< John 7 >

1 After those things happened, Jesus went around in Galilee [province]. He did not want to travel in Judea [province], because he knew that the Jewish [leaders there] were wanting to kill him.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Jesu ń rìn ní Galili, nítorí tí kò fẹ́ rìn ní Judea, nítorí àwọn Júù ń wá a láti pa.
2 But when the time of the Jewish celebration [called] ‘Celebration of [Living in] Shelters’ was near,
Àjọ àwọn Júù tí í ṣe àjọ àgọ́ súnmọ́ etílé tan.
3 Jesus’ [younger] brothers said to him, “[Since many people] here [have left you], you should leave and go to Judea [province and perform] some miracles there, so that your disciples may see them!
Nítorí náà, àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Lọ kúrò níhìn-ín yìí, kí o sì lọ sí Judea, kí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ pẹ̀lú lè fi iṣẹ́ rẹ hàn fún aráyé.
4 No one who wants to become famous does things secretly. [You say] you are doing these miracles, [so do some miracles there] so that everyone [MTY] can see them!”
Nítorí pé kò sí ẹnikẹ́ni tí í ṣe ohunkóhun níkọ̀kọ̀, tí òun tìkára rẹ̀ sì ń fẹ́ kí a mọ òun ní gbangba. Bí ìwọ bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí, fi ara rẹ hàn fún aráyé.”
5 [They said this critically], because even [though they were] his own [younger] brothers, they did not believe he [was from God].
Nítorí pé àwọn arákùnrin rẹ̀ pàápàá kò tilẹ̀ gbà á gbọ́.
6 So Jesus said to them, “It is not yet time for me [MTY] [to go to the celebration]. For you, any time is right [to go to the celebration].
Nítorí náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Àkókò gan an fún mi kò tí ì dé; fún ẹ̀yin, gbogbo àkókò ni ó dára fún yín.
7 [The people] [MTY] [who] ([do not believe in me/do not belong to God]) cannot hate you, but they hate me because I tell them that what they are doing is evil.
Ayé kò lè kórìíra yín; ṣùgbọ́n èmi ni ó kórìíra, nítorí tí mo jẹ́rìí gbé é pé, iṣẹ́ rẹ̀ burú.
8 You [(pl)] go ahead to the celebration. I am not going up [to Jerusalem] to the celebration [yet], because now is not the right time for me [to go].”
Ẹ̀yin ẹ gòkè lọ sí àjọ yìí, èmi kì yóò tí ì gòkè lọ sí àjọ yìí; nítorí tí àkókò mi kò ì tí ì dé.”
9 After he said that, Jesus stayed [a little longer] in Galilee.
Nígbà tí ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún wọn tan, ó dúró ní Galili síbẹ̀.
10 However, [a few days] after his younger brothers left to go up to the celebration, he went also. He went, along with [us] disciples, but no others went with us.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ gòkè lọ tan, nígbà náà ni òun sì gòkè lọ sí àjọ náà pẹ̀lú, kì í ṣe ní gbangba, ṣùgbọ́n bí ẹni pé níkọ̀kọ̀.
11 At the celebration, the Jewish [leaders] were looking for him. They were asking people, “Has Jesus come?”
Nígbà náà ni àwọn Júù sì ń wá a kiri nígbà àjọ wí pé, “Níbo ni ó wà?”
12 Among the crowds, many people were whispering about Jesus. Some were saying, “He is a good man!” But others were saying instead, “No! He is deceiving the crowds!”
Ìkùnsínú púpọ̀ sì wà láàrín àwọn ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀, nítorí àwọn kan wí pé, “Ènìyàn rere ní í ṣe.” Àwọn mìíràn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n òun ń tan ènìyàn jẹ ni.”
13 But no one was speaking so that others could hear them, because they were afraid of the Jewish [leaders] [SYN].
Ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ ní gbangba nítorí ìbẹ̀rù àwọn Júù.
14 In the middle of the days of the celebration, Jesus went to the Temple [courtyard] and began to teach people.
Nígbà tí àjọ dé àárín; Jesu gòkè lọ sí tẹmpili ó sì ń kọ́ni.
15 The Jewish [elders] were amazed [at what he was saying]. They said, “This man never studied [in one of our religious schools]! So (how can he have learned [so much about Scripture]?/it is difficult for us to believe that he has learned [so much about Scripture]!) [RHQ]”
Ẹnu sì ya àwọn Júù, wọ́n wí pé, “Ọkùnrin yìí ti ṣe mọ ìwé, nígbà tí kò kọ́ ẹ̀kọ́?”
