< 1 Corinthians 11 >

1 [Follow my example], just like I [try to] follow Christ’s example.
Ẹ máa tẹ̀lé àpẹẹrẹ mi, gẹ́gẹ́ bí èmi náà ti ń tẹ̀lé àpẹẹrẹ Kristi.
2 I praise you because you remember all the things [that I taught you] and because you follow the instructions that I gave you. You have done just like I told you to do.
Èmí yìn yín fún rírántí mi nínú ohun gbogbo àti fún dídi gbogbo ẹ̀kọ́ tí mo kọ́ ọ yín mú ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí mo ṣe fi lélẹ̀ fún un yín.
3 [Now], I want you to know that the one who has authority over [MTY] every man is Christ, and the ones who have authority over women are men (OR, their husbands), and the one who has authority over Christ is God.
Ṣùgbọ́n mo fẹ́ kí ẹ̀yin mọ̀ pé, Kristi ni orí olúkúlùkù ọkùnrin, orí obìnrin sì ni ọkọ rẹ̀ àti orí Kristi sì ní Ọlọ́run.
4 [So] if any man [wears a covering over] his head when he prays or speaks a message God gave him, he disgraces himself [SYN].
Gbogbo ọkùnrin tó bá borí rẹ̀ nígbà tó bá ń gbàdúrà tàbí sọtẹ́lẹ̀ kò bọ̀wọ̀ fún orí rẹ̀.
5 Also, if any woman does not wear a covering over her head when she prays or speaks a message that God gave her, she disgraces herself (OR, she dishonors her husband). That would be acting like [SIM] [women who are ashamed because] their heads have been shaved.
Bẹ́ẹ̀ náà ni obìnrin tí ó bá ń gbàdúrà tàbí tí ó bá ń sọtẹ́lẹ̀ láìbo orí rẹ̀, kò bu ọlá fún orí ara rẹ̀ nítorí ọ̀kan náà ni pẹ̀lú ẹni tí ó fárí.
6 So, if women do not wear coverings over their heads [when they pray or speak messages that God gave them], they should let someone shave their heads [so that they will be ashamed]. But since women are ashamed if someone cuts their hair [short] or shaves off their hair, they should wear coverings over their heads [when they pray or speak messages that God gave them].
Ṣùgbọ́n tí obìnrin bá kọ̀ láti bo orí rẹ̀, ẹ jẹ́ kí ó gé irun rẹ̀. Bí ó bá sì jẹ́ nǹkan ìtìjú fún un láti gé irun orí rẹ́, nígbà náà kí ó fi gèlè bo orí rẹ̀.
7 Men should not wear coverings over their heads [when they pray or speak messages that God gave them], because they represent what God is like [MET] and they show how great God is. But women show how great men (OR, their husbands) are.
Ṣùgbọ́n ọkùnrin kò ní láti fi nǹkan bo orí rẹ́ nígbà tí ó bá ń sìn, nítorí àwòrán àti ògo Ọlọ́run ni òun í ṣe, ṣùgbọ́n ògo ọkùnrin ni obìnrin í ṣe.
8 [Remember that God intends that men have authority over women. We know that] because [God] did not make [the first] man, [Adam], from the [first] woman, [Eve]. Instead, he made that woman [from a bone that he took] from the man.
Ọkùnrin kò ti inú obìnrin wá, ṣùgbọ́n a yọ obìnrin jáde lára ọkùnrin,
9 Also, [God] did not create [the first] man [to help] the woman. Instead, [he] created the woman [to help] the man.
bẹ́ẹ̀ ni a kò dá ọkùnrin fún àǹfààní obìnrin ṣùgbọ́n a da obìnrin fún ọkùnrin.
10 For that reason, women should wear something [to cover] their heads [as a symbol of their being under their husbands’] [MTY] authority. They should also [cover their heads] so that the angels [will see that and rejoice].
Nítorí ìdí èyí àti nítorí àwọn angẹli, ni obìnrin ṣe gbọdọ̀ ní àmì àṣẹ rẹ̀ ní orí rẹ̀.
11 However, remember that [even though God created the first] woman from [the first] man, all other men [have been born] from women. So men cannot be independent of women, nor can women be independent of men. But all things, [including men and women], come from God.
Ẹ rántí pé, nínú ètò Ọlọ́run obìnrin kò lè wà láìsí ọkùnrin, bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin kò lè wà láàsí obìnrin.
Lóòtítọ́ láti ara ọkùnrin ni a ti yọ obìnrin jáde bẹ́ẹ̀ sì ni ọkùnrin tipasẹ̀ obìnrin wa. Ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ohun gbogbo ti wà.
13 Consider this for yourselves: Is it proper for [RHQ] women to pray to God while they do not have coverings over their heads?
Kí ni ẹ̀yìn fúnra yín rò lórí ọ̀rọ̀ yìí? Ǹjẹ́ ó tọ̀nà fún obìnrin láti máa gbàdúrà Ọlọ́run ní gbangba láìbo orí rẹ̀ bí?
