< Luke 12 >

1 While they were doing that, many thousands of people gathered [around Jesus]. There were so many that they were stepping on each other. Then Jesus said to his disciples, “Beware of [becoming] hypocrites [like] the Pharisees. Their [evil influence] [MET] [spreads to others like] yeast [spreads its influence in dough].
Ó sì ṣe, nígbà tí àìníye ìjọ ènìyàn péjọpọ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí wọn ń tẹ ara wọn mọ́lẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sísọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ẹ máa ṣọ́ra yín nítorí ìwúkàrà àwọn Farisi tí í ṣe àgàbàgebè.
2 People will not be able to continue concealing the things that [they or other] people try to conceal now. [God] will [some day] cause the things that are hidden now to be known {[everyone] to know the things that they hide now}.
Kò sí ohun tí a bò, tí a kì yóò sì fihàn; tàbí tí ó pamọ́, tí a kì yóò mọ̀.
3 All the things that you say in the dark [secretly, some day] will be heard {people will hear them} in the daylight. The things you have whispered [SYN] privately among yourselves in your rooms will be proclaimed {[people] will proclaim them} publicly.”
Nítorí náà ohunkóhun tí ẹ̀yin sọ ní òkùnkùn, ní gbangba ni a ó ti gbọ́ ọ; àti ohun tí ẹ̀yin bá sọ sí etí ní iyàrá, lórí òrùlé ni a ó ti kéde rẹ̀.
4 “My friends, listen [carefully]. Do not be afraid of people who [are able to] kill you, but after they kill you, there is nothing more that they can do [to hurt you].
“Èmi sì wí fún yín ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn tí ó ń pa ara ènìyàn kú, lẹ́yìn èyí, wọn kò sì ní èyí tí wọ́n lè ṣe mọ́.
5 But I will warn you about the one that you should truly be afraid of. You should be afraid of [God], because he not only has [the power to] cause people to die, he has the power to throw them into hell afterward! Yes, he is truly the one that you should be afraid of! (Geenna g1067)
Ṣùgbọ́n èmi ó sì sọ ẹni tí ẹ̀yin ó bẹ̀rù fún yín: Ẹ bẹ̀rù ẹni tí ó lágbára lẹ́yìn tí ó bá pànìyàn tan, láti wọ́ ni lọ sí ọ̀run àpáàdì. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín òun ni kí ẹ bẹ̀rù. (Geenna g1067)
6 [Think about] the sparrows. [They are worth so little] that [you] can [RHQ] buy five of them for only two small coins. But not one of them is ever forgotten by God {God never forgets one of them}!
Ológoṣẹ́ márùn-ún sá à ni a ń tà ní owó idẹ wẹ́wẹ́ méjì? A kò sì gbàgbé ọ̀kan nínú wọn níwájú Ọlọ́run?
7 You are worth more [to God] than many sparrows. So do not be afraid [of what people can do to you! God] even knows how many hairs there are on each of your heads, [so that if you(sg) lose one hair, he knows about it. So nothing bad can happen to you without his knowing it].
Ṣùgbọ́n gbogbo irun orí yín ni a kà pé ṣánṣán. Nítorí náà kí ẹ má ṣe bẹ̀rù, ẹ̀yin ní iye lórí ju ológoṣẹ́ púpọ̀ lọ.
8 I want to tell you also that if people, [without being afraid, are willing to] tell others [that they are my disciples], [I], the one who came from heaven, will acknowledge before [God that they are my disciples]. [I will do that while] God’s angels listen.
“Mo sì wí fún yín pẹ̀lú, Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́wọ́ mi níwájú àwọn ènìyàn. Ọmọ Ènìyàn yóò sì jẹ́wọ́ rẹ̀ níwájú àwọn angẹli Ọlọ́run.
9 But if people [are] afraid to say in front of others that they are [my disciples], [I] will say, while God’s angels listen, that they are not [my disciples].
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sẹ́ mi níwájú ènìyàn, a ó sẹ́ ẹ níwájú àwọn angẹli Ọlọ́run.
