< 1 Samuel 2 >

1 Then Hannah prayed, saying, “I rejoice in [what] you, [, have done]. I am strong [MET] because I belong to you. I (laugh at/ridicule) my enemies, because you, Yahweh have rescued me [from being taunted by them].
Hana sì gbàdúrà pé, “Ọkàn mi yọ̀ sí Olúwa; ìwo agbára mi ni a sì gbé sókè sí Olúwa. Ẹnu mi sì gbòòrò lórí àwọn ọ̀tá mi, nítorí ti èmi yọ̀ ni ìgbàlà rẹ̀.
2 There is no one who is holy like you, Yahweh. There is no other god like you. There is no one like you, our God, who can protect us [as though you were putting us beneath] a huge rock [where we can hide from danger].
“Kò sí ẹni tí ó mọ́ bi Olúwa; kò sí ẹlòmíràn bí kò ṣe ìwọ; kò sì sí àpáta bi Ọlọ́run wa.
3 [You people who oppose God], stop boasting! Yahweh is a God who knows [everything], and he will evaluate/judge everyone’s actions. So don’t speak so arrogantly!
“Má ṣe halẹ̀; má ṣe jẹ́ kí ìgbéraga ti ẹnu yín jáde nítorí pé Ọlọ́run olùmọ̀ ni Olúwa, láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá ni a ti ń wọn ìwà.
4 Yahweh, you break the bows/weapons of mighty soldiers, and you give strength to those who stumble [because of being weak].
“Ọ̀run àwọn alágbára ti ṣẹ́, àwọn tí ó ṣe aláìlera ni a fi agbára dì ní àmùrè.
5 Many people who previously had plenty to eat, now have to work for other people [to earn money] to buy food, but many who were always hungry are not hungry any more. The woman who did not have any children before, now has given birth to many/seven children, and the woman who had many children before, now is very lonely [because they have all died].
Àwọn tí ó yọ̀ fún oúnjẹ ti fi ara wọn ṣe alágbàṣe, àwọn tí ebi ń pa kò sì ṣe aláìní. Tó bẹ́ẹ̀ tí àgàn fi bí méje. Ẹni tí ó bímọ púpọ̀ sì di aláìlágbára.
6 Yahweh, you cause some people to die, and you restore some people who are almost dead. For some people, [it seems that they will soon] go to where the dead people are, but you cause them to become healthy again. (Sheol h7585)
“Olúwa pa ó sì sọ di ààyè; ó mú sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà òkú, ó sì gbé dìde. (Sheol h7585)
7 Yahweh, you cause some people to be poor and you cause some people to be rich, you humble some people and you honor some people.
Olúwa sọ di tálákà; ó sì sọ di ọlọ́rọ̀; ó rẹ̀ sílẹ̀, ó sì gbé sókè.
8 [Sometimes] you lift poor people up so that they are no longer [despondent, sitting in the dust, ] or sitting on heaps of ashes; you cause them to sit next to princes; you cause them to sit on chairs/thrones where people who are highly honored sit. Yahweh, you are the one who laid the foundations of the earth, and you have set the whole world on those foundations.
Ó gbé tálákà sókè láti inú erùpẹ̀ wá, ó gbé alágbe sókè láti orí òkìtì eérú wá, láti mú wọn jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé, láti mu wọn jogún ìtẹ́ ògo, “Nítorí pé ọ̀wọ́n ayé ti Olúwa ni, ó sì ti gbé ayé ka orí wọn.
9 You will protect your loyal/faithful people [SYN], but you will cause the wicked to die [EUP] and descend to the dark [place where dead people are]. We do not defeat [our enemies] by our own strength;
Yóò pa ẹsẹ̀ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ mọ́, àwọn ènìyàn búburú ni yóò dákẹ́ ní òkùnkùn. “Nípa agbára kò sí ọkùnrin tí yóò borí.
10 Yahweh, you will break into pieces those who oppose you. You will cause thunder in the sky to show that you (oppose/are angry with) them. Yahweh, you will judge [people everywhere, even those who live in] the most remote places on the earth. You will give strength to the king whom you will appoint, and give him great power [over his enemies].”
