in order that people of all ethnic groups may hear it. Then the end [of the world] will come.”
A ó sì wàásù ìyìnrere nípa ìjọba náà yìí ní gbogbo ayé ká, láti ṣe ẹ̀rí fún gbogbo orílẹ̀-èdè, nígbà náà ni òpin yóò dé.
15 “[But before the world ends], the disgusting person who will defile [the] holy [Temple and cause people to abandon it will stand in the Temple. Daniel the prophet spoke and wrote] about that [long ago]. May everyone who reads [this] pay attention [to the following warning from me: ]
“Nítorí náà, nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìríra ‘ìsọdahoro, tí a ti ẹnu wòlíì Daniẹli sọ,’ tí ó bá dúró ní ibi mímọ́ (ẹnikẹ́ni tí ó bá kà á kí ó yé e),
16 When you see that happen [in the Temple, those of you] who are in Judea [district] must flee to the [higher] hills!
nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ni Judea sálọ sí orí òkè.
17 Those who are outside their houses must not go back into their houses to get things [before they flee].
Kí ẹni tí ó wà lórí ilé rẹ̀ má ṣe sọ̀kalẹ̀ wá mú ohunkóhun jáde nínú ilé rẹ̀.
18 Those who are [working] in a field should not turn back to get their outer clothing [before they flee].
Kí àwọn tí ó sì wà lóko má ṣe darí wá sí ilé láti mú àwọn aṣọ wọn.
19 I [feel] very sorry for women who will be pregnant and women who will be nursing [their babies] in those days, [because it will be very difficult for them to run away]
Ṣùgbọ́n àánú ṣe mí fún àwọn obìnrin ti ó lóyún, àti fún àwọn tí ó ń fún ọmọ loyan ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì!
20 Pray that you will not have to flee (in the winter/in the rainy season) [when it will be hard to travel]. [People who think that God never allows anyone to do any work on] our day of rest [will not help you as you flee, so] pray also that you will not have to flee on such a day,
Ẹ sì máa gbàdúrà kí sísá yín má ṣe jẹ́ ìgbà òtútù, tàbí ọjọ́ ìsinmi.
21 because people will suffer very severely [when those things happen]. People have never suffered that severely since [God] created the world until now, and no one will ever [suffer like that again].
Nítorí ìpọ́njú ńlá yóò wà, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ láti ìgbà ìbẹ̀rẹ̀ ọjọ́ ayé wá títí di ìsinsin yìí irú rẹ̀ kì yóò sì ṣí.
22 If [God had not decided to] shorten that time [MTY] [when people will suffer so much], everyone [LIT] would die. But [he has decided to] shorten it because [he is concerned] about [the people] whom [he] has chosen.”
“Lóòótọ́, àfi bí a ké ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì kúrú, gbogbo ẹ̀dá alààyè yóò ṣègbé. Ṣùgbọ́n nítorí ti àwọn àyànfẹ́ ni a ó fi ké ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì kúrú.
23 “[At that time] people will appear [who will] falsely [say that they are] the Messiah or [that they are] prophets. They will perform many kinds (of miracles/of things that ordinary people cannot do), in order to deceive people. They will even try [to see] if [it is] possible to deceive [you people whom God has] chosen. So, at that time, if someone says to you, ‘Look, here [is] the Messiah!’ or [if someone says], ‘Over there is the Messiah!’ do not believe it!
Nígbà náà, bí ẹnikẹ́ni bá sọ fún yín pé, ‘Wo Kristi náà,’ tàbí pé ó ti farahàn níhìn-ín tàbí lọ́hùn ún, ẹ má ṣe gbà á gbọ́.
Nítorí àwọn èké Kristi àti àwọn èké wòlíì yóò dìde. Wọn yóò sì ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ àmì àti ìyanu. Bí ó bá lè ṣe é ṣe wọn yóò tan àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run pàápàá jẹ.
25 Do not forget [that] I have warned you about all this before [it happens].
Wò ó, mo ti kìlọ̀ fún yín tẹ́lẹ̀.
26 So if someone says to you, ‘Look, [the Messiah] is in the desolate area!’ do not go there. [Likewise, if someone says to you], ‘Look, he is in a secret room!’ do not believe [that person],
“Nítorí náà, bí ẹnìkan bá sọ fún yín pé, ‘Olùgbàlà ti dé,’ àti pé, ‘Ó wà ní aginjù,’ ẹ má ṣe wàhálà láti lọ wò ó, tàbí tí wọ́n bá ní, ó ń fi ara pamọ́ sí iyàrá,” ẹ má ṣe gbà wọn gbọ́.
