< Matthew 12 >

1 During that period of time, on a (Sabbath/Jewish day of rest), Jesus [and we] disciples were walking through some grain fields. And because we were hungry, we began to pick some of the heads of grain and eat them. [The laws of Moses permitted people to do that if they were hungry].
Ní àkókò náà ni Jesu ń la àárín oko ọkà kan lọ ní ọjọ́ ìsinmi, ebi sì ń pa àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀. Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí i ya orí ọkà, wọ́n sì ń jẹ ẹ́.
2 Some Pharisees saw us [do what they considered to be work]. So they said to Jesus, [accusing him], “Look! Your disciples are doing [work] that is not permitted [in our] laws [PRS] [for us] to do on our day of rest!”
Nígbà tí àwọn Farisi rí èyí. Wọ́n wí fún pé, “Wò ó! Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ ń ṣe ohun tí kò bá òfin mu ní ọjọ́ ìsinmi.”
3 [Jesus wanted to show them that the record in the Scriptures indicated that God permitted people to disobey certain religious laws when they needed food]. [So] he said to them, “[It is written] {[Someone wrote]} [in the Scriptures] [RHQ] what [our revered ancestor King] David did when he and the men with him were hungry. You have read about that, ([but you do not think about what it implies!/so why do you not think about what it implies]?) [RHQ]
Jesu dáhùn pé, “Ẹ̀yin kò ha ka ohun tí Dafidi ṣe nígbà tí ebi ń pa á àti àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀.
4 David entered the big tent [where they worshipped] God [and asked for some food. The high priest gave him] the bread that had been {they had} presented [to God]. According to the laws [of Moses], only priests were permitted to eat that bread, but David and the men who were with him ate it. And [God did not consider that what they did was wrong]
Ó wọ inú ilé Ọlọ́run, òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀ jẹ àkàrà tí a yà sọ́tọ̀, èyí tí kò yẹ fún wọn láti jẹ, bí kò ṣe fún àwọn àlùfáà nìkan.
5 Also, think about the laws that [Moses wrote] [RHQ]. He said that [even though] the priests, [by working] in the Temple on our Jewish day of rest, are not obeying the Jewish day of rest [laws], they are not guilty. You have surely read that, [but you do not understand what it means].
Tàbí ẹ̀yin kò ti kà á nínú òfin pé ní ọjọ́ ìsinmi, àwọn àlùfáà tí ó wà ní tẹmpili ń ba ọjọ́ ìsinmi jẹ́ tí wọ́n sì wà láìjẹ̀bi.
6 Note this: [God allows men to work in] the Temple [on our rest day because that work must be done. But in addition, I] tell you that [I have] more [authority than the authority of] the Temple. So, it is more important for you to obey my teachings than to obey your traditions about our rest day.
Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, ẹni tí ó pọ̀ ju tẹmpili lọ wà níhìn-ín.
7 [You should think about] these words [of God in the Scriptures]: ‘I want you to [act] mercifully toward people, and not [just] offer sacrifices.’ If you understood what that means, you would not condemn [my disciples], who have done no wrong.
Bí ó bá jẹ́ pé ẹ mọ ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ yìí, ‘Àánú ni èmi ń fẹ́ kì í ṣe ẹbọ,’ ẹ̀yin kì bá tí dá aláìlẹ́ṣẹ̀ lẹ́bi.
8 [And I want you to know that] I, the one who came from heaven, have [the] authority [to determine what is right for my disciples to do on] the days of rest.”
Nítorí pé Ọmọ Ènìyàn jẹ́ Olúwa ọjọ́ ìsinmi.”
9 After Jesus left there [that day], he went into a building where we Jews worship God.
Nígbà tí Jesu kúrò níbẹ̀ ó lọ sí Sinagọgu wọn,
10 [He saw] a man with a shriveled hand there. [The Pharisees thought that Jesus would be disobeying the tradition about not working on the day of rest if he healed the man, so one of] them asked him, “Does [God] permit [us] to heal [people] on our day of rest?” [They asked that question] so that they might accuse him [if he healed someone] (on the Sabbath/on the Jewish rest day).
ọkùnrin kan tí ọwọ́ rẹ̀ kan rọ wà níbẹ̀. Wọ́n ń wá ọ̀nà láti fi ẹ̀sùn kan Jesu, wọ́n béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ ó tọ́ láti mú ènìyàn láradá ní ọjọ́ ìsinmi?”
