< Galatians 6 >

1 My fellow believers, if [you] discover that a person [among your congregation] is sinning, [those of] you whom [God’s] Spirit [is directing and empowering] should gently correct that person. [Furthermore, each of] you [who corrects another person should] be very cautious in order that you might not [sin like that when] you are tempted {[when something] tempts you}.
Ará, bí a tilẹ̀ mú ènìyàn nínú ẹ̀ṣẹ̀ kan, kí ẹ̀yin tí í ṣe ti Ẹ̀mí mú irú ẹni bẹ́ẹ̀ bọ̀ sípò nínú ẹ̀mí ìwà tútù; kí ìwọ tìkára rẹ̀ máa kíyèsára, kí a má ba à dán ìwọ náà wò pẹ̀lú.
2 [When there are ones who have] problems, you should help each other. By doing that, you will complete what Christ requires.
Ẹ máa ru ẹrù ọmọnìkejì yín, kí ẹ sì fi bẹ́ẹ̀ mú òfin Kristi ṣẹ.
3 Keep in mind that those who [refuse to help others because they think that they are more important than other people, although they are] not really more important, are deceiving themselves.
Nítorí bí ènìyàn kan bá ń ro ara rẹ̀ sí ẹnìkan, nígbà tí kò jẹ́ nǹkan, ó ń tan ara rẹ̀ jẹ.
4 Instead, each [of you] should [constantly] test/judge [and decide if you can approve what you yourself are doing and thinking]. Then you can boast because of what you yourself [are doing and thinking], and not because what you are doing is superior to what other persons [are doing].
Ṣùgbọ́n kí olúkúlùkù yẹ iṣẹ́ ara rẹ̀ wò, nígbà náà, ohun ìmú-ṣogo rẹ̀ yóò jẹ́ nínú ti ara rẹ̀ nìkan, kì yóò sì jẹ nínú ti ọmọnìkejì rẹ̀.
5 Keep in mind that you must each perform your own [individual] tasks.
Nítorí pé olúkúlùkù ni yóò ru ẹrù ara rẹ̀.
6 [You] who are being taught {whom others are teaching} [God’s truth] should share your various [material] things [EUP] with your teachers.
Ṣùgbọ́n kí ẹni tí a ń kọ́ nínú ọ̀rọ̀ náà máa pèsè ohun rere gbogbo fún ẹni tí ń kọ́ni.
7 You should not deceive yourselves. [Remember that] God is never outwitted {no one ever fools God}. [Just like] a farmer will reap exactly the kind [of crop that] he plants [MET], [God will reward people according to what they have done] [MET].
Kí a má ṣe tàn yín jẹ; a kò lè gan Ọlọ́run: nítorí ohunkóhun tí ènìyàn bá fúnrúgbìn, òhun ni yóò sì ká.
8 [God] will punish eternally those who do what their self-directed natures urge them to do. But those who please [God’s] Spirit will live forever [with God] because of what [God’s] Spirit does for them. (aiōnios g166)
Nítorí ẹni tí ó bá ń fúnrúgbìn sípa ti ara yóò ká ìdíbàjẹ́ ti ara ṣùgbọ́n ẹni tí ń fúnrúgbìn sípa ti ẹ̀mí yóò ti inú ẹ̀mí ká ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
9 But we should not (tire of/become discouraged while) doing what pleases God, because [eventually], at the time [that God] has determined, we will receive a reward [MET], if we do not stop [doing the good things that we have been doing].
Ẹ má sì jẹ́ kí àárẹ̀ ọkàn mú wa ní ṣíṣe rere, nítorí tí a ó kórè nígbà tí àkókò bá dé, bí a kò bá ṣe àárẹ̀.
10 So, whenever we have opportunities, we should do [what is] good to all people. But especially we should do what is good to all our fellow believers.
Ǹjẹ́ bí a ti ń rí àǹfààní gba, ẹ jẹ́ kí a máa ṣoore fún gbogbo ènìyàn, àti pàápàá fún àwọn tí í ṣe ará ilé ìgbàgbọ́.
11 I am now writing this last part of this letter to you in my own handwriting. Notice the large letters with which I am now writing. I am doing this in order that I might emphasize this:
Ẹ wo bí mo ti fi ọwọ́ ara mi kọ̀wé gàdàgbà-gàdàgbà sí yín.
12 Some Jewish believers are trying to force you to perform certain rituals so that other Jews will think highly of them. They are insisting that you be circumcised {that someone must circumcise you}. They are doing that only in order that other Jews would no longer (persecute them/cause them to suffer) for proclaiming that God will save us because of our trusting in what Christ accomplished when he died on the cross [MTY, MET].
Iye àwọn tí ń fẹ́ ṣe àṣehàn ni ara wọn ń rọ yín láti kọlà; kìkì nítorí pé kí a má ba à ṣe inúnibíni sí wọn nítorí àgbélébùú Kristi.
13 The reason that I say that is that the ones who are insisting that you be circumcised {that someone circumcise you} do not themselves fully obey the laws that God gave to Moses. Instead, they desire that you let someone circumcise you in order that they might boast to those Jews who would (persecute them/cause them to suffer) that you did that because they insisted [MTY] that you do it.
Nítorí àwọn tí a kọ ní ilà pàápàá kò pa òfin mọ́, ṣùgbọ́n wọ́n ń fẹ́ mú yin kọlà, kí wọn lè máa ṣògo nínú ara yín.
14 I myself, however, strongly desire that I never boast about anything like that. The only thing I will boast about is what our Lord Jesus Christ accomplished by dying on the cross [MTY]. Because of what Christ did on the cross, I no longer am interested in the things that those who do not trust Christ [MTY] think are important, and those people are no longer interested in the things that I [MET] think are important.
Ṣùgbọ́n kí a má ṣe rí i pé èmi ń ṣògo, bí kò ṣe nínú àgbélébùú Jesu Kristi Olúwa wa, nípasẹ̀ ẹni tí a ti kan ayé mọ́ àgbélébùú fún mi, àti èmi fún ayé.
15 I will boast about Christ dying on the cross because God is concerned neither that people are circumcised nor that people are not circumcised. Instead, he is concerned only that people conduct their lives in a completely new way.
Nítorí pé nínú Kristi Jesu, ìkọlà kò jẹ́ ohun kan, tàbí àìkọlà, bí kò ṣe ẹ̀dá tuntun.
16 I pray that God will give inner peace and act kindly towards all who will act according to this new way of life. It is all those who live according to this new way of life who are now truly God’s people [MET], as the Israeli people were God’s people previously.
Kí àlàáfíà àti àánú wà lórí gbogbo àwọn tí ń rìn ní ìlànà yìí, àti lórí Israẹli Ọlọ́run.
17 Finally, I say that people have persecuted me/caused me to suffer for declaring the truth about Jesus, and as a result I have scars on my body. Your new teachers do not have scars like mine! So do not trouble/bother me about these matters again!
Láti ìsinsin yìí lọ, kí ẹnikẹ́ni má ṣe yọ mí lẹ́nu mọ́; nítorí èmi ń ru àpá Jesu Olúwa kiri ní ara mi.
18 My fellow believers, I pray that our Lord Jesus Christ will kindly accomplish what he desires within you. (Amen!/May it be so!)
Ará, oore-ọ̀fẹ́ Jesu Kristi Olúwa wa, kí ó wà pẹ̀lú ẹ̀mí yín. Àmín.

< Galatians 6 >