27 because just like lightning flashes from the east to the west [and people everywhere can] see it [SIM], when [I], the one who came from heaven, return again, [everyone will see me].
Nítorí bí mọ̀nàmọ́ná ti ń tàn láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀-oòrùn, bẹ́ẹ̀ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn yóò jẹ́.
28 [When I return, it will be as obvious to everyone as the fact that] wherever you see vultures gathering, you know that there will be an animal carcass [MET] there. (OR, Just like the vultures gather together wherever there is an animal carcass, God will punish sinful people wherever they are.)”
Nítorí ibikíbi tí òkú bá gbé wà, ibẹ̀ ni àwọn ẹyẹ igún ń kójọpọ̀ sí.
29 “Immediately after many people have suffered during those days, [the universe will become dark]. The sun will become dark. The moon will not shine. The stars will fall from the sky. And the powerful [objects] in the sky will be shaken. (OR, And the spiritual beings in space will be deposed.)
“Lójúkan náà, lẹ́yìn ìpọ́njú ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, “‘ni oòrùn yóò ṣókùnkùn, òṣùpá kì yóò sì fi ìmọ́lẹ̀ rẹ hàn; àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò já sílẹ̀, agbára ojú ọ̀run ni a ó mì tìtì.’
30 After that, something [will be seen] {[people will observe something]} in the sky that indicates that [I], the one who came from heaven, [am returning to the earth]. Then [unbelieving people from] all ethnic groups of the earth will [mourn because they will be afraid] of [God punishing them]. They will see [me], the one who came from heaven, coming on the clouds with power and great glory [as I return to the earth].
“Nígbà náà ni àmì Ọmọ Ènìyàn yóò sì fi ara hàn ní ọ̀run, nígbà náà ni gbogbo ẹ̀yà ayé yóò káàánú, wọn yóò sì rí Ọmọ Ènìyàn tí yóò máa ti ojú ọ̀run bọ̀ ti òun ti ògo àti agbára ńlá.
31 I will send my angels [to the earth] from everywhere in the heavens. [They will be] blowing trumpets loudly. [Then] from throughout the whole earth [DOU] they will gather the people whom I have chosen.”
Yóò sì rán àwọn angẹli rẹ̀ jáde pẹ̀lú ohùn ìpè ńlá, wọn yóò sì kó gbogbo àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ láti orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé àti ọ̀run jọ.
32 “[Now] I [want you to] learn something [from] this parable about [how] fig trees [grow]. [In this area], when the buds [of a fig tree] become tender and its leaves begin to sprout, you know that summer is near.
“Nísinsin yìí, ẹ kọ́ òwe lára igi ọ̀pọ̀tọ́. Nígbà tí ẹ̀ka rẹ̀ bá ti ń yọ tuntun tí ó bá sì ń ru ewé, ẹ̀yin mọ̀ pé ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn súnmọ́ tòsí.
33 Similarly, when you see all these things that I [have just described happening], you will know that [the time for me to return] is very close [MET].
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí i tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ń ṣẹlẹ̀, kí ẹ mọ̀ pé ìpadàbọ̀ mi dé tán lẹ́yìn ìlẹ̀kùn.
34 Keep this in mind: All of these events will happen before all the people who have observed the things that I have done have died.
Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ìran yìí kì yóò kọjá títí tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ.
35 [You can be certain that these] things that I have told [you] about will happen. You can be more certain of that than you can be certain that the earth and sky [LIT] will continue to exist.”
Ọ̀run àti ayé yóò rékọjá, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi kì yóò rékọjá.
36 “But neither I, nor any other person, nor any angel in heaven, knows either the day or the hour [when the things that I have told you about will happen]. Only [God, my] Father, [knows].
“Ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan ti ó mọ ọjọ́ àti wákàtí tí òpin náà yóò dé, àwọn angẹli ọ̀run pàápàá kò mọ̀ ọ́n. Àní, ọmọ kò mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe Baba mi nìkan ṣoṣo ló mọ̀ ọ́n.
37 It will be like what happened when Noah lived. Until the flood came, [the people] did not know that [anything bad would happen] to them. Before the flood waters covered the earth, [the people] were eating and drinking [as usual]. Some men were marrying women and [some parents] were giving their daughters to men to marry them. They were doing all this until the day that Noah [and his family] entered the big boat. And then the flood came and drowned all [those who were not in the boat]. Similarly, [the unbelieving people will not know] when [I, the one who came from heaven], will return, [and they will not] be [expecting me].
Bí ó ṣe rí ní ìgbà ayé Noa, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn yóò sì rí.