11 He replied to them, “Would anyone among you who has [only] one sheep that falls into a hole (on the Sabbath/on the Jewish rest day) [just leave it there] [RHQ]? [Certainly not]! You would take hold of it and lift it out right away, [and that would be acceptable work on our day of rest, too]
Ó dá wọn lóhùn pé, “Bí ó bá jẹ́ wí pé bí ẹnikẹ́ni nínú yín bá ní àgùntàn kan ṣoṣo, tí ó sì bọ́ sínú kòtò ní ọjọ́ ìsinmi, ǹjẹ́ kì yóò dìímú, kí ó sì fà á jáde.
12 [Because] sheep are valuable, [their owners may work on our day of rest in order to rescue them. So, because] people are more valuable than sheep, it is certainly right for us to do something good [by healing another person any day, including] our day of rest!”
Ǹjẹ́ mélòó mélòó ní ènìyàn ní iye lórí ju àgùntàn kan lọ! Nítorí náà ó yẹ láti ṣe rere ní ọjọ́ ìsinmi.”
13 Then he said to the man, “Stretch out your [withered] hand!” The man stretched it out, and it became normal like the other hand!
Nígbà náà, ó sì wí fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ,” bí òun sì ti nà án, ọwọ́ rẹ̀ sì bọ̀ sí ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ èkejì.
14 Then the Pharisees left [the meeting house. They were worried that the people would reject their traditions and would accept Jesus’ teaching instead. So] they met together to plan how they could kill him.
Síbẹ̀ àwọn Farisi jáde lọ pe ìpàdé láti dìtẹ̀ mú un àti bí wọn yóò ṣe pa Jesu.
15 Because Jesus knew [that the Pharisees were plotting to kill him], he [took us disciples and] went away from there. Crowds, [including many sick people], followed him, [wanting him to heal them], and he healed them all.
Nígbà tí Jesu sì mọ̀, ó yẹra kúrò níbẹ̀. Ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì mú gbogbo àwọn aláìsàn láradá.
16 But he told them firmly that they should not tell [other people yet] who he was.
Ṣùgbọ́n ó kìlọ̀ fún wọn pé kí wọ́n kí ó má ṣe fi òun hàn.
17 [By acting humbly like that] he fulfilled what was written by Isaiah the prophet {what Isaiah the prophet wrote} [long ago about the Messiah]. [Isaiah wrote] that God said:
Èyí jẹ́ ìmúṣẹ àsọtẹ́lẹ̀ èyí tí wòlíì Isaiah sọ nípa rẹ̀ pé,
18 Take note of my servant whom I have chosen, the one whom I love and with whom I am pleased. I will put my Spirit in him, and he will proclaim that [God] will judge the non-Jews justly.
“Ẹ wo ìránṣẹ́ mi ẹni tí mo yàn. Àyànfẹ́ mi ni ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi; èmi yóò fi ẹ̀mí mi fún un. Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ àwọn kèfèrí.
19 He will not quarrel [with people], neither will he shout. He will not [teach with] a loud voice in the [main] streets.
Òun kì yóò jà, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò kígbe; ẹnikẹ́ni kì yóò gbọ́ ohùn rẹ ní ìgboro.
20 Until he has justly judged [the people who trust in him and] has declared them not guilty, he will not destroy [anyone who is weak like] a smashed stalk [MET], nor will he silence [anyone who is as helpless as] a smoldering [linen] wick [MET, DOU].
Koríko odò títẹ̀ kan ni òun kì yóò fọ́, àti òwú-fìtílà tí ń jó tan an lọ lòun kì yóò fẹ́ pa. Títí yóò fi mú ìdájọ́ dé ìṣẹ́gun.
21 As a result, the non-Jews will confidently expect [that he will do great things for them].
Ní orúkọ rẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò fi ìrètí wọn sí.”
22 One day when Jesus was at home, [some men] brought to [Jesus] a man [who, because of being] controlled by a demon {a demon controlled him}, was blind and unable to speak. [Jesus] healed him [by expelling the demon]. As a result, the man [began to] talk and [was able to] see.
Nígbà náà ni wọ́n mú ọkùnrin kan tó ni ẹ̀mí èṣù tọ̀ ọ́ wá, tí ó afọ́jú, tí ó tún ya odi. Jesu sì mú un láradá kí ó le sọ̀rọ̀, ó sì ríran.
