< 1 Corinthians 9 >

1 I am certainly free [to do all the things that God allows me to do.] [RHQ] I am an apostle. [RHQ] [You] certainly [know that] I have seen Jesus our Lord. [RHQ] It is a result of my work that you [have believed in] the Lord [Jesus]. [RHQ]
Èmi kò ha ni òmìnira bí? Èmi kò ha ń ṣe aposteli bí? Èmi kò ha ti rí Jesu Olúwa bí? Ẹ̀yìn ha kọ́ ní èrè iṣẹ́ mi nínú Olúwa bí?
2 And even though other people may think that I am not an apostle, you certainly should know that I am an apostle. [Remember that] your having become Christians [MET] [as a result of my telling you about] the Lord (confirms/shows that it is true) that I am an apostle.
Ní ìrònú àwọn ẹlòmíràn, èmi kì í ṣe aposteli. Dájúdájú aposteli ni mo jẹ́ fún un yín, tí n kì bá ṣe fún àwọn ẹlòmíràn. Nítorí èdìdì iṣẹ́ aposteli mi ni ẹ̀yin jẹ́ nínú Olúwa.
3 In order to defend myself, this [is what I say] to those who criticize me [by claiming that I do not act like an apostle].
Èyí ni ìdáhùn mi sí àwọn tí ń béèrè ẹ̀tọ́ aposteli mi.
4 As for Barnabas and me, we certainly have the right [as apostles] to receive [from you and other congregations] food and drink [for our work]. [RHQ]
Ṣé a kò ní ẹ̀tọ́ láti máa jẹ àti láti máa mu bí?
5 [We have the] same right [that] the other apostles and the Lord Jesus’ [younger] brothers and [especially] Peter have. They all take along a wife who is a believer [when they travel various places in order to tell people about Christ. And they have a right that the people whom they work among will support their wives, too]. So Barnabas and I certainly have those same rights. [RHQ]
Ṣé àwa kò ní ẹ̀tọ́ láti máa mú ìyàwó tí í ṣe onígbàgbọ́ káàkiri gẹ́gẹ́ bí àwọn aposteli mìíràn? Àti bí arákùnrin Olúwa, àti Kefa.
6 It would be ridiculous to think that Barnabas and I are the only apostles who must work to earn money to pay our expenses [while we are doing God’s work! [RHQ]]
Ṣé èmi nìkan àti Barnaba, àwa kò ha ní agbára láti máa ṣiṣẹ́ bọ́ ara wa ni?
7 Soldiers certainly do not pay their own wages. [RHQ] Those who plant a vineyard would certainly eat some of the grapes [when they become ripe]. [RHQ] Those who care for sheep would certainly drink the milk from those sheep. [RHQ] [Similarly, those who tell others about Christ certainly have a right to receive] ([financial help/food]) [from the people to whom they preach].
Ta ni ó ṣíṣẹ́ ológun tí ó sanwó ara rẹ̀? Ta ní gbin ọgbà àjàrà tí kì í jẹ nínú èso rẹ̀? Tàbí ta ní ń bọ ọ̀wọ́ ẹran tí kì í sí ì jẹ nínú wàrà ọ̀wọ́ ẹran?
8 I am saying that, not only because people think that it is right. [RHQ] [No], I am [RHQ] saying it because it is what [God said] in the laws [that he gave to Moses].
Èmi ha sọ nǹkan wọ̀nyí bí ènìyàn? Tàbí òfin kò wí bákan náà bì?
9 Moses wrote in one of those laws, “While an ox is threshing [grain], you must not tie its mouth shut [so that it cannot eat the grain].” (God was not only concerned about oxen [when he gave that law]./Was God [only] concerned about oxen [when he gave that law]?) [RHQ]
Nítorí nínú òfin tí Ọlọ́run fún Mose, ni a tí kọ ọ́ pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń tẹ ọkà lẹ́nu.” Ǹjẹ́ màlúù ni Ọlọ́run n ṣe ìtọ́jú rẹ̀ bi?
10 [No], he was [RHQ] concerned about us, also! Yes, [God caused Moses to] write those words [because he is concerned] about us! Those who plow the ground confidently expect [to eat some of] the crop [that grows]. Those who thresh grain confidently expect [to eat some of the grain that they thresh. Similarly, we who proclaim the message about Christ have the right to confidently expect to receive financial help for our work].
Dájúdájú ó sọ eléyìí fún wa pé, nítorí wa ni a ṣe kọ̀wé yìí kí ẹni tí ń tulẹ̀ lè máa tulẹ̀ ní ìrètí àti ẹni tí ń pakà lè ni ìrètí láti ní ìpín nínú ìkórè.
