< Acts 20 >

1 After the people at Ephesus had stopped rioting, Paul summoned the believers. He encouraged them [to continue to trust in the Lord Jesus. Soon] after that, he told them goodbye and left to go to Macedonia [province].
Nígbà tí ariwo náà sí rọlẹ̀, Paulu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn, ó sì gbà wọ́n ní ìyànjú, ó dágbére fún wọn, ó dìde láti lọ sí Makedonia.
2 [After he arrived] there, he visited [each town where there were believers], and encouraged them. Then he arrived in Greece [province], [which is also called Achaia].
Nígbà tí ó sì tí la apá ìhà wọ̀nyí kọjá, tí ó sì ti fi ọ̀rọ̀ púpọ̀ gbà wọ́n ní ìyànjú, ó wá sí ilẹ̀ Giriki.
3 He stayed there for three months. Then he planned to return to Syria by ship, but [he heard that] some of the Jews [SYN] [in that area] were planning to kill him [as he traveled. So] he decided instead to go [by land, and he traveled] again through Macedonia.
Ó sì dúró níbẹ̀ ní oṣù mẹ́ta, nígbà tí àwọn Júù sì dènà dè é, bí ó ti ń pète àti bá ọkọ̀ ojú omi lọ sí Siria, ó pinnu rẹ̀ láti gbà Makedonia padà lọ.
4 The men who were going to travel with him [to Jerusalem were] Sopater, [who was] a son of Pyrrhus, who grew up in Berea [town]; Aristarchus and Secundus, who were from Thessalonica [city; ] Gaius, [who was] from Derbe [town; ] Timothy, [who was from Galatia province; ] and Tychicus and Trophimus who were from Asia [province].
Sopateru ará Berea ọmọ Pirusi sì bá a lọ dé Asia, àti nínú àwọn ará Tẹsalonika, Aristarku àti Sekundu, àti Gaiusi ará Dabe, àti Timotiu; Tikiku àti Tirofimu ará Asia.
5 Those [seven] men went ahead of [Paul and me, Luke, by ship from Macedonia, so] they got to Troas [before we did and] waited for [the two of] us there.
Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí tí lọ síwájú, wọ́n dúró dè wá ni Troasi.
6 [But we two(exc) traveled by land as far as] Philippi [city]. After the Jewish festival [when they eat] unleavened bread, we got on a ship [that was going from] the port near [Philippi to Troas city]. After five days we [(exc)] arrived at Troas and we met the other men who had traveled there [ahead of us]. Then we [all] stayed in Troas for seven days.
Àwa sì ṣíkọ̀ láti Filipi lọ lẹ́yìn àjọ àìwúkàrà, a sì dé ọ̀dọ̀ wọn ní Troasi ni ọjọ́ méje.
7 (On Sunday evening/On the evening of the first day of the week), we [(exc) and the other believers there] gathered together to celebrate the Lord’s Supper [and to eat other food] [SYN]. Paul spoke to the believers. He continued teaching them until midnight, because he was planning to leave [Troas] the next day.
Ọjọ́ èkínní ọ̀sẹ̀ nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn péjọ láti bu àkàrà, Paulu sì wàásù fún wọn, ó múra láti lọ ní ọjọ́ kejì: ó sì fa ọ̀rọ̀ rẹ̀ gùn títí di àárín ọ̀gànjọ́.
8 Many [oil] lamps were burning in the upstairs room in which we [(exc)] had gathered, [so the fumes caused some people to become sleepy].
Fìtílà púpọ̀ sì wà ní iyàrá òkè náà, níbi tí wọn gbé péjọ sí.
9 A young man whose name was Eutychus was there. He was seated on [the sill of] an [open] window [on the third story of the house]. As Paul continued talking for a long time, Eutychus became sleepier and sleepier. Finally, he was sound/really asleep. He fell [out of the window] from the third story down [to the ground. Some of the believers went down] immediately and picked him up. [But he was] dead.