10 [I will tell you] also that [God is willing to] forgive people who say bad things about me, the one who came from heaven, but [he] will not forgive anyone who says evil things about what the Holy Spirit [does].
Àti ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí Ọmọ Ènìyàn, a ó dárí rẹ̀ jì í; ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí Ẹ̀mí Mímọ́, a kì yóò dárí rẹ̀ jì í.
11 [So] when people ask you in Jewish worship houses and in the presence of rulers and other authorities [about your trusting in me], do not worry about how you will answer them [when they accuse you]. Do not worry about what you should say,
“Nígbà tí wọ́n bá sì mú yin wá sí Sinagọgu, àti síwájú àwọn olórí, àti àwọn aláṣẹ, ẹ má ṣe ṣàníyàn pé, báwo tàbí ohun kín ni ẹ̀yin yóò fèsì rẹ̀ tàbí kín ni ẹ̀yin ó wí.
12 because the Holy Spirit will tell you at that very time what you should say.”
Nítorí Ẹ̀mí Mímọ́ yóò kọ́ yín ní wákàtí kan náà ní ohun tí ó yẹ kí ẹ sọ.”
13 Then one of the people in the crowd said to [Jesus], “Teacher, tell my [older] brother to divide my father’s property and give me [the part that belongs] to me!”
Ọ̀kan nínú àwùjọ wí fún un pé, “Olùkọ́, sọ fún arákùnrin mi kí ó pín mi ní ogún.”
14 But Jesus replied to him, “Man, (no one appointed me in order that I would settle [matters when people are] disputing about property!/did anyone appoint me in order that I would settle [matters when people are] disputing about property?) [RHQ]”
Ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin yìí, ta ni ó fi mí jẹ onídàájọ́ tàbí olùpíngún fún yín?”
15 Then he said to the whole crowd, “Guard yourselves very carefully, in order that you do not desire other people’s things in any way! No one can make his life secure by [obtaining] many possessions.”
Ó sì wí fún wọn pé, “Kíyèsára kí o sì máa ṣọ́ra nítorí ojúkòkòrò: nítorí ìgbésí ayé ènìyàn kò dúró lé ọ̀pọ̀ ohun tí ó ní.”
16 Then Jesus told the people this illustration: “There was a certain rich man whose crops grew very well.
Ó sì pa òwe kan fún wọn pé, “Ilẹ̀ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ so ọ̀pọ̀lọpọ̀ èso.
17 [So] he said [to himself], ‘I do not know what to do, because I do not have any place [big enough] to store all my crops!’
Ó sì rò nínú ara rẹ̀ pé, ‘Èmi ó ti ṣe, nítorí tí èmi kò ní ibi tí èmi ó gbé kó èso mi jọ sí.’
18 Then he thought to himself, ‘[I know] what I will do! I will tear down my grain bins and build larger ones! Then I will store all my wheat and other goods in [the big new bins].
“Ó sì wí pé, ‘Èyí ni èmi ó ṣe: èmi ó wó àká mi palẹ̀, èmi ó sì kọ́ èyí tí ó tóbi; níbẹ̀ ni èmi ó gbé to gbogbo èso àti ọrọ̀ mi jọ sí.
19 [Then] I will say to myself [SYN], “Now I have plenty of goods stored up. [They will last] for many years. [So now] I will take life easy. I will eat and drink [all that I want to] and be happy [for a long time]!”’
Èmi ó sì wí fún ọkàn mi pé, ọkàn, ìwọ ní ọrọ̀ púpọ̀ tí a tò jọ fún ọ̀pọ̀ ọdún; sinmi, máa jẹ, máa mu, máa yọ̀.’
20 But God said to him, ‘You foolish [man]! Tonight you will die! (Then all [the goods] you have saved up [for yourself] will [belong to someone else, not to] you!/Do you think that you [will benefit from] all that you have stored up for yourself?) [RHQ]’”
“Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fún un pé, ‘Ìwọ aṣiwèrè, lóru yìí ni a ó béèrè ọkàn rẹ lọ́wọ́ rẹ; ǹjẹ́ ti ta ni nǹkan wọ̀nyí yóò ha ṣe, tí ìwọ ti pèsè sílẹ̀?’
