< Acts 10 >

1 [There was] a man [who lived] in Caesarea [city] whose name was Cornelius. He was an officer who commanded 100 men in a large group of [Roman] soldiers from Italy.
Ọkùnrin kan sì wà ni Kesarea ti a ń pè ní Korneliu, balógun ọ̀rún ti ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí a ń pè ni Itali.
2 He always tried to do what would please God; he and his entire household [MTY] [were non-Jews who] habitually worshipped God. He sometimes gave money to help poor [Jewish] people, and he prayed to God regularly.
Olùfọkànsìn, àti ẹni ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run tilétilé rẹ̀ gbogbo, ẹni tí ó ń tọrẹ àánú púpọ̀ fún àwọn ènìyàn, tí ó sì ń gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run nígbà gbogbo.
3 [One day] at about three o’clock in the afternoon [Cornelius saw] a vision. He clearly saw an angel whom God [had sent]. The angel came into [his room] and said to him, “Cornelius!”
Níwọ́n wákàtí kẹsànán ọjọ́, ó rí nínú ìran kedere angẹli Ọlọ́run kan wọlé tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Korneliu!”
4 Cornelius stared at the angel and became terrified. Then he asked [fearfully], “Sir, what do you [(sg)] want?” The angel answered him, “You [(sg)] have pleased God because you have been praying [regularly to him] and you often give money to [help] poor people. [Those things have been] like a sacrifice [to God].
Nígbà tí ó sì tẹjúmọ́ ọn, ti ẹ̀rù sì bà á, ó ní, “Kín ni, Olúwa?” Ó sì wí fún un pé, “Àdúrà rẹ àti ọrẹ-àánú, tìrẹ gòkè lọ síwájú Ọlọ́run fún ìrántí.
5 So, now command some men to go to Joppa and [tell them to] bring back a man named Simon whose other name is Peter.
Sì rán ènìyàn nísinsin yìí lọ sí Joppa, kí wọn sì pe Simoni wá, ẹni ti àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Peteru.
6 He is staying with a man, [also] named Simon, who makes leather. His house is near the ocean.”
Ó wọ̀ sí ilé Simoni aláwọ, tí ilé rẹ̀ wà létí Òkun; òun ni yóò sọ fún ọ bí ìwọ ó ti ṣe.”
7 When the angel who spoke to Cornelius had gone, Cornelius summoned two of his household servants and a soldier who served him, one who also worshipped God.
Nígbà tí angẹli náà tí ó bá Korneliu sọ̀rọ̀ sì fi i sílẹ̀ lọ ó pe méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ ilé rẹ̀, àti ọmọ-ogun olùfọkànsìn kan, nínú àwọn ti ó máa ń dúró tì í nígbà gbogbo.
8 He explained to them everything [that the angel had said. Then] he told them to go to Joppa [to ask Peter to come to Caesarea].
Nígbà tí ó sì tí ṣàlàyé ohun gbogbo fún wọn, ó rán wọn lọ sí Joppa.
9 About noon the next day those [three men] were traveling [along the road] and were coming near [Joppa. As they were approaching Joppa], Peter went up on the [flat] housetop to pray.
Ni ọjọ́ kejì bí wọ́n ti ń lọ lọ́nà àjò wọn, tí wọ́n sì súnmọ́ ilé náà, Peteru gun òkè ilé lọ láti gbàdúrà ni ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́,
10 He became hungry and wanted something to eat. While someone was preparing the food, [Peter] saw [this] vision:
ebi sì pa á gidigidi, ó sì ń fẹ́ láti jẹun, ó bọ́ sí ojúran.
11 (He saw heaven open/He saw an opening in the sky) and something like a large sheet was being lowered [to the ground]. [It was tied at] its four corners [with ropes].
Ó sì rí ọ̀run ṣí, ohun èlò kan si sọ̀kalẹ̀ bí gọgọwú ńlá, tí a ti igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, sọ̀kalẹ̀ sí ilẹ̀.
