< Mark 7 >

1 [One day some] Pharisees and some men who teach the [Jewish] laws gathered around Jesus. They had come from Jerusalem [to investigate him].
Àwọn Farisi sì péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti àwọn kan nínú àwọn akọ̀wé, tí ó wá láti Jerusalẹmu,
2 The Pharisees and all of the [other] Jews [strictly] observe the traditions that their ancestors [taught. For example, they refuse to] eat until they first wash their hands [with a special ritual], especially after they [return] from [buying things in] the marketplace. [They think that God will be angry with them if they do not do that, because some person or thing unacceptable to God might have touched] ([them/the things they bought]). There are many other such [traditions] that they accept and try to obey. Specifically, they wash [in a special way] their cups, pots, kettles, containers, and beds [in order that using these things will not make God reject them].
wọ́n sì ṣe àkíyèsí wí pé díẹ̀ nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Jesu ń fi ọwọ́ àìmọ́ jẹun, èyí yìí ni wẹ ọwọ́.
3
(Àwọn Farisi, àti gbogbo àwọn Júù, bí wọ́n kò bá wẹ ọwọ́ wọn gidigidi, wọn kì í jẹun nítorí wọ́n ti pa òfin àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn àgbà mọ́.
4
Nígbà tí wọ́n bá sì ti ọjà dé sílé, wọn kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ kan oúnjẹ àfi tí wọ́n bá bu omi wẹ ara wọn. Èyí sì jẹ́ ọ̀kan nínú ogunlọ́gọ̀ àpẹẹrẹ òfin àti ìlànà tí wọ́n ti dì mú fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún sẹ́yìn, bí i fífọ kọ́ọ̀bù, àwọn ìkòkò, àti kẹ́tù.)
5 That day, those Pharisees and men who taught the [Jewish] laws saw that some of his disciples were eating food with hands that they had not washed [using the special ritual]. So they questioned Jesus, saying, “[Your] disciples disobey the traditions of our ancestors! (You should not [let them] eat food if they have not washed their hands [using our special ritual]!/Why do you [let them] eat food if they have not washed their hands [using our special ritual]?) [RHQ]”
Nítorí èyí àwọn Farisi àti àwọn olùkọ́ òfin béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kò tẹ̀lé àwọn òfin àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn àgbà nítorí wọ́n fi ọwọ́ àìmọ́ jẹun?”
6 Jesus said to them, “Isaiah [rebuked your ancestors], and his words describe very well you people who only pretend to be good! He wrote these words [that God said]: These people speak [as if they] honor me, but they [SYN] really do not think about honoring me at all.
Jesu dá wọn lóhùn wí pé, “Ẹyin àgàbàgebè yìí, òtítọ́ ni wòlíì Isaiah ń sọtẹ́lẹ̀ nípa tí ẹ̀yin àgàbàgebè, bí a ti kọ ọ́ pé: “‘Àwọn ènìyàn wọ̀nyí fi ẹnu wọn bu ọlá fún mi ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnà sí mi.
7 It is useless for them to worship me, because they teach only what people have commanded [as if I myself had commanded them].
Ìsìn wọn jẹ́ lásán, ìkọ́ni wọ́n jẹ́ kìkìdá òfin tí àwọn ènìyàn fi ń kọ́ni.’
8 You, [like your ancestors], refuse [to do] what God has commanded. Instead, you follow only the traditions that (others/your ancestors) have [taught].”
Nítorí tí ẹ̀yin fi òfin Ọlọ́run sí apá kan, ẹ̀yin ń tẹ̀lé àṣà àwọn ènìyàn.”
9 Jesus also said to them, “[You think] [IRO] that you are clever in refusing to do what God commanded just so that you can obey your own traditions!
Ó si wí fún wọn: “Ẹ̀yin sá à mọ̀ bí ẹ ti ń gbé òfin Ọlọ́run jù sẹ́yìn kí ẹ lè mú òfin tiyín ṣẹ.
10 [For example, our ancestor] Moses [wrote God’s] command, ‘Honor your fathers and your mothers’. He also wrote, ‘[The authorities must] execute a person who speaks evil about his father or mother.’
Mose fún un yín ní òfin yìí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run pé, ‘Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ.’ Ó tún sọ pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀ aburú sí baba tàbí ìyá rẹ̀ ní láti kú ni.’
11 But you [teach people that it is all right that people no longer must help their parents. You teach people that it is all right if people] give their things to God [instead of giving them to their parents]. You allow them to say to their parents, ‘What I was going to give to you [to provide for you, I have now promised to] give to God. So I [cannot any longer help you]!’ As a result, you are [actually telling people] that they no longer have to help their parents!
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wá sọ pé ó dára bákan náà fún ọkùnrin kan bí kò bá tilẹ̀ pèsè fún àìní àwọn òbí rẹ̀, ṣùgbọ́n kí o sọ fún wọn pé, ‘Ẹ má ṣe bínú baba tàbí ìyá mi, n kò lè ràn yín lọ́wọ́ nísinsin yìí,’ nítorí tí mo ti fi ẹ̀bùn tí ǹ bá fi fún un yín fún Ọlọ́run.
Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò si jẹ́ kí ó ṣe ohunkóhun fún baba tàbí ìyá rẹ̀ mọ́.
13 And, by doing that, you disregard what God commanded! You teach your own traditions to others [and tell them strongly that they should obey them] And you do many other things like that.”
Ẹ̀yin ń fi òfin àtọwọ́dọ́wọ́ tiyín tí ẹ fi lélẹ̀, sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run di asán àti ọ̀pọ̀ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń ṣe.”
14 Then Jesus again summoned the crowd [to come closer. Then] he said to them [figuratively], “All of you people listen to me! [Try to] understand [DOU] [what I am about to tell you].
Lẹ́yìn náà, Jesu pe ọ̀pọ̀ ènìyàn láti wá gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀. Ó sì wí fún wọn pé, “Gbogbo yín ẹ tẹ́tí sílẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí èyí ó yé e yín.
15 Nothing that people eat causes [God to] consider them to be unacceptable. On the contrary, it is that which comes from people’s (inner beings/hearts) that causes God to reject them.”
Kò sí ohunkóhun láti òde ènìyàn, tí ó wọ inú rẹ̀ lọ, tí ó lè sọ ọ́ di aláìmọ́, ṣùgbọ́n àwọn nǹkan tí ó ti inú rẹ jáde, àwọn wọ̀nyí ní ń sọ ènìyàn di aláìmọ́.”
17 After Jesus had left the crowd and then entered a house with the disciples, they asked him about the parable [that he had just spoken].
Nígbà tí Jesu sì wọ inú ilé kan lọ, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn tẹ̀lé é, wọ́n sì béèrè ìtumọ̀ àwọn òwe tí ó pa.
18 He replied, “([I am disappointed that] you also do not understand [what it means]!/Why can you not understand [what it means]?) [RHQ] (You ought to understand that nothing that [enters us from] outside can cause [God to] consider us unacceptable to him./Can you not understand that nothing that [enters us from] outside of us can cause [God to] consider us unacceptable to him?) [RHQ]
Jesu béèrè wí pé, “Àbí kò sí èyí tí ó yé yín nínú ọ̀rọ̀ náà? Ẹ̀yin kò rí i wí pé ohunkóhun tí ó wọ inú ènìyàn láti òde kò lè sọ ènìyàn di aláìmọ́?
19 Instead of entering [and ruining] our minds/souls, it goes into our stomachs, and afterwards the refuse passes out [of our bodies].” By saying this, Jesus was declaring that people [can eat] any food without causing [God] to reject them.
Nítorí tí kò lọ sínú ọkàn rẹ̀, ṣùgbọ́n sínú ara, a sì yà á jáde, a sì gbá gbogbo oúnjẹ dànù.” (Nípa sísọ èyí, Jesu fihàn pé gbogbo oúnjẹ jẹ́ “mímọ́.”)
20 He also said, “It is the [thoughts and actions] that come from within people that cause [God] to consider them unacceptable to him.
Nígbà náà, ó fi kún un pé, “Èyí ti ó ti ọkàn ènìyàn jáde ni ń sọ ni di aláìmọ́.
21 Specifically, it is people’s innermost being [that causes them to] think things that are evil; they act immorally, they steal [things], they commit murder.
Nítorí pé láti inú ọkàn ènìyàn ni àwọn èrò búburú wọ̀nyí ti ń jáde wá: àgbèrè, olè, ìpànìyàn, panṣágà,
22 They [commit] adultery, they are greedy, they [act] maliciously, they deceive [people]. They [act] indecently, they envy [people], they speak evil about others, they are proud, and they [act] foolishly.
ọ̀kánjúwà, odì yíyàn, ìtànjẹ, ìmọ-tara-ẹni, ìlara, ọ̀rọ̀ ẹ̀yìn, ìgbéraga, òmùgọ̀.
23 People think [these thoughts] and then they do these evil actions, and that is what causes [God to] consider them unacceptable to him.”
Gbogbo àwọn nǹkan búburú wọ̀nyí ń tí inú wá, àwọn ló sì ń sọ yín di aláìmọ́.”
24 After Jesus [and his disciples] left [Galilee district], they went to the region around Tyre. While he stayed at a certain house, he desired that no one know [it], but people soon found out [that he was there].
Nígbà náà ni Jesu kúrò ní Galili, ó sí lọ sí agbègbè Tire àti Sidoni, ó sì gbìyànjú láti nìkan wà pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ fún àkókò díẹ̀, ṣùgbọ́n eléyìí kò ṣe é ṣe, nítorí pé kò pẹ́ púpọ̀ tí ó wọ ìlú nígbà tí ìròyìn dídé rẹ̀ tàn káàkiri.
25 A certain woman, whose daughter had an evil spirit [within her], heard about Jesus. At once she came to him and prostrated herself at his feet.
Láìpẹ́, obìnrin kan tí ọmọbìnrin rẹ̀ ní ẹ̀mí àìmọ́ tọ̀ ọ́ wá, ó ti gbọ́ nípa Jesu, ó wá, ó sì wólẹ̀ lẹ́sẹ̀ Jesu.
