< Jeremiah 39 >

1 After King Zedekiah had been ruling Judah for almost nine years, King Nebuchadnezzar came in January with his army, and they surrounded Jerusalem.
Ó sì ṣe, nígbà tí a kó Jerusalẹmu, ní ọdún kẹsànán Sedekiah, ọba Juda, nínú oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli gbógun ti Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, wọ́n sì dó tì í.
2 One and a half years later, after Zedekiah had been ruling for almost eleven years, on July 18, [soldiers from Babylonia] broke through the city [wall. Then they rushed in and captured the city].
Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù kẹrin ọdún kọkànlá Sedekiah, ni a wó odi ìlú náà.
3 Then all the officers of the king of Babylon came in and sat down at the Middle Gate [to decide what they would do to the city. They included] Nergal-Sharezer from Samgar, Nebo-Sarsekim who was one of the chief army officers, another Nergal-Sharezer, the king’s advisor, and many other officials.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli wá, wọ́n sì jókòó ní àárín ẹnu ibodè, àní Nergali-Ṣareseri ti Samgari, Nebo-Sarsikimu olórí ìwẹ̀fà, Nergali-Ṣareseri, olórí amòye, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli yóò kú.
4 When King Zedekiah and all his soldiers realized that [the army of Babylonia had broken into the city], they fled. [They waited until] it was dark. Then they went out of the city through the king’s garden, through the gate that was between the two walls. Then they started [running] toward the Jordan River Valley.
Nígbà tí Sedekiah ọba Juda àti àwọn ọmọ-ogun rí wọn, wọ́n sá, wọ́n kúrò ní ìlú ní alẹ́, wọ́n gba ọ̀nà ọgbà ọba lọ láàrín ẹnu ibodè pẹ̀lú odi méjì, wọ́n dojúkọ aginjù.
5 But the soldiers from Babylonia pursued the king, and they caught him on the plains near Jericho. They took him to the King of Babylon, who was at Riblah [town] in the Hamath [region]. There the king of Babylon told [his soldiers what] they should do to punish Zedekiah.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Babeli lé wọn, wọ́n bá Sedekiah láàrín aginjù Jeriko. Wọ́n mú un ní ìgbèkùn, wọ́n sì mú u tọ Nebukadnessari ọba Babeli àti Ribla ní ilẹ̀ Hamati, níbi tí wọ́n ti ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
6 They forced Zedekiah to watch while they killed his sons and all the officials from Judah.
Níbẹ̀ ní Ribla, ni ọba Babeli ti dúńbú àwọn ọmọ Sedekiah lójú rẹ̀, tí ó sì tún pa gbogbo àwọn ọlọ́lá ilẹ̀ Juda.
7 [Then] they gouged out Zedekiah’s eyes. They fastened him with bronze chains and took him to Babylon.
Nígbà náà ni ó fọ́ ojú Sedekiah, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti gbé e lọ sí ilẹ̀ Babeli.
8 [Meanwhile, ] the Babylonian army burned the palace and all the other buildings in Jerusalem. And they tore down the city walls.
Àwọn Babeli dáná sun ààfin ọba àti ilé àwọn ènìyàn, wọ́n sì wó odi Jerusalẹmu.
9 Then Nebuzaradan, the captain of the [king’s] bodyguards, forced to go to Babylon [most of] the other people who remained in the city and the Jews who had joined the soldiers of Babylonia.
Nebusaradani olórí àwọn ọmọ-ogun mú lọ sí ìgbèkùn Babeli pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú ìlú.
10 But he allowed some of the very poor people to remain in Judah, and he gave them vineyards and fields [to take care of].
Ṣùgbọ́n Nebusaradani olórí ogun fi àwọn aláìní sílẹ̀ ní Juda, àwọn tí kò ní ohun kankan ní àkókò náà, ó fún wọn ní ọgbà àjàrà àti oko.
11 King Nebuchadnezzar had [previously] told Nebuzaradan to find me. He said,
Nísinsin yìí, Nebukadnessari ọba àwọn Babeli pàṣẹ lórí Jeremiah, láti ọ̀dọ̀ Nebusaradani olórí ogun wá wí pé:
12 “Make sure that no one harms him. Take care of him, and do for him whatever he requests you to do.”
“Ẹ gbé e, kí ẹ sì bojútó o. Ẹ má ṣe ṣe ohun búburú fún un, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá béèrè ni kí ẹ fi fún un.”
13 So he and Nebushazban, who was one of their chief officers, and Nergal-Sharezer the king’s advisor, and other officers of the King of Babylon
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú, Nebusaradani balógun ìṣọ́, àti Nebusaradani olórí ìwẹ̀fà, àti Nergali-Ṣareseri, olórí amòye àti gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli,
14 sent [some men] to bring me out of the courtyard outside of the palace. They took me to Gedaliah who was the son of Ahikam and grandson of Shaphan. Then Gedaliah took me to my home, and I stayed [in Judah] among [my own] people [who had been allowed to remain there].
ránṣẹ́ láti mú Jeremiah kúrò nínú túbú. Wọ́n gbé e lọ fún Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani láti mú padà lọ sí ilé àti máa wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 While I was [still] being guarded in the palace courtyard, Yahweh gave me this message:
Nígbà tí Jeremiah wà nínú túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá wí pé:
16 “Say this to Ebed-Melech, the official from Ethiopia: ‘This is what the Commander of the armies of angels, the God whom [we] Israelis [worship], says: “I will do to this city everything that I said that I would do. I will not enable the people to prosper; I will cause them to experience disasters. You will see Jerusalem being destroyed,
“Lọ sọ fún Ebedimeleki ará Kuṣi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi ṣetán láti mú ọ̀rọ̀ mi ṣẹ lórí ìlú yìí nípa àjálù kì í ṣe àlàáfíà. Ní àkókò náà ni yóò ṣẹ lójú rẹ.
17 but I will rescue you from the people whom you are afraid of.
Ṣùgbọ́n, Èmi yóò gbà ọ́ lọ́jọ́ náà ni Olúwa wí. A kò ní fi ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí o bẹ̀rù.
18 You trusted me, so I will save you. You will not be killed by [your enemies’] swords; you will remain alive. [That will surely happen because I], Yahweh, have said it.’”
Èmi yóò gbà ọ́ là; o kò ní ṣubú láti ipa idà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ, nítorí pé ìwọ ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú mi, ni Olúwa wí.’”

< Jeremiah 39 >