12 Inside the sheet were all kinds of creatures. [These included animals and birds that the Mosaic laws forbade Jews to eat]. Some had four feet, others scurried across the ground, and others were wild birds.
Nínú rẹ̀ ni onírúurú ẹranko ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin wà, àti ohun tí ń rákò ni ayé àti ẹyẹ ojú ọ̀run.
13 Then [he heard] God [SYN] say to him, “Peter, stand up, kill [and cook some of these] and eat [their meat]!”
Ohùn kan si fọ̀ sí i pe, “Dìde, Peteru; máa pa kí o sì máa jẹ.”
14 But Peter replied, “Lord, surely you [(sg)] do not [really want me to do that]! I have never eaten any [meat] that [our Jewish law says] is unacceptable to God or [something that we(exc)] must not eat!”
Ṣùgbọ́n Peteru dáhùn pé, “Rara, Olúwa; nítorí èmi kò jẹ ohun èèwọ̀ àti aláìmọ́ kan rí.”
15 [Then Peter heard] [MTY] God talk to him a second time. He said, “[I am] God, [so] if I have made something acceptable [to eat], do not say that it is not acceptable [to eat]!”
Ohùn kan sì tún fọ̀ sí i lẹ́ẹ̀méjì pé, “Ohun tí Ọlọ́run bá ti wẹ̀mọ́, ìwọ má ṣe pè é ní èèwọ̀ mọ́.”
16 [This happened] three [times, so Peter knew that he had to think carefully about what it might mean]. Immediately [after God had said that the third time], ([the] sheet [with the animals and birds] was the pulled back into heaven/[someone] pulled the sheet [with the animals and birds] up into the sky again).
Èyí sì ṣe lẹ́ẹ̀mẹ́ta; lójúkan náà a sì gbé ohun èlò náà padà lọ sókè ọ̀run.
17 While Peter was trying to understand what that vision meant, the men who had been sent by Cornelius {whom Cornelius had sent} [arrived in Joppa. They asked people how to get to] Simon’s house. [So they found his house] and were standing outside the gate.
Bí Peteru sì ti ń dààmú nínú ara rẹ̀ bí òun bá ti mọ̀ ìran tí òun ri yìí sí, si wò ó, àwọn ọkùnrin tí a rán wá láti ọ̀dọ̀ Korneliu dé. Wọ́n ń béèrè ilé Simoni, wọ́n dúró ní ẹnu-ọ̀nà.
18 They called and were asking if a man named Simon, whose other name was Peter, was staying there.
Wọn nahùn béèrè bí Simoni tí a ń pè ní Peteru, wọ̀ níbẹ̀.
19 While Peter was still trying to understand [what] the vision [meant], [God’s] Spirit said to him, “Three men [are here who] want to see you.
Bí Peteru sì ti ń ronú ìran náà, Ẹ̀mí wí fún un pé, “Wò ó, àwọn ọkùnrin mẹ́ta ń wá ọ.
20 So get up and go downstairs and go with them! Do not think that you [(sg)] should not go with them [because of their being non-Jews], because I have sent them [here]!”
Ǹjẹ́ dìde, sọ̀kalẹ̀ kí ó sì bá wọn lọ, má ṣe kó ara ró láti bá wọn lọ, nítorí èmi ni ó rán wọn.”
21 So Peter went down to the men and said to them, “[Greetings!] I am [the man] you are looking for. Why have you come?”
Nígbà náà ni Peteru sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn ọkùnrin náà tí a rán, ó sì wí pé, “Wò ó, èmi ni ẹni tí ẹ̀yin ń wá, kín ni ìdí rẹ̀ ti ẹ fi wá?”
22 One of them replied, “Cornelius, who is a [Roman] army officer, [sent us here]. He is a righteous man who worships God, and all of the Jewish people [HYP] [who know about him] say that he is a very good man. An angel (who was sent from God/whom God sent) said to him, ‘Tell some men to [go to Joppa to see Simon Peter and] bring him here, so that you [(sg)] can hear what he has to say.’”