A ó fọ́ àwọn ọ̀tá Olúwa túútúú; láti ọ̀run wá ni yóò sán àrá sí wọn; Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ òpin ayé. “Yóò fi agbára fún ọba rẹ̀, yóò si gbé ìwo ẹni àmì òróró rẹ̀ sókè.”
11 Then Elkanah [and his family] returned to Ramah, but Samuel, the little boy, stayed to help Eli the priest serve Yahweh.
Elkana sì lọ sí Rama, sí ilé rẹ̀, ọmọ náà sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Olúwa níwájú Eli àlùfáà.
12 Eli’s two [, who were also priests, ] were very wicked. They did not revere (OR, respect/obey) Yahweh.
Àwọn ọmọ Eli sì jẹ́ ọmọ Beliali; wọn kò mọ Olúwa.
13 While the people were boiling the meat from their sacrifices [in the huge pot at the temple], one of Eli’s sons, [would send his servant to come with a large three-pronged fork in his hand].
Iṣẹ́ àwọn àlùfáà pẹ̀lú àwọn ènìyàn ni pé nígbà tí ẹnìkan bá ṣe ìrúbọ, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, nígbà tí ẹran náà bá ń hó lórí iná, pẹ̀lú ọ̀pá-ẹran náà oníga mẹ́ta ní ọwọ́ rẹ̀.
14 [He] would stick the fork into [the meat in] the pot, and whatever meat fastened onto the fork, he would take [and give it] to the priest who sent him. Eli’s sons did this to all the Israeli people who came to Shiloh [to offer sacrifices].
Òun a sì fi gún inú apẹ, tàbí àgé tàbí ọpọ́n, tàbí ìkòkò, gbogbo èyí tí ọ̀pá-ẹran oníga náà bá mú wá sí òkè, àlùfáà á mú un fún ara rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń ṣe sí gbogbo Israẹli tí ó wá sí ibẹ̀ ní Ṣilo.
15 Furthermore, before the fat [on the meat] was [cut off and] and burned [as a sacrifice to Yahweh], the servant of the priest would [sometimes] come to the man who was making the sacrifice and say to him, “Give me some meat [now to take] to the priest for him to roast! He wants raw meat; he does not want boiled meat.”
Pẹ̀lú, kí wọn tó sun ọ̀rá náà, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, á sì wí fún ọkùnrin tí ó ń ṣe ìrúbọ pé, “Fi ẹran fún mi láti sun fún àlùfáà; nítorí tí kì yóò gba ẹran sísè lọ́wọ́ rẹ, bí kò ṣe tútù.”
16 If the man said to the servant, “Let the priests [cut off and] burn the fat first; then you can take what you want,” the servant would reply, “No, give it to me now; if you do not give it to me, I will take it forcefully!”
Bí ọkùnrin náà bá sì wí fún un pé, “Jẹ́ kí wọn ó sun ọ̀rá náà nísinsin yìí, kí o sì mú iyekíye tí ọkàn rẹ̀ bá fẹ́,” nígbà náà ni yóò dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n kí ìwọ ó fi í fún mi nísinsin yìí, bí kó ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó fi agbára gbà á.”
17 Yahweh considered that the young [sons of Eli] were committing a very great sin, because they were treating very disrespectfully the offerings that were being given to Yahweh.
Ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì tóbi gidigidi níwájú Olúwa: nítorí tí àwọn ènìyàn kórìíra ẹbọ Olúwa.
18 As for Samuel, who was still a very young boy, he continued to do work for Yahweh, wearing a little sacred linen vest [like the Supreme Priest wore].
Ṣùgbọ́n Samuẹli ń ṣe ìránṣẹ́ níwájú Olúwa, ọmọdé, ti a wọ̀ ní efodu ọ̀gbọ̀.
19 Each year his mother made a [new] little robe for him and took it to him when she went up [to Shiloh] with her husband to offer a sacrifice.
