< Joshua 14 >

1 Eleazar the Supreme Priest, Joshua, and the leaders of the [twelve] tribes repeated what land would be allotted to each of the Israeli tribes in Canaan.
Ìwọ̀nyí ni ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli gbà gẹ́gẹ́ bí ogún ní ilẹ̀ Kenaani, tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn agbo ilé Israẹli pín fún wọn.
2 Yahweh had told Moses many years previously in what way he wanted the division of the land to be decided. Moses had already declared that two and a half tribes would be allotted land on the east side of the Jordan [River]. Joseph had two sons, Manasseh and Ephraim. [Half of the tribe descended from Manasseh was allotted land on the east side of the Jordan, along with the tribes of Reuben and Gad]. The people belonging to the nine and a half other tribes [on the west side of the Jordan River] threw (lots/stones that had been marked) to decide which land each tribe would receive. The tribe of Levi was not allotted any land. They received only towns [that already existed], towns in which to live, and (pastures/fields of grass) for their animals.
Ìbò ni a fi pín ìní wọn fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án ààbọ̀ gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ọwọ́ Mose.
3
Mose ti fún àwọn ẹ̀yà méjì àti ààbọ̀ ní ogún wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi ni kò fi ìní fún ní àárín àwọn tí ó kù.
4
Àwọn ọmọ Josẹfu sì di ẹ̀yà méjì, Manase àti Efraimu. Àwọn ọmọ Lefi kò gba ìpín ní ilẹ̀ náà bí kò ṣe àwọn ìlú tí wọn yóò máa gbé, pẹ̀lú pápá oko tútù fún ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran wọn.
5
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli pín ilẹ̀ náà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
6 One day some men from the tribe of Judah went to Joshua while he and all the Israelis were at Gilgal. Among those men was Jephunneh’s son Caleb. He said to Joshua, “[I am sure that] you remember what Yahweh said to the prophet Moses about you and me when we were at Kadesh-Barnea.
Àwọn ọkùnrin Juda wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ní Gilgali. Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti wí fún un pé, “Ìwọ rántí ohun tí Olúwa sọ fún Mose ènìyàn Ọlọ́run ní Kadeṣi-Barnea nípa ìwọ àti èmi.
7 I was 40 years old at that time. Moses sent me [and you and some other men] to explore this land. When we returned, I gave to Moses a true report [IDM] about what we had seen.
Mo jẹ́ ọmọ ogójì ọdún nígbà tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa rán mi láti Kadeṣi-Barnea lọ rin ilẹ̀ náà wò. Mo sì mú ìròyìn wá fún un gẹ́gẹ́ bí o ti dá mi lójú,
8 The other men who went with us [gave a report that] caused the people to be afraid [IDM]. But I fully/completely believed [that] Yahweh [would enable us to take the land from the people who lived there].
ṣùgbọ́n àwọn arákùnrin mi tí wọ́n bá mi lọ mú àyà àwọn ènìyàn já. Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi fi gbogbo ọkàn tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run mi.
9 So on that day, Moses solemnly promised me, ‘[Some of] the land on which you walked will become yours. It will belong to your descendants forever. I am giving it to you because you fully trusted in Yahweh, my God.’
Ní ọjọ́ náà, Mose búra fún mi pé, ‘Ilẹ̀ tí ẹsẹ̀ rẹ ti rìn ni yóò jẹ́ ìní rẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ láéláé, nítorí pé ìwọ fi tọkàntọkàn wà pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run mi.’
10 “Now Yahweh has done for me what he promised. Forty-five years have passed since Moses said that to me during the time that we were wandering around in the desert. And just like Yahweh promised, he has kept me alive and well all during that time. Now I am eighty-five years old.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, kíyèsi i Olúwa dá mi sí gẹ́gẹ́ bí ó ti wí, láti ọdún márùndínláàádọ́ta yìí wá, láti ìgbà tí Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún Mose, nígbà tí Israẹli ń rìn kiri nínú aginjù, sì kíyèsi i nísinsin yìí, èmi nìyìí lónìí, ọmọ àrùndínláàdọ́rùn-ún ọdún.
11 I am as strong today as I was on the day that Moses sent me [to explore this land]. I am as ready to fight now as I was then.
Síbẹ̀ èmi ní agbára lónìí, bí ìgbà tí Mose rán mi jáde. Èmi sì ní agbára láti jáde fún ogun nísinsin yìí gẹ́gẹ́ bí mo ti wà ní ìgbà náà.
12 So please give me the hilly area that Yahweh promised to give to me at that time long ago. At that time, you heard [me say] that the Amalek people-group lived there. You heard me say that their cities were large, and they had walls around them [to protect them from attacks by their enemies]. But now, Yahweh will help me, and as a result I will force them to leave, just like Yahweh said would happen.”
Nísinsin yìí fi ìlú orí òkè fún mi èyí tí Olúwa ṣe ìlérí fún mi ní ọjọ́ náà. Ìwọ gbọ́ ní ìgbà náà pé àwọn ọmọ Anaki ti wà ní ibẹ̀, àti àwọn ìlú wọn tóbi, pé ó sì ṣe olódi, ṣùgbọ́n bí Olúwa ba fẹ́, èmi yóò lé wọn jáde, gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ.”
13 So Joshua [asked God to] bless Caleb, and he gave to Caleb [the city of] Hebron.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua súre fun Kalebu ọmọ Jefunne ó si fun un ní Hebroni ni ilẹ̀ ìní.
14 Previously that city was called Kiriath-Arba, because Arba was the greatest man among the Amalek people-group. Hebron still belongs to the descendants of Caleb, because Caleb completely/fully trusted in Yahweh, the God whom we Israelis [worship], and obeyed him. After that happened, there was (peace/no battles) in [Canaan] land [for many years].
Bẹ́ẹ̀ ni Hebroni jẹ́ ti Kalebu ọmọ Jefunne ará Kenissiti láti ìgbà náà, nítorí tí ó tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tọkàntọkàn.
(Hebroni a sì máa jẹ́ Kiriati-Arba ní ẹ̀yìn Arba, èyí tí ó jẹ́ ènìyàn ńlá nínú àwọn ọmọ Anaki.) Nígbà náà ni ilẹ̀ náà sinmi ogun.

< Joshua 14 >