< 2 Timothy 1 >

1 [I], Paul, [am writing this letter. I am] an apostle whom Christ Jesus chose so that I would do what God wanted. He chose me [to tell people that God] has promised [that they will] live [eternally] as a result of their having a close relationship with Christ Jesus.
Paulu, aposteli ti Jesu Kristi nípa ìfẹ́ Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìlérí ìyè ti ń bẹ nínú Kristi Jesu,
2 [I am writing to you], Timothy, whom I love [as if you were] my own son. [I pray that] God our Father and Christ Jesus our Lord will [continue to act] kindly to you, be merciful to you, and [cause you to have] inner peace,
Sí Timotiu, ọmọ mi olùfẹ́ ọ̀wọ́n: Oore-ọ̀fẹ́, àánú àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa, àti Kristi Jesu Olúwa wa.
3 I thank God [for all that he has done for you]. I serve him, and my ancestors [served him, too. I serve him] in a manner that I know to be right. [I thank him] while repeatedly I [pray for you] at night and during the day.
Mo dá ọpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run, ẹni tí èmi ń sìn pẹ̀lú ẹ̀rí ọkàn mímọ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba mi ti í ṣe, pé ni àìsimi lọ́sàn án àti lóru ni mo ń ṣe ìrántí rẹ nínú àdúrà mi.
4 [While I am thanking God for you], I very much want to see you because I remember how you cried [MTY] [when we separated. I want to see you] in order that I may be (filled with joy/very happy).
Bí mo ti rántí omijé rẹ, bẹ́ẹ̀ ni mo ń fẹ́ láti rí ọ kí èmi kí ó lè kún fún ayọ̀.
5 [I thank God because] I remember that you sincerely believe [in Christ Jesus]. First, your grandmother, Lois, and your mother, Eunice, [believed in him and], I am (convinced/very sure) that you also believe in him.
Nígbà ti mo bá rántí ìgbàgbọ́ àìṣẹ̀tàn rẹ, èyí ti ó kọ́kọ́ ń bẹ nínú Loisi ìyá ńlá rẹ, àti nínú Eunike ìyá rẹ̀ àti, èyí tí ó dá mi lójú pé ó ń gbé inú rẹ̀ pẹ̀lú.
6 Because [I am sure that you believe in him], I remind you to do fervently/wholeheartedly [MET] what God has (assigned for/appointed) you to do and what he has enabled you to do. [God] ([assigned for/appointed]) you to do it as a result of my putting my hands [on you to show/indicate that he had chosen you to do his work].
Nítorí ìdí èyí ni mo ṣe ń ran ọ létí pé kí ó máa rú ẹ̀bùn Ọlọ́run sókè èyí ti ń bẹ nínú rẹ nípa ìgbọ́wọ́lé mi.
7 Remember that God has put [his Spirit] within us. [His Spirit does not cause us to be] afraid. Instead, [he causes us to be] powerful [to work for God], and he helps us to love [others] and [to] control what we say and do.
Nítorí pé Ọlọ́run kò fún wa ni ẹ̀mí ìbẹ̀rù, bí kò ṣe ti agbára, àti ti ìfẹ́, àti ti ìsẹ́ra-ẹni ti ó yè kooro.
8 So never be ashamed/reluctant to tell others the message about our Lord. And do not [be ashamed] of me, [even though I am] a prisoner [because I preach about] him. Instead, [be willing to] suffer as I do as you proclaim the message about Christ. [Endure what you will suffer] by letting God empower [you to endure it].