Ọ̀dọ́mọkùnrin kan tí a ń pè ní Eutiku sì jókòó lójú fèrèsé, oorun sì wọ̀ ọ́ lára; bí Paulu sì ti pẹ́ ní ìwàásù, ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lójú oorun, ó ṣubú láti òkè kẹta wá sílẹ̀, a sì gbé e dìde ní òkú.
10 Paul [also] went down. He lay down and stretched out on top of the young man and put his arms around him. Then he said [to the people who were standing around], “Do not worry, he is alive [again now]!”
Nígbà tí Paulu sì sọ̀kalẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ tì i, ó sì gbé e mọ́ra, ó ní, “Ẹ má ṣe yọ ara yín lẹ́nu; nítorí tí òun wà láààyè.”
11 Then Paul, [along with the others], went upstairs again and they ate the Lord’s Supper and other food [SYN]. Afterwards, Paul conversed with the believers until dawn. Then he left.
Nígbà tí ó sì tún gòkè lọ, ó sì jẹ oúnjẹ Olúwa, ó sì sọ̀rọ̀ pẹ́ títí ó fi di àfẹ̀mọ́júmọ́, nígbà náà ni ó sì lọ.
12 The [other] people took the young man [home], and were greatly encouraged because he was alive [again].
Wọ́n sì mú ọmọkùnrin náà lọ sílẹ̀ láààyè, inú gbogbo wọn sì dùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
13 We then went to the ship. Paul did not get on the ship [with us in Troas], because he preferred to go [more quickly] overland to Assos [town]. The rest of us got on the ship and sailed for Assos.
Nígbà ti àwa sì ṣáájú, àwa sì ṣíkọ̀ lọ sì Asosi, níbẹ̀ ni a ti lérò láti gba Paulu sínú ọkọ̀: nítorí bẹ́ẹ̀ ni ó tí pinnu rẹ̀, òun tìkára rẹ̀ ń fẹ́ bá ti ọ̀nà-ẹsẹ̀ lọ.
14 We [(exc)] met Paul in Assos. He got on [the ship] with us, and we sailed to Mitylene [town].
Nígbà tí ó sì pàdé wa ní Asosi, a gbà á sínú ọkọ̀, a sì wá sí Miletu.
15 The day after [we reached Mitylene], we [sailed from there and] arrived [at a place] near Kios [Island]. The day after that, we sailed to Samos [Island]. The next day we [left Samos and] sailed to Miletus [town].
Nígbà tí a sì ṣíkọ̀ kúrò níbẹ̀, ní ọjọ́ kejì a dé ọ̀kánkán Kiosi; ní ọjọ́ kejì rẹ̀ a dé Samosi, ni ọjọ́ kejì rẹ̀ a sì dé Miletu.
16 [Miletus was just south of Ephesus city]. Paul had [earlier] decided that he would not get on a ship that would stop at Ephesus, because he did not want to spend [several] days in Asia [province]. If possible, he wanted to arrive in Jerusalem by the [time of the] Pentecost festival, [and the time of that festival was near].
Paulu ṣa ti pinnu rẹ̀ láti bá ọkọ̀ ojú omi kọjá sí Efesu, nítorí ki ó má ba à lo àkókò kankan ni Asia: nítorí tí ó ń yára bí yóò ṣe ṣe é ṣe fún un láti wà ní Jerusalẹmu lọ́jọ́ Pentikosti.
17 [When the ship arrived at] Miletus, Paul sent [a messenger] to Ephesus to ask the elders of the congregation to come to talk with him.
Ní àti Miletu ni Paulu ti ránṣẹ́ sí Efesu, láti pé àwọn alàgbà ìjọ wá sọ́dọ̀ rẹ̀.
18 When the elders arrived, Paul said to them, “You personally know how I [conducted myself among you the entire time] that I was with you, from the first day when I arrived [here] in Asia [province until the day I left].