21 [Then Jesus ended this illustration by saying], “That is what will happen to those who store up goods just for themselves, but who do not value the things [that] God [considers] valuable.”
“Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó to ìṣúra jọ fún ara rẹ̀, tí kò sì ní ọrọ̀ lọ́dọ̀ Ọlọ́run.”
22 Then [Jesus] said to his disciples, “So I want to tell you this: Do not worry about [things you need] in order to live. Do not worry about [whether you will have enough food] to eat or [enough clothes] to wear.
Jesu sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Nítorí náà mo wí fún yín pé, ẹ má ṣe ṣe àníyàn nítorí ẹ̀mí yín pé, kín ni ẹ̀yin yóò jẹ tàbí nípa ara yin pe kín ni ẹyin o fi bora.
23 It is important to have sufficient food and clothing, but (the way you conduct your lives is more important./is not the way you conduct your lives more important?) [RHQ]
Ẹ̀mí sá à ju oúnjẹ lọ, ara sì ju aṣọ lọ.
24 Think about the birds: They do not plant [seeds], and they do not harvest [crops]. They do not have rooms or buildings in which to store crops. But God provides food for them. [And] you are certainly much more valuable than birds. [So God will certainly provide what you need]!
Ẹ kíyèsi àwọn ẹyẹ ìwò: wọn kì í fúnrúgbìn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í kórè: wọn kò ní àká, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní abà, Ọlọ́run sá à ń bọ́ wọn: mélòó mélòó ni tí ẹ̀yin fi sàn ju ẹyẹ lọ!
25 (There is not a one of you who can add a little bit to how long he lives by worrying about it!/Is there any of you who can add a little bit to how long he lives by worrying about it?) [RHQ]
Ta ni nínú yín nípa àníyàn ṣíṣe tí ó lè fi ìgbọ̀nwọ́ kan kún ọjọ́ ayé rẹ̀?
26 Worrying is a small thing to do. So since you cannot add to your life, (you certainly should not worry about other things that [you need to have in order to live!]/why do you worry about other things that [you need to have in order to live]?) [RHQ]
Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin kò ti lè ṣe èyí tí ó kéré bí eléyìí, èéṣe tí ẹ̀yin fi ń ṣàníyàn nítorí ìyókù?
27 Think about the way that flowers grow [in the fields]. They do not work [to earn money], and they do not make their own clothes. But I tell you that [even though King] Solomon, [who lived long ago, wore very beautiful clothes], his clothes were not as beautiful as one of those [flowers].
“Ẹ kíyèsi àwọn lílì bí wọ́n ti ń dàgbà; wọn kì í ṣiṣẹ́, wọn kì í rànwú; ṣùgbọ́n kí èmi wí fún yín, a kò ṣe Solomoni pàápàá lọ́ṣọ̀ọ́ ní gbogbo ògo rẹ̀ tó ọ̀kan nínú ìwọ̀nyí.
28 God makes the flowers beautiful, but they grow in the fields for only a short time. Then [they are cut at the same time that the grass] is cut, and thrown into an oven [to be burned to make heat for baking] bread. [So they really are not worth very much. But you are very precious to] God, [and he] will [care for you] much more [than he cares for the grass by filling it with beautiful flowers]. So he will certainly provide clothes for you, who [live much longer than the grass. Why] [RHQ] [do you] trust him so little?
Ǹjẹ́ bí Ọlọ́run bá wọ koríko igbó ní aṣọ tó bẹ́ẹ̀ èyí tí ó wà lónìí, tí a sì gbá a sínú iná lọ́la: mélòó mélòó ni yóò wọ̀ yín láṣọ, ẹ̀yin onígbàgbọ́ kékeré.
29 Do not always be concerned about having enough to eat and drink, and do not be worrying about those things.
Kí ẹ má sì ṣe lé ohun tí ẹ ó jẹ, tàbí ohun tí ẹ ó mu, kí ẹ má sì ṣe ṣe àníyàn nínú ọkàn.
30 The people who do not know God are always worried about such things. But your Father [in heaven] knows that you need those things, [so you should not worry about them].
