< Hebrews 1 >

1 Long ago God communicated frequently to our ancestors in various ways by what the prophets [said and wrote].
Ní ìgbà àtijọ́, Ọlọ́run bá àwọn baba ńlá wa sọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì ní ọ̀pọ̀ ìgbà àti ní onírúurú ọ̀nà,
2 But now when this final age [is beginning], God has communicated to us [just once] by means of what (his Son/the man who was also God) [said and did. God] appointed him in order that he would possess everything [that truly belongs to God. God also appointed] him in order that he would create the universe. (aiōn g165)
ṣùgbọ́n ní ìgbà ìkẹyìn yìí Ọlọ́run ń bá wa sọ̀rọ̀ nípasẹ̀ Ọmọ rẹ̀ Jesu Kristi, ẹni tí ó fi ṣe ajogún ohun gbogbo, nípasẹ̀ ẹni tí ó dá gbogbo ayé yìí àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀. (aiōn g165)
3 He manifests God’s glory. He exactly represents [what God is like]. He (sustains everything by means of his powerful words. When he had [enabled people to be] freed from the [guilt of] their sins [MET], he sat down in heaven [EUP] [to rule] at the place of greatest honor [MTY] with God [MTY].
Ọmọ tí í ṣe ìtànṣán ògo Ọlọ́run àti àwòrán òun tìkára rẹ̀, tí ó sì ń fi ọ̀rọ̀ agbára rẹ̀ mú ohun gbogbo dúró. Lẹ́yìn tí ó ti ṣe ìwẹ̀nù ẹ̀ṣẹ̀ wa tan, ó wá jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún Ọláńlá ní òkè.
4 By doing that, he [showed that he] was very much greater than the angels, to the extent that his relationship [MTY] [to God, as his Son], is more excellent than the relationship the angels [have to God].
Nítorí náà, ó sì ti fi bẹ́ẹ̀ di ẹni tí ó ga ní ipò ju angẹli lọ, bí ó ti jogún orúkọ èyí tí ó tayọ̀ tiwọn.
5 [We know that] because [in the Scriptures] no one [RHQ] ever reported that God said to any angel [what he said to his Son], You [(sg)] are my Son! Today I have declared to all that I am your Father [DOU]! And he said in another Scripture passage, I will be his Father, and he will be my Son [DOU].
Nítorí kò sí ọ̀kan nínú àwọn angẹli tí Ọlọ́run fi ìgbà kan sọ fún pé: “Ìwọ ni ọmọ mi; lónìí ni mo bí ọ”? Àti pẹ̀lú pé, “Èmi yóò jẹ́ baba fún un, Òun yóò sì jẹ́ ọmọ mi”?
6 And [we know his Son is greater than the angels because in] another [Scripture passage someone wrote this about God’s esteemed Son], when God was about to send him into the world: All God’s angels must worship him.
Àti pẹ̀lú, nígbà tí Ọlọ́run rán àkọ́bí rẹ̀ wá si ayé wa yìí. Ó pàṣẹ pé, “Ẹ jẹ́ kí gbogbo àwọn angẹli Ọlọ́run foríbalẹ̀ fún un.”
7 [And in the Scriptures it is written that] someone said this about the angels: [God] makes the [angels] who serve him [to be changeable like] [MET] winds and flames of fire.
Àti nípa ti àwọn angẹli, ó wí pé, “Ẹni tí ó dá àwọn angẹli rẹ̀ ní ẹ̀mí, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ní ọwọ́ iná.”
8 But on the other hand, [in the Scriptures it is written that God said] this to his Son: You [(sg)] who are [also] God will rule forever [MTY], and you will reign righteously over your kingdom [MTY]. (aiōn g165)
Ṣùgbọ́n ó sọ nípa tí Ọmọ rẹ̀ pé, “Ìtẹ́ rẹ, Ọlọ́run, láé àti láéláé ni, ọ̀pá aládé òdodo ni ọ̀pá ìjọba rẹ. (aiōn g165)
9 You have loved [people’s] righteous [deeds] and you have hated [people’s] lawless [deeds]. So I, your God, have caused you to be more joyful [MTY] than anyone else.
Ìwọ fẹ́ òdodo, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kórìíra iṣẹ́ búburú; nítorí èyí ni Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ ṣe fi àmì òróró ayọ̀ yàn ọ tí ó gbé ọ ju àwọn ẹgbẹ́ rẹ lọ.”
10 And [we also know that his Son is superior to angels because in the Scriptures the Psalmist wrote that] someone said to God’s Son, Lord, it was you who created the earth in the beginning. You also made [the rest of] the universe (OR, the [things in] the sky) [MTY].
Ó tún sọ pé, “Ní àtètèkọ́ṣe, ìwọ Olúwa, ìwọ fi ìdí ayé sọlẹ̀, àwọn ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ ara rẹ.
11 Everything in the universe will disappear, but you will keep on living [forever]. They will wear out as clothing [wears out].
Wọn yóò ṣègbé, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà síbẹ̀ gbogbo wọn ni yóò di àkísà bí ẹ̀wù.
12 You will dispose of them as one rolls up an [old] coat [before getting rid of it]. [Then], you will exchange [everything that is in the universe for what is new], as someone puts on a new garment [in exchange for an old garment] [SIM]. But you [are not like what you created]; You stay the same, and you live forever [LIT]!
Ní kíká ni ìwọ yóò ká wọn bí aṣọ, bí ìpààrọ̀ aṣọ ni a ó sì pààrọ̀ wọn. Ṣùgbọ́n ìwọ fúnra rẹ̀ kì yóò yípadà àti pé ọdún rẹ kì yóò ní òpin.”
13 [We also know that his Son is superior to angels because no one ever stated] [RHQ] [in the Scriptures] that God said to any angel [what he said to his Son], Sit [in the place of honor] next to me and rule with me [MTY] while I put all of your enemies completely under your control [MET]!
Èwo nínú àwọn angẹli ní a gbọ́ pé Ọlọ́run fi ìgbà kan wí fún pé, “Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ”?
14 The angels are [only] spirits who serve [God] [RHQ]. [God] sends them [to earth] in order to help those he has saved (OR, those whom he will save).
Kì í ha á ṣe ẹ̀mí tí ń jíṣẹ́ ni àwọn angẹli í ṣe bí; tí a rán lọ síta láti máa ṣiṣẹ́ fún àwọn tí yóò jogún ìgbàlà?

< Hebrews 1 >