Nígbà tí wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin tìkára yín mọ̀, láti ọjọ́ kìn-ín-ní tí mo tí dé Asia, bí mo ti bá yín gbé, ní gbogbo àkókò náà.
19 [You know how] I was serving the Lord [Jesus] very humbly and how I sometimes wept [about people. You also know how] I suffered because the Jews [SYN] [who were not believers often] tried [to harm me].
Bí mo ti ń fi ìrẹ̀lẹ̀ inú gbogbo sin Olúwa, àti omijé púpọ̀, pẹ̀lú ìdánwò, tí ó bá mi, nípa rìkíṣí àwọn Júù.
20 You also know that, as I preached [God’s message] to you, I never left out anything that would help you. You know that I taught you [God’s message] when many people were present, and I [also went to your] homes and taught it there.
Bí èmí kò ti fàsẹ́yìn láti sọ ohunkóhun tí ó ṣàǹfààní fún un yín, àti láti máa kọ́ ọ yín ní gbangba àti láti ilé dé ilé.
21 I preached both to Jews and to non-Jews, telling them [all] that they must turn away from their sinful behavior. [I also told them they should] believe in our Lord Jesus.”
Tí mo ń sọ fún àwọn Júù, àti fún àwọn Giriki pẹ̀lú, ní ti ìrònúpìwàdà sí Ọlọ́run, àti ti ìgbàgbọ́ nínú Jesu Kristi Olúwa wa.
22 “And now note this: I am going to Jerusalem, because [God’s] Spirit has clearly shown me that I must go there. I do not know what will happen to me [while I am there].
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, ẹ̀mí mi ń fà sì Jerusalẹmu, láìmọ̀ ohun tí yóò bá mi níbẹ̀.
23 But I do know that in each city [where I have stopped], the Holy Spirit has (told me/[caused the believers to] tell me) that [in Jerusalem] people will put me in prison [PRS] and will cause me to suffer [PRS].
Bí kò ṣe bí Ẹ̀mí Mímọ́ tí ń sọ ní ìlú gbogbo pé, ìdè àti ìyà ń bẹ fún mi.
24 But I do not care even if people kill me, if first I am able to finish the work [MET] that the Lord Jesus has told me [to do. He appointed me] to tell people the good message that God [saves us] by doing for us what we do not deserve.
Ṣùgbọ́n èmi kò ka ọkàn mi sí nǹkan rárá bi ohun tí ó ṣọ̀wọ́n fún mi àti iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí mo tí gbà lọ́dọ̀ Jesu Olúwa, láti máa ròyìn ìyìnrere oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
25 I have preached to you the message about how God desires to rule [people’s lives]. But now I know that today is the last time that you fellow believers will see me [SYN].
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, èmi mọ̀ pé gbogbo yín, láàrín ẹni tí èmi tí ń wàásù ìjọba Ọlọ́run, kì yóò rí ojú mi mọ́.
26 So I want you all to understand that if anyone [who has heard me preach] dies [without trusting in Jesus], it is not my fault [MTY],
Nítorí náà mo pè yín ṣe ẹlẹ́rìí lónìí yìí pé, ọrùn mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀jẹ̀ ènìyàn gbogbo.
27 because I told you [LIT] everything [HYP] that God has planned for us [(inc)].
Nítorí tí èmi kò fàsẹ́yìn láti sọ gbogbo ìpinnu Ọlọ́run fún un yin.
28 [You leaders] must continue to believe and obey [God’s message. You must also help] all the other believers [MET] for whom the Holy Spirit has caused you to be responsible [MTY]. Watch over [MET] yourselves and the other believers [as] a shepherd [watches over his sheep]. God bought them with the blood [that flowed from] his [Son’s body on the cross].
Ẹ kíyèsára yin, àti sí gbogbo agbo tí Ẹ̀mí Mímọ́ fi yín ṣe alábojútó rẹ̀, láti máa tọ́jú ìjọ Ọlọ́run, tí ó tí fi ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ rà.