Nítorí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè ayé ń wá kiri. Baba yín sì mọ̀ pé, ẹ̀yin ń fẹ́ nǹkan wọ̀nyí.
31 Instead, be concerned about letting [God] completely direct [your life]. Then [he] will also give you enough of the things [you need].
Ṣùgbọ́n ẹ máa wá ìjọba Ọlọ́run, gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni a ó sì fi kún un fún yín.
32 [You who are my disciples are like a] small flock of sheep, [and I am like your shepherd]. So you should not be afraid. Your Father [in heaven] wants to let you rule with him [in heaven].
“Má bẹ̀rù, agbo kékeré, nítorí dídùn inú Baba yín ni láti fi ìjọba fún yín.
33 [So now] sell the things that you own. Give [the money that you get for those things] to poor people. [If you do that, it will be as though] you are providing for yourselves purses that will not wear out, and [God will give] you a treasure in heaven that will always be safe. There, no thief can come near [to steal it], and no termite can destroy it.
Ẹ ta ohun tí ẹ̀yin ní, kí ẹ sì tọrẹ àánú kí ẹ sì pèsè àpò fún ara yín, tí kì í gbó, ìṣúra ní ọ̀run tí kì í tán, ní ibi tí olè kò lè súnmọ́, àti ibi tí kòkòrò kì í bà á jẹ́.
34 Remember that [the things] that you [think are the most] valuable are [the things] that you will be constantly concerned about.”
Nítorí ní ibi tí ìṣúra yín gbé wà, níbẹ̀ ni ọkàn yín yóò gbé wà pẹ̀lú.
35 “Be always ready [for doing God’s work] [MET], like [people] who have put on their work clothes and are ready [during the day], with their lamps burning all night.
“Ẹ di àmùrè yín, kí fìtílà yín sì máa jó.
36 Be [ready for me to return] [MET], like servants who are waiting for their master to return after being at a wedding feast [for several days]. They are [waiting to] open the door for him and [start working for him again] as soon as he arrives and knocks at the door.
Kí ẹ̀yin tìkára yín dàbí ẹni tí ń retí olúwa wọn, nígbà tí òun ó padà ti ibi ìgbéyàwó dé, pé nígbà tí ó bá dé, tí ó sì kànkùn, kí wọn lè ṣí i sílẹ̀ fún un lọ́gán.
37 If those servants are awake when he returns, [he will] be very pleased with them. I will tell you this: He will put on [the kind of clothes] that servants wear and tell them to sit down, and he will serve them a meal.
Ìbùkún ni fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ náà nígbà tí olúwa náà bá dé tí yóò bá wọn tí wọn ń ṣọ́nà; lóòótọ́ ni mo wí fún yín, yóò di ara rẹ̀ ní àmùrè yóò sì mú wọn jókòó láti jẹun, yóò sì jáde wá láti ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
38 [Even] if he comes between midnight and sunrise, if he finds that his servants are [awake and] ready [for him], he will be very pleased with them.
Bí olúwa wọn bá sì dé nígbà ìṣọ́ kejì, tàbí tí ó sì dé nígbà ìṣọ́ kẹta, tí ó sì bá wọn bẹ́ẹ̀, ìbùkún ni fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ náà.
39 But you must also remember this: If owners of a house knew what time a thief was coming, they [would stay awake and] would not allow their house to be broken into [and their goods to be stolen] {[the thief] to break into the house [and steal their goods]}.
Ṣùgbọ́n ẹ mọ èyí pé, baálé ilé ìbá mọ wákàtí tí olè yóò wá, òun ìbá máa ṣọ́nà, kì bá tí jẹ́ kí a já wọ inú ilé òun.
40 Similarly, you must be ready [for me to return], because [I], the one who came from heaven, will come [again] at a time when you do not expect [me to come].”
Nítorí náà, kí ẹ̀yin múra pẹ̀lú, nítorí Ọmọ Ènìyàn ń bọ̀ ní wákàtí tí ẹ̀yin kò nírètí.”
41 Peter said, “Lord, are you [(sg)] speaking this illustration [only] for us or for everyone [else also]?”
Peteru sì wí pé, “Olúwa, ìwọ pa òwe yìí fún wa, tàbí fún gbogbo ènìyàn?”