23 All the crowd [who saw it] marveled. They began asking [each other], “Could this man be the [Messiah, the] descendant of [King] David, [whom we have been expecting]?”
Ẹnu sì ya gbogbo àwọn ènìyàn. Wọ́n wí pé, “Èyí ha lè jẹ́ Ọmọ Dafidi bí?”
24 Because the Pharisees [and the men who taught the Jewish laws] heard [that the people thought that Jesus might be the Messiah because he had expelled the demon], they said, “[It is not God, but] Beelzebub, the ruler of the demons, who enables [this man] to expel demons [from people!]”
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Farisi gbọ́ èyí, wọ́n wí pé, “Nípa Beelsebulu nìkan, tí í ṣe ọba ẹ̀mí èṣù ni ọkùnrin yìí fi lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde.”
25 But Jesus knew what [the Pharisees] were thinking [and saying]. So, [in order to show them that what they said did not make sense], he said to them, “If [the people in] [MTY] one nation fight against each other, [they] will destroy their nation {their nation will be destroyed}. If [people who live in] the same city or house fight each other, they will certainly not remain [as one group or family].
Jesu tí ó mọ èrò wọn, ó wí fún wọn pé, “Ìjọbakíjọba tí ó bá yapa sí ara rẹ̀ yóò parun, ìlúkílùú tàbí ilékílé tí ó bá yapa sí ara rẹ̀ kì yóò dúró.
26 [Similarly], if Satan were expelling his own [demons] [MTY], [it would be as though] he was fighting against himself. (His kingdom would not continue!/How could his kingdom continue?) [RHQ] His rule over them would [certainly] not last!
Bí èṣù bá sì ń lé èṣù jáde, a jẹ́ wí pé, ó ń yapa sí ara rẹ̀. Ìjọba rẹ yóò ha ṣe le dúró?
27 Furthermore, if [it is true that] Satan enables me to expel demons, is it also true that your disciples [who] expel demons [do so] by [Satan’s] power [RHQ]? [No] So they will show you that you [are not thinking logically].
Àti pé, bi èmi bá ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde nípa Beelsebulu, nípa ta ni àwọn ènìyàn yín fi ń lé wọn jáde? Nítorí náà ni wọn yóò ṣe má ṣe ìdájọ́ yín.
28 But because it is God’s Spirit who [enables] me to expel demons, [that proves that the power of] God to rule [people’s lives] has come to you.
Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé nípa Ẹ̀mí Ọlọ́run ni èmi fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, a jẹ́ pé ìjọba Ọlọ́run ti dé bá yín.
29 [I will illustrate why I am able to expel demons]. (A person cannot go into the house of a strong man) [RHQ] [But if he ties up the strong man], then he will be able to steal [the things in that man’s] house.
“Tàbí, báwo ni ẹnikẹ́ni ṣe lè wọ ilé alágbára lọ kí ó sì kó ẹrù rẹ̀, bí kò ṣe pé ó kọ́kọ́ di alágbára náà? Nígbà náà ni ó tó lè kó ẹrù rẹ̀ lọ.
30 [No one can be neutral]. Those who do not acknowledge [that the Holy Spirit enables] me [to expel demons] are opposing me, and those who do not gather [people to become] my [disciples] are causing [those people] to [DOU] go away [from me].
“Ẹni tí kò bá wà pẹ̀lú mi, òun lòdì sí mi, ẹni tí kò bá mi kójọpọ̀ ń fọ́nká.
31 You [are saying that it is not the Holy Spirit who is enabling me to expel demons]. So I will say this to you: [If] those who offend and slander other people in any way are [then sorry and ask God to forgive them, God] will forgive them. But people who discredit what the Holy Spirit does will not be forgiven {[God] will not forgive [people] who discredit what the Holy Spirit does}.
Nítorí èyí, mo wí fún yín, gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àti ọ̀rọ̀-òdì ni a yóò dárí rẹ̀ jí ènìyàn, ṣùgbọ́n ìsọ̀rọ̀-òdì sí Ẹ̀mí Mímọ́ kò ní ìdáríjì.
