< Acts 1 >

1 [Dear] Theophilus, In my first book [that I wrote for you], I wrote about many of the things that Jesus did and taught
Nínú ìwé mi ìṣáájú, Teofilu, ni mo ti kọ ní ti ohun gbogbo tí Jesu bẹ̀rẹ̀ sí ṣe àti kọ́
2 until the day on which he was taken {[God] took him} up [to heaven]. Before [he went to heaven], saying what the Holy Spirit [told him], he told the apostles whom he had chosen [the things that he wanted them to know].
títí ó fi di ọjọ́ tí a gbà á lọ sókè ọ̀run, lẹ́yìn tí ó ti ti ipa Ẹ̀mí Mímọ́ pàṣẹ fún àwọn aposteli tí ó yàn.
3 After he had suffered [and died on the cross], [he became alive again]. As he appeared to them [often] during [the next] 40 days, the apostles saw him many times. He proved to them in many ways that he was alive again. He talked [with them] about [how] God would rule [MET] [the lives of people who accepted him as their king].
Lẹ́yìn ìjìyà rẹ̀, ó fi ara rẹ̀ hàn fún wọn àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀rí tí ó dájú pé òun wà láààyè. Ó fi ara hàn wọ́n fún ogójì ọjọ́, ó sì sọ̀rọ̀ nípa ìjọba Ọlọ́run.
4 [One time] while he was with them, he told them, “Do not leave Jerusalem [yet]. Instead, wait [here] until my Father sends [his Spirit] [MTY] [to you], as he promised [to do]. You have heard me speak [to you] about that.
Ní àkókò kan bí ó sì ti ń jẹun pẹ̀lú wọn, ó pàṣẹ yìí fún wọn, “Ẹ má ṣe kúrò ní Jerusalẹmu, ṣùgbọ́n ẹ dúró de ìlérí tí Baba mi ṣe ìlérí, èyí tí ẹ̀yin tí gbọ́ lẹ́nu mi.
5 John baptized people in water [because they said that they wanted to change their lives], but after a few days [LIT] [God] will put the Holy Spirit within you(pl) [to truly change your lives].”
Nítorí Johanu fi omi bamitiisi yín, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ díẹ̀ sí i, a o fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi yín.”
6 One day when the [apostles] met together [with Jesus], they asked him, “Lord, will you [(sg)] now become the King [MET] over [us] Israelite people [like King David, who ruled long ago]?” (OR, “Lord, will you [(sg)] now [defeat the Romans and] restore the kingdom [to us] Israelite people?”)
Nítorí náà, nígbà tí wọ́n sì péjọpọ̀, wọn bi í léèrè pé, “Olúwa, láti ìgbà yí lọ ìwọ yóò ha mú ìjọba padà fún Israẹli bí?”
7 He replied to them, “You do not [need] to know the time [periods] and days [when that will happen]. My Father alone has decided [when he will make me king].
Ó sì wí fún wọn pé, “Kì í ṣe tiyín ni láti mọ àkókò tàbí ìgbà tí Baba ti yàn nípa àṣẹ òun tìkára rẹ̀.
8 But [you do need to know that] the Holy Spirit will make you [spiritually] strong when he comes to live in you. Then you will [powerfully] tell people about me in Jerusalem and in all [the other places in] Judea [district], in Samaria [district], and in places far away all over [IDM] the world.”
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò gba agbára, nígbà tí Ẹ̀mí Mímọ́ bá bà lé e yín; ẹ̀yin yóò sì máa ṣe ẹlẹ́rìí mi ni Jerusalẹmu, àti ní gbogbo Judea, àti ní Samaria, àti títí dé òpin ilẹ̀ ayé.”
9 After he said that, he was taken {[God] took him} up [to heaven], while they were watching. [He went up into] a cloud [PRS], which prevented them from seeing him [any more].
Nígbà tí ó sì tí wí nǹkan wọ̀nyí, a gbà á sókè lójú wọn; ìkùùkuu àwọsánmọ̀ sì gbà á kúrò lójú wọn.
