< Acts 7 >

1 Then the high priest asked Stephen, “Are the things that [these people are saying about you(sg)] true?”
Nígbà náà ni olórí àlùfáà wí pé, “Òtítọ́ ha ni àwọn ẹ̀sùn tí wọ́ fi kàn ọ́ bí?”
2 Stephen replied, “Fellow Jews and respected leaders, [please] listen to me! The glorious God [whom we(inc) worship] appeared to our ancestor Abraham while he was still [living] in Mesopotamia [region], before he moved to Haran [town].
Ní ìdáhùn sí èyí ó wí pé, “Ẹ̀yin arákùnrin àti ẹ̀yin baba, ẹ fetísílẹ̀ sí mi! Ọlọ́run ògo fi ara hàn fún Abrahamu baba wa, nígbà tí ó wà ni Mesopotamia, kí ó to ṣe àtìpó ni Harani.
3 God said to him, ‘Leave this land where you [(sg)] and your relatives [are living], and go into the land to which I will lead you.’
Ọlọ́run wí fún un pé, ‘Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.’
4 So Abraham left that land, [which was also called] Chaldea, and he arrived in Haran and lived there. After his father died, God told him to move to this land in which you [and I] are now living.”
“Nígbà náà ni ó jáde kúrò ní ilẹ̀ àwọn ará Kaldea, ó sì ṣe àtìpó ni Harani. Lẹ́yìn ìgbà tí baba rẹ̀ sì kú, Ọlọ́run mú un sípò padà wá sí ilẹ̀ yìí, níbi tí ẹ̀yin ń gbé báyìí.
5 “[At that time] God did not give Abraham any [land here], not even a small plot of [this] land that would belong to him. God promised that he would [later] give this land to him and his descendants, and that it would [always] belong [to them. However], at that time Abraham did not have any children [who would] ([inherit it/receive it after he died]).”
Kò sí fún un ni ìní kan, ànító bi ìwọ̀n ààyè ẹsẹ̀ kan. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ṣe ìlérí fún pé, òun yóò fi ilẹ̀ ìní náà fún un àti fún àwọn irú-ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí kò tí ì ní ọmọ.
6 “[Later] God told Abraham, ‘Your descendants will go and live in a foreign country. They [will live there] for 400 years, and [during that time their leaders] will mistreat your descendants and force them to work as slaves.’
Ọlọ́run sì sọ báyìí pé, ‘Irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irinwó ọdún.
7 But God [also] said, ‘I will punish the people who make them work as slaves. Then, after that, your descendants will leave [that land] and they will [come and] worship me in this land.’”
Ọlọ́run wí pé, Orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́; lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde kúrò, wọn ó sì wá sìn mí níhìn-ín yìí.’
8 “Then God commanded Abraham that [every male in his household and all of his male descendants] should be circumcised [to show that they all belonged to God] and that they would obey what he had told Abraham to do. Later Abraham’s son, Isaac, was born, and when Isaac was eight days old, Abraham circumcised him. [Later] Isaac’s son, Jacob, was born, and Isaac [similarly circumcised] him. And Jacob [similarly circumcised] his twelve sons. They are the twelve men [from whom we(inc) Jews have all descended].”
Ó sì fún Abrahamu ni májẹ̀mú ìkọlà. Abrahamu bí Isaaki, ó kọ ọ́ ní ilà ni ọjọ́ kẹjọ tí ó bí i. Isaaki sí bí Jakọbu, Jakọbu sì bí àwọn baba ńlá méjìlá.
9 “[You know that] Jacob’s [older] sons became jealous [because their father favored their younger brother] Joseph. So they sold him [to merchants/traders who took him] [MTY] to Egypt. There he became a slave [of an official who lived there]. But God [helped] Joseph.
“Àwọn baba ńlá sí ṣe ìlara Josẹfu, wọ́n sì tà á sí Ejibiti; ṣùgbọ́n Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀,
10 He protected him whenever people caused him to suffer. He enabled Joseph to be wise; and he caused Pharaoh, the king of Egypt, to think well of Joseph. So Pharaoh appointed him to rule [over] Egypt and to look after all of Pharaoh’s property [MTY].”