11 And because we have proclaimed God’s message to you, we certainly have the right to receive from you the things that we need for our bodies [MET]! [MET, RHQ]
Bí àwa ti fún irúgbìn ohun ti ẹ̀mí sínú ọkàn yín, ohun ńlá ha ni bí àwa ó ba ká ohun ti yín tí ṣe ti ara?
12 Since other people [who preached to you] had that right, certainly Barnabas and I have the same right. [RHQ] However, neither of us insisted [that you give us the things that] we have a right [to receive from you]. Instead, we were willing to endure anything in order that we not hinder [anyone from believing] the message about Christ.
Bí àwọn ẹlòmíràn bá ní ẹ̀tọ́ tí ìrànlọ́wọ́ sì wá láti ọ̀dọ̀ yín, àwa ha kọ́ ni ó tọ́ sí jù? Ṣùgbọ́n àwa kò lo agbára yìí ṣùgbọ́n àwa faradà ohun gbogbo, kí àwa má ba à ṣe ìdènà fún ìyìnrere Kristi.
13 You should keep in mind that [the priests and servants] in the Temple eat [some of the food that people bring to] the Temple. [RHQ] Specifically, the priests who work at the altar eat some of [the food that the people bring to sacrifice on] the altar.
Ǹjẹ́ ó yé e yín pé Ọlọ́run sọ fún àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili pé kí wọ́n mú oúnjẹ tàbí àwọn ẹ̀bùn tí wọ́n mú wá fún òun, láti fi ṣe ìtọ́jú ara wọn? Àti àwọn tí ń dúró tí pẹpẹ wọn a máa ṣe àjọpín pẹ̀lú pẹpẹ.
14 So the Lord has commanded that those who proclaim the good message [about him] should receive from [those who hear that] message what they need to live on.
Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ti fi àṣẹ lélẹ̀ pé, àwọn tí ń wàásù ìyìnrere kí wọn sì máa jẹ́ nípa ìyìnrere.
15 However, I have not requested that you [give me] those things that I have a right [to receive from you]. Furthermore, I am writing this to you, not in order to request you to begin [giving me financial help now]. I would rather die than to [receive help from you]. I do not want anyone to prevent me from boasting [about my proclaiming God’s message to you without receiving financial help from you].
Síbẹ̀síbẹ̀ n kò ì tí ì lo irú àwọn ẹ̀tọ́ wọ̀nyí rí. Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì kọ ìwé yìí láti fi sọ fún un yín pé, mo fẹ́ bẹ̀rẹ̀ sí í gbà irú nǹkan bẹ̀ ẹ́ lọ́wọ́ yín. Kí a sọ òtítọ́, ó sàn fún mi láti kú sínú ebi ju pé kí n sọ ògo tí mo ní láti wàásù nù.
16 When I proclaim the message about Christ, I cannot boast [about doing it], because [Christ] has commanded me [to do it]. I would be very miserable (OR, [I am afraid that] God would punish me) if I did not proclaim that message.
Nítorí pé bí mo ti ń wàásù ìyìnrere, kì í ṣe ohun tí mo lè máa ṣògo lè. Èmi kò tilẹ̀ le è ṣe é ní, kí a tilẹ̀ sọ pé mo fẹ́ kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Ègbé ni fún mi tí mo bá kọ̀ láti wàásù ìyìnrere.
17 If I had decided by myself to proclaim it, [God] would reward me. But I did not decide by myself to do that. I am simply doing the work that [God] entrusted to me.
Tó bá jẹ́ pé mò ń wàásù tinútinú mi, mo ní èrè kan, ṣùgbọ́n tí ń kò bá ṣe tinútinú mi, a ti fi iṣẹ́ ìríjú lé mi lọ́wọ́.
18 So perhaps you wonder what my reward is. [RHQ] [I will tell you]. When I proclaim the good message [about Christ], I do not ask people for financial help. It [makes me very happy not to ask for help, and being happy is the] reward I get. I do not want to use the rights that I have [when I proclaim] the gospel.
Ní irú ipò báyìí, kín ni ẹ rò pé yóò jẹ èrè mi ni láti jẹ́? Èrè mi ní àgbàyanu ayọ̀ tí mo ń rí gbà nípa ìwàásù ìyìnrere láìgba owó lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, láìbéèrè ẹ̀tọ́ mi lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni.
19 I am not obligated to do what anyone else thinks that I should do. Nevertheless, when I have been with any group of people, I have made myself [do what they believed that I should do, just like a slave does what his master wants him to do]. I have done that in order that I might convince more people [to trust in Christ].
Bí mo ti jẹ́ òmìnira tí ń kò sì darapọ̀ mọ́ ẹnikẹ́ni, mo sọ ara mi di ẹrú lọ́dọ̀ gbogbo ènìyàn, láti lè jèrè ọ̀pọ̀lọpọ̀ sí i.