Pẹ̀lúpẹ̀lú, ìyá rẹ̀ máa ń dá aṣọ ìlekè péńpé fún un, a sì máa mú wá fún un lọ́dọọdún, nígbà tí ó bá bá ọkọ rẹ̀ gòkè wá láti ṣe ìrúbọ ọdún.
20 Then Eli would [ask God to] bless Elkanah and his wife, and he would say to Elkanah, “I hope/desire that Yahweh will enable your wife to give birth to other children, to take the place of the one whom she dedicated to Yahweh.” Then Elkanah and his family would return home.
Eli súre fún Elkana àti aya rẹ̀ pé, “Kí Olúwa fún ọ ní irú-ọmọ láti ara obìnrin yìí wá, nítorí ẹ̀bùn tí ó béèrè tí ó sì tún fún Olúwa.” Wọ́n sì lọ sí ilé wọn.
21 And Yahweh was very kind to Hannah, and enabled her to give birth to three [other] sons and two daughters. Their son Samuel grew up while he was doing work for Yahweh [in the Sacred Tent].
Olúwa si bojú wo Hana, ó sì lóyún, ó bí ọmọkùnrin mẹ́ta àti ọmọbìnrin méjì. Samuẹli ọmọ náà sì ń dàgbà níwájú Olúwa.
22 Eli became very old. He often heard about all the [evil] things that his sons were doing to the Israeli people. He heard that they [sometimes] (slept with/had sex with) the women who worked at the entrance to the tent where [God] spoke to [his people].
Eli sì di arúgbó gidigidi, ó sì gbọ́ gbogbo èyí ti àwọn ọmọ rẹ̀ ṣe sí gbogbo Israẹli; àti bi wọ́n ti máa ń bá àwọn obìnrin sùn, tí wọ́n máa ń péjọ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ.
23 He said to them, “(It is terrible that you do such things!/Why do you do such things?) [RHQ] Many people keep telling me about the evil things that you do.
Ó sì wí fún wọn pé, kí ni ó ti ri “Èétirí tí èmi fi ń gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ sí yín? Nítorí tí èmi ń gbọ́ iṣẹ́ búburú yín láti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn.
24 My sons, stop it! The reports [about you] that the people who belong to Yahweh tell others are terrible [EUP]!
Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí kì ṣe ìròyìn rere èmi gbọ́; ẹ̀yin mú ènìyàn Olúwa dẹ́ṣẹ̀.
25 If one person sins against another person, God can (intercede/act as a referee) between them. But if someone sins against Yahweh, no one can [RHQ] (intercede/act as a referee) between them!” But Eli’s sons would not listen to what their father said. This was because Yahweh had decided [that someone should] them.
Bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì, onídàájọ́ yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀: ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí Olúwa, ta ni yóò bẹ̀bẹ̀ fún un?” Wọn kò sì fi etí sí ohùn baba wọn, nítorí tí Olúwa ń fẹ́ pa wọ́n.
26 The boy Samuel continued to grow up, and the things that he did pleased Yahweh and the people.
Ọmọ náà Samuẹli ń dàgbà, ó sì rí ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa, àti ènìyàn pẹ̀lú.
27 One day, a prophet came to Eli and told him, “This is what Yahweh has told me: ‘When your ancestors were slaves of the king of Egypt, I appeared to Aaron.
Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ Eli wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí, ‘Èmi fi ara mi hàn ní gbangba fún ilé baba rẹ, nígbà tí wọ́n ń bẹ ní Ejibiti nínú ilé Farao.
28 From all the tribes of the Israeli people, I chose him [and his male descendants] to be priests for me. I appointed them to go up to my altar, to burn incense, to wear a sacred apron [as they worked] for me. And I declared that they could take [and eat some of the meat] that the Israeli people burned [on the altar].
Èmi sì yàn án kúrò láàrín gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti jẹ́ àlùfáà mi, láti rú ẹbọ lórí pẹpẹ mi, láti fi tùràrí jóná, láti wọ efodu níwájú mi, èmi sì fi gbogbo ẹbọ tí ọmọ Israẹli máa ń fi iná sun fún ìdílé baba rẹ̀.