29 I know [very well] that after I leave, [people who teach] [MET] [false doctrines] will come among you and will do great harm to the believers. [They will be like] fierce wolves [that kill sheep].
Nítorí tí èmi mọ̀ pé, lẹ́yìn lílọ mi, ìkookò búburú yóò wọ àárín yín, yóò sì tú agbo ká.
30 Even in your own group of believers there will be some who will deceive [other] believers by teaching them messages that are false. They will teach those messages so that some people [will believe them and] will become their followers.
Láàrín ẹ̀yin tìkára yín ni àwọn ènìyàn yóò sì dìde, tí wọn yóò máa sọ̀rọ̀-òdì, láti fa àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sẹ́yìn wọn.
31 So watch out [that none of you stops believing the true message about our Lord Jesus]. Remember that day and night for [about] three years I repeatedly taught you that message, and warned you with tears [in my eyes not to believe any other message].”
Nítorí náà ẹ máa ṣọ́ra, ki ẹ sì máa rántí pé, fún ọdún mẹ́ta, èmi kò dẹ́kun láti máa fi omijé kìlọ̀ fún olúkúlùkù ní ọ̀sán àti ní òru.
32 “[Now as I leave you], I ask God to protect you and to keep you believing the message [that he saves us(inc)] by doing for us what we do not deserve. [If you continue believing] the message [that I told you], you will become [spiritually mature], and God will give you the blessings that he has promised to give to all of those who belong to him.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ará, mo fi yín lé Ọlọ́run lọ́wọ́ àti ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀, tí ó lè gbé yín dúró, tí ó sì lè fún yín ní ìní láàrín gbogbo àwọn tí a sọ di mímọ́.
33 [As for myself], I have not desired anyone’s money [MTY] or [fine] clothing.
Èmí kò ṣe ojúkòkòrò fàdákà, tàbí wúrà, tàbí aṣọ ẹnikẹ́ni.
34 You yourselves know that I have worked [with my hands] [MTY] to earn the money that my companions and I needed.
Ẹ̀yin tìkára yín sá à mọ̀ pé, ọwọ́ mi wọ̀nyí ni mo fi ṣiṣẹ́ láti fi pèsè fún àìní mi, àti tí àwọn tí ó wà pẹ̀lú mi.
35 In everything that I did, I showed you that we [(inc)] should work hard in order [to have enough money] to give some to those who are needy. We [(inc)] should remember that our Lord Jesus himself said, ‘You are happy when people give you what you need, but God will be happy with you when you give other people what they need.’”
Nínú ohun gbogbo mo fi àpẹẹrẹ fún un yín pé, nípa ṣíṣe iṣẹ́ bẹ́ẹ̀, ó yẹ kí ẹ máa ran àwọn aláìlera lọ́wọ́, ki ẹ sì máa rántí ọ̀rọ̀ Jesu Olúwa, bí òun tìkára rẹ̀ tí wí pé, ‘Láti fún ni ní ìbùkún ju láti gbà lọ.’”
36 When Paul had finished speaking, he knelt down with all of the elders and prayed.
Nígbà tí ó sì tí wí nǹkan wọ̀nyí, ó kúnlẹ̀, ó sì bá gbogbo wọn gbàdúrà.
37 They all cried a lot, and they hugged Paul and kissed him.
Gbogbo wọn sì sọkún gidigidi, wọ́n sì rọ̀ mọ́ Paulu lọ́rùn, wọ́n sì fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
38 They were especially sad because he had said that they would never see him [SYN] again. Then they [all] went with him to the ship.
Inú wọn sì bàjẹ́ jùlọ fún ọ̀rọ̀ tí ó sọ pé, wọn kì yóò rí ojú òun mọ́, wọ́n sì sìn ín títí dé inú ọkọ̀.

< Acts 20 >