< Genesis 42 >

1 When someone told Jacob that there was grain in Egypt that people could buy, he said to his sons, “(Why do you just sit there looking at each other?/Do not just sit there looking at each other!) [RHQ] We need some grain!”
Nígbà tí Jakọbu mọ̀ pé ọkà wà ní Ejibiti, ó wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pé, “Èéṣe tí ẹ ń wo ara yín lásán?”
2 He said to them, “Someone told me that there is grain for sale in Egypt. Go down there and buy some for us, in order that we will not die!”
“Mo tí gbọ́ pé ọkà wà ní ilẹ̀ Ejibiti. Ẹ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibẹ̀ kí ẹ sì rà wá fún wa, kí a má ba à kú.”
3 So Joseph’s ten [older] brothers went down to Egypt to buy some grain.
Nígbà náà ni mẹ́wàá nínú àwọn arákùnrin Josẹfu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ra ọkà.
4 But Jacob did not send Benjamin, Joseph’s [younger] brother, to go with the others, because he was afraid/worried that something terrible might happen to him like what happened to Joseph.
Ṣùgbọ́n Jakọbu kò rán Benjamini àbúrò Josẹfu lọ pẹ̀lú wọn nítorí ẹ̀rù ń bà á kí aburú má ba à ṣẹlẹ̀ sí i.
5 So Jacob’s other sons went down from Canaan to Egypt to buy grain, and others from there went too, because there was a famine in Canaan also.
Nítorí náà, àwọn ọmọ Israẹli wà lára àwọn tó lọ Ejibiti lọ ra oúnjẹ nítorí ìyàn náà mú ni ilẹ̀ Kenaani pẹ̀lú.
6 At that time Joseph was the governor of Egypt. He was the one who sold grain to people who came from all over Egypt and from many other countries [HYP] to buy grain. So when Joseph’s brothers arrived, [they were told that it was necessary for them to talk with Joseph. So they went to him and] prostrated themselves before him with their faces to the ground.
Nísinsin yìí, Josẹfu ni alábojútó fún gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, òun sì ni ó ń bojútó ọkà títà fún gbogbo ènìyàn ìlú náà. Nítorí náà nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu dé, wọ́n tẹríba, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún Josẹfu.
7 As soon as Joseph saw his brothers, he recognized them. But he pretended that he did not know them. He spoke harshly to them, saying, “Where do you come from?” One of them replied, “We have come from Canaan, to buy some grain.”
Lọ́gán tí Josẹfu ti rí àwọn arákùnrin rẹ̀ ni ó ti dá wọn mọ̀, ṣùgbọ́n ó ṣe bí i wí pé kò mọ̀ wọ́n, ó sì sọ̀rọ̀ líle sí wọn. Ó béèrè pé, “Níbo ni ẹ ti wá?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Láti ilẹ̀ Kenaani ni a ti wá ra oúnjẹ.”
8 Although Joseph recognized his brothers, they did not recognize him.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, Josẹfu mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, síbẹ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kò mọ̀ ọ́n.
9 And then Joseph remembered what he had dreamed about them many years previously. [But he decided not to tell them yet that he was their younger brother]. He said to them, “You are spies! You have come to find out whether we will be able to defend ourselves [if you attack us]!”
Nígbà náà ni ó rántí àlá rẹ̀ tí ó lá sí wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Amí ni yín, ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
10 One of them replied, “No, sir! We have come to buy grain.
Wọ́n dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ olúwa wa, àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá láti ra oúnjẹ ni.
11 We are all sons of one man. We are honest men, not spies.”
Ọmọ baba ni wá, olóòtítọ́ ènìyàn sì ni wá pẹ̀lú, àwa kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.”
12 He said to them, “[I do not believe you]. You have come just to see whether we would be able to defend ourselves if we were attacked!”
Ó wí fún wọn pé, “Rárá! Ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
13 But one of them replied, “No, that is not true! Originally there were twelve of us who were brothers, the sons of one man. Our younger brother is with our father. One [younger] brother has died. [EUP]”
Ṣùgbọ́n wọ́n tún dáhùn pé, “Arákùnrin méjìlá ni àwa ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ baba kan náà, tí ó ń gbé ní ilẹ̀ Kenaani. Èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wa ń bẹ lọ́dọ̀ baba wa, ọ̀kan sì ti kú.”
14 Joseph replied, “[You are lying! I think] it is just as I told you. You are spies!
Josẹfu wí fún wọn pé, “Bí mo ti wí fún un yín náà ni, Ayọ́lẹ̀wò ni yín!
15 But this is how I will determine whether what you are saying is true. I think that as surely as the king lives, you are spies. And you will not leave this place until your youngest brother comes here!
Èyí sì ni a ó fi dán an yín wò, èmi búra pé, níwọ̀n ìgbà tí Farao bá wà láààyè, ẹ kì yóò kúrò níbí, àyàfi bí arákùnrin yín kan tókù bá wá sí ibí.
