< John 14 >

1 [Jesus continued by saying to us], “Stop being anxious/worried. Keep on trusting in God (OR, You are trusting in God); also keep trusting in me.
“Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín kí ó dàrú, ẹ gba Ọlọ́run gbọ́, kí ẹ sì gbà mí gbọ́ pẹ̀lú.
2 Where my Father is [in heaven] there is plenty of room! If that were not true, I would have told you. I am about to go [there] to prepare a place for you.
Nínú ilé Baba mi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ibùgbé ni ó wà, ìbá má ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ìbá tí sọ fún yín. Èmi ń lọ láti pèsè ààyè sílẹ̀ fún yín.
3 And because I will go [there] and prepare a place for you, I will return and take you there to be with me. I will do that so that you may also be where I am.
Bí mo bá sì lọ láti pèsè ààyè sílẹ̀ fún un yín, èmi ó tún padà wá, èmi ó sì mú yín lọ sọ́dọ̀ èmi tìkára mi; pé níbi tí èmi gbé wà, kí ẹ̀yin lè wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
4 You know the road to the place where I am going.”
Ẹ̀yin mọ ibi tí èmi gbé ń lọ, ẹ sì mọ ọ̀nà náà.”
5 Thomas said to him, “Lord, we do not know where you are going. [So] how can we know the road?”
Tomasi wí fún un pé, “Olúwa, a kò mọ ibi tí ìwọ ń lọ, a ó ha ti ṣe mọ ọ̀nà náà?”
6 Jesus said to him, “I am the road [MET] [to where my Father is]. I am the [one who reveals] [MET] the truth [about God] and the [one who gives eternal] life [to people]. I am the only one who can [enable people] to come to [my] Father. There is no other way.
Jesu dá wọn lóhùn pé, “Èmi ni ọ̀nà, òtítọ́ àti ìyè, kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè wá sọ́dọ̀ Baba, bí kò ṣe nípasẹ̀ mi.
7 If you [really] knew who I was, you would have known my Father also. From now on, you know him, and [it is as though] you have seen him.”
Ìbá ṣe pé ẹ̀yin ti mọ̀ mí, ẹ̀yin ìbá ti mọ Baba mi pẹ̀lú, láti ìsinsin yìí lọ ẹ̀yin mọ̀ ọ́n, ẹ sì ti rí i.”
8 Philip said to him, “Lord, show us your Father and that will be enough for us!”
Filipi wí fún un pé, “Olúwa, fi Baba náà hàn wá, yóò sì tó fún wa.”
9 Jesus said to him, “Philip, I have been with you for a long time. So (surely you should know who I [really am]!/why have you not come to know who I [really am]?) [RHQ] Those who have seen me, [it is as though] they have seen [my] Father. So (why do you say ‘Show us [your] Father’?/you should not say ‘Show us [your] Father’!) [RHQ]
Jesu wí fún un pé, “Bí àkókò tí mo bá yín gbé ti tó yìí, ìwọ, kò sì tí ì mọ̀ mí síbẹ̀ Filipi? Ẹni tí ó bá ti rí mi, ó ti rí Baba. Ìwọ ha ti ṣe wí pé, ‘Fi Baba hàn wá!’
10 Do you not [RHQ] believe that I have a close relationship with [my] Father, and that [my] Father has a close relationship with me? The messages that I tell you do not come from me. They come from my Father, who has a close relationship with me. He is enabling me to [teach these things, and] to perform the miracles that he [wants me to perform].
Ìwọ kò ha gbàgbọ́ pé, èmi wà nínú Baba, àti pé Baba wà nínú mi? Ọ̀rọ̀ tí èmi ń sọ fún yín, èmi kò dá a sọ; ṣùgbọ́n Baba ti ó wà nínú mi, òun ní ń ṣe iṣẹ́ rẹ̀.
11 Believe that I have a close relationship with [my] Father and that [my] Father has a close relationship with me. If you do not believe that just because of what I say, believe it because of the miracles themselves [that I have done].
Ẹ gbà mí gbọ́ pé, èmi wà nínú Baba, Baba sì wà nínú mi, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ gbà mí gbọ́ nítorí àwọn ẹ̀rí iṣẹ́ náà pàápàá!