16 Jesus replied to them, “What I teach does not come from myself. It comes from [God], the one who sent me.
Jesu dáhùn, ó sì wí pé, “Ẹ̀kọ́ mi kì í ṣe tèmi, bí kò ṣe ti ẹni tí ó rán mi.
17 Those who choose to do what God wants will find out whether what I teach comes from God or whether I am speaking with [only] my own [authority].
Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀ yóò mọ̀ ní ti ẹ̀kọ́ náà, bí ìbá ṣe ti Ọlọ́run, tàbí bí èmi bá sọ ti ara mi.
18 Those who speak with [only] their own [authority] do that [only] so that others will honor them. But I am [doing things so that others] will honor the one who sent me, and I am someone who speaks the truth. I never lie.
Ẹni tí ń sọ ti ara rẹ̀ ń wá ògo ara rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ń wá ògo ẹni tí ó rán an, òun ni olóòtítọ́, kò sì sí àìṣòdodo nínú rẹ̀.
19 [Think about] the laws that Moses gave you [RHQ]. None of you [completely] obeys those laws. So why are you trying to kill me, [saying I do not obey the laws concerning] ([the Sabbath/the Jewish day of rest])?”
Mose kò ha fi òfin fún yín, kò sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí ó pa òfin náà mọ́? Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá ọ̀nà láti pa mí?”
20 Someone in the crowd answered, “[By saying this you show that] you are crazy (OR, A demon is controlling you)! Certainly no one is trying to kill you!”
Ìjọ ènìyàn dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Ìwọ ní ẹ̀mí èṣù, ta ni ń wá ọ̀nà láti pa ọ́?”
21 Jesus replied to them, “Because I did a miracle [of healing someone] (on the Sabbath/on the Jewish rest day), you are all shocked.
Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Kìkì iṣẹ́ àmì kan ni mo ṣe, ẹnu sì ya gbogbo yín.
22 Moses gave you [a law that you must] circumcise [the male children and that you must do that exactly seven days after they are born. Actually], it was your ancestors, [Abraham and Isaac and Jacob], not Moses, who [started that ritual]. But because of that law, you sometimes circumcise them (on the Sabbath/on the Jewish rest day), [but that is working, too]
Síbẹ̀, nítorí pé Mose fi ìkọlà fún yín (kò tilẹ̀ kúkú wá láti ọ̀dọ̀ Mose bí kò ṣe láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá yín); nítorí náà ẹ sì ń kọ ènìyàn ní ilà ní ọjọ́ ìsinmi.
23 You [sometimes] circumcise boys (on the Sabbath/on the Jewish rest day) so that the law of Moses is not disobeyed {[you] do not disobey the law of Moses}, so (it is ridiculous that you are angry with me, saying [I worked] (on the Sabbath/on the Jewish rest day) by healing a man!/why are you angry with me, saying [I worked] (on the Sabbath/on the Jewish rest day) by healing a man?) [RHQ] [Healing someone is far more helpful than circumcising a baby boy]!
Bí ènìyàn bá ń gba ìkọlà ní ọjọ́ ìsinmi, kí a má ba à rú òfin Mose, ẹ ha ti ṣe ń bínú sí mi, nítorí mo mú ènìyàn kan láradá ní ọjọ́ ìsinmi?
24 Stop deciding whether my healing this man is wrong according to what you see! Instead, decide according to what is really the right action [to help people]”!
Ẹ má ṣe ìdájọ́ nípa ti ara, ṣùgbọ́n ẹ máa ṣe ìdájọ́ òdodo.”
25 Some of the people from Jerusalem were saying, “(This is the man that they are trying to kill!/Isn’t this the man that they are trying to kill?) [RHQ]
Nígbà náà ni àwọn kan nínú àwọn ará Jerusalẹmu wí pé, “Ẹni tí wọ́n ń wá ọ̀nà láti pa kọ́ yìí?
26 He is saying these things (publicly/in front of many people), but our [Jewish] rulers are not saying anything to [oppose] him. Is that because they have decided that he is truly (the Messiah/God’s chosen king)?
Sì wò ó, ó ń sọ̀rọ̀ ní gbangba, wọn kò sì wí nǹkan kan sí i. Àwọn olórí ha mọ̀ nítòótọ́ pé, èyí ni Kristi náà?
27 But [he cannot be the Messiah, because] we know where this man came from. When the Messiah really comes, no one will know where he comes from.”
Ṣùgbọ́n àwa mọ ibi tí ọkùnrin yí gbé ti wá, ṣùgbọ́n nígbà tí Kristi bá dé, kò sí ẹni tí yóò mọ ibi tí ó gbé ti wá.”