20 Specifically, when I was with fellow Jews, I did the things that Jews [think that people should do]. I did that in order that I might convince some of them [to trust in Christ]. Although I am now not obligated to obey the Jewish laws and rituals, when I was with those who believe that they are obligated to obey those laws, I did the things that they [think that people should do]. I did that in order to convince some of them [to trust in Christ].
Nígbà tí mó wà lọ́dọ̀ àwọn Júù, mo dàbí ọ̀kan nínú wọn, kí wọn ba à lè tẹ́tí sí ìwàásù ìyìnrere mi àti ki n le jèrè wọn fún Kristi. Nígbà tí mo bá wà láàrín àwọn tó wà lábẹ́ òfin èmi kì í bá wọn jiyàn rárá (bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò sí lábẹ́ òfin), kí èmi lè jèrè àwọn ti ń bẹ lábẹ́ òfin.
21 When I was with (non-Jews/those who do not know those laws), I did the things that non-Jews [think that people should do], in order that I might convince some of them [to trust in Christ]. I do not mean that I disobey God’s laws. No, I obey the things that Christ commanded us to do.
Nígbà tí mo bá wà láàrín àwọn tí kò sí lábẹ́ òfin, èmi náà yóò dàbí ẹni tí kò sí lábẹ́ òfin (èmi kì í ṣe aláìlófin sí Ọlọ́run, ṣùgbọ́n èmí ń bẹ lábẹ́ òfin Kristi), kí èmi le jèrè àwọn tí kò sí lábẹ́ òfin.
22 When I was with those who doubt [whether God will permit them to do certain things that others] ([disapprove of/think it is not right to do]), I [avoided doing those things], in order that I might convince some of them [to trust in Christ]. In summary, I have done all the things [that the people I have been with think that others should do], in order that by every possible means I might convince some of them [to trust in Christ].
Nígbà tí mo bá wà láàrín àwọn aláìlera, èmi náà yóò di aláìlera, kí èmi lé jèrè àwọn aláìlera. Mo di ohun gbogbo fún gbogbo ènìyàn, kí èmi ba à lè gba díẹ̀ là lábẹ́ bí ó ti wù kí ó rí.
23 I do all these things in order that [more people will believe] the message about Christ, and in order that I, along with other believers, may receive the good things [that God promises to give us].
Èmi sì ń ṣe ohun gbogbo nítorí ti ìyìnrere, kí èmi kí ó lè jẹ́ alábápín nínú rẹ̀ pẹ̀lú yín.
24 When people run in a race, they all run, but only one of them wins the race and as a result gets a prize. You certainly know that [RHQ]. So, [just like] runners [exert themselves fully to win a race] [MET], [you should exert yourselves fully to do the things that God wants you to do], in order that you may receive the reward [that God wants to give you].
Ẹ̀yin kò mọ̀ pé, olúkúlùkù ẹni tí ó ní ipa nínú eré ìje ni ó máa ń sáré, ṣùgbọ́n ẹnìkan ṣoṣo ni ń gba ipò ẹ̀bùn tí ó ga jù. Nítorí náà, ẹ sá eré ìje yín kí ẹ ba à le borí.
25 All athletes exercise their bodies strenuously in many ways. They do that in order to receive a wreath [as a reward to wear on their heads]. Those wreaths fade, but we will receive a reward that will last forever [LIT].
Gbogbo ẹni tí ó ń sáré ìje a máa lọ nínú ìsẹ́ra-ẹni tí ó lágbára. Wọ́n ń ṣe èyí láti gba adé ìdíbàjẹ́. Ṣùgbọ́n àwa ń sá eré ìje tiwa láti fi gba adé ọ̀run àìdíbàjẹ́ láéláé.
26 For that reason, I [try hard to please God] [MET], [like a] runner who runs toward the goal [LIT]. I [try hard to accomplish what God wants me to accomplish, like] a boxer tries hard to hit his opponent, not to miss hitting him.
Nítorí náà, mo ń sá eré ìje lọ sójú àmì, kì í ṣe bí ẹni ti kò dá lójú. Mò ń jà kí n lè borí, kì í ṣe bí ẹni tí ń bá afẹ́fẹ́ jà.
27 I beat my body [to make it do what I want it to do] [MET], [as] slaves [obey their masters], in order that, after I have proclaimed [God’s message] to others, he will not [say that I do] not deserve to receive a reward.
Ṣùgbọ́n èmi ń kó ara mi ní ìjánu, mo sì ń mú un wá sí abẹ́ ìtẹríba, pé lẹ́yìn tí mo ti wàásù fún àwọn ẹlòmíràn, nítorí ohunkóhun, kí èmi fún rara mi má ṣe di ẹni ìtanù fún ẹ̀bùn náà.

< 1 Corinthians 9 >