Wọ́n sì wí pé, “Korneliu balógun ọ̀rún, ọkùnrin olóòtítọ́, àti ẹni ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó sì ní orúkọ rere lọ́dọ̀ gbogbo orílẹ̀-èdè àwọn Júù, òun ni a ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run kọ́ nípasẹ̀ angẹli mímọ́, láti ránṣẹ́ pè ọ́ wá sí ilé rẹ̀ àti láti gbọ́ ọ̀rọ̀ lẹ́nu rẹ.”
23 So Peter [said that he would go with them, and then he] invited them into [the house] and told them that they could stay [there that night]. Acts 10:23b-26 The next day Peter got ready and went with the men. Several of the believers from Joppa went with him.
Nígbà náà ni Peteru pè wọ́n wọlé, ó gbà wọ́n lálejò. Ní ọjọ́ kejì, ó sì dìde, ó bá wọn lọ, díẹ̀ nínú àwọn ti o ti gbàgbọ́ ní Joppa sì bá a lọ pẹ̀lú.
24 The day after that, they arrived in Caesarea. Cornelius was waiting for them. He had also invited his relatives and close friends [to come to his house, so they were there, too].
Lọ́jọ́ kejì wọ́n sì wọ Kesarea, Korneliu sì ti ń retí wọn, ó sì ti pe àwọn ìbátan àti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ jọ.
25 When Peter entered the house, Cornelius met him and bowed low in front of him to worship him.
Ó sì ṣe bí Peteru ti ń wọlé, Korneliu pàdé rẹ̀, ó wólẹ̀ lẹ́sẹ̀ rẹ̀, ó sì foríbalẹ̀ fún un.
26 But Peter [grasped Cornelius by the hand and] lifted him to his feet. He said, “Stand up! [Do not revere/worship me] I myself am only human, [like you]!”
Ṣùgbọ́n Peteru gbé e dìde, ó ni, “Dìde ènìyàn ni èmi tìkára mi pẹ̀lú.”
27 While he was talking to Cornelius, Peter [and the others] entered [a large room inside the house]. Peter saw that many people had gathered together [there].
Bí ó sì ti ń bá a sọ̀rọ̀, ó wọlé ó sì rí àwọn ènìyàn púpọ̀ tí wọ́n péjọ.
28 Then Peter said to them, “You all know that any [of us] Jews think we are disobeying [our Jewish] laws if we [(exc)] associate with a non-Jewish person or [if we even] visit him. However, God has shown me [in a vision] that I should not say about anyone that God will not accept him.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin mọ̀ bí ó ti jẹ́ èèwọ̀ fún ẹni tí ó jẹ́ Júù, láti bá ẹni tí ó jẹ́ ará ilẹ̀ mìíràn kẹ́gbẹ́, tàbí láti tọ̀ ọ́ wá; ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti fihàn mi pé, ki èmi má ṣe pé ẹnikẹ́ni ni èèwọ̀ tàbí aláìmọ́.
29 So when you sent [some men] to ask me to come [here], I came [right away. I] did not say that I could not go [with non-Jewish people. So, please tell me], why have you asked me to come [here]?”
Nítorí náà ni mo sì ṣe wá ní àìjiyàn, bí a ti ránṣẹ́ pè mi, ǹjẹ́ mo béèrè, nítorí kín ní ẹ̀yin ṣe ránṣẹ́ pè mi?”
30 Cornelius replied, “About this time four days ago I was praying [to God] in my house, [as I regularly do] at three o’clock in the afternoon. Suddenly a man whose clothes [shone] brightly stood in front of me,
Korneliu sì dáhùn pé, “Ní ìjẹrin, mo ń ṣe àdúrà wákàtí kẹsànán ọjọ́ ni ilé mi títí di idayìí, sì wò ó, ọkùnrin kan aláṣọ, àlà dúró níwájú mi.
