< Jeremiah 3 >

1 “[Moses wrote that] if a man divorces his wife and then she marries another man, her first husband certainly must not [RHQ] take her back again [to be his wife], because that would certainly [RHQ] cause the whole nation to become unacceptable to me. But you have more [idols than] prostitutes have men whom they have slept with! So, [why should I accept you if] you return to me?” [RHQ] says Yahweh.
“Bí ọkùnrin kan bá sì kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ tí obìnrin náà sì lọ fẹ́ ọkọ mìíràn, ǹjẹ́ ọkùnrin náà tún lè tọ̀ ọ́ wá? Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kò ní di aláìmọ́ bí? Ṣùgbọ́n ìwọ ti gbé pẹ̀lú onírúurú panṣágà gẹ́gẹ́ bí olùfẹ́, ṣé ìwọ yóò tún padà sọ́dọ̀ mi bí?” ni Olúwa wí.
2 “Look up at the barren hilltops. On every hilltop there are [RHQ] [idols that you have worshiped]. [It is as though] they are all lovers with whom you have had sex. [It is as though] you have sat along the roadsides like an Arab, waiting [to attack and steal things from] those who pass by. Because of worshiping idols and all the other wicked things that you have done, you have caused the [entire] land to become unacceptable to me.
“Gbé ojú rẹ sókè sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, kí o sì wò ó ibi kan ha wà tí a kò bà ọ́ jẹ́? Ní ojú ọ̀nà, ìwọ jókòó de àwọn olólùfẹ́, bí i ará Arabia kan nínú aginjù, ìwọ sì ti ba ilẹ̀ náà jẹ́ pẹ̀lú ìwà àgbèrè àti ìwà búburú rẹ.
3 That is why I have not sent you any rain at the times of the year when you needed it. But you are like prostitutes [MET] who are not at all ashamed [for what they have done].
Nítorí náà, a ti fa ọ̀wààrà òjò sẹ́yìn, kò sì ṣí òjò àrọ̀kúrò. Síbẹ̀ ìwọ ní ojú líle ti panṣágà, ìwọ sì kọ̀ láti ní ìtìjú.
4 Now each of you says to me, ‘You are my father! You have loved me ever since I was young!
Ǹjẹ́ ìwọ kò ha a pè mí láìpẹ́ yìí pé, ‘Baba mi, ìwọ ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.
5 So surely you will not [RHQ] be angry with me forever!’ But you will not quit sinning!”
Ìwọ yóò ha máa bínú títí? Ìbínú rẹ yóò ha máa lọ títí láé?’ Báyìí ni o ṣe ń sọ̀rọ̀ ìwọ ṣe gbogbo ibi tí ìwọ le ṣe.”
6 [One day] when Josiah was the king of Judah, Yahweh said to me, “Have you seen what the people of Israel have done? They have turned away from me, like a woman who has abandoned her husband and sleeps with other men. They have gone up on every hilltop and under every big tree and worshiped idols there [MET].
Ní àkókò ìjọba Josiah ọba, Olúwa wí fún mi pé, “Ṣé o ti rí nǹkan tí àwọn Israẹli aláìnígbàgbọ́ ti ṣe? Wọ́n ti lọ sí àwọn òkè gíga àti sí abẹ́ àwọn igi, wọ́n sì ti ṣe àgbèrè níbẹ̀.
7 I thought that they would return to me, so I said to them, ‘Come back to me!’ But they refused. So I sent them away [to other countries, like a man] writes a note saying that he is divorcing his wife and then sends his wife away because she has committed adultery [MET].
Mo rò pé nígbà tí wọ́n ti ṣe èyí wọn yóò padà, wọn kò padà, Juda aláìgbàgbọ́ arábìnrin rẹ̀ náà sì rí i.
8 The people of Judah saw what I did to them. But they are just like the people of Israel. They are not afraid [of what I will do to them]. They also [have turned away from me and are worshiping idols like] women who abandon their husbands and go to other men [MET].
Mo fún Israẹli aláìnígbàgbọ́ ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀, mo sì ké wọn kúrò nítorí gbogbo àgbèrè wọn. Síbẹ̀ mo rí pé Juda tí ó jẹ́ arábìnrin rẹ̀ kò bẹ̀rù, òun náà sì jáde lọ láti lọ ṣe àgbèrè.
9 They thought that worshiping idols did not matter to me, so they have made the [entire] land unacceptable to me by worshiping idols of wood and stone.
Nítorí ìwà èérí Israẹli kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi.
10 The people of Judah have pretended to return to me, but they have not really done that. [This is true because I], Yahweh, have said it.”
Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Juda arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olóòtítọ́,” ni Olúwa wí.
11 Then Yahweh said to me, “The people of Israel have turned away from me, but what the people of Judah have done is worse.
