< Hebrews 5 >

1 Every [Jewish] Supreme Priest was chosen by [God] {[God] chose every [Jewish] Supreme Priest} from among [ordinary] men. They were appointed {[He] appointed them} in order that they would come before him on behalf of the people. [Specifically, God appointed them] in order that they would bring gifts [to him on behalf of the people], and in order to sacrifice [animals to him] for people who sinned.
Nítorí olórí àlùfáà kọ̀ọ̀kan tí a yàn nínú àwọn ènìyàn, ní a fi jẹ nítorí iṣẹ́ ìsìn àwọn ènìyàn sí Ọlọ́run láti máa mú ẹ̀bùn àti ẹbọ wá nítorí ẹ̀ṣẹ̀.
2 The Supreme Priests could deal gently with those who ignorantly sinned, since the Supreme Priests themselves tended to sin easily.
Ẹni tí ó lè ṣe jẹ́ẹ́jẹ́ pẹ̀lú àwọn aláìmòye, tí ó sì lé bá àwọn tí ó ti yapa kẹ́dùn, nítorí a fi àìlera yí òun náà ká pẹ̀lú.
3 As a result, they had to offer something to God for their own sins, just like [they had to offer something to God] for [other] people who sinned.
Nítorí ìdí èyí ni ó ṣe yẹ, bí ó ti ń rú ẹbọ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ní ń ṣe fún ara rẹ̀ náà.
4 Furthermore, [it is an honor to be a Supreme Priest] so no one honors himself [by appointing himself to become a Supreme Priest]. Instead, God chose each man [to become a Supreme Priest], as he chose Aaron [to be the first Supreme Priest].
Kọ sí ẹni tí o gba ọlá yìí fún ara rẹ̀, bí kò ṣe ẹni tí a pè láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá gẹ́gẹ́ bí a ti pe Aaroni.
5 Similarly, Christ also did not honor himself by appointing himself to become a Supreme Priest. Instead, God [appointed him by] saying to [him what he never said to any other priest, what the] Psalmist wrote in the Scriptures, You [(sg)] are my Son! Today I have declared that I am your Father!
Bẹ́ẹ̀ ni Kristi pẹ̀lú kò sì ṣe ara rẹ̀ lógo láti jẹ́ olórí àlùfáà; bí kò ṣe ẹni tí o wí fún ún pé, “Ìwọ ni ọmọ mi, lónìí ni mo bí ọ.”
6 And he also said [to Christ what the Psalmist wrote] in another Scripture passage, You are a priest eternally just like Melchizedek was a priest. (aiōn g165)
Bí ó ti wí pẹ̀lú ní ibòmíràn pé, “Ìwọ ni àlùfáà títí láé ní ipasẹ̀ Melkisedeki.” (aiōn g165)
7 When Christ lived on the earth [MTY], he prayed [DOU] to God and tearfully cried out loudly to him. [Specifically], he asked [God], who was able to help him, that he would not [fear the sufferings just before] he died. As a result, God listened to him, because Christ reverently submitted [to what God wanted him to do].
Ní ìgbà ọjọ́ Jesu nínú ayé, ó fi ìkérora rara àti omijé gbàdúrà, tí ó sì bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ ẹni tí ó lè gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú, a sì gbóhùn rẹ̀ nítorí ó ní ẹ̀mí ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ̀.
8 Although Christ is [God’s own Son], he learned to obey [God] by suffering [before he died].
Bí òun tilẹ̀ ń ṣe Ọmọ Ọlọ́run, síbẹ̀ ó kọ́ ìgbọ́ran nípa ohun tí ó jìyà rẹ̀.
9 By becoming (all [that] God intended him to be/perfect), [he has now] become fully qualified [to be our Supreme Priest. As a result, he is the one who saves] eternally all who obey him. (aiōnios g166)
Bí a sì ti sọ ọ di pípé, o wa di orísun ìgbàlà àìnípẹ̀kun fún gbogbo àwọn tí ó ń gbọ́ tirẹ̀, (aiōnios g166)
10 Furthermore, God has designated him to be [our] Supreme Priest in the way that Melchizedek was a Supreme Priest.
tí a yàn ní olórí àlùfáà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ní ipasẹ̀ Melkisedeki.
11 Although there is much to say [to you(pl)] about [how Christ resembles Melchizedek], this is hard [for me] to explain [to you] because you now understand things so slowly.
Nípa èyí àwa ní ohun púpọ̀ láti sọ, tí ó sì ṣòro láti túmọ̀, nítorí pé ẹ yigbì ní gbígbọ́.
12 [You became Christians long ago. So] by now you should be teaching [spiritual truths to others]. But you still need someone to teach you again the truths that God has revealed. [I am talking about] the truths that we teach people [when they] first [believe in Christ]. You need [those elementary truths] like babies need milk [MET]. You are not [ready for advanced teaching, which is like] the solid food [which mature people need] [MET].
Nítorí pé báyìí ó ti yẹ kí ẹ jẹ́ olùkọ́ni, ẹ tún wà ní ẹni tí ẹnìkan yóò máa kọ́ ni ìbẹ̀rẹ̀ ìpìlẹ̀ ẹ̀kọ́ àwọn ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ẹ sì tún di irú àwọn tí ó mu wàrà, tí wọn kò sì fẹ́ oúnjẹ líle.
13 Remember that those [who are still learning these elementary truths] [MET] have not become familiar with [what God] says concerning becoming/being righteous. They are [just like] [MET] babies [who need] milk!
Nítorí olúkúlùkù ẹni tí ń mu wàrà jẹ́ aláìlóye ọ̀rọ̀ òdodo, nítorí ọmọ ọwọ́ ni.
14 But [the more advanced spiritual truth] is for people who are [spiritually] mature, just like [MET] solid food is for [people who are physically] mature. They can tell the difference between what is good and what is evil, because they have trained themselves [to keep doing that].
Ṣùgbọ́n oúnjẹ líle wà fún àwọn tí ó dàgbà, àwọn ẹni nípa ìrírí, tí wọn ń lo ọgbọ́n wọn láti fi ìyàtọ̀ sáàrín rere àti búburú.

< Hebrews 5 >