ó sì yọ ọ́ kúrò nínú ìpọ́njú rẹ̀ gbogbo. Ó sì fún Josẹfu ní ọgbọ́n, ó sì mú kí ó rí ojúrere Farao ọba Ejibiti; òun sì fi jẹ baálẹ̀ Ejibiti àti gbogbo ilé rẹ̀.
11 “[While Joseph was doing that work], there was a time (when there was very little food/of famine) throughout Egypt and also throughout Canaan. People did not have enough food to eat. People were suffering. [At that time] Jacob and his sons [in Canaan] also could not find [enough] food.
“Ìyàn kan sì mú ni gbogbo ilẹ̀ Ejibiti àti ni Kenaani, àti ìpọ́njú ńlá, àwọn baba wa kò sì rí oúnjẹ.
12 When Jacob heard [people report that] there was grain/food [that people could buy] in Egypt, he sent Joseph’s older brothers [to go there to buy grain. They went and bought grain from Joseph, but they did not recognize him. Then they returned home].
Ṣùgbọ́n nígbà tí Jakọbu gbọ́ pé alikama ń bẹ ni Ejibiti, ó rán àwọn baba wa lọ lẹ́ẹ̀kínní.
13 When Joseph’s brothers went to Egypt the second time, [they again bought grain from Joseph]. But this time [he] told them who he was. [And] people told Pharaoh that Joseph’s people were Hebrews [and that those men who had come from Canaan were his brothers].
Nígbà kejì Josẹfu fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn arákùnrin rẹ̀, a sì tún fi wọ́n hàn fún Farao.
14 Then after Joseph sent [his brothers back home, they] told their father Jacob [that Joseph wanted] him and his entire family to come [to Egypt. At that time] ([Jacob’s family consisted of] 75 people/there were 75 people in Jacob’s family) [SYN].
Lẹ́yìn èyí, Josẹfu ránṣẹ́ pe Jakọbu baba rẹ̀, àti àwọn ìbátan rẹ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ, gbogbo wọ́n sì tó àrùndínlọ́gọ́rin ọkàn.
15 [So when] Jacob [heard that, he and all his family] went to [live in] Egypt.” Acts 7:15b-16 “[Later on], Jacob died [there], and our [other] ancestors, [his sons, also died there].
Nígbà náà ni Jakọbu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, ní ibi tí òun àti àwọn baba wa kú sí.
16 [But] the bodies [of Jacob and Joseph] were brought {[they] brought the bodies [of Jacob and Joseph]} [back to our land], and [Jacob’s body] was buried {they buried [Jacob’s body]} [in the tomb that Abraham had bought, and they buried Joseph’s body] in Shechem in the ground that [Jacob] had bought from Hamor’s sons.”
A sì gbé òkú wọn padà wá sí Ṣekemu, a sì tẹ́ wọn sínú ibojì ti Abrahamu rà ni ọwọ́ àwọn ọmọ Amori ní Ṣekemu ní iye owó wúrà kan.
17 “Our ancestors had become very numerous when it was almost time for [God to rescue them] from Egypt, [as] he had promised Abraham that he would do.
“Nígbà tí àkókò tí Ọlọ́run yóò mú ìlérí tí ó ṣe fún Abrahamu ṣẹ kù sí dẹ̀dẹ̀, àwọn ènìyàn wa ń gbèrú si gidigidi ní iye ní ilẹ̀ Ejibiti.
18 Another king had begun to rule in Egypt. He did not know that Joseph, [long before that time, had greatly helped the people of Egypt] [MTY].
Ṣùgbọ́n ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
19 That king cruelly tried to get rid of our ancestors. He oppressed them and caused them to suffer greatly. He [even commanded] them to leave their baby [boys] outside [their homes] so that they would die.”
Òun náà ni ó ṣe àrékérekè sí àwọn ìbátan wa. Wọn sì hùwà búburú sí àwọn baba wa, tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi já àwọn ọmọ ọwọ́ wọn kúrò lọ́wọ́ wọn nítorí kí wọn má ṣe yè.
20 “During that time Moses was born, and he was a very beautiful [LIT] [child]. So his parents [secretly] cared for him in their house for three months.