10 While [the apostles] were [still] staring towards the sky as he was going up, suddenly two men who were wearing white clothes stood beside them. [They were angels].
Bí wọ́n sì ti tẹjúmọ́ ojú ọ̀run bí ó ti ń lọ sókè, lójijì, àwọn ọkùnrin méjì tí ó wọ aṣọ funfun dúró létí ọ̀dọ̀ wọn.
11 One [of] them said, “You men from Galilee [district], (you do not need to stand [here any longer] looking up at the sky!/why do you still stand [here] looking up at the sky?) [RHQ] [Some day] this same Jesus, whom [God] took from you up to heaven, will come back [to earth]. He will return in the same manner as you [just now] saw him when he went up to heaven, [but he will not return now].”
Wọ́n sì wí pé, “Ẹ̀yin ara Galili, èéṣe tí ẹ̀yin fi dúró tí ẹ̀ ń wo ojú ọ̀run? Jesu yìí, tí a gbà sókè ọ̀run kúrò lọ́wọ́ yín, yóò padà bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ ti rí tí ó ń lọ sì ọ̀run.”
12 Then [after the two angels left], the apostles returned to Jerusalem from Olive [Tree] Hill, which was about (a half mile/one kilometer) [MTY] from Jerusalem.
Lẹ́yìn náà ni wọ́n padà sí Jerusalẹmu láti orí òkè ti a ń pè ni olifi, tí ó tó ìwọ̀n ìrìn ọjọ́ ìsinmi kan.
13 When they entered [the city], they went upstairs to the room [in the house] where they were staying. [Those who were there included] Peter, John, James, Andrew, Philip, Thomas, Bartholomew, Matthew, [another] James [the son] of Alphaeus, Simon who belonged to the group that wanted to expel the Romans, and Judas [the son] of [another man named] James.
Nígbà tí wọn sì wọlé, wọn lọ sí iyàrá òkè, níbi tí wọ́n ń gbé. Àwọn tó wà níbẹ̀ ni: Peteru, Jakọbu, Johanu àti Anderu; Filipi àti Tomasi; Bartolomeu àti Matiu; Jakọbu ọmọ Alfeu, Simoni Sealoti, àti Judasi arákùnrin Jakọbu.
14 All these apostles agreed concerning the things about which they continually were praying [together. Others who prayed with them] included the women [who had accompanied Jesus], Mary who was Jesus’ mother, and his [younger] brothers.
Gbogbo àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú àwọn obìnrin àti Maria ìyá Jesu àti àwọn arákùnrin rẹ̀ fi ọkàn kan dúró láti máa gbàdúrà.
15 During those days Peter stood up among his fellow believers. There were [at that place] a group of about 120 of [Jesus’ followers]. Peter said,
Ní ọjọ́ wọ̀nyí ni Peteru sí dìde dúró láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn (iye àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ́ ọgọ́fà)
16 “My fellow believers, [there are words that King] David wrote [MTY] in the Scriptures long ago that needed to be fulfilled {to happen [as he said they would]}. The Holy Spirit, [who knew that Judas would be the one who would fulfill those words], told David what to write.
ó wí pé, “Ẹ̀yin ará, ìwé mímọ́ kò lè ṣe kí ó má ṣẹ, èyí tí Ẹ̀mí Mímọ́ ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu Dafidi nípa Judasi, tí ó ṣe atọ́nà fún àwọn tí ó mú Jesu.
17 [Although] Judas had been chosen {[Jesus] had chosen Judas}, along with [the rest of] us [(exc)] to serve [as an apostle], Judas was the person who led to Jesus the people who seized him.”
Nítorí ọ̀kan nínú wa ni òun ń ṣe tẹ́lẹ̀, òun sì ní ìpín nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ yìí.”
18 [The Jewish leaders] gave Judas money when he [promised to] treacherously/wickedly [betray Jesus. Later Judas returned that money to them]. When Judas [hanged himself], his body fell down [to the ground]. His abdomen burst open, and all his intestines spilled out. [So] the [Jewish leaders] bought a field [using] that money.