29 So why do you show disrespect for the sacrifices and offerings that I commanded [the people to bring] to me [RHQ]? You are honoring your sons more than you are honoring me, by allowing them to get fat from eating the best parts of all the sacrifices that the Israeli people bring to me!’
Èéha ṣe tí ẹ̀yin fi tàpá sí ẹbọ àti ọrẹ mi, tí mo pàṣẹ ní ibùjókòó mi, ìwọ sì bu ọlá fún àwọn ọmọ rẹ jù mí lọ, tí ẹ sì fi gbogbo àṣàyàn ẹbọ Israẹli àwọn ènìyàn mi mú ara yín sanra.’
30 “Therefore, this is what Yahweh, the God whom we Israelis [worship], declares: ‘I definitely promised that Aaron and his descendants would continue to serve [IDM] me forever.’ But now I declare this: ‘It will not continue like that! I will honor those who honor me, but I will despise those who despise me.
“Nítorí náà Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí pé, ‘Èmi ti wí nítòótọ́ pé, ilé rẹ àti ilé baba rẹ, yóò máa rìn níwájú mi títí.’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa wí pé, ‘Kí á má rí i! Àwọn tí ó bú ọlá fún mi ni èmi yóò bu ọlá fún, àti àwọn tí kò kà mí sí ni a ó sì ṣe aláìkàsí.
31 Listen carefully! There will soon be a time when I will cause all the strong [young men] in your family to die. The result will be that no men in your family will [live long enough to] become old men.
Kíyèsi i, àwọn ọjọ́ ń bọ̀ tí èmi ó gé agbára rẹ kúrò, àti agbára baba rẹ, tí kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ.
32 You will be distressed and envious as you see the blessings that I will give to [the other people in] Israel. And [I repeat that] no men in your family will ever live long enough to become old men.
Ìwọ yóò rí wàhálà ti Àgọ́, nínú gbogbo ọlá tí Ọlọ́run yóò fi fún Israẹli; kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ láéláé.
33 There is one of your descendants whom I will spare, and not prevent him from serving me as a priest. But he will become blind, and then he will always be sad and grieving. But all your other descendants will die violently.
Ọkùnrin tí ó jẹ́ tìrẹ, tí èmi kì yóò gé kúrò ní ibi pẹpẹ mi ni a ó dá sí láti sọkún yọ lójú àti láti banújẹ́. Ṣùgbọ́n gbogbo irú-ọmọ ilé rẹ̀ ni a ó fi idà pa ní ààbọ̀ ọjọ́ wọn.
34 And your two sons, Hophni and Phinehas, will both die on the same day. And that will prove to you [that all that I have said will come true/happen].
“‘Kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ọmọ ọkùnrin rẹ̀ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, yóò jẹ́ àmì fún ọ—àwọn méjèèjì yóò kú ní ọjọ́ kan náà.
35 ‘have chosen another man to be my priest. He is one who will serve me faithfully: He will do everything I want [DOU] him to do. And I will enable him to have many descendants [IDM] who will be priests and will always serve me by helping the king whom I will choose.
Èmi yóò dìde fún ara mi láti gbé àlùfáà olódodo dìde fún ara mi, ẹni tí yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó wà ní ọkàn mi àti inú mi. Èmi yóò fi ẹsẹ̀ ilé rẹ̀ múlẹ̀ gbọningbọnin òun yóò sì ṣe òjíṣẹ́ níwájú ẹni òróró mi ní ọjọ́ gbogbo.
36 All of your descendants who remain alive will have to go to that priest and ask him to give them money and food, and they will each have to say, “Please allow me to help the other priests, in order that I may [earn some money to] buy some food.”’”
Nígbà náà olúkúlùkù ẹnikẹ́ni tí ó bá kù ní ìdílé yín, yóò jáde wá yóò sì foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀ nítorí ẹyọ fàdákà àti nítorí èépá àkàrà àti ẹ̀bẹ̀ pé, “Jọ̀wọ́ yàn mí sí ọ̀kan nínú iṣẹ́ àwọn àlùfáà, kí èmi kí ó le máa rí oúnjẹ jẹ.”’”

< 1 Samuel 2 >