Nítorí náà, má ṣe tijú láti jẹ́rìí nípa Olúwa wa, tàbí èmi òǹdè rẹ̀; ṣùgbọ́n kí ìwọ ṣe alábápín nínú ìpọ́njú ìyìnrere nípa agbára Ọlọ́run,
9 [God] saved us and chose us to conduct our lives in a pure way. It was not our doing good deeds/actions [that caused him to do this for us—something] that we did not deserve. Instead, before (time began/he created the world) he purposed/planned to [be kind to us] as a result of what Christ Jesus [would do for us]. (aiōnios g166)
ẹni ti ó gbà wá là, ti ó si pè wá sínú ìwà mímọ́—kì í ṣe nípa iṣẹ́ tí a ṣe ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ète àti oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀. Oore-ọ̀fẹ́ yìí ni a fi fún wa nínú Kristi Jesu láti ìpìlẹ̀ ayérayé, (aiōnios g166)
10 Now, as a result of our Savior Christ Jesus having come, it has been revealed {he has shown} [that he acts kindly toward us. Specifically, Christ Jesus] has declared that we [will not remain dead after we] die! He has also revealed that, as a result of [our hearing and accepting] the message [about Christ, we] will live [forever in bodies that will] not decay!
ṣùgbọ́n tí a fihàn nísinsin yìí nípa ìfarahàn Jesu Kristi Olùgbàlà wa, ẹni ti ó pa ikú run, tí ó sì mú ìyè àti àìkú wá sí ìmọ́lẹ̀ nípasẹ̀ ìyìnrere.
11 I was chosen {Christ chose me} to go as an apostle to many places and proclaim that message to people.
Fún ti ìyìnrere tí a yàn mi láti jẹ oníwàásù àti aposteli àti olùkọ́.
12 So, even though I suffer [here in this prison], I am not ashamed [of being here] (OR, I am very confident), because I know [Christ Jesus], the one whom I have trusted, and I am convinced/sure that he is able to keep safe the good message that he has entrusted to me (OR, the things that I have entrusted [to him]), and that he will reward me at the time [MTY] [when he comes again].
Nítorí ìdí èyí ní èmi ṣe ń jìyà wọ̀nyí pẹ̀lú. Ṣùgbọ́n ojú kò tì mí, nítorí èmi mọ ẹni tí èmi gbàgbọ́, ó sì dá mi lójú pé, òun lè pa ohun ti mo fi lé e lọ́wọ́ mọ́ títí di ọjọ́ náà.
13 Be sure that you tell others the same correct message that you heard from me. [And as you tell it], keep trusting [in Christ Jesus] and keep loving [others] as Christ Jesus [enables you to do].
Ohun tí ó gbọ́ láti ọ̀dọ̀ mi, pa a mọ́ gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ ẹ̀kọ́ rere nínú ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́ Kristi Jesu.
14 Do not let anyone persuade you to change the [good message that] God has entrusted/given to you. Allow the Holy Spirit who lives in us to [direct what you say].
Pa ohun rere ti a ti fi lé ọ lọ́wọ́ mọ́ nípa Ẹ̀mí Mímọ́ ti ń gbé inú wa.
15 You know that [almost] all [the believers] in Asia [province] have (turned away from/abandoned) me, including Phygelus and Hermogenes.
Èyí ni ìwọ mọ̀ pé, gbogbo àwọn ti ó wà ni agbègbè Asia ti fi mí sílẹ̀, nínú àwọn ẹni tí Figeliu àti Hamogene gbé wà.
16 [But I pray that] the Lord will be kind to the family of Onesiphorus for the following reasons: Often he cheered me up and, [even though] I was a prisoner [MTY], he was not ashamed (of me/[to admit he was] my [friend]).
Kí Olúwa fi àánú fún ilé Onesiforu; nítorí ti ó máa ń tù mi lára nígbà púpọ̀, ẹ̀wọ̀n mi kò sì tì í lójú.
17 On the contrary, when he came here to Rome, he diligently searched for me until he found me.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wà ni Romu, ó fi ẹ̀sọ̀ wá mi, ó sì rí mi.
18 [I pray that] the Lord will be kind to him on that day [MTY] [when he, the Lord, will judge people]. And how much Onesiphorus served [me] in Ephesus [city], you know very well.
Kí Olúwa fi fún un kí ó lè rí àánú lọ́dọ̀ Olúwa ni ọjọ́ náà! Ìwọ tìkára rẹ sá à mọ̀ ọ̀nà gbogbo tí ó gbà ràn mí lọ́wọ́ ni Efesu.

< 2 Timothy 1 >