42 The Lord replied, “[I am saying it for you and for anyone else] [MET, RHQ] who is like a faithful and wise manager in his master’s house. His master appoints him to [supervise affairs in his house] and to give all the [other] servants their food at the proper time. [Then he leaves on a long trip].
Olúwa sì dáhùn wí pé, “Ta ni olóòtítọ́ àti ọlọ́gbọ́n ìríjú náà, tí olúwa rẹ̀ fi jẹ olórí agbo ilé rẹ̀, láti máa fi ìwọ̀n oúnjẹ wọ́n fún wọn ní àkókò?
43 If the servant is doing that work when his master returns, [his master] will be very pleased with him.
Ìbùkún ni fún ọmọ ọ̀dọ̀ náà, nígbà tí olúwa rẹ̀ bá dé, tí yóò bá a kí ó máa ṣe bẹ́ẹ̀.
44 I tell you this: His master will appoint him to supervise all of his affairs [permanently].
Lóòótọ́ ni mo wí fún yín yóò fi jẹ olórí ohun gbogbo tí ó ní.
45 But that servant might think to himself, ‘My master [has been away] for a long time, [so he probably will] not return soon [and find out what I am doing].’ [Then he might] start to beat the [other] servants, both male and female ones. [He might also start] to eat [a lot of food] and get drunk.
Ṣùgbọ́n bí ọmọ ọ̀dọ̀ náà bá wí ní ọkàn rẹ̀, pé, ‘Olúwa mi fi ìgbà bíbọ̀ rẹ̀ falẹ̀!’ Tí ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í lu àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í jẹ àti sí mu àmupara:
46 [If he does that, and if] his master returns on a day when the servant does not expect him, then his master will (cut him into two pieces/punish him severely) [HYP] and put him [in the place where he puts all] those who do not [serve him] faithfully.
Olúwa ọmọ ọ̀dọ̀ náà yóò dé ní ọjọ́ tí kò retí rẹ̀, àti ní wákàtí tí kò dábàá, yóò sì jẹ ẹ́ ní yà gidigidi, yóò sì yan ipò rẹ̀ pẹ̀lú àwọn aláìgbàgbọ́.
47 Every servant who knows what his master wants him to do but who does not get himself ready and does not do what his master desires will be beaten severely {[The master] will beat severely every servant who knows what his master wants him to do but who does not get himself ready and does not do what his master desires}.
“Àti ọmọ ọ̀dọ̀ náà, tí ó mọ ìfẹ́ olúwa rẹ̀, tí kò sì múra sílẹ̀, tí kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, òun ni a ó nà púpọ̀.
48 But every [servant] who did not know [what his master wanted] him to do, and who did things for which he deserved to be punished, will be beaten lightly {[the master] will beat lightly every [servant] who did not know [what his master wanted] him to do and did the things for which he deserved that [his master] would beat him}. [God will treat his people similarly, because he] expects a lot from those people whom [he] has allowed [to understand a lot]. People who entrust things [to others’ care] expect those people [to care for those things] very well. Similarly, [God] expects a lot from those people whom he has allowed [to understand a lot]. Furthermore, he expects the most from people to whom he has given the most [ability].”
Ṣùgbọ́n èyí tí kò mọ̀, tí ó ṣe ohun tí ó yẹ sí lílù, òun ni a ó lù níwọ̀n. Nítorí ẹnikẹ́ni tí a fún ní púpọ̀, lọ́dọ̀ rẹ̀ ni a ó gbé béèrè púpọ̀: lọ́dọ̀ ẹni tí a bá gbé fi púpọ̀ sí, lọ́dọ̀ rẹ ni a ó gbé béèrè sí i.
49 “I came to earth to cause [there to be trials] [MET], [which will purify you as] fire [purifies metal] (OR, to cause judgment/divisions among you). I wish that the time when [you] will be purified {when [God] will purify you} (OR, when divisions will be caused {to cause divisions among people}) had already begun.
