< 2 Corinthians 6 >

1 [Therefore], because I am working together with God [himself], I say this to you very strongly: God has [already] kindly [forgiven you because Christ died for you], so do not now [say] “It does not matter [if I live just to please myself].”
Gẹ́gẹ́ bí alábáṣiṣẹ́pọ̀ nínú Ọlọ́run, ǹjẹ́, àwa ń rọ̀ yín kí ẹ má ṣe gba oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run lásán.
2 For God said [long ago in the Scriptures]: When it is the right time [for me] to help you, [you will ask me to help you], and I will hear you. Then I will [send] a Savior to help you. [So listen to what] I am telling you: God [has sent] his Savior, so now is the time when [God is ready to] save [people from the guilt of their sins].
Nítorí o wí pé, “Ní àkókò ìtẹ́wọ́gbà mi, èmi tí gbọ́ ohùn rẹ, àti ọjọ́ ìgbàlà, èmi sì ti ràn ọ́ lọ́wọ́.” Èmi wí fún ọ, nísinsin yìí ní àkókò ìtẹ́wọ́gbà, nísinsin yìí ni ọjọ́ ìgbàlà.
3 Neither I nor the men [working] with me do anything that would hinder people from trusting in Christ, and so we cannot be accused {no one can accuse [us]} [of not] serving [God properly].
Àwa kò sì gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ kankan si ọ̀nà ẹnikẹ́ni, ki iṣẹ́ ìránṣẹ́ wa má ṣe di ìsọ̀rọ̀-òdì sí.
4 Instead, in everything [that we(exc) say and do], we show [people] that we serve God faithfully. We patiently endure [all the things that happen to us. People cause us] many troubles and, as a result, we are anxious [and often do not know what to do].
Ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀, ni ọnà gbogbo, àwa ń fi ara wa hàn bí àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ sùúrù, nínú ìpọ́njú, nínú àìní, nínú wàhálà,
5 Sometimes we have been beaten [and bound] {People have beaten [us and tied us]} [with] chains in prison. [Angry mobs] have attacked us, [wanting to kill us]. We have continued working [for God until we had no more strength to work]. We have had many sleepless nights, and we have [often been without food].
nípa nínà, nínú túbú, nínú ìrúkèrúdò, nínú iṣẹ́ àṣekára, nínú àìsàn, nínú ìgbààwẹ̀.
6 [All that we think about and all that we do is] pure [in God’s sight]. Knowing [how God wants us to conduct our lives, we do what pleases him]. We are patient [with those who oppose us]. We are kind [to everyone. We depend on] the Holy Spirit [to help us]. We love people sincerely [as God wants us to love them].
Nínú ìwà mímọ́, nínú ìmọ̀, nínú ìpamọ́ra, nínú ìṣeun, nínú Ẹ̀mí Mímọ́, nínú ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn.
7 We faithfully teach [the true] message [about Christ], and God [gives us] his power [as we teach it. Like soldiers] using weapons [MET] [in a battle], we, by [living] righteously, [defend God’s message and refute those who attack it].
Nínú ọ̀rọ̀ òtítọ́, nínú agbára Ọlọ́run, nínú ìhámọ́ra òdodo ní apá ọ̀tún àti ní apá òsì.
8 [We serve God faithfully], whether [people] praise us [(exc)] or [whether they] despise us, whether [people say] bad things [about us(exc)] or [whether they say] good things [about us. We keep teaching] the truth, [even though some people say that] we are deceiving [people].
Nípa ọlá àti ẹ̀gàn, nípa ìyìn búburú àti ìyìnrere: bí ẹlẹ́tàn, ṣùgbọ́n a jásí olóòtítọ́,
9 [Some people] know [well that we are true servants of God, and yet others], who know us, refuse to [believe that. People have often tried to] kill us [(inc)], yet we are still alive. We have [often] been beaten, but we have not been killed {[People have often] beaten us [(exc)], but [they] have not killed us}.