28 [They said that because they thought Jesus was born in Nazareth]. So while Jesus was teaching [people] in the Temple [courtyard], he shouted, “Yes, [you say that] you know me, and [you think] you know [IRO] where I am from. But I have come here not (because I appointed myself/with my own authority). Instead, [God] is the one who truly sent me. You do not know him.
Nígbà náà ni Jesu kígbe ní tẹmpili bí ó ti ń kọ́ni, wí pé, “Ẹ̀yin mọ̀ mí, ẹ sì mọ ibi tí mo ti wá, èmi kò sì wá fún ara mi, ṣùgbọ́n olóòtítọ́ ni ẹni tí ó rán mi, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀.
29 But I know him, because I have come from him. He is the one who sent me!”
Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ̀ ni mo ti wá, òun ni ó rán mi.”
30 Then they tried to seize him [because he said that he had come from God]. But no one put their hands on him [to do that], because it was not yet the time [MTY] [for him to die].
Nítorí náà wọ́n ń wá ọ̀nà à ti mú un, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e, nítorí tí wákàtí rẹ̀ kò tí ì dé.
31 But many of the crowd believed that he [had come from God]. They said, “When the Messiah comes, he certainly will not do more miracles than this man has done, will he?”
Ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn sì gbà á gbọ́, wọ́n sì wí pé, “Nígbà tí Kristi náà bá dé, yóò ha ṣe iṣẹ́ àmì jù wọ̀nyí, tí ọkùnrin yìí ti ṣe lọ?”
32 The Pharisees heard them whispering these things about him. So they and the chief priests sent some Temple guards to seize him.
Àwọn Farisi gbọ́ pé, ìjọ ènìyàn ń sọ nǹkan wọ̀nyí lábẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀; àwọn Farisi àti àwọn olórí àlùfáà sì rán àwọn oníṣẹ́ lọ láti mú un.
33 Then Jesus said, “I will be with you for only a short time. Then I will return to the one who sent me.
Nítorí náà Jesu wí fún wọn pé, “Níwọ́n ìgbà díẹ̀ ni èmi yóò wà pẹ̀lú yín, èmi yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó rán mi.
34 Then you will search for me, but you will not find me. And you will not be able to come to the place where I am.”
Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi, àti ibi tí èmi bá wà, ẹ̀yin kì yóò le wà.”
35 So the Jewish [leaders] [SYN] said to themselves, “Where is this man about to go with the result that we will not be able to find him? [Some Jewish people have] dispersed [and live] among Greek people. He is not intending to go [and live among them] and teach them, is he?
Nítorí náà ni àwọn Júù ń bá ara wọn sọ pé, “Níbo ni ọkùnrin yìí yóò gbé lọ tí àwa kì yóò fi rí i? Yóò ha lọ sí àárín àwọn Helleni tí wọ́n fọ́n káàkiri, kí ó sì máa kọ́ àwọn Helleni bí.
36 When he said ‘You will search for me, but you will not be able to find me,’ and when he said ‘You will not be able to come to the place where I am,’ what [did he mean]?”
Ọ̀rọ̀ kín ni èyí tí ó sọ yìí, ‘Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ kì yóò sì rí mi,’ àti ‘Ibi tí èmi bá wà ẹ̀yin kì yóò le wà’?”
37 [On each of the seven days of the celebration, the high priest poured out some water on the altar in the Temple to remember how God provided water for the people in the desolate area long ago. But the water he poured did not help anyone who was thirsty. So] on the last day of the festival, which was the most important day, Jesus stood up [in the Temple courtyard] and said with a loud voice, “Those who are thirsty should come to me to drink [what I will give them].
Lọ́jọ́ tó kẹ́yìn, tí í ṣe ọjọ́ ńlá àjọ, Jesu dúró, ó sì kígbe wí pé, “Bí òǹgbẹ bá ń gbẹ ẹnikẹ́ni, kí ó tọ̀ mí wá, kí ó sì mu.
38 Just like the Scriptures teach, streams of water shall flow out from within those who believe in me, and that water will cause them to live [eternally].”
Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí gbọ́ gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ ti wí, láti inú rẹ̀ ni odò omi ìyè yóò ti máa sàn jáde wá.”
39 When Jesus said that, he was referring to [God’s] Spirit, whom those who believed in Jesus would receive later. Up to that time God had not sent the Spirit [to live within believers], because Jesus had not yet [died and returned to his] glorious [home in] heaven, [from where he would send the Spirit].