14 (Everyone senses that it is disgraceful for men to have long hair./Doesn’t everyone sense that it is disgraceful for men to have long hair?) [RHQ]
Ǹjẹ́ ìwà abínibí yín kò ha kọ́ yín pé, bí ọkùnrin bá ní irun gígùn, àbùkù ni ó jẹ́ fún un.
15 But it is very delightful if women have long hair, because [God] gave them long hair to be like a [beautiful] covering [for their heads].
Ṣùgbọ́n bí obìnrin bá ní irun gígùn, ògo ni ó jẹ́ fún un nítorí irun gígùn tí a fi fún un jẹ́ ìbòrí fún un.
16 But whoever wants to argue [with me about my saying that women should have a covering over their heads when they pray or speak a message from God should consider the fact that] we [apostles] do not [permit] any other custom, and the [other] congregations of God do not have any other custom.
Ṣùgbọ́n tí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ jiyàn lórí ọ̀rọ̀ yìí, ohun kan tí mo lè sọ sí gbogbo rẹ̀ ni pé, a kò ní ìlànà tí ó yàtọ̀ sí èyí tí mo ti sọ, pé obìnrin gbọdọ̀ fi gèlè bo orí rẹ̀ nígbà tí ó bá ń sọtẹ́lẹ̀ tàbí tí ó bá ń gbàdúrà láàrín ìjọ Ọlọ́run.
17 Now I want to tell you [about some other things]. I do not praise you about them, because whenever you believers meet together, good [things do not happen]. Instead, bad things [happen].
Nínú àwọn àlàkalẹ̀ èmi ko ni yìn yín nítorí pé bí ẹ bá péjọ kì í ṣe fún rere bí ko ṣe fún búburú.
18 First of all, people have told me that when you gather together as a group [to worship God], you divide into groups [that are hostile to each other]. To some extent I believe that is true.
Lọ́nà kìn-ín-ní, mo gbọ́ pe ìyapa máa ń wà láàrín yín ní ìgbà tí ẹ bá péjọpọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìjọ, mo sì gba èyí gbọ́ dé ààyè ibìkan.
19 It seems that you must divide into [groups that despise each other] in order that it might be clear/evident which people among you [God] approves of!
Kò sí àní àní, ìyàtọ̀ gbọdọ̀ wa láàrín yín, kí àwọn tí ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ Ọlọ́run láàrín yín le farahàn kedere.
20 When you gather together, you [IRO] eat the meal [that you say is to remember the death of] the Lord [Jesus for us].
Nígbà tí ẹ bá pàdé láti jẹun, kì í ṣe oúnjẹ alẹ́ Olúwa ni ẹ máa ń jẹ.
21 But [what happens when] you eat is that each person eats his own meal before [he thinks about sharing his food with anyone else]. As a result, [when the meal is over], some people are [still] hungry and others are drunk! [So it is not a meal that honors the Lord].
Ṣùgbọ́n tí ara yín, nígbà tí ẹ bá fẹ́ jẹun, olúkúlùkù yín a máa sáré jẹ oúnjẹ rẹ̀ láìdúró de ẹnìkejì rẹ̀. Ebi a sì máa pa wọ́n, ẹlòmíràn wọ́n sì ń mu àmuyó àti àmupara.
22 ([You act as though] you do not have your own houses in which you can eat and drink [whatever you want to]!/Do you not have your own houses in which you can eat and drink [whatever you want to]?) [RHQ] Do you not realize [RHQ] [that by acting selfishly in this way], it is God’s people whom you are despising, and it is the poor people [in your group] whom you are treating as though they were not important? What shall I say to you about that [RHQ]? Do [you expect] me to praise you [about what you do] [RHQ]? I certainly will not praise you!
Ṣé ẹ̀yin kò ní ilé tí ẹ ti lè jẹ, tí ẹ sì ti lè mu ni? Tàbí ẹ̀yin ń gan ìjọ Ọlọ́run ni? Ẹ̀yin sì ń dójútì àwọn aláìní? Kín ni kí èmi ó wí fún un yín? Èmi yóò ha yìn yín nítorí èyí? A! Rárá o. Èmi kọ́, n kò ní yìn yín.
23 The Lord taught me these things that I also taught you: During the night that Jesus was betrayed {[Judas] enabled [the enemies of] the Lord Jesus to seize him}, he took some bread.
Nítorí èyí tí èmi gbà lọ́wọ́ Olúwa ni mo ti fi fún un yin. Ní alẹ́ ọjọ́ tí Judasi fihàn, Olúwa Jesu Kristi mú àkàrà.
24 After he thanked God for it, he broke it into pieces. [Then he gave it to his disciples] and said, “This bread [represents] [MET] (OR, is) my body, that [I am about to sacrifice] for you. Eat bread in this [way again and again] to remember my [offering myself as a sacrifice for you].”
Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run fún àkàrà náà tan, ó bù ú, ó fi fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ gbà kí ẹ sì jẹ, èyí ní ara mi tí a fi fún un yín. Ẹ máa ṣe eléyìí ni rántí mi.”