12 Listen to this carefully: [You] who trust in me will do the [kinds of] miracles [that I have done]. [Because of what I will do for you] (OR, [Because I will send God’s Spirit to you]) after I go to my Father, you will be able to do [miracles] that will be greater than [the ones I have done].
Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́, iṣẹ́ tí èmi ń ṣe ni òun yóò ṣe pẹ̀lú; iṣẹ́ tí ó tóbi ju wọ̀nyí lọ ni yóò sì ṣe; nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba.
13 And whatever you, using my authority, ask me to do, I will do it, in order that I can show [you] how great [my] Father is.
Ohunkóhun tí ẹ̀yin bá sì béèrè ní orúkọ mi, òun náà ni èmi ó ṣe, kí a lè yin Baba lógo nínú Ọmọ.
14 Anything that you ask [my Father to do, anything that you ask] with my [authority] [MTY], I will do.”
Bí ẹ̀yin bá béèrè ohunkóhun ní orúkọ mi, èmi ó ṣe é.
15 “If you love me, you will do what I have commanded you.
“Bí ẹ̀yin bá fẹ́ràn mi, ẹ ó pa òfin mi mọ́.
16 Then I myself will request [my] Father, and he will send you someone else who will (encourage/be like a legal counsel for) you. (aiōn g165)
Nígbà náà èmi yóò wá béèrè lọ́wọ́ Baba. Òun yóò sì fún yín ní olùtùnú mìíràn. Olùtùnú náà yóò máa bá yín gbé títí láé. (aiōn g165)
17 [I am talking about] the Spirit, who [will teach you God’s] truth. He will be with you forever. Those who are opposed to God [MTY] cannot receive him, because they cannot understand what he [does], and they cannot know who he is. But you know who he is, because he is with you and he will be inside you.
Òun ni Ẹ̀mí òtítọ́. Ayé kò le gbà á. Nítorí ayé kò mọ̀ ọ́n, bẹ́ẹ̀ ni kò rí i rí. Ẹ̀yin mọ̀ ọn nítorí láti ìgbà tí ẹ ti wà pẹ̀lú mí. Òun náà ti wà pẹ̀lú yín. Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kan yóò wọ inú yín láti máa gbé ibẹ̀.
18 [When I leave you], I will not let you be alone/helpless [MET]. [When I send the Spirit, it will be like] I am coming back to you (OR, [When I rise from the dead], I will come back to you.)
Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìní Olùtùnú, kí ẹ ma dàbí ọmọ tí kò ní òbí. Rárá o! Mo tún ń tọ̀ yín bọ̀.
19 Soon those who do not belong to God [MTY] will not see me any more. But [when the Spirit comes to you, it will be as though] you will be seeing me again (OR, But [after I become alive again], you will see me again.) Because I will be alive again, you also will have [eternal] life.
Nígbà díẹ̀ sí i, ayé kì yóò rí mi mọ́; ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò rí mi, nítorí tí èmi wà láààyè, ẹ̀yin yóò wà láààyè pẹ̀lú.
20 At that time you will know that I have a close relationship with my Father, and you will have a close relationship with me, and I will have a close relationship with you.
Ní ọjọ́ náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi wà nínú Baba mi, àti ẹ̀yin nínú mi, àti èmi nínú yín.
21 Those who have accepted my commands and obey them are the people who love me. My Father will love those who love me. I also will love them, and I will fully reveal to them [what I am like].”
Ẹni tí ó bá ní òfin mi, tí ó bá sì ń pa wọ́n mọ́, òun ni ẹni tí ó fẹ́ràn mi, ẹni tí ó bá sì fẹ́ràn mi, a ó fẹ́ràn rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Baba mi, èmi ó sì fẹ́ràn rẹ̀, èmi ó sì fi ara mi hàn fún un.”
22 Then Judas spoke to him. He was not Judas Iscariot (OR, Judas, the man from Kerioth [Town]), [but instead a disciple whose other name was Thaddeus]. He said, “Lord, what has happened so that you can fully reveal to us what you are like, and not reveal that to those who do not belong to God [MTY]?”