(Judasi fi èrè àìṣòótọ́ rẹ̀ ra ilẹ̀ kan; nígbà tí ó sì ṣubú ni ògèdèǹgbé, ó bẹ́ ní agbede-méjì, gbogbo ìfun rẹ̀ sì tú jáde.
19 All the people who reside in Jerusalem heard [about that], so they called that field in their own [Aramaic] language, Akeldama, which means ‘Field of Blood’, [because it was where someone bled and died].
Ó si di mí mọ̀ fún gbogbo àwọn ti ń gbé Jerusalẹmu; nítorí náà ni wọ́n fi ń pè ilẹ̀ náà ni Alkedama ní èdè wọn, èyí sì ni, Ilẹ̀ Ẹ̀jẹ̀.)
20 [Peter also said], “[I perceive that what happened to Judas is like what the writer of] Psalms [desired to happen]: ‘May his house become deserted, and may there be no one to live in it.’ (OR, ‘[Judge him, Lord, so that neither he nor] anyone [else] may live in his house!)’ And it seems that [these other words that David wrote also refer to Judas: ] ‘Let someone else take over his work as a leader.’”
Peteru sì wí pé, “Nítorí a ti kọ ọ́ nípa rẹ̀ nínú Ìwé Saamu pé, “‘Jẹ́ ki ibùgbé rẹ̀ di ahoro, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀,’ àti, “‘Ipò rẹ̀ ni kí ẹlòmíràn kí ó gbà.’
21 “So it is necessary [for us apostles] to choose a man [to replace Judas. He must be one who] accompanied [MTY] us all the time when the Lord Jesus was with us.
Nítorí náà, ó di dandan láti yan ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti ń bá wa rìn ni gbogbo àkókò tí Jesu Olúwa ń wọlé, tí ó sì jáde láàrín wa.
22 [That would be] from [the time when] John [the Baptizer] baptized [Jesus] until the day when Jesus was taken {when [God] took Jesus} from us up [to heaven]. He must be one who saw Jesus alive again [after he died].”
Bẹ́ẹ̀ láti ìgbà bamitiisi Johanu títí ó fi di ọjọ́ náà ti a gbe é lọ sókè kúrò lọ́dọ̀ wa. Ó yẹ kí ọ̀kan nínú àwọn wọ̀nyí ṣe ẹlẹ́rìí àjíǹde rẹ̀ pẹ̀lú wa.”
23 So the [apostles and other believers] suggested [the names of two men who qualified. One man was] Joseph, who was called {whom people called} Barsabbas (OR, Joseph Barsabbas) who [also] had the [Roman] name Justus. The other man was Matthias.
Wọn sì yan àwọn méjì, Josẹfu tí a ń pè ní Barsaba (ẹni tí a sọ àpèlé rẹ̀ ni Justu) àti Mattia.
24 Then they prayed like this: “Lord [Jesus], Judas stopped being an apostle. [He died and] went to the place where he [deserved to be] [EUP]. [So we(exc) need to choose someone] to replace [Judas in order] that he can serve [you(sg) by becoming] an apostle. You [(sg)] know what everyone is really like. So [please] show us which of these two men you have chosen.”
Wọn sì gbàdúrà, wọn sì wí pé, “Olúwa, ìwọ mọ ọkàn gbogbo ènìyàn, fihàn wá nínú àwọn méjì yìí, èwo ni ìwọ yàn
kí ó lè gba ipò nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ aposteli yìí, èyí tí Judasi kúrò nínú rẹ̀, ki òun kí ó lè lọ sí ipò ti ara rẹ̀.”
26 Then they cast lots [to choose between the two of] them, and the lot fell for Matthias. (OR, Then [one of] the [apostles] shook [in a container] small objects/stones [that] they [had marked to determine which man God had chosen]. And the small object/stone [that they had marked] for Matthias fell [out of the container]). So Matthias was considered {they considered Matthias} [to be an apostle] along with the [other] eleven apostles.
Wọ́n sì dìbò fún wọn; ìbò sí mú Mattia; a sì kà á mọ́ àwọn aposteli mọ́kànlá.

< Acts 1 >