< 2 Chronicles 16 >

1 When Asa had been ruling [Judah] for almost 36 years, King Baasha of Israel went [with his army] to attack Judah. They [captured the town of] Ramah [north of Jerusalem] and started to build a wall around [it], in order to prevent any people from entering or leaving the area in Judah that was ruled by King Asa [because the only road into Judah from Israel went through Ramah].
Ní ọdún kẹrìndínlógójì ìjọba Asa, Baaṣa ọba Israẹli gòkè wá sí Juda ó sì kọlu Rama, láti ma bá a jẹ́ kí ẹnikẹ́ni lè jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba Juda lọ.
2 So Asa told his workers to take all the silver and gold that was in the storerooms of the temple and in his own palace, and take and give it to Ben-Hadad, the king of Syria, who was ruling in Damascus. [He sent him a message, ] saying
Nígbà náà ni Asa mú wúrà àti fàdákà jáde nínú ilé ìṣúra ilé Olúwa àti ààfin ọba ó sì ránṣẹ́ sí Beni-Hadadi ọba Siria, ẹni tí ń gbé ní Damasku, ó wí pé,
3 “I want there to be a peace treaty between me and you, like there was between my father and your father. Look, I am sending you [a lot of] silver and gold. So please cancel the treaty that you have made with Baasha, the king of Israel, in order that he will take his soldiers away from attacking mine, [because he will be afraid of your army].”
“Májẹ̀mú kan wà láàrín èmi àti ìrẹ, bí ó ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Ẹ wò ó, mo fi wúrà àti fàdákà ránṣẹ́ sí ọ; lọ, ba májẹ̀mú tí o bá Baaṣa ọba Israẹli dá jẹ́, kí ó lè lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
4 Ben-Hadad agreed to do what King Asa [suggested]. He sent the commanders of his armies [with their soldiers] to attack some of the towns in Israel. They captured Ijon, Dan, Abel-Beth-Maacah and all the cities in the area belonging to the tribe of Naphtali where supplies were kept.
Beni-Hadadi sì gbọ́ ti Asa ọba, ó sì rán àwọn olórí ogun rẹ̀ lọ sí àwọn ìlú Israẹli, wọ́n sì kọlu Ijoni, Dani, Abeli-Maimu, àti gbogbo ìlú ìṣúra Naftali.
5 When Baasha heard about that, he [commanded his troops to] stop fortifying Ramah and doing other work there.
Nígbà tí Baaṣa gbọ́ èyí, ó sì dá kíkọ́ Rama dúró, ó sì dá iṣẹ́ rẹ̀ dúró.
6 Then King Asa gathered all the men of Judah, and they took away from Ramah all the stones and timber that Baasha’s men had been using [to build the wall around that town]. They took those materials to [the town of] Geba and [the city of] Mizpah [north of Jerusalem] and built walls around them.
Nígbà náà ní ọba Asa kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda jọ, wọ́n sì kó òkúta àti igi Rama lọ èyí ti Baaṣa ń fi kọ́lé; ó sì fi kọ́ Geba àti Mispa.
7 At that time the prophet Hanani went to King Asa and said to him, “Because you relied on the king of Syria and not on Yahweh our God, you missed your opportunity to destroy the army of the king of Syria.
Ní àkókò náà wòlíì Hanani wá sí ọ̀dọ̀ Asa ọba Juda, ó sì wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ọba Siria, ìwọ kò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run rẹ, nítorí náà ni ogún ọba Siria ṣe bọ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ.
8 The huge armies from Ethiopia and Libya with all their chariots and soldiers [riding] on horses [were certainly very powerful. But] when you relied on Yahweh, he enabled your army to defeat them.
Àwa kì í ṣe ará Etiopia àti àwọn ará Libia àwọn alágbára ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin? Síbẹ̀ nígbà tí ìwọ bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sì fi wọ́n lé ọwọ́ rẹ.
9 That happened because Yahweh sees [what is happening] all over the earth, and he strengthens those who completely trust him. You have done a very foolish thing, so from now on other armies will be fighting your army.”
Nítorí ojú Olúwa yí gbogbo ayé ká láti fi agbára fún àwọn ẹni tí ó ní ọkàn pípé sí i. Ìwọ ti ṣe ohun aṣiwèrè, láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ yóò wà lójú ogun.”
10 Asa was very angry with the prophet because of what the prophet had said. So he [commanded his officials to] put Hanani in prison. At that same time, he started to treat some of his people very cruelly.
Asa sì bínú pẹ̀lú sí wòlíì nítorí èyí, ó sì mú un bínú gidigidi tí ó sì fi mú un sínú túbú. Ní àkókò náà Asa sì ni díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn náà lára.
11 All the things that Asa did while he was ruling, from the time he started to rule until he died, are written in the scroll containing the record of the [activities of the] kings of Judah and Israel.
Àwọn iṣẹ́ ìjọba Asa, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni akọ sínú ìwé ọba Juda àti Israẹli.
12 When Asa had been ruling for almost 39 years, he was afflicted with a disease in his feet. The disease was very severe, but in spite of that, he did not request help from Yahweh. Instead he sought help only from doctors.
Ní ọdún kọkàndínlógójì ìjọba rẹ̀, Asa sì ṣe àìsàn pẹ̀lú ààrùn nínú ẹsẹ̀ rẹ̀. Bi ó tilẹ̀ jẹ pé ààrùn rẹ̀ lágbára, síbẹ̀ kódà nínú àìsàn rẹ̀ kò wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ àwọn oníṣègùn nìkan.
13 When he had been ruling for almost 40 years, he died.
Nígbà náà tí ó pé ọdún kọ́kànlélógójì rẹ̀, Asa kú, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn ìjọba baba rẹ̀,
14 He was buried in the tomb that his workers had made for him in [the part of Jerusalem called] ‘The City of David’. They laid his corpse on a bed covered with spices and various perfumes that had been mixed together. They also lit a huge fire to honor him.
wọ́n sì sin ín sínú isà òkú tí ó ti gbẹ́ jáde fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Wọ́n sì tẹ sí orí àkéte tí ó fi òórùn dídùn kún, àti onírúurú tùràrí tí a fi ọgbọ́n pèsè, wọ́n sì da iná ńlá nítorí rẹ̀.

< 2 Chronicles 16 >