25 Similarly, after they ate their meal, he took a cup [MTY] [of wine]. He [thanked God for it. Then he gave it to his disciples], saying, “[The wine in] [MTY] this cup [represents] [MET] (OR, is) my blood [that will flow from my body] ([to put into effect/to establish]) the new agreement [that God is making with people]. Whenever you drink wine in this way, do it to remember that [my blood flowed for you].”
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ lẹ́yìn oúnjẹ alẹ́, ó sì mú ago wáìnì, ó sì wí pé, “Ago yìí ni májẹ̀mú tuntun nínú ẹ̀jẹ̀ mi, ẹ máa ṣe èyí, nígbàkígbà ti ẹ̀yìn bá ń mu ú, ní ìrántí mi.”
26 [Remember that] until the Lord [Jesus] returns [to the earth], whenever you eat the [bread that represents his body] and drink the wine [MTY] [that represents his blood], you are telling other people that he died [for you].
Nítorí nígbàkígbà tí ẹ bá ń jẹ lára àkàrà yìí, tí ẹ sì ǹ mu nínú ago yìí, ni ẹ tún sọ nípa ikú Olúwa. Ẹ máa ṣe eléyìí títí yóò fi padà dé.
27 So, those who eat that bread and drink that wine [MTY] in a way that is not proper [for those who belong to the Lord] are guilty of [acting in a way that is contrary to what] our [Lord intended when he offered] his body [as a sacrifice] and his blood [flowed when he died].
Nítorí náà tí ẹnikẹ́ni bá jẹ lára àkàrà yìí, tí ẹ sì ń mu nínú ago Olúwa yìí, ní ọ̀nà tí kò bójúmu, yóò jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ sí ara àti ẹ̀jẹ̀ Olúwa.
28 Before any believer eats that bread and drinks that wine [MTY], he should think carefully about [what he is doing],
Ìdí nìyìí tí ó fi yẹ kí ènìyàn yẹ ara rẹ̀ wò dáradára kí ó tó jẹ lára àkàrà nà án àti kí ó tó mu nínú ago náà.
29 because if anyone eats [the bread that represents Christ’s body] and drinks [the wine that represents his blood] without recognizing that all God’s [people should be united, God will] punish him [for doing that].
Nítorí tí ẹ bá jẹ lára àkàrà, tí ẹ sì mu nínú ago láìyẹ, tí ẹ kò ronú ara Kristi àti nǹkan tí ó túmọ̀ sí, ẹ̀ ń jẹ, ẹ sì ń mú ẹ̀bi ìdájọ́ Ọlọ́run wá sórí ara yín.
30 Many people in your group are weak and sick, and several have died [EUP] because of [the way they acted when they ate that bread and drank that wine].
Ìdí nìyìí tí ọ̀pọ̀ yín fi di ẹni tí kò lágbára mọ́, tí ọ̀pọ̀ yín sì ń ṣàìsàn, àwọn mìíràn nínú yín tilẹ̀ ti sùn.
31 If we would think carefully about what we [are doing], [God] would not judge [and punish] us [like that].
Ṣùgbọ́n tí ẹ bá yẹ ara yín wò dáradára, kí ẹ tó jẹ ẹ́, a kì yóò dá yín lẹ́jọ́.
32 But when the Lord judges [and punishes] us [for acting wrongly], he disciplines us [to correct us], in order that he will not [need to] punish us when he punishes [the people who do not trust in Christ] [MTY].
Ṣùgbọ́n nígbà tí a bá dá wa lẹ́jọ́, láti ọwọ́ Olúwa ni a ti nà wá, kí a má ba à dá wa lẹ́bi pẹ̀lú ayé.
33 So, my fellow believers, when you gather together to eat [food to remember the Lord’s dying for you], wait until everyone [has arrived so that you can find out who does not have enough food].
Nítorí náà, ẹ̀yin arákùnrin mi ọ̀wọ́n, nígbàkígbà ti ẹ bá péjọ láti jẹ́ oúnjẹ alẹ́ Olúwa, tàbí fún ìsìn oúnjẹ alẹ́ Olúwa, ẹ dúró de ara yín.
34 Those who are so hungry [that they cannot wait to eat until everyone else has arrived] should eat in their own homes [first], in order that when you gather together God will not judge [and punish them for] ([being inconsiderate of/not being concerned about]) [others]. And when I come [to Corinth] I will give you instructions about other matters [concerning the Lord’s Supper].
Bí ebi bá ń pa ẹnikẹ́ni nínú yin, kí ó jẹun láti ilé wá, kí ó má ba á mú ìjìyà wá sórí ara rẹ̀ nígbà tí ẹ bá péjọ. Tí mo bá dé, èmi yóò máa sọ̀rọ̀ lórí àwọn kókó-ọ̀rọ̀ ìyókù tí n kò ì ti fẹnu bà lẹ́sẹẹsẹ.

< 1 Corinthians 11 >