Judasi (kì í ṣe Judasi Iskariotu) wí fún un pé, “Olúwa, èéha ti ṣe tí ìwọ ó fi ara rẹ hàn fún àwa, tí kì yóò sì ṣe fún aráyé?”
23 Jesus replied to him, “Those who love me will obey what I have told them. My Father will [also] love them. It is those people whom my Father and I will [be able to] come to and (live with/have a personal relationship with).
Jesu dáhùn ó sì wí fún un pé, “Bí ẹnìkan bá fẹ́ràn mi, yóò pa ọ̀rọ̀ mi mọ́. Baba mi yóò sì fẹ́ràn rẹ̀, àwa ó sì tọ̀ ọ́ wá, a ó sì ṣe ibùgbé wa pẹ̀lú rẹ̀.
24 But those who do not love me will not obey what I have told them. [So I cannot reveal to them what I am really like]. These words that I am telling you have not come just from me. They came from [my] Father, the one who sent me.
Ẹni tí kò fẹ́ràn mi ni kò pa ọ̀rọ̀ mi mọ́. Ọ̀rọ̀ tí ẹ̀yin ń gbọ́ kì í ṣe ti èmi, ṣùgbọ́n ti Baba tí ó rán mi.
25 I have told you all these things while I am still with you.
“Nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti sọ fún yín, nígbà tí mo ń bá yín gbé.
26 But [my] Father will send the Holy Spirit. He is the one who will (encourage/be like a legal counsel for) you. He will come with my authority [MTY]. He will teach you all of [God’s truth that you need to know]. He will also cause you to remember all the things that I have told you.
Ṣùgbọ́n Olùtùnú náà, Ẹ̀mí Mímọ́, ẹni tí Baba yóò rán ní orúkọ mi, òun ni yóò kọ́ yín ní ohun gbogbo, yóò sì rán yín létí ohun gbogbo tí mo ti sọ fún yín.
27 As I leave you, I am causing you to have [inner] peace. This [inner] peace comes from me. I am not causing you to have something that those who do not belong to God [MTY] can give you. [So] stop being anxious/worried, and do not be afraid.
Àlàáfíà ni mo fi sílẹ̀ fún yín pé, àlàáfíà mi ni mo fi fún yin, kì í ṣe bí ayé ti fi fún ni. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín dàrú, ẹ má sì jẹ́ kí ó wárìrì.
28 You heard me say to you, ‘I am going away, but [later] I will come back to you.’ If you loved me, you would be glad that I am going back to [my] Father, because [my] Father is greater than I am, [and there he will honor me and will send the Spirit to you].
“Ẹ̀yin sá ti gbọ́ bí mo ti wí fún yín pé, ‘Èmi ń lọ, èmi ó sì tọ̀ yín wá.’ Ìbá ṣe pé ẹ̀yin fẹ́ràn mi, ẹ̀yin ìbá yọ̀ nítorí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba; nítorí Baba mi tóbi jù mí lọ.
29 I have told you [these things now] before they happen, so that when they happen you will believe [that what I said is true].
Èmi sì ti sọ fún yín nísinsin yìí kí ó tó ṣẹ, pé nígbà tí ó bá ṣẹ, kí ẹ lè gbàgbọ́.
30 I will not [be able to] talk to you much longer, because what happens to me will be as though [Satan], the ruler of this world, is coming [to attack me]. But he has no [control over what happens to] me.
Èmi kì yóò bá yín sọ̀rọ̀ púpọ̀, nítorí ọmọ-aládé ayé yí wá, kò sì ní nǹkan kan lòdì sí mi.
31 Instead, the people who do not belong to God [MTY] must learn [from what happens to me] that I love [my] Father, and I am doing the things that he has commanded me to do. Now, let’s get up and leave here.”
Ṣùgbọ́n nítorí kí ayé lè mọ̀ pé èmi fẹ́ràn Baba; gẹ́gẹ́ bí Baba sì ti fi àṣẹ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi ń ṣe. “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a lọ kúrò níhìn-ín yìí.

< John 14 >