31 and said, ‘Cornelius, when you [(sg)] have prayed, you have been heard by God {God has heard [when] you [(sg)] have prayed [to him]}. He has also noticed that you have [often] given money to [help] poor people, [and he is pleased with that].
Ó sì wí pé, ‘Korneliu, a gbọ́ àdúrà rẹ, ọrẹ-àánú rẹ̀ sì wà ni ìrántí níwájú Ọlọ́run.
32 So now, send [messengers to go] to Joppa, [in order] to ask Simon whose other name is Peter to come [here]. He is staying near the ocean in a house that belongs to [another] man named Simon, who makes leather. [When Simon Peter comes, he will tell you a message from God].’
Ǹjẹ́ ránṣẹ́ lọ sí Joppa, kí ó sì pe Simoni wá, ẹni ti àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Peteru; ó wọ̀ ní ilé Simoni aláwọ létí òkun.’
33 So I immediately sent [some men who asked] you [(sg) to come here], and I [certainly] thank you for coming. Now we [(exc)] all are gathered [here, knowing that] God is with us, in order to hear all the things that the Lord [God] has commanded you [to say. So please speak to us].”
Nítorí náà ni mo sì ṣe ránṣẹ́ sì ọ lójúkan náà, ìwọ sì ṣeun tí ó fi wá. Gbogbo wa pé níwájú Ọlọ́run nísinsin yìí, láti gbọ́ ohun gbogbo, ti a pàṣẹ fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.”
34 So Peter began to speak [MTY] to them. He said, “[Now] I understand that it is true that God does not favor only certain groups [of people].
Peteru sì ya ẹnu rẹ, ó sì wí pé, “Nítòótọ́ mo wòye pé, Ọlọ́run kì í ṣe ojúsàájú ènìyàn.
35 Instead, from every group of people he accepts [everyone who] honors him and who does what pleases him.
Ṣùgbọ́n ni gbogbo orílẹ̀-èdè, ẹni tí ó bá bẹ̀rù rẹ̀, ti ó sì ń ṣiṣẹ́ òdodo, ẹni ìtẹ́wọ́gbà ni lọ́dọ̀ rẹ̀.
36 [You know] the message that God sent to [us] Israelis. [He] proclaimed [to us the good news that he] would cause [people] to have peace [with him] because of what Jesus Christ [has done]. This [Jesus is Lord not only over us Israelis. He] is [also the] Lord [who rules] over all [people].
Ẹyin mọ ọrọ̀ tí Ọlọ́run rán sí àwọn ọmọ Israẹli láti kéde ìròyìn ayọ̀ àlàáfíà nípasẹ̀ Jesu Kristi, ẹni ti ṣe Olúwa ohun gbogbo.
37 You know what [he] did throughout the land of Judea, beginning in Galilee. He began [to do those things] after John had been proclaiming [to people that they should turn away from their sinful behavior before] he baptized them.
Ẹ̀yin náà mọ ọ̀rọ̀ náà tí a kéde rẹ̀ yíká gbogbo Judea, tí a bẹ̀rẹ̀ rẹ̀ láti Galili, lẹ́yìn bamitiisi ti Johanu wàásù rẹ̀.
38 You know that God gave [MTY] his Holy Spirit to Jesus, [the Man] from Nazareth [town], and gave him the power [to do miracles. You also know] how Jesus went to many places, always doing good deeds and healing [people. Specifically], he was continually healing all the people whom the devil was causing to suffer. [Jesus was able to do those things] because God was always helping him.”
Àní Jesu ti Nasareti, gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti da Ẹ̀mí Mímọ́ àti agbára le lórí; ẹni tí ó ń kiri ṣe oore, ó ń ṣe ìmúláradá gbogbo àwọn tí èṣù sì ń pọ́n lójú; nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
39 “We [apostles] tell people about all the things that [we saw Jesus] do in Jerusalem and in the [rest of] Israel. [The leaders in Jerusalem] had him killed by being nailed to a cross.