Nítorí bí àwọn ọjọ́ náà ti wà ṣáájú ìkún omi, tí wọ́n ń jẹ́ tí wọ́n ń mu, tí wọ́n ń gbéyàwó, tí wọ́n sì ń fa ìyàwó fún ni, títí tí ó fi di ọjọ́ tí Noa fi bọ́ sínú ọkọ̀.
Ènìyàn kò gbàgbọ́ nípa ohun tí o ṣẹlẹ̀ títí tí ìkún omi fi dé nítòótọ́, tí ó sì kó wọn lọ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn.
40 When I [return], I [will not take all people up to heaven. I will take only those who trust in me. For example], two [people] will be in the fields. One of them will be taken {[I] will take one of them} up [to heaven] and the other [person] will be left {and I will leave the other [person]} [here to be punished].
Àwọn ọkùnrin méjì yóò máa ṣiṣẹ́ nínú oko, a o mú ẹnìkan, a ó sì fi ẹni kejì sílẹ̀.
41 [Similarly], two [women] will be at the mill grinding grain. One of them will be taken up [to heaven] and the other will be left.
Àwọn obìnrin méjì yóò jùmọ̀ máa lọ ọlọ pọ̀, a yóò mú ọ̀kan, a ó fi ẹni kejì sílẹ̀.
42 So, because you do not know what day [I], your Lord, will return [to the earth], you need to be ready [for me to return at any time].
“Nítorí náà, ẹ múra sílẹ̀, nítorí ẹ kò mọ ọjọ́ tí Olúwa yín yóò dé.
43 You know that if the owners of a house knew at what time in the night thieves would come, they would be awake and prevent the thieves from breaking into their houses. Similarly, I [will come just like unexpectedly as a thief].
Ṣùgbọ́n, kí ẹ mọ èyí pé, baálé ilé ìbá mọ wákàtí náà tí olè yóò wá, ìbá máa ṣọ́nà, òun kì bá ti jẹ́ kí a já wọ ilé rẹ̀.
44 So you need to be ready [for my return], because [I], the one who came from heaven, will return [to the earth] at a time when you do not expect [me to come].”
Nítorí náà, ẹ gbọdọ̀ wà ní ìmúrasílẹ̀, nítorí ní wákàtí àìròtẹ́lẹ̀ ni dídé Ọmọ Ènìyàn yóò jẹ́.
45 “Think about what every faithful and wise servant is like [RHQ]. The house owner appoints one servant to supervise the other servants. He tells him to give them food at the proper times. [Then he leaves on a long trip].
“Ǹjẹ́ olóòtítọ́ àti ọlọ́gbọ́n ọmọ ọ̀dọ̀ wo ni olúwa rẹ̀ lè fi ṣe olùbojútó ilé rẹ̀ láti bọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ lójoojúmọ́?
46 If that servant is doing that [work] when the house owner returns, [the house owner] will be very pleased with him.
Alábùkún fún ni ọmọ ọ̀dọ̀ ti olúwa rẹ̀ dé tí ó sì bá a lórí iṣẹ́ ṣíṣe.
47 Think about this: The house owner will appoint [that one servant] to be the supervisor of all his possessions.
Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, èmi yóò sì fi irú ẹni bẹ́ẹ̀ ṣe alákòóso gbogbo ohun tí mo ní.
48 But a wicked servant might say to himself, ‘The owner [has been away] for a long time, [so he probably] will not return soon [and find out what I am doing.’]
Ṣùgbọ́n bí ọmọ ọ̀dọ̀ náà bá jẹ́ ènìyàn búburú náà bá wí ní ọkàn rẹ̀ pé, ‘Olúwa mi kì yóò tètè dé.’
49 [So he] will begin to beat the other servants and eat and get drunk.
Tí ó sì bẹ̀rẹ̀ si í fi ìyà jẹ́ àwọn ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, tí ó ń jẹ, tí ó sì ń mu àmupara.
50 [Then] the house owner will come back at a time when the servant does not expect him [DOU].
Nígbà náà ni olúwa ọmọ ọ̀dọ̀ yóò wá ní ọjọ́ àti wákàtí tí kò retí.
51 He will punish that servant severely [HYP], (OR, cut that servant into two pieces) and he will put him where (the hypocrites/the ones who only pretended to be good) are put. In that place the people cry and grind their teeth [because they suffer very much].”
Yóò sì jẹ ẹ́ ní ìyà gidigidi, yóò sì rán an sí ibùgbé àwọn àgàbàgebè, níbẹ̀ ni ẹkún àti ìpayínkeke yóò wà.

< Matthew 24 >

The World is Destroyed by Water
The World is Destroyed by Water