“Iná ni èmi wá láti sọ sí ayé; kín ni èmi sì ń fẹ́ bí kò ṣe kí iná náà ti jo!
50 I must soon suffer [IDM] greatly. I am distressed, and I will continue to be distressed until my suffering is finished.
Ṣùgbọ́n èmi ní bamitiisi kan tí a ó fi bamitiisi mi; ara ti ń ni mí tó títí yóò fi parí!
51 Do you think that as a result of my coming to earth people will live together peacefully? No! I must tell you, [that is not what will happen! Instead, people] will be divided.
Ẹ̀yin ṣe bí àlàáfíà ni èmi fi sí ayé? Mo wí fún yín, bẹ́ẹ̀ kọ́; ṣùgbọ́n bí kò ṣe ìyapa.
52 Because some people in one house [will believe in me and some will not], they will be divided. [For example], three people in one house [who do not believe in me] will oppose two [who do believe], or two [who do not believe in me] will oppose three [who do believe].
Nítorí láti ìsinsin yìí lọ, ènìyàn márùn-ún yóò wà ní ilé kan náà tí a ó yà ní ipa, mẹ́ta sí méjì, àti méjì sí mẹ́ta.
53 A man will oppose his son, or a son will oppose his father. A woman will oppose her daughter, or a woman will oppose her mother. A woman will oppose her daughter-in-law, or a woman will oppose her mother-in-law.”
A ó ya baba nípa sí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ ọkùnrin sí baba; ìyá sí ọmọbìnrin, àti ọmọbìnrin sí ìyá rẹ̀, ìyá ọkọ sí ìyàwó ọmọ, àti ìyàwó ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀.”
54 He [also] said to the crowds, “[In this country], when you see a [dark] cloud forming in the west, you immediately say ‘It is going to rain!’ and that is what happens.
Ó sì wí fún ìjọ ènìyàn pẹ̀lú pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá rí àwọsánmọ̀ tí ó ṣú ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, lọ́gán ni ẹ̀yin yóò sọ pé, ‘Ọ̀wààrà òjò ń bọ̀,’ a sì rí bẹ́ẹ̀.
55 [In this region], when the wind blows from the south, you say, ‘It is going to be a very hot day!’ and that is what happens.
Nígbà tí afẹ́fẹ́ gúúsù bá ń fẹ́, ẹ̀yin á ní, ‘Oòrùn yóò mú,’ yóò sì ṣe bẹ́ẹ̀.
56 You hypocrites! By observing the clouds and the wind, you are able to discern what is happening regarding [the weather]. It is disgusting that you are not able to discern [what God is doing] at this present time [RHQ]!
Ẹ̀yin àgàbàgebè! Ẹ̀yin le mòye ojú ọ̀run àti ti ayé. Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin kò mọ àkókò yìí?
57 (Each of you ought to determine now what is the right thing for you to do, [while you still have time to do that]!/Why cannot each of you determine what is the right [thing for you to do now while you still have time to do that]?) [RHQ]
“Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin tìkára yín kò fi ro ohun tí ó tọ́?
58 [If you do not do that, God will punish you] [MET]. [It will be like what happens when] someone takes one of you to court, saying that you [(sg)] have done something very bad. You should try to settle things with him while you are still on the way to the court. If he forces you to go to the judge, the judge will decide that you are guilty and put you into the hands of the court officer. Then that officer will put you in prison.
Nígbà tí ìwọ bá bá ọ̀tá rẹ lọ sọ́dọ̀ onídàájọ́, rí i pé o bá a parí ọ̀rọ̀ ní ọ̀nà kí ó má ba à fà ọ́ fún adájọ́, adájọ́ a fi ọ́ lé ẹ̀ṣọ́ lọ́wọ́, òun a sì tì ọ́ sínú túbú.
59 I tell you that if you go to prison, you will never get out, [because you will never be able to] pay every bit [of what the judge says you owe] [MET]. [Similarly, you ought to settle accounts with God before you die, too].”
Kí èmi wí fún ọ, ìwọ kì yóò jáde kúrò níbẹ̀, títí ìwọ ó fi san ẹyọ owó kan tí ó kù!”

< Luke 12 >