26 This woman [was not a Jew. Her ancestors came] from Greece [country], but she was born in [the region around] Phoenicia [town] in Syria district. She pleaded with Jesus that he expel the evil spirit from her daughter.
Giriki ní obìnrin náà, Siro-Fonisia ní orílẹ̀-èdè rẹ̀. Ó bẹ Jesu kí ó bá òun lé ẹ̀mí èṣù náà jáde lára ọmọbìnrin òun.
27 But he [wanted to see how strongly she believed in him. So, suggesting that he should help the Jews first and not the non-Jews whom some Jews called dogs] [MET], [he] spoke to her saying, “First let the children eat all they want, because it is not good for someone to take the food [the mother has prepared] for the children and then throw it to the [little] dogs.”
Jesu sọ fún obìnrin yìí pé, “Ní àkọ́kọ́, ó yẹ kí a fi oúnjẹ tẹ́ àwọn ọmọ lọ́rùn ná. Nítorí kò tọ́ kí a mú oúnjẹ àwọn ọmọ fún àwọn ajá.”
28 But [to show that she believed that non-Jews could also receive help from God] [MET], she replied to him, “Sir, [what you say is] correct, but even the [little] dogs, which lie under the table, eat the crumbs that the children [drop].”
Obìnrin náà dáhùn wí pé, “Òótọ́ ni ọ̀rọ̀ yín Olúwa, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ajá pàápàá a máa ní àǹfààní láti jẹ èérún oúnjẹ tí ó bá bọ́ sílẹ̀ láti orí tábìlì.”
29 [Jesus] said to her, “Because of what you have said, [you have shown me that you believe in what I can do for you]. So I will help you. Now you may go [home, because I have caused] the evil spirit to leave your daughter.”
“Ó sì wí fún un pé, nítorí ọ̀rọ̀ yìí, máa lọ, ẹ̀mí àìmọ́ náà ti jáde kúrò lára ọmọbìnrin rẹ.”
30 The woman returned to her house and saw that her child was lying [quietly] on the bed and that the evil spirit had left.
Nígbà tí ó padà dé ilé, ó bá ọmọbìnrin rẹ̀ ní ìdùbúlẹ̀ jẹ́jẹ́ lórí ibùsùn, ẹ̀mí àìmọ́ náà ti fi í sílẹ̀.
31 Jesus [and his disciples] left the region around Tyre [city] and went [north] through Sidon [city], then [toward the east] through the district of the Ten Towns, and then [south] to [the towns near] Lake Galilee.
Nígbà náà ni Jesu fi agbègbè Tire àti Sidoni sílẹ̀, ó wá si Òkun Galili láàrín agbègbè Dekapoli.
32 [There], people brought to him a man who was deaf and who could hardly talk. They begged [Jesus] to lay his hands on him [in order to heal him].
Níbẹ̀ ọkùnrin kan tí kò lè sọ̀rọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ Jesu, àwọn ènìyàn sì bẹ Jesu pé kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e.
33 [So Jesus] took him away from the crowd [in order that the two of them could be] alone. Then he put [one of] his fingers into [each of] the man’s ears. After he spat [on his fingers], he touched the man’s tongue [with his fingers].
Jesu sì mú ọkùnrin náà kúrò láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn. Ó sì fi àwọn ìka rẹ̀ sí etí ọkùnrin náà, ó tu itọ́ ṣọ́wọ́. Ó sì fi kan ahọ́n rẹ̀.
34 Then he looked up toward heaven, he sighed [because he was concerned for the man], and then [in his own language] he said to the man’s [ears], “Ephphatha”, which means, “Be opened {Open up}!”.
Nígbà náà ni Jesu wòkè ọ̀run, ó sì mí kanlẹ̀, ó sì pàṣẹ wí pé, “Efata!” (èyí ni, “Ìwọ ṣí!”).
35 At once the man could hear plainly [MTY]. He also began to speak clearly because [what was causing him to be unable to speak] was healed {Jesus healed [what was causing him to be unable to speak]}.
Lójúkan náà, etí rẹ̀ sì ṣí, okùn ahọ́n rẹ̀ sì tú, ó sì ń sọ̀rọ̀ ketekete.
36 Jesus told ([the people/his friends]) not to tell anyone [what he had done]. But, although he ordered them [and others] repeatedly [not to tell anyone about it], they kept talking about it very much.
Jesu pàṣẹ fún ọ̀pọ̀ ènìyàn tó wà níbẹ̀ pé kí wọn má ṣe tan ìròyìn náà ká. Ṣùgbọ́n bí ó ti ń pa wọ́n lẹ́nu mọ́ tó, náà ni wọ́n ń tan ìròyìn náà káàkiri tó.
37 [People who heard about it] were utterly amazed and were saying [enthusiastically], “Everything he has done is wonderful! [Besides doing other amazing things], he enables deaf people to hear! And he enables those who cannot speak to speak!”
Àwọn ènìyàn sì kún fún ìyanu, wọ́n wí pé, “Ó ṣe ohun gbogbo dáradára, Ó mú kí adití gbọ́rọ̀, odi sì sọ̀rọ̀.”

< Mark 7 >