“Ní àkókò náà ni a bí Mose ọmọ tí ó se iyebíye, tí wọn sí bọ́ lóṣù mẹ́ta ni ilé baba rẹ̀.
21 Then they had to put him outside [the house, but] Pharaoh’s daughter [found him and] adopted him and cared for him as [though he were] her own son.
Nígbà tí wọn sí gbe é sọnù, ọmọbìnrin Farao gbé e, ó sì tọ ọ́ dàgbà gẹ́gẹ́ bí ọmọ ara rẹ̀.
22 Moses was taught {[The Egyptian teachers] taught Moses} many kinds of wise things [HYP] that the people in Egypt knew, and [when he grew up], he spoke powerfully and did things powerfully.”
A sì kọ́ Mose ni gbogbo ọgbọ́n ara Ejibiti, ó sì pọ̀ ni ọ̀rọ̀ àti ní ìṣe.
23 “[One day] when Moses was about 40 years old, he decided that he would [go and] see his fellow Israelis. [So he went to the place where they worked].
“Nígbà tí Mose di ọmọ ogójì ọdún, ó sọ sí i lọ́kàn láti lọ bẹ àwọn ọmọ Israẹli ará rẹ̀ wò.
24 He saw an Egyptian beating one of the Israelis. So he went over to help [MTY] the Israeli man who was being hurt/beat {whom [the Egyptian] was hurting/beating}, and he (got revenge on/paid back) the Israeli man by killing the Egyptian [who was hurting/beating him].
Nígbà tí ó sì rí ọ̀kan nínú wọ́n tí ará Ejibiti kan ń jẹ́ ní ìyà, ó gbèjà rẹ̀, ó gbẹ̀san ẹni tí wọ́n jẹ ní ìyà nípa lílu ará Ejibiti náà pa.
25 Moses was thinking that his fellow Israelis would understand that God had sent him to free them [from being slaves]. But they did not understand that.
Mose rò bí àwọn ará òun mọ̀ pé Ọlọ́run yóò ti ọwọ́ òun gbà wọn; ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀.
26 The next day, Moses saw two Israeli men fighting [each other]. He tried to make them stop fighting by saying to them, ‘Men, you two are fellow [Israelis! So] (stop hurting each other!/why are you hurting each other?) [RHQ]’
Ní ọjọ́ kejì Mose yọ sí àwọn ọmọ Israẹli méjì bí wọ́n ti ń jà. Òun si fẹ́ parí ìjà fún wọn. Ó wí pé, ‘Ènìyàn mi, ará ni ẹ̀yin; èéṣe tí ẹ̀yin fi ń ṣe ohun tí kò tọ́ sí ara yín?’
27 But the man who was injuring the other man pushed Moses away and said to him, ‘(No one appointed you [(sg)] to rule and judge us [(exc)]!/Do you [(sg)] think someone appointed you [(sg)] to rule and judge us [(exc)]?) [RHQ]
“Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fínràn sí ẹnìkejì rẹ̀ ti Mose sí ẹ̀gbẹ́ kan, ó wí pé, ‘Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa?
28 Do you want to kill me as you killed the Egyptian yesterday?’
Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti lánàá?’
29 When Moses heard that, [he thought to himself, ‘Obviously, people know what I have done, and someone will kill me.’ He was afraid, so] he fled [from Egypt] to Midian land. He lived there [for some years]. He [got married, and he and his wife] had two sons.”
Mose sì sá nítorí ọ̀rọ̀ yìí, ó sì wa ṣe àtìpó ni ilẹ̀ Midiani, níbi tí ó gbé bí ọmọ méjì.
30 “[One day] 40 years later, [the Lord God appeared as] an angel to Moses. He appeared in a bush that was burning in the desert near Sinai Mountain.
“Nígbà tí ogójì ọdún sì pé, angẹli Olúwa fi ara han Mose ní ijù, ní òkè Sinai, nínú ọ̀wọ́-iná nínú igbó.