16 Send one of your group to go and get your younger brother and bring him here. I will put the rest of you in prison, in order that I may test what you have said to find out whether what you are telling me is true. If the one who goes does not bring your younger brother here, then, just as surely as the king lives, it will be clear that you are lying and that you are spies.”
Ẹ rán ọ̀kan nínú yín lọ láti mú arákùnrin yín wá, àwa yóò fi ẹ̀yin tókù pamọ́ sínú túbú, kí àwa ba à lè mọ bóyá òtítọ́ ni ẹ̀yin ń wí. Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé irọ́ ni ẹ̀yin ń pa, ní òtítọ́ bí Farao ti ń bẹ láààyè ayọ́lẹ̀wò ni yín!”
17 Then Joseph put them all in prison for three days.
Ó sì fi gbogbo wọn sínú túbú fún ọjọ́ mẹ́ta.
18 On the third day, Joseph went to the prison and said to them, “I am a man who fears that God [will punish me if I do not do what I promise]. So do what I tell you, and I will spare your lives.
Ní ọjọ́ kẹta, Josẹfu wí fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe kí ẹ̀yin ba à le yè nítorí mo bẹ̀rù Ọlọ́run.
19 If you are honest men, let one of your brothers stay here in prison, and the rest of you can take some grain back to your families who are very hungry because of the famine.
Tí ó bá jẹ́ pé olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ jẹ́ kí ọ̀kan nínú yín dúró ni túbú ní ìhín, nígbà tí àwọn yòókù yín yóò gbé ọkà lọ fún àwọn ará ilé e yín tí ebi ń pa.
20 But if you come back here again, you must bring your youngest brother to me, so that you can prove that what you told me is true, and as a result I will not have you executed.” So they agreed to do that.
Ṣùgbọ́n ẹ gbọdọ̀ mú arákùnrin tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn yín wá, kí n ba à le mọ òtítọ́ ohun ti ẹ ń wí, kí ẹ má ba à kú.” Wọn sì gbà láti ṣe èyí.
21 They said to each other, “It is surely because of what we did to our [younger] brother that (we are being punished/God is punishing us)! We saw that he [SYN] was very distressed when he pleaded with us not to harm him. But we did not pay any attention to him, and that is why we are having this trouble!”
Wọ́n ń sọ ọ́ láàrín ara wọn wí pé, “Àwa jẹ̀bi nítòótọ́ nípa ti arákùnrin wa. A rí ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀ nígbà tí ó ń bẹ̀ wá nítorí ẹ̀mí rẹ̀, ṣùgbọ́n a kò gbẹ́bẹ̀, nítorí náà ni ìdààmú yìí fi dé bá wa.”
22 Reuben said to them, “I told you not to harm the boy [RHQ], but you did not pay attention to what I said! Now we are being (paid back/punished) for killing him [MTY]!”
Reubeni dá wọn ní ohùn pé, “Èmi kò wí fún yín pé kí ẹ má se ṣẹ̀ sí ọmọdékùnrin náà? Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí a ń béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ wa.”
23 While they were talking with Joseph, they were speaking through (an interpreter/someone who knew their language and the Egyptian language), but when they said these things among themselves, they were speaking in their own language, and they did not know that Joseph could understand their language, and that he could understand what they were saying.
Wọn kò sì mọ̀ pé, Josẹfu ń gbọ́ wọn ní àgbọ́yé nítorí ògbufọ̀ ni ó ń lò tẹ́lẹ̀.
24 [Because of what they said, Joseph realized that they admitted that what they had done to him many years previously was wrong]. He could not keep from crying, [and he did not want them to see him crying], so he left them and went outside the room and began to cry. But then he returned to them and talked to them again. Then he took Simeon, and while they were watching, he told his servants to tie him up. He left Simeon in the prison and told the others that they could go.
Ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún. Ó sì tún yí padà sí wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀. Ó mú Simeoni kúrò láàrín wọn, ó sì dè é ní ojú wọn.
25 Joseph told his servants to fill the men’s sacks with grain, but he also told them to put the money that each one had paid for the grain in the top of his sack. He also told them to give them food to eat along the way. After the servants did those things for Joseph’s older brothers,
Josẹfu pàṣẹ pé kí wọn bu ọkà kún inú àpò wọn, kí wọn sì mú owó ẹnìkọ̀ọ̀kan padà sínú àpò rẹ̀, kí wọn sì fún wọn ní ohun tí wọn yóò lò nírín-àjò wọn padà sílé. Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe èyí fún wọn,
26 his older brothers loaded the sacks of grain on their donkeys and left.
wọn gbé ẹrù wọn lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọn sì padà lọ sí ilé.
27 At the place where they stopped to sleep that night, one of them opened his sack to get some grain for his donkey. He was amazed to see his money in the top of the sack.