bí ẹni tí a kò mọ̀, ṣùgbọ́n a mọ̀ wá dájúdájú; bí ẹni tí ń kú lọ, ṣùgbọ́n a ṣì wà láààyè; bí ẹni tí a nà, ṣùgbọ́n a kò sì pa wá,
10 Although we [(exc)] are often very sad [because people have rejected our message], we are always joyful [because of all that God has done for us]. Even though we [(exc)] are poor, we make [it possible for] many people to be [spiritually] rich. It is true that [in this world] we [(exc)] have nothing [valuable] [HYP], but [because we belong to God’s family], all [that God has] belongs to us.
bí ẹni tí ó kún fún ìbànújẹ́, ṣùgbọ́n àwa ń yọ̀ nígbà gbogbo; bí tálákà, ṣùgbọ́n àwa ń sọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ dí ọlọ́rọ̀; bí ẹni tí kò ní nǹkan, ṣùgbọ́n àwa ni ohun gbogbo.
11 You [fellow believers] in Corinth, [I have been] completely honest with you. [I have told you exactly how we(exc) feel about you, that] we love you very much [IDM].
Ẹ̀yin ará Kọrinti, a ti bá yín sọ òtítọ́ ọ̀rọ̀, a ṣí ọkàn wa páyà sí yín.
12 We are not [treating you as though we do not] love you, but you are [treating us as though you do] not love us.
Àwa kò fa ìfẹ́ wa sẹ́yìn fún yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin fa ìfẹ́ yín sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ wa.
13 In return [for our loving you, will you not] love [us] [IDM] just as [much as we love you?] I am writing [to you] as if you were my own children.
Ní sísán padà, ní ọ̀nà tí ó dára, èmi ń sọ bí ẹni pé fún àwọn ọmọdé, ẹ̀yin náà ẹ ṣí ọkàn yín páyà pẹ̀lú.
14 Do not (team up/have a close relationship) with anyone who does not trust [in Christ. I say this] because we who [trust in Christ and do] what is right should not [RHQ] [want to do things] with wicked people. Or [to say it in another way], just like light and darkness never join together, so [those who belong to Christ and those who belong to Satan should never join together] [RHQ].
Ẹ má ṣe fi àìdọ́gba dàpọ̀ pẹ̀lú àwọn aláìgbàgbọ́, nítorí ìdàpọ̀ kín ni òdodo ní pẹ̀lú àìṣòdodo? Ìdàpọ̀ kín ni ìmọ́lẹ̀ sì ní pẹ̀lú òkùnkùn?
15 There is no [RHQ] agreement of any kind between Christ and Satan. [So], believers have no [RHQ] common [spiritual] interests with unbelievers.
Ìrẹ́pọ̀ kín ni Kristi ní pẹ̀lú Beliali? Tàbí ìpín wó ni ẹni tí ó gbàgbọ́ ní pẹ̀lú aláìgbàgbọ́?
16 [Just] as no one would [dare to bring] idols into the Temple [in Jerusalem], believers should never [RHQ] join with those who worship idols. [I say that] because [MET] [the Holy Spirit is in us, and so] we are [like] the Temple of the all-powerful God. [It is] as God himself said [in the Scriptures]: I will live in [my people]. I will always be with/helping them. [They will say to me], “You are our God,” and [I will say to them], “You are my people.”
Ìrẹ́pọ̀ kín ni tẹmpili Ọlọ́run ní pẹ̀lú òrìṣà? Nítorí ẹ̀yin ní tẹmpili Ọlọ́run alààyè; gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti wí pé: “Èmi á gbé inú wọn, èmi o sì máa rìn láàrín wọn, èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.”
17 [In another place in the Scriptures we read that] the Lord said: Get away from those who do evil things; keep yourselves separated from them. Do [nothing sinful that would make you] unacceptable to me. Then I will welcome you [as members of my family].
Nítorí náà, “Ẹ jáde kúrò láàrín wọn, kí ẹ sì yá ara yín si ọ̀tọ̀, ni Olúwa wí. Ki ẹ má ṣe fi ọwọ́ kan ohun àìmọ́; Èmi ó sì gbà yín.”
18 [The Lord also said]: I will [care for you] as [MET] a loving father [cares for his children], and [it will be as though] you are my own sons and daughters. I, the all-powerful Lord, am saying this [to you].
Àti, “Èmi o sì jẹ́ Baba fún yín. Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ọmọkùnrin mi àti ọmọbìnrin mi, ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< 2 Corinthians 6 >