Olúwa wí fún mi pé, “Israẹli aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Juda tí ó ní ìgbàgbọ́ lọ.
12 So go and tell this to the people of Israel: ‘Yahweh says this to you Israeli people who have turned away from him: I am merciful. I will not continue to be angry with you forever. So return to me.
Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá: “‘Yípadà, Israẹli aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Ojú mi kì yóò korò sí ọ mọ́, nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí. Èmi kì yóò sì bínú mọ́ títí láé.
13 But you must admit/say that you are guilty, and that you have rebelled against me, Yahweh, your God, that you have worshiped idols under big trees everywhere, and you have not obeyed me. You have turned away from me.
Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ, ìwọ ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ ti wá ojúrere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì lábẹ́ gbogbo igikígi tí ó gbilẹ̀, ẹ̀yin kò gba ohun mi gbọ́,’” ni Olúwa wí.
14 But you belong to me. So I will take you, one from [each] city and two from [each] clan, and bring you [back] to Jerusalem [from the countries to which you were exiled].
“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,” ni Olúwa wí, “nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Sioni.
15 [If you do that], I will appoint for you leaders with whom I am pleased, leaders who will guide you [well] because they will know and understand [what pleases me].
Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀.
16 And when you become very numerous [DOU] in your land, you will not need to talk about the Sacred Chest that contained the Ten Commandments. You will not think about it, and you will not want to make a new one.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí, “àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa.’ Kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́.
17 At that time people will say, “Jerusalem is [the place where] Yahweh’s throne is.” [People from] all nations will come there to worship me. And they will no longer stubbornly do the evil things that they desire.
Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jerusalẹmu ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀-èdè yóò péjọ sí Jerusalẹmu láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle búburú wọn mọ́.
18 At that time you people [MTY] of Israel and the people of Judah will return from [being (exiled/forced to live) in] lands to the northeast. You will return to the land that I gave to your ancestors to belong to them [forever].
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Juda yóò darapọ̀ mọ́ ilé Israẹli. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.
19 You people of Israel, I wanted to accept you to be my children. I wanted to give you [this] delightful land. It is a land more desirable/pleasant than the land of any other nation! I wanted you to call me ‘father’, and I wanted you to never turn away from me.
“Èmi fúnra mi sọ wí pé, “‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó, kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrin kí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’ Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’ o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.
20 But you have abandoned me like wives who have abandoned their husbands.’” [That is what] Yahweh said, and [I told it] to the people of Israel.
Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí aláìgbàgbọ́ obìnrin sí ọkọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ o jẹ́ aláìgbàgbọ́ sí mi. Ìwọ ilé Israẹli,” ni Olúwa wí.
21 People will hear a noise on the barren hilltops. It will be the noise made by people weeping and pleading [for God to be merciful to them]. They will be admitting/saying that they have forgotten Yahweh their God, and that they turned away from behaving as God wanted them to.
A gbọ́ ohùn àgàn láti ibi gíga, ẹkún àti ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí wọ́n ti yí ọ̀nà wọn po, wọ́n sì ti gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn.
22 Yahweh will say to them, “You Israeli people, come back to me! [If you do that], I will cause you to never turn away from me again.” [The people will reply], “We are returning to you, because you are Yahweh, our God.
“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́, Èmi ó wo ìpadàsẹ́yìn kúrò ní ọ̀nà títọ́ rẹ sàn.” “Bẹ́ẹ̀, ni a ó wá sọ́dọ̀ rẹ nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run wa.
23 We did not get any help from [the idols that we worshiped on] the hilltops; we did not get any help from making all that noise up there.
Nítòótọ́, asán ni ìbọ̀rìṣà àti ìrúkèrúdò tí ó wà ní àwọn orí òkè kéékèèké àti àwọn òkè gíga, nítòótọ́, nínú Olúwa Ọlọ́run wa ni ìgbàlà Israẹli wà.
24 From the time when we were young, the shameful [god Baal] has taken away [from us] everything that our ancestors worked hard to acquire. He has taken away their flocks [of sheep] and herds [of cattle], their sons and their daughters.
Láti ìgbà èwe wa ni àwọn òrìṣà ìtìjú ti jẹ èso iṣẹ́ àwọn baba wa run, ọ̀wọ́ ẹran wọn àti agbo ẹran wọn, ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
25 So, now we should lie down feeling very ashamed [DOU], because we and our ancestors have sinned against Yahweh our God, and we have never obeyed him.”
Jẹ́ kí a dùbúlẹ̀ nínú ìtìjú wa, kí ìtìjú wa bò wá mọ́lẹ̀. A ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, àwa àti àwọn baba wa, láti ìgbà èwe wa títí di òní a kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”

< Jeremiah 3 >