Níbi tí wọ́n ti dúró láti sùn lóru ọjọ́ náà, ọ̀kan nínú wọn tú àpò rẹ̀ láti mú oúnjẹ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì rí owó rẹ̀ ní ẹnu àpò rẹ̀.
28 He exclaimed to his brothers, “Someone has returned my money! Here it is in my sack!” They started shaking with fear, and said to each other, “What is this that God has done to us?”
Ó sì wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “a ti dá owó mi padà, òun nìyí ní ẹnu àpò mi.” Ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì ń gbọ̀n, wọ́n sì wí pé, “Èwo nìyí tí Ọlọ́run ṣe sí wa yìí.”
29 When they returned to their father in Canaan land, they told him all that had happened to them. One of them said,
Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Jakọbu baba wọn ní ilẹ̀ Kenaani, wọ́n ròyìn gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún un wí pé,
30 “The man who governs the whole land of Egypt talked very harshly to us. He acted toward us as though we were spying on his country.
“Ọkùnrin náà tí í ṣe alábojútó ilẹ̀ náà, sọ̀rọ̀ líle sí wa, ó sì fi ẹ̀sùn kàn wá pé a wá yọ́ ilẹ̀ náà wò ni.
31 But we told him, ‘We are honest men! We are not spies.
Ṣùgbọ́n, a wí fún un pé, ‘Rárá o, olóòtítọ́ ènìyàn ni wá, a kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.
32 Originally there were twelve of us who were brothers, the sons of one father. One has died [EUP], and our youngest brother is with our father in Canaan.’
Arákùnrin méjìlá ni wá, ọmọ baba kan náà, ọ̀kan ti kú, èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wà lọ́dọ̀ baba wa ni ilẹ̀ Kenaani.’
33 The man who is the governor of the land [did not believe us], so he said to us, ‘This is how I will know if you are truly honest men: Leave one of your brothers here with me. Then the rest of you can take some grain for your families that are starving from hunger and go.
“Nígbà náà ni ọkùnrin tí ó jẹ́ alábojútó ilẹ̀ náà wí fún wa pé, ‘Báyìí ni n ó ṣe mọ̀ bóyá olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ fi ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ níbí, pẹ̀lú mi, ẹ sì mú oúnjẹ lọ fún àwọn ará ilé yín tí ebi ń pa kú lọ, lọ́wọ́ ìyàn.
34 But when you return, bring your youngest brother to me, in order that I will know that you are not spies, but instead, that you are honest men. Then I will release your brother for you. And then you can buy whatever you want in this country.’”
Ṣùgbọ́n ẹ mú arákùnrin yín tí ó kéré jùlọ wá fún mi kí n le mọ̀ pé dájúdájú ẹ kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò bí kò ṣe ènìyàn tòótọ́. Nígbà náà ni n ó mú arákùnrin yín padà fún un yín, lẹ́yìn náà ẹ le máa wá ṣe òwò bí ó ti wù yín ní ilẹ̀ yìí.’”
35 As they were emptying their sacks, they were surprised that in each man’s sack was his pouch of money! When they and their father saw all the pouches of money, they were frightened.
Bí wọ́n sì ti ń tú àpò ẹrù wọn, ẹnìkọ̀ọ̀kan bá owó tí ó san fún ọjà náà lẹ́nu àpò rẹ̀! Ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi, àwọn àti baba wọn.
36 Their father Jacob said to them, “You have caused two of my children to be taken from me! Joseph is dead, and Simeon is gone! And now you want to take Benjamin from me! It is I who am suffering because of all these things that are happening!”
Jakọbu baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ ti mú mi pàdánù àwọn ọmọ mi. N kò rí Josẹfu mọ́, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì rí Simeoni náà mọ. Ẹ sì tún fẹ́ mú Benjamini lọ. Èmi ni gbogbo ohun búburú yìí wá ń ṣẹlẹ̀ sí!”
37 Reuben said to his father, “I will be responsible for Benjamin. [I will take him to Egypt and] bring him back to you. Let me take care of him. If I do not bring Benjamin back to you, you may kill both of my sons.”
Nígbà náà ni Reubeni wí fún baba rẹ̀ pé, “Pa àwọn ọmọ mi méjèèjì bí n kò bá mú Benjamini padà wá fún ọ, èmi ni kí o fà á lé lọ́wọ́, n ó sì mu un padà wá.”
38 But Jacob said, “No, I will not let my son go down there with you. His [older] brother is dead, and he is the only [one of my wife Rachel’s] sons who is left! If something harms him while you are traveling, you would cause me, a gray-haired old man, to die because of sorrow.” (Sheol h7585)
Ṣùgbọ́n Jakọbu wí pé, “Ọmọ mi kì yóò bá a yín lọ, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀. Bí ohunkóhun bá ṣẹlẹ̀ sí i, ìbànújẹ́ ni yóò sì pa mi kú ni ọjọ́ ogbó mi yìí.” (Sheol h7585)

< Genesis 42 >