31 When Moses saw that, he was greatly surprised, [because the bush was not burning up]. As he went over to look more closely, he heard the Lord [God] say [to him],
Nígbà tí Mose sì rí i, ẹnu yà á sí ìran náà; nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti wò ó fín, ohùn Olúwa kọ sí i,
32 ‘I [am] the God [whom] your ancestors [worshipped]. I [am] the God that Abraham, Isaac and Jacob [worship].’ Moses [was so afraid that he] began to shake. He was afraid to look [at the bush any longer].
wí pé ‘Èmi ni Ọlọ́run àwọn baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu,’ Mose sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù, kò sì dáṣà láti wò ó mọ́.
33 Then the Lord [God] said to him, ‘Take your sandals off [to show that you(sg) revere me]. Because I [am here], the place where you are standing is holy/sacred.
“Olúwa sì wí fún un pé, ‘Bọ́ bàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.
34 I have surely seen how the people of Egypt are continually causing my people to suffer. I have heard my people when they groan [because those people continually oppress them]. So I have come down to rescue them [from Egypt]. Now get ready, because I am going to send you [back] to Egypt [to do that].’”
Ní rí rí, mo ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi tí ń bẹ ni Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ìkérora wọn, mo sì sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n. Wá nísinsin yìí, Èmi ó sì rán ọ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.’
35 “This Moses [is the one who had tried to help our Israeli people, but] whom they rejected [by saying], ‘No one [RHQ] appointed you to rule and judge [us!’] Moses [is the one whom] God [himself] sent to rule them and to free them [from being slaves. He is the one whom] an angel in the bush [commanded to do that].
“Mose náà yìí tí wọ́n kọ̀, wí pé, ‘Ta ni ó fi jẹ olórí àti onídàájọ́?’ Òun náà ni Ọlọ́run rán lọ láti ọwọ́ angẹli, tí ó farahàn án ní pápá, láti ṣe olórí àti olùdáǹdè.
36 Moses [is the one who] led our ancestors out [from Egypt]. He did many kinds of miracles in Egypt, at the Red Sea, and during the 40 years [that the Israelite people lived] in the desert.
Òun ni ó mú wọn jáde, lẹ́yìn ìgbà tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ni Òkun pupa, àti ni aginjù ní ogójì ọdún.
37 This Moses is the one who said to the Israelite people, ‘God will appoint a prophet for you from among your own people. [He will speak words from God], just like I [speak his words to you].’
“Èyí ni Mose náà ti ó wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ọlọ́run yóò gbé wòlíì kan bí èmi dìde nínú àwọn ènìyàn yín.’
38 This man [Moses] was [our people’s leader] when they gathered together in the desert. It is Moses to whom [God sent] the angel on Sinai Mountain to [give him our laws], and [he was the one who told] our [other] ancestors [what the angel had said]. He was the one who received [from God] words that tell us how to live [eternally, and Moses] passed [them] on to us.”
Èyí náà ni ẹni tí ó wà nínú ìjọ ní ijù pẹ̀lú angẹli náà tí ó bá a sọ̀rọ̀ ní orí òkè Sinai, àti pẹ̀lú àwọn baba wa; ẹni ti ó gba ọ̀rọ̀ ìyè láti fi fún wa.
39 “[However], our ancestors did not want to obey [Moses]. Instead, [while he was still on the mountain], they rejected him [as their leader] and decided that they wanted to return to Egypt.
“Ṣùgbọ́n àwọn baba wa kò fẹ́ gbọ́ tirẹ̀. Dípò bẹ́ẹ̀, wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀, àti pé nínú ọkàn wọn, wọn fẹ́ yípadà lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
40 So they told [his older brother] Aaron, ‘Make idols for us who will be our gods to lead us [back to Egypt]! As for that fellow Moses who led us out of Egypt we [(exc)] do not know what has happened to him!’
Wọ́n wí fún Aaroni pé, ‘Dá òrìṣà fún wa tí yóò máa tọ́nà ṣáájú wa; nítorí bí ó ṣe ti Mose yìí tí ó mú wa jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, a kò mọ̀ ohun tí ó ṣe é.’
41 So, they made [out of gold] an image [that looked like] a calf. Then they sacrificed [animals and offered other things] to [honor] that idol, and they sang and danced to honor the idol that they themselves had made.
