< Exodus 31 >

1 Yahweh [also] said to Moses/me, “Note that I have chosen Bezalel, the son of Uri and grandson of Hur, from the tribe of Judah, [for special tasks].
Olúwa wí fún Mose pé,
2
“Wò ó, Èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
3 I have caused him to be completely controlled/empowered by my Spirit, and I have given him special ability [to make things] and have enabled him to know how to do very skilled work.
Èmi sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
4 He can engrave skillful designs in gold, silver, and bronze.
Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,
5 He can cut (jewels/valuable stones) and enclose them [in tiny gold settings/frames]. He can carve things from wood and do other skilled work.
láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
6 Note that I have also appointed Oholiab, the son of Ahisamach, from the tribe of Dan, to work with him. I have also given special ability to other men, in order that they can make all the things that I have commanded you [to be made].
Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́. “Bákan náà, Èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
7 That includes the Sacred Tent, the sacred chest and its lid, all the other things that will be inside the Sacred Tent,
“àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,
8 the table and all the things that are used with it, the pure gold lampstand and all the things that are used to take care of it, the altar [for burning] incense,
tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,
9 the altar for offering sacrifices that will be burned and all the things that will be used with it, the washbasin and its base,
pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,
10 all the beautiful sacred clothes for Aaron and his sons to wear when they work as priests,
àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,
11 the oil for anointing, and the sweet-smelling incense for the Holy Place. [The skilled workers] must make all these things exactly as I have told you to do.”
òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún Ibi Mímọ́. “Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”
12 Yahweh also said to Moses/me,
Olúwa wí fún Mose pé,
13 “Tell the Israeli people, ‘Obey my instructions regarding the (rest days/Sabbath days). Those days will remind you [and your descendants], throughout all future generations, that I, Yahweh, have (set you apart/chosen you) to be my people.
“Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.
14 You must obey [my rules about] the Sabbath days because they are holy/sacred. Those who treat those days in an irreverent way by working on those days must be executed [to show that] I no longer consider them to belong to my people.
“‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ.
15 You may work for six days [each week], but the seventh day [of each week] is a solemn day of rest, dedicated to me, Yahweh. Anyone who does any work on a day of rest is to be executed [because I no longer want them to be able to associate with my people].
Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́.
16 You Israeli people must respect the rest day, and you [and your descendants] must (celebrate it/keep it holy) throughout all future generations. [It will remind you] of the agreement that I have made with you that will last forever.
Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé.
17 It will remind you Israeli people and remind me [of that agreement] because I, Yahweh, created the heavens and the earth in six days, and on the seventh day I stopped doing that work and relaxed.’”
Yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’”
18 When Yahweh finished talking with Moses/me on the top of Sinai Mountain, he gave him/me the two stone slabs on which he had engraved his commandments with his own fingers.
Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.

< Exodus 31 >