< Matthew 2 >

1 Jesus was born in Bethlehem [town] in Judea [province] during the time [MTY] that King Herod [the Great ruled there. Some time] after Jesus was born, some men who studied the stars and who lived in a [country] east [of Judea] came to Jerusalem.
Lẹ́yìn ìgbà tí a bí Jesu ní Bẹtilẹhẹmu ti Judea, ni àkókò ọba Herodu, àwọn amòye ti ìlà-oòrùn wá sí Jerusalẹmu.
2 They asked [people], “Where is the one who has been born [in order that he might be] the king of [you] Jews? [We believe that your new king] has been born, because we have seen the star [that we believe indicated that] he has been [born]. [We saw it while we were in our country] east [of here]. So we have come to worship him.”
Wọ́n si béèrè pé, “Níbo ni ẹni náà tí a bí tí í ṣe ọba àwọn Júù wà? Àwa ti rí ìràwọ̀ rẹ̀ ní ìlà-oòrùn, a sì wá láti foríbalẹ̀ fún un.”
3 When King Herod heard [what those men were asking], he became worried [that someone else might be proclaimed] {[people might proclaim someone else]} [king of the Jews to replace him]. Many [of the people] of Jerusalem [MTY, HYP] [also] became worried [because they were afraid of what King Herod might do].
Nígbà tí ọba Herodu sì gbọ́ èyí, ìdààmú bá a àti gbogbo àwọn ara Jerusalẹmu pẹ̀lú rẹ̀.
4 Then Herod gathered together all the ruling priests and men who taught the people the [Jewish] laws and he asked them where [the prophets had predicted that] the Messiah was to be born.
Nígbà tí ó sì pe àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin jọ, ó bi wọ́n léèrè níbi ti a ó gbé bí Kristi?
5 They said to him, “[He will be born] in Bethlehem, [here] in Judea [province], because it was written by the prophet [Micah] {the prophet [Micah] wrote} [long ago what God said]:
Wọ́n sì wí pé, “Ní Bẹtilẹhẹmu ti Judea, èyí ni ohun tí wòlíì ti kọ ìwé rẹ̀ pé,
6 ‘You [who live in] Bethlehem [APO], in Judea [province], your town is certainly very important [LIT], because a man from your [town] will become a ruler. He will guide my people [who live in] Israel.’”
“‘Ṣùgbọ́n ìwọ Bẹtilẹhẹmu, ní ilẹ̀ Judea, ìwọ kò kéré jù láàrín àwọn ọmọ-aládé Juda; nítorí láti inú rẹ ni Baálẹ̀ kan yóò ti jáde, ẹni ti yóò ṣe ìtọ́jú Israẹli, àwọn ènìyàn mi.’”
7 Then [King] Herod secretly summoned those men who studied the stars. He asked them exactly when the star [first] appeared. [By what they told him, he was able to know the approximate age of the baby].
Nígbà náà ni Herodu ọba pe àwọn amòye náà sí ìkọ̀kọ̀, ó sì wádìí ni ọwọ́ wọn, àkókò náà gan an tí wọ́n kọ́kọ́ rí ìràwọ̀.
8 Then he [concealed what he really planned to do and] said to them, “Go to Bethlehem and inquire thoroughly [where] the infant is. When you have found him, [come back and] report to me so that I, myself, can go [there and] worship him, too.”
Ó sì rán wọn lọ sí Bẹtilẹhẹmu, ó sì wí pé, “Ẹ lọ ṣe ìwádìí fínní fínní ní ti ọmọ náà tí a bí. Lẹ́yìn tí ẹ bá sì rí i, ẹ padà wá sọ fún mi, kí èmi náà le lọ foríbalẹ̀ fún un.”
9 After the men heard what the king [told them], they went [toward Bethlehem]. To their surprise, the star that they had seen while they were in the eastern [country] went ahead of them [again] until it stood above [the house] where the child was.
Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ọba, wọ́n mú ọ̀nà wọn pọ̀n, sì wò ó, ìràwọ̀ tí wọ́n ti rí láti ìhà ìlà-oòrùn wá, ó ṣáájú wọn, títí tí ó fi dúró lókè ibi tí ọmọ náà gbé wà.
10 When they saw the star, they rejoiced greatly [and followed it].
Nígbà tí wọ́n sì rí ìràwọ̀ náà, ayọ̀ kún ọkàn wọn.
11 They [found] the house and entered it and saw the child and his mother, Mary. They bowed down and worshipped him. Then they opened their treasure [boxes] [MTY] and they gave gold, [costly] frankincense, and myrrh to him.
Bí wọ́n tí wọ inú ilé náà, wọn rí ọmọ ọwọ́ náà pẹ̀lú Maria ìyá rẹ̀, wọ́n wólẹ̀, wọ́n foríbalẹ̀ fún un. Nígbà náà ni wọ́n tú ìṣúra wọn, wọ́n sì ta Jesu lọ́rẹ: wúrà, tùràrí àti òjìá.
12 [Because] God [knew that King Herod planned to kill Jesus], in a dream the men who studied the stars were warned {he warned the men who studied the stars} that they should not return to [King] Herod. So they returned to their country, [but instead of traveling back on the same road, they] went on a different road.