Wọ́n sì yá ère ẹgbọrọ màlúù ni ọjọ́ wọ̀nyí. Wọ́n sì rú ẹbọ sí ère náà, wọ́n sì ń yọ̀ nínú ohun tí wọ́n fi ọwọ́ ara wọn ṣe.
42 So God rejected them. He abandoned them to worship the sun, moon and stars in the sky. This agrees with the words that one of the prophets wrote that God said, You Israelite [people] [MTY], when you [repeatedly] killed animals and offered them as sacrifices during those 40 years [that you were] in the desert, (you [most certainly] were not offering them to me!/what makes you think that you were offering them to me?) [RHQ]
Ọlọ́run sì padà, ó fi wọn sílẹ̀ láti máa sin ogun ọ̀run: òòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀. Èyí wà ní ìbámu pẹ̀lú bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé àwọn wòlíì pé: “‘Ẹ̀yin ha mú ẹran tí a pa àti ẹbọ wa fún mi ní ogójì ọdún ní ijù bí, ìwọ ilé Israẹli?
43 [On the contrary], you carried [with you from place to place] the tent [that contained the idol] representing [the god] Molech [that you worshipped]. You also [carried with you] the image of the star [called] Rephan. [Those] were idols that you had made, [and you] worshipped [them instead of me]. So I will [cause you to] be taken away {[people to] take you} [from your own country. You will be taken] {[They will take you]} [far from your homes to regions] even farther than Babylon [Country].”
Ẹ̀yin sì tẹ́wọ́gbà àgọ́ Moleki, àti ìràwọ̀ Refani òrìṣà yín, àwòrán tí ẹ̀yin ṣe láti máa bọ wọ́n. Nítorí náà èmi yóò kó yín lọ sí ìgbèkùn rékọjá Babeli.’
44 “While our ancestors were in the desert, they worshipped God at the tent that showed [that he was there with them]. They had made the tent exactly like God had commanded Moses [to make it. It was] exactly like the model that Moses had seen [when he was up on the mountain].
“Àwọn baba wa ní àgọ́ ẹ̀rí pẹ̀lú wọn ní ijù. Èyí tí a ṣe gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó ba Mose sọ̀rọ̀ pé kí ó ṣe é, gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ tí ó ti rí.
45 [Later on], other ancestors of ours carried that tent with them when Joshua led them [into this land]. That was during the time that they took this land for themselves, when God forced the people [who previously lived here] to leave. So the Israelis were able to possess this land. [The tent remained in this land and was still here] when [King] David ruled.
Ti àwọn baba wa tí ó tẹ̀lé wọn sí mú bá Joṣua wá sí ilẹ̀ ìní àwọn aláìkọlà, tí Ọlọ́run lè jáde kúrò níwájú àwọn baba wa, títí dí àkókò Dafidi.
46 David pleased God, and he asked God to let him build a house where [he and] all of our Israeli people could worship God.
Ẹni tí ó rí ojúrere níwájú Ọlọ́run, tí ó sì tọrọ láti rí ibùgbé fún Ọlọ́run Jakọbu.
47 But [instead, God let David’s son] Solomon build a house [where people could worship] God.”
Ṣùgbọ́n Solomoni ni ó kọ́ ilé fún un.
48 “However, [we(inc) know that] God is greater than everything, and he does not live in [houses that] people [SYN] have made. It is like the prophet [Isaiah] wrote. He wrote [these words that God had spoken: ]
“Ṣùgbọ́n Ọ̀gá-ògo kì í gbé ilé ti a fi ọwọ́ kọ́, gẹ́gẹ́ bí wòlíì ti wí pé:
49 Heaven is (my throne/the place from which I rule the entire universe), and the earth is (my footstool/[merely like] a stool on which I may rest my feet). I myself [SYN] have made everything [both in heaven and on the earth]. So you [human beings], ([you] really cannot build a house that would be [adequate] for me!/do you think you can build a house that would be [appropriate] for me?) [RHQ] You cannot [RHQ] make a place good enough for me [to live in]!”