Ṣùgbọ́n ó sọ èyí ní ti ẹ̀mí, tí àwọn tí ó gbà á gbọ́ ń bọ̀ wá gbà, nítorí a kò tí ì fi Èmí Mímọ́ fún ni; nítorí tí a kò tí ì ṣe Jesu lógo.
40 When some of the crowd heard those words, they said, “Surely this man is the prophet [whom God promised to send who would be like Moses]!”
Nítorí náà, nígbà tí ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, wọ́n wí pé, “Lóòótọ́ èyí ni wòlíì náà.”
41 Others said, “He is the Messiah!” But others, [thinking Jesus was born in Galilee], said, “The Messiah will not come from Galilee [province], will he?
Àwọn mìíràn wí pé, “Èyí ni Kristi náà.” Ṣùgbọ́n àwọn kan wí pé kínla, “Kristi yóò ha ti Galili wá bí?
42 (Did [a prophet] not write in the Scriptures that the Messiah will come from [King] David’s family, and be born in Bethlehem, where [King] David lived?/[It is written] in the Scriptures that the Messiah will come from [King] David’s family, and be born in Bethlehem, where [King] David lived!) [RHQ]”
Ìwé mímọ́ kò ha wí pé, Kristi yóò ti inú irú-ọmọ Dafidi wá, àti Bẹtilẹhẹmu, ìlú tí Dafidi ti wá?”
43 So the people were divided because of [what they thought about] Jesus.
Bẹ́ẹ̀ ni ìyapa wà láàrín ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀.
44 Some people wanted to seize him, but no one tried [to do that].
Àwọn mìíràn nínú wọn sì fẹ́ láti mú un; ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e.
45 So the Temple guards returned to the chief priests and the Pharisees, [the ones who had sent them to arrest Jesus]. They said to the guards, “Why did you not [seize him and] bring him [here]?”
Ní ìparí, àwọn ẹ̀ṣọ́ tẹmpili padà tọ àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisi lọ, wọ́n sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi mú un wá?”
46 They replied, “No one ever spoke such [amazing things] as this man does!”
Àwọn ẹ̀ṣọ́ dáhùn wí pé, “Kò sí ẹni tí ó tí ì sọ̀rọ̀ bí ọkùnrin yìí rí!”
47 Then the Pharisees replied, “Have you been deceived {Has [he] deceived you}, too?
Nítorí náà àwọn Farisi dá wọn lóhùn pé, “A ha tan ẹ̀yin jẹ pẹ̀lú bí?
48 (None of our rulers nor any of us Pharisees have believed that (he [is the Messiah]!/he [came from God]!)/Have any of our [Jewish] rulers or any of us Pharisees believed that (he [is the Messiah]?/he [came from God]?)) [RHQ]
Ǹjẹ́ nínú àwọn ìjòyè, tàbí àwọn Farisi ti gbà á gbọ́ bí?
49 Not one! But, on the contrary, some of this crowd [have believed in him]. They do not know [the true teachings of] our laws! They will go to hell [for listening to him]!” (questioned)
Ṣùgbọ́n ìjọ ènìyàn yìí, tí ko mọ òfin di ẹni ìfibú.”
50 Then Nicodemus spoke. He was the one who earlier went to Jesus [at night]. He was also a member of the Jewish council. He said to [the rest of the Council members],
Nikodemu ẹni tí ó tọ Jesu wá lóru rí, tí ó sì jẹ́ ọ̀kan nínú wọn sì sọ fún wọn pé,
51 “[We] have not listened to what he says to find out what he is doing. (It is not permitted in our [Jewish] law [PRS] for us to say, before questioning someone, that we must punish him!/Is it permitted in our [Jewish] law [PRS] for us to say, before questioning someone, that we must punish him?) [RHQ]”
“Òfin wa ha ń ṣe ìdájọ́ ènìyàn kí ó tó gbọ́ ti ẹnu rẹ̀ àti kí ó tó mọ ohun tí ó ṣe bí?”
52 They replied to him, “(Are you another [disgusting person] from Galilee?/[You talk like] another [disgusting person] from Galilee!) [RHQ] Read [what is written in the Scriptures] You will find that no prophet comes from Galilee [province, like he does]!”
Wọ́n dáhùn wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ pẹ̀lú wá láti Galili bí? Wá kiri, kí o sì wò nítorí kò sí wòlíì kan tí ó ti Galili dìde.”
53 [Then they all left and went to their own homes.
Wọ́n sì lọ olúkúlùkù sí ilé rẹ̀.

< John 7 >