32 [God is willing to] forgive people who criticize [me], the One who came from heaven. But I [warn you that] those who say evil things about what the Holy Spirit [does] will not be forgiven {[God] will not forgive people who speak evil words about what the Holy Spirit [does]}. They will not be forgiven {[He] will not forgive them} now, and they will never be forgiven {[he] will never forgive them}.” (aiōn g165)
Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí Ọmọ Ènìyàn, a ó dáríjì í, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sọ ọ̀rọ̀-òdì sí Ẹ̀mí Mímọ́, a kì yóò dáríjì í, ìbá à ṣe ní ayé yìí tàbí ní ayé tí ń bọ̀. (aiōn g165)
33 “Think about this: You can know whether [a person is good and what that person says is good, in the same way that you] can know whether a tree [MET] and the fruit it produces [MET] are good. [You can also know whether a person and what that person says is evil in the same way that you can know] whether a tree [MET] and its fruit [MET] are blighted. You can know whether a tree is good by [seeing] its fruit, and similarly [people can know the evil character of you Pharisees by listening to your accusations against me].
“E sọ igi di rere, èso rẹ̀ a sì di rere tàbí kí ẹ sọ igi di búburú, èso rẹ a sì di búburú, nítorí nípa èso igi ni a ó fi mọ̀ igi.
34 [What] you [teach harms people spiritually like poisonous] snakes [harm them physically] [MET]! You are not able to speak good things because you are evil [RHQ]. Evil people [SYN] [like you] speak what comes from all that is in their (inner beings/hearts).
Ẹ̀yin ọmọ paramọ́lẹ̀, báwo ni ẹ̀yin tí ẹ jẹ búburú ṣe lè sọ̀rọ̀ rere? Ọkàn ènìyàn ni ó ń darí irú ọ̀rọ̀ tí ó lè jáde lẹ́nu rẹ̀.
35 Good people [speak good things. That is like] taking good things out of buildings where they are stored. But evil people [speak evil things. That is like] taking evil things out of buildings where they are stored.
Ẹni rere láti inú yàrá ìṣúra rere ọkàn rẹ̀ ní mú ohun rere jáde wá, àti ẹni búburú láti inú ìṣúra búburú ni; mu ohun búburú jáde wá.
36 I tell you that on the day when God judges [MTY], he will make people recall every useless word they have spoken, [and he will judge them accordingly].
Ṣùgbọ́n, mo sọ èyí fún yín, ẹ̀yin yóò jíyìn gbogbo ìsọkúsọ yín ní ọjọ́ ìdájọ́.
37 Based on the words that you have spoken, [God] will [either] declare that you are righteous based on the words that you have spoken, or [else] he will condemn you.”
Nítorí nípa ọ̀rọ̀ ẹnu yín ni a fi dá yin láre, nípa ọ̀rọ̀ ẹnu yín sì ni a ó fi dá yin lẹ́bi.”
38 Then some of the Pharisees and men who taught the [Jewish] laws responded [to what Jesus was teaching] by saying to him, “Teacher, we want to see you [perform] a miracle [that would prove to us that God sent you].”
Nígbà náà ni, díẹ̀ nínú àwọn Farisi àti àwọn olùkọ́ òfin wí fún pé “Olùkọ́, àwa fẹ́ rí iṣẹ́ àmì kan lọ́dọ̀ rẹ̀”.
39 Then Jesus said to them, “[You] people [have already seen me perform miracles], but you are evil, and you do not faithfully worship God [MET]! You want [me to perform] a miracle [that would prove to you that God sent me], but [God will enable] you to see only one miracle. It will be [like] what happened to Jonah the prophet [MET].
Ó sì dá wọn lóhùn wí pé, “Ìran búburú àti ìran panṣágà ń béèrè àmì; ṣùgbọ́n kò sí àmì tí a ó fi fún un, bí kò ṣe àmì Jona wòlíì.
40 Jonah was in the stomach of a huge fish for three days and nights [before God caused him to live again]. Similarly, for three days and nights I, the one who came from heaven, will be in a place [where dead people are, and then God will cause me to live again].
Bí Jona ti gbé inú ẹja ńlá fún ọ̀sán mẹ́ta àti òru mẹ́ta, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ẹ̀mí Ọmọ Ènìyàn yóò gbé ní inú ilẹ̀ fún ọ̀sán mẹ́ta àti òru mẹ́ta.
41 When [God] judges [all people], the people who lived in Nineveh will stand [in front of him] with [you] people who [have seen me perform miracles]. The [people of Nineveh turned from their sinful ways as a result of hearing what] Jonah preached. [Jonah was important, but I], who am more important than Jonah, [have come and preached to you, but you have not turned from your sinful ways. So] when [God] judges [all people, he] will condemn you.
