< Joshua 20 >

1 Then Yahweh said to Joshua,
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé,
2 “Tell the Israeli people that they should choose some cities to which people [can run] in order to be safe/protected, like I told Moses that they should do.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn yan àwọn ìlú ààbò, gẹ́gẹ́ bí mo ti pàṣẹ fún ọ láti ẹnu Mose,
3 If someone kills another person accidentally, not intending to kill that person, the one who killed that person may run/escape to one of these cities and be safe/protected from someone trying to get revenge for that person’s death [MTY].
kí ẹni tí ó bá ṣèèṣì pa ènìyàn tàbí tí ó bá pa ènìyàn láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ lè sálọ sí ibẹ̀, fún ààbò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó pa.
4 When the one who killed someone arrives at the gate of one of those cities, he must stop there and tell the leaders of the city what happened. [If they believe him], they must allow him to enter the city, and they must give him a place to live among them.
Nígbà tí ó bá sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí, yóò sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àtiwọ ibodè ìlú, kí ó sì ṣe àlàyé ara rẹ̀ ní iwájú àwọn àgbàgbà ìlú náà. Nígbà náà ni wọn yóò gbà á sí ìlú wọn, wọn yóò sì fun ní ibùgbé láàrín wọn.
5 If some relative of the one who was killed comes to that city to get revenge, the leaders of that city must not allow the relative to take the killer, because what happened was accidental. He did not hate that person and as a result deliberately kill him.
Bí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ bá ń lépa rẹ̀, wọn kò gbọdọ̀ fi àwọn ọ̀daràn náà lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ láìmọ̀, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
6 But the person who killed someone must stay in that city until the city judges put him on trial. [Only if the judges decide that the person who has run/escaped to their city did not deliberately kill the other person will they allow him to stay in that city], and he must stay there until the Supreme Priest dies. Then he may safely go back to his own town, [because the death of the Supreme Priest will be considered to atone/pay for the death of the person who was killed].”
Òun ó sì máa gbé inú ìlú náà, títí yóò fi jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn àti títí ikú olórí àlùfáà tí ó ń ṣiṣẹ́ ìsìn nígbà náà. Nígbà náà ó lè padà sí ilé rẹ̀ ní ìlú tí ó ti sá wá.”
7 So the Israelis chose these cities to be cities to which people could run to be safe/protected: Kedesh in the Galilee district in the hilly area where the tribe of Naphtali lived; Shechem in the hilly area where the tribe of Ephraim lived; Kiriath-Arba (which is [now named] Hebron) in the hilly area where the tribe of Judah lived;
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan Kedeṣi ní Galili ní ìlú òkè Naftali, Ṣekemu ní ìlú òkè Efraimu, àti Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) ní ìlú òkè Juda.
8 Bezer, on the east side of the Jordan [River] near Jericho, in the flat land in the desert where the tribe of Reuben lived; Ramoth in the Gilead [region] in the land where the tribe of Gad lived; and Golan in the Bashan region where the tribe of Manasseh lived.
Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani ti Jeriko, wọ́n ya Beseri ní aginjù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ẹ̀yà Reubeni, Ramoti ní Gileadi ní ẹ̀yà Gadi, àti Golani ní Baṣani ní ẹ̀yà Manase.
9 Any Israeli or any foreigner who lived among us, anyone who killed someone (accidentally/without planning to do it), was allowed to run to one of those cities, and be safe/protected from some relative of the person who died coming there and killing him to get revenge. He could stay in that city until there was a trial there [to decide whether he was telling the truth or not when he said that he did not plan to kill that person].
Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé ní àárín wọn tí ó ṣèèṣì pa ẹnìkan lè sálọ sí àwọn ìlú tí a yà sọ́tọ̀ wọ̀nyí, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má sì ṣe pa á kí ó to di àkókò tí yóò jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn.

< Joshua 20 >