< Job 17 >

1 “My (life/time to live) is almost ended; I have no strength left; my grave is waiting for me.
“Ẹ̀mí mi bàjẹ́, ọjọ́ mi ni a ti gé kúrú, isà òkú dúró dè mí.
2 Those who are around me are making fun of me; I [SYN] watch them while they (taunt/make fun of) me.”
Nítòótọ́ àwọn ẹlẹ́yà wà lọ́dọ̀ mi, ojú mi sì tẹ̀mọ́ ìmúnibínú wọn.
3 “God, [it is as though I am in prison; ] please pay the money in order that I may be released, because there is certainly no one else who will help me.
“Fi fún mi Olúwa, ìlérí tí ìwọ fẹ́; ta ni yóò le ṣe ààbò fún mi?
4 You have prevented my friends from understanding [what is true about me]; do not allow them to triumph over me, [saying that I have done things that are wrong].
Nítorí pé ìwọ ti sé wọ́n láyà kúrò nínú òye; nítorí náà ìwọ kì yóò gbé wọn lékè.
5 [Our ancestors often said, ‘It often happens that] when someone betrays his friends in order to get some of their property, it is that person’s children who will be punished for it;’ [so I desire/hope that will be true of these friends of mine who are lying about me].
Ẹni tí ó sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn dídún fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ fún èrè, òun ni ojú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò mú òfo.
6 “But now people use that saying of our ancestors when they talk about me; they spit in my face [to insult me].
“Ọlọ́run ti sọ mi di ẹni òwe fún àwọn ènìyàn; níwájú wọn ni mo dàbí ẹni ìtutọ́ sí ní ojú.
7 (My sight has become dim/I cannot see well) because I am extremely sad, and my arms and legs are [very thin, with the result that they almost do not cast] [MET] a shadow.
Ojú mí ṣú bàìbàì nítorí ìbìnújẹ́, gbogbo ẹ̀yà ara mi sì dàbí òjìji.
8 Those who [say that they] are good/righteous are shocked [when they see what has happened to me], and people who [say that they] (are innocent/have not done anything that is wrong) say that I am wicked/godless and should be punished.
Àwọn olódodo yóò yanu sí èyí, ẹni aláìṣẹ̀ sì bínú sí àwọn àgàbàgebè.
9 Those who [claim that they] are righteous will continue to do what [they think] is right, and those [who say] they have not sinned will continue to become stronger.
Olódodo pẹ̀lú yóò di ọ̀nà rẹ̀ mú, àti ọlọ́wọ́ mímọ́ yóò máa lera síwájú.
10 “But even if all of those people came [and stood in front of me], I would not find anyone among them who is wise.
“Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti gbogbo yín, ẹ yípadà, kí ẹ si tún padà nísinsin yìí; èmi kò le rí ọlọ́gbọ́n kan nínú yín.
11 My (life/time to live) is almost ended; I have not been able to do the things that I confidently expected to do; [I have not been able to accomplish] anything that I [SYN] desired.
Ọjọ́ tí èmi ti kọjá, ìrò mi ti fà yá, àní ìrò ọkàn mi.
12 My friends do not know when it is night and when it is day; when it is night, they claim that it is daylight; when it is becoming dark, they claim it is becoming light.
Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń ṣọ́ òru di ọ̀sán; wọ́n ní, ìmọ́lẹ̀ súnmọ́ ibi tí òkùnkùn dé.
13 If my home will be the place where dead people are, where will I sleep in the darkness? (Sheol h7585)
Bí mo tilẹ̀ ní ìrètí, ipò òku ní ilé mi; mo ti tẹ́ ibùsùn mi sínú òkùnkùn. (Sheol h7585)
14 I may say to the grave, ‘You will be [like] a father to me,’ and say to the maggots [that will eat my body], ‘You will be [like] a mother or younger sisters to me [because you will be where I will always be].’
Èmi ti wí fún ìdíbàjẹ́ pé, ìwọ ni baba mi, àti fún kòkòrò pé, ìwọ ni ìyá mi àti arábìnrin mi,
15 But if I say those things, (will there be anything good that I can confidently expect to happen to me?/there will be nothing good that I can confidently expect to happen to me.) [RHQ] (Is there anyone who knows anything good that I can expect when I am in the grave?/No one knows anything good that I can expect when I am in the grave.) [RHQ]
ìrètí mi ha dà nísinsin yìí? Bí ó ṣe ti ìrètí mi ni, ta ni yóò rí i?
16 After I descend to the place where the dead are, (will I be able to confidently expect anything good there?/I certainly will not be able to confidently expect anything good there.) [RHQ] [It will be as though] [RHQ] I and the things I hope for will descend with me into the dust [where the dead are].” (Sheol h7585)
Yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ipò òkú, nígbà tí a jùmọ̀ sinmi pọ̀ nínú erùpẹ̀ ilẹ̀?” (Sheol h7585)

< Job 17 >