“Àwa sì ni ẹlẹ́rìí gbogbo ohun tí ó ṣe, ní ilẹ̀ àwọn Júù, àti ni Jerusalẹmu. Ẹni tí wọ́n pa nípa gbígbékọ́ sí orí igi.
40 However, God caused him to become alive again on the third day [after he had died]. God [also] enabled [some of us(exc)] to see him [so that we would know that he was alive again].
Òun ni Ọlọ́run jí dìde ni ọjọ́ kẹta ó sì fi i hàn gbangba.
41 God [did] not [let] all the [Jewish] people see him. Instead, he had chosen us [apostles] beforehand to see [Jesus after he became alive again], and to tell others [about him]. We [apostles are the people] who ate meals with him (after he had become alive [again]/after he had risen from the dead).
Kì í ṣe fún gbogbo ènìyàn ni o ri, bí kò ṣe fún àwa ti a jẹ́ ẹlẹ́rìí ti a ti ọwọ́ Ọlọ́run yàn tẹ̀lé, ti a bá a jẹ, ti a sì bá à mu lẹ́yìn ìgbà ti ó jíǹde kúrò nínú òkú.
42 God commanded us to preach to the people and tell them that Jesus is the one whom he has appointed to judge [everyone some day. He will judge all] those who will [still] be living and all those who will have died [by that time].
Ó sì pàṣẹ fún wa láti wàásù fún àwọn ènìyàn, àti láti jẹ́rìí pé, òun ni a ti ọwọ́ Ọlọ́run yàn ṣe onídàájọ́ ààyè àti òkú.
43 All of the prophets [who wrote about the Messiah long ago] told [people] about him. [They wrote] that if people believe in the Messiah [MTY], God would forgive [them for] their sins, because of what [the Messiah would do] for them.”
Òun ni gbogbo àwọn wòlíì jẹ́rìí sì pé, ẹnikẹ́ni ti ó bá gbà á gbọ́ yóò rí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ gbà nípa orúkọ rẹ̀.”
44 While Peter was still speaking those words, suddenly the Holy Spirit (came down on/began to control) all [those non-Jewish people] who were listening to the message.
Bí Peteru sì ti ń sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí lẹ́nu, Ẹ̀mí Mímọ́ bà lé gbogbo àwọn ti ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà.
45 The Jewish believers who had come with Peter [from Joppa] were amazed that [God] had generously given the Holy Spirit to the non-Jewish people, too.
Ẹnu sì yà àwọn onígbàgbọ́ ti a ti kọ nílà tí wọ́n bá Peteru wá, nítorí ti a tu ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ sórí àwọn aláìkọlà pẹ̀lú.
46 [The Jewish believers knew that God had done that] because they were hearing those people speaking languages [MTY] [that they had not learned] and telling how great God is.
Nítorí wọ́n gbọ́, wọ́n ń fọ onírúurú èdè, wọn sì yin Ọlọ́run lógo. Nígbà náà ni Peteru dáhùn wí pé,
47 Then Peter said [to the other Jewish believers who were there], “[God] has given them the Holy Spirit just like [he gave him] to us [Jewish believers], so (surely all of you would agree that [we(exc)] should baptize these people!/would any of you forbid that these people should be baptized?) [RHQ]”
“Ẹnikẹ́ni ha lè ṣòfin pe, kí a má bamitiisi àwọn wọ̀nyí tí wọ́n gba Ẹ̀mí Mímọ́ bí àwa?”
48 Then Peter told those [non-Jewish] people that they should be baptized [to show that they had believed] [MTY] in the [Lord] Jesus Christ. [So they baptized all of them. After they were baptized], they requested that Peter stay [with them] several days. [So Peter and the other Jewish believers did that].
Ó sì pàṣẹ kí a bamitiisi wọn ni orúkọ Jesu Kristi. Nígbà náà ni wọ́n bẹ̀ ẹ́ kí ó dúró ni ọjọ́ mélòó kan.

< Acts 10 >