“‘Ọ̀run ni ìtẹ́ mi, ayé ni àpótí ìtìsẹ̀ mi. Irú ilé kín ní ẹ̀yin yóò kọ́ fún mi? ni Olúwa wí. Tàbí níbo ni yóò jẹ́ ibi ìsinmi mi?
Ọwọ́ mi kò ha ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.’
51 “You people are extremely stubborn [MET], not wanting to obey God or listen [MTY] [to him!] You are exactly like your ancestors! You always resist the Holy Spirit [as they did]!
“Ẹ̀yin ọlọ́rùn líle àti aláìkọlà àyà àti etí! Bí àwọn baba yín gẹ́lẹ́ ni ẹ̀yin rí. Nígbà gbogbo ni ẹ̀yin máa ń dènà Ẹ̀mí Mímọ́!
52 Your ancestors caused [RHQ] every prophet to suffer, [including Moses]. They even killed those who long ago announced [that the Messiah] would come, the one who always did what pleased God. [And the Messiah has come! He is the one whom] you [recently] turned over [to his enemies] and [insisted that] they kill him!
Ǹjẹ́ ọ̀kan tilẹ̀ wà nínú àwọn wòlíì tí àwọn baba yín kò ṣe inúnibíni sí? Wọn sì ti pa àwọn ti ó ti ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa wíwá Ẹni Olódodo náà. Nísinsin yìí ẹ̀yin ti dalẹ̀ rẹ̀ ẹ̀yin sí ti pa.
53 You [are the people] who have received God’s laws. [Those were laws] that God caused angels to give [to our ancestors]. However, [incredibly], you have not obeyed them!”
Ẹ̀yin tí ó gba òfin, gẹ́gẹ́ bí àwọn angẹli ti fi fún ni, tí ẹ kò sì pa á mọ́.”
54 When the Jewish Council members [and others there] heard all that [Stephen said], they became very angry. They were grinding their teeth [together because they were so angry] at him!
Nígbà tí wọn sì gbọ́ nǹkan wọ̀nyí ọkàn wọn gbọgbẹ́ dé inú, wọn sì payínkeke sí i.
55 But the Holy Spirit completely controlled Stephen. He looked up into heaven and saw a dazzling light from God, and [he saw] Jesus standing at God’s right side.
Ṣùgbọ́n Stefanu, ẹni tí ó kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó tẹjúmọ́ ọ̀run, ó sì rí ògo Ọlọ́run, àti Jesu dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.
56 “Look,” he said, “I see heaven open, and I [see] the one who came from heaven standing at God’s right side!”
Ó sì wí pé, “Wò ó, mo rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, Ọmọ Ènìyàn sì dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.”
57 [When the Jewish Council members and others heard that], they shouted loudly. They put their hands over their ears [so that they could not hear Stephen, and immediately] they all rushed at him.
Nígbà náà ni wọn kígbe ní ohùn rara, wọn sí di etí wọ́n, gbogbo wọn sì sáré sí i, wọ́n sì rọ́ lù ú,
58 They dragged him outside the city [of Jerusalem] and started to throw stones at him. The people who were accusing him [took off] their outer garments [in order to throw stones more easily, and] they put their clothes [on the ground] next to a young man whose name was Saul, [so that he could guard them].
wọ́n sì wọ́ ọ sẹ́yìn òde ìlú, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sísọ ọ́ ní òkúta; àwọn ẹlẹ́rìí sì fi aṣọ wọn lélẹ̀ lẹ́sẹ̀ ọmọkùnrin kan tí a ń pè ní Saulu.
59 While they continued to throw stones at Stephen, Stephen prayed, “Lord Jesus, receive my spirit!”
Bí wọ́n ti ń sọ Stefanu ní òkúta, ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Jesu Olúwa, gba ẹ̀mí mi.”
60 Then Stephen fell on his knees and cried out, “Lord, do not punish them (OR, forgive them) [LIT] for this sin!” After he had said that, he died.
Nígbà náà ni ó wólẹ̀ lórí eékún rẹ̀, ó kígbe sókè pé, “Olúwa, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ yìí sí wọn ní ọrùn.” Nígbà ti ó sì wí èyí tán, ó sùn lọ.

< Acts 7 >