Àwọn ará Ninefe yóò dìde pẹ̀lú ìran yìí ní ọjọ́ ìdájọ́. Wọn yóò sì dá a lẹ́bi. Nítorí pé wọ́n ronúpìwàdà nípa ìwàásù Jona. Ṣùgbọ́n báyìí ẹni tí ó pọ̀jù Jona wà níhìn-ín yìí.
42 The queen from [Sheba, South of Israel, who lived long ago, came from a distant region in order to listen to King Solomon teach] many wise things. But now [I], [a man] who [is much] greater [and wiser] than Solomon, am here, [but you have not listened to what I have told you]. So at the time when [God] judges [all people], the queen from [Sheba will stand in front of him, along] with you people, and will condemn you.”
Ọbabìnrin gúúsù yóò sì dìde ní ọjọ́ ìdájọ́ sí ìran yìí yóò sì dá a lẹ́bi; nítorí tí ó wá láti ilẹ̀ ìkangun ayé láti gbọ́ ọ̀rọ̀ ọgbọ́n láti ẹnu Solomoni. Ṣùgbọ́n báyìí ẹni tí ó pọ̀jù Solomoni ń bẹ níhìn-ín yìí.
43 “[Sometimes] when an evil spirit leaves a person, it wanders around in desolate areas, seeking [someone in whom it can] rest. If it does not find anyone,
“Nígbà tí ẹ̀mí búburú kan bá jáde lára ènìyàn, a máa rìn ní ibi gbígbẹ́, a máa wá ibi ìsinmi, kò sì ní rí i.
44 it says [to itself], ‘I will return to the person [MET] in whom I used to live.’ So it goes back [and finds that the Spirit of God is not in control of that] person’s [life. The person’s life is like] a house that has been swept clean and everything put in order [MET], [but it is] empty.
Nígbà náà ni ẹ̀mí náà yóò wí pé, ‘Èmi yóò padà sí ara ọkùnrin tí èmí ti wá.’ Bí ó bá sì padà, tí ó sì bá ọkàn ọkùnrin náà ni òfìfo, a gbà á mọ́, a sì ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
45 Then [this evil spirit] goes and gets seven other spirits that are [even] more evil, and they [all] enter [that person] and [begin] living there. [So, although] that person’s condition [was bad] before, it becomes much worse. That is what [you] wicked people who [have heard me teach] will experience.”
Nígbà náà ni yóò lọ, yóò sì mú ẹ̀mí méje mìíràn pẹ̀lú ara rẹ̀, tí ó burú ju òun fúnra rẹ̀ lọ. Gbogbo wọn yóò sì wá sí inú rẹ̀, wọn yóò máa gbé ibẹ̀. Ìgbẹ̀yìn ọkùnrin náà a sì burú ju ìṣáájú rẹ̀ lọ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni yóò rí fún ìran búburú yìí pẹ̀lú.”
46 While Jesus was still speaking to the crowds, his mother and his [younger] brothers [arrived]. They stood outside [the house], wanting to speak with him.
Nígbà tí ó ń sọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn, wò ó, ìyá rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ dúró lóde, wọ́n fẹ́ bá a sọ̀rọ̀.
47 Someone said to him, “Your mother and your [younger] brothers are standing outside [the house], wanting to talk to you.”
Nígbà náà ni ẹnìkan wí fún un pé, “Ìyá rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ ń dúró dè ọ́ lóde wọ́n ń fẹ́ bá ọ sọ̀rọ̀.”
48 Then Jesus said to the person who told him [that], “([I will tell you something about] my mother and brothers [MET].[/Do you know] who I [consider to be like] my mother and my brothers?)” [MET, RHQ]
Ó sì fún ni èsì pé, “Ta ni ìyá mi? Ta ni àwọn arákùnrin mi?”
49 He then pointed toward [us] disciples and said, “These are ones [whom I love as much as I love] my mother and my brothers [MET].
Ó nawọ́ sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó wí pé, “Wò ó, ìyá mi àti àwọn arákùnrin mi ni wọ̀nyí.”
50 Those who do what [God] my Father [who is] in heaven wants, are [as dear to me] [MET] [as] my brother, my sister, or my mother.”
Nítorí náà, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe ìfẹ́ Baba mi tí ń bẹ ní ọ̀run, ni arákùnrin mi àti arábìnrin mi àti ìyá mi.”

< Matthew 12 >