Nítorí pé Ọlọ́run ti kìlọ̀ fún wọn ní ojú àlá pé kí wọ́n má ṣe padà tọ Herodu lọ mọ́, wọ́n gba ọ̀nà mìíràn lọ sí ìlú wọn.
13 After the men who studied the stars left [Bethlehem], an angel [from] the Lord appeared to Joseph in a dream. He said, “Get up, take the child and his mother, and flee to Egypt. Stay there until I tell you [(sg) that you should leave], because [King] Herod is about [to send soldiers] to look for the child so that they can kill him.”
Nígbà tí wọn ti lọ, angẹli Olúwa fi ara hàn Josẹfu ní ojú àlá pé, “Dìde, gbé ọmọ ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀, kí ó sì sálọ sí Ejibiti. Dúró níbẹ̀ títí tí èmi yóò fi sọ fún ọ, nítorí Herodu yóò wá ọ̀nà láti pa ọmọ ọwọ́ náà.”
14 So Joseph got up, he took the child and his mother [that] night, and they fled to Egypt.
Nígbà náà ni ó sì dìde, ó mú ọmọ ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀ ní òru, ó sì lọ sí Ejibiti,
15 They stayed there until [King] Herod died, [and then they left Egypt]. By doing that, it was {they} fulfilled what the prophet [Hosea] wrote, which had been said by the Lord {which the Lord had said}, I have told my son to come out of Egypt.
ó sì wà níbẹ̀ títí tí Herodu fi kú. Èyí jẹ́ ìmúṣẹ àsọtẹ́lẹ̀ ohun tí Olúwa sọ láti ẹnu wòlíì pé, “Mo pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.”
16 [While King] Herod [was still living], because he realized that he had been tricked by the men who studied the stars {the men who studied the stars had tricked him}, he became furious. Then, [assuming that Jesus was still in Bethlehem or the surrounding regions], Herod sent [soldiers there] to kill all the boy babies two years old and younger. [Herod calculated how old the baby was], according to what the men who studied the stars told him [about when the star first appeared].
Nígbà tí Herodu rí í pé àwọn amòye náà ti tan òun jẹ, ó bínú gidigidi, ó sì pàṣẹ kí a pa gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí ó wà ní Bẹtilẹhẹmu àti ní ẹkùn rẹ̀ láti àwọn ọmọ ọdún méjì sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àkókò tí ó ti fi ẹ̀sọ̀ ẹ̀sọ̀ béèrè lọ́wọ́ àwọn amòye náà.
17 [Because Bethlehem and Ramah towns were in the area where the descendants of Jacob’s wife Rachel lived, when soldiers killed the infant boys], they fulfilled what Jeremiah the prophet wrote,
Nígbà náà ni èyí tí a ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu wòlíì Jeremiah wá ṣẹ pé:
18 [Women] in Ramah were weeping and wailing loudly. [Women who were the descendants] of Rachel, [the ancestor of the women there] [SYN], were grieving for [what happened to] their children. [Even though people tried to comfort them], they would not be comforted {stop mourning}, because their children were dead.
“A gbọ́ ohùn kan ní Rama, ohùn réré ẹkún àti ọ̀fọ̀ ńlá, Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀. Ó kọ̀ láti gbìpẹ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
19 After Herod died [and while Joseph and his family were still in Egypt], an angel that the Lord [had sent] appeared to Joseph in Egypt in a dream.
Lẹ́yìn ikú Herodu, angẹli Olúwa fi ara hàn Josẹfu lójú àlá ní Ejibiti
20 He said to Joseph, “Take the child and his mother and go back to Israel [to live], because the people who were looking for the child [in order to kill him] have died.”
Ó sì wí fún un pé, “Dìde gbé ọmọ ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀ padà sí ilẹ̀ Israẹli, nítorí àwọn tí ń wá ẹ̀mí ọmọ ọwọ́ náà láti pa ti kú.”
21 So Joseph took the child and his mother, and they went back to Israel.
Nítorí náà, o sì dìde, ó gbé ọmọ ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀ ó sì wá sí ilẹ̀ Israẹli.
22 When Joseph heard that Archaelaus now ruled in Judea [district] instead of his father, [King] Herod [the Great], he was afraid to go there. Because he was warned {[God] warned Joseph} in a dream [that it was still dangerous for them to live in Judea], he [and Mary and Jesus] went to Galilee [District]
Ṣùgbọ́n nígbà tí ó gbọ́ pé Akelausi ni ó ń jẹ ọba ní Judea ní ipò Herodu baba rẹ̀, ó bẹ̀rù láti lọ sí ì bẹ̀. Nítorí tí Ọlọ́run ti kìlọ̀ fún un ní ojú àlá, ó yí padà, ó sì gba ẹkùn Galili lọ,
23 to Nazareth [to live there]. The result was that what had been said by the ancient prophets {what the ancient prophets had said} [about the Messiah], that he would be called {people would call him} a Nazareth-man, was fulfilled {came true}.
ó sì lọ í gbé ní ìlú tí a pè ní Nasareti. Nígbà náà ni èyí tí a sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì wá sí ìmúṣẹ: “A ó pè é ní ará Nasareti.”

< Matthew 2 >