< 1 Chronicles 12 >

1 David went to Ziklag [town] to escape from [King] Saul. While he was there, many warriors came and joined him, and they helped him when he fought battles.
Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin tí ó wá sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Siklagi, nígbà tí ó sá kúrò níwájú Saulu ọmọ Kiṣi (wọ́n wà lára àwọn jagunjagun ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́ láti ibi ìjà.
2 They carried bows [and arrows]. They were able to shoot arrows and to sling stones. They could use either their right arms or their left arms to do that. They were relatives of Saul from the tribe of Benjamin.
Wọ́n sì mú wọn pẹ̀lú ìtẹríba wọ́n sì lágbára láti ta ọfà tàbí láti ta kànnàkànnà òkúta ní ọwọ́ òsì tàbí ní ọwọ́ ọ̀tún, wọ́n sì jẹ́ ìbátan ọkùnrin Saulu láti ẹ̀yà Benjamini):
3 Their leader was Ahiezer. Next in command was Joash. They were both sons of Shemaah from Gibeah [city]. [These are the names of some of those warriors: ] Jeziel and Pelet, the sons of Azmaveth; Beracah; Jehu from Anathoth [town];
Ahieseri olórí wọn àti Joaṣi àwọn ọmọ Ṣemaah ará Gibeah: Jeṣieli àti Peleti ọmọ Asmafeti, Beraka, Jehu ará Anatoti.
4 Ishmaiah from the Gibeon [city], who was a leader of the thirty mighty warriors; Jeremiah, Jahaziel, Johanan, and Jozabad from Gederah [town];
Àti Iṣmaiah ará Gibeoni, ọkùnrin alágbára kan lára àwọn ọgbọ̀n ẹni tí ó jẹ́ olórí nínú àwọn ọgbọ̀n; Jeremiah, Jahasieli, Johanani, Josabadi ará Gedera,
5 Eluzai, Jerimoth, Bealiah, Shemariah, and Shephatiah from Haruph [town];
Elusai, Jerimoti, Bealiah, Ṣemariah àti Ṣefatia ará Harufiti;
6 Elkanah, Isshiah, Azarel, Joezer and Jashobeam, who were descendants of Korah;
Elkana, Iṣiah, Asareeli, Joeseri àti Jaṣobeamu ará Kora;
7 Joelah and Zebadiah, who were sons of Jeroham, from Gedor [town].
àti Joẹla, àti Sebadiah àwọn ọmọ Jerohamu láti Gedori.
8 Some men from the tribe of Gad [east of the Jordan River] joined David when he was at his fortress in [the caves in] the desert. They were brave warriors who were trained for fighting battles and able to use shields and spears well. They [SYN] were as fierce as [SIM, MTY] lions, and they could run as fast as [HYP, SIM] deer/gazelles on the hills/mountains.
Díẹ̀ lára àwọn ará Gadi yà sọ́dọ̀ Dafidi ní ibi gíga ní aginjù. Wọ́n sì jẹ́ onígboyà ológun tí ó múra fún ogun tí ó sì lágbára láti di asà àti ẹṣin mú. Ojú wọn sì dàbí ojú kìnnìún, wọ́n sì yára bí àgbọ̀nrín lórí àwọn òkè.
9 Ezer was their leader. Next in command was Obadiah. Next was Eliab.
Eseri sì jẹ́ ìjòyè, Obadiah sì jẹ́ igbákejì akọgun, Eliabu ẹlẹ́ẹ̀kẹta,
10 Next was Mishmannah. Next was Jeremiah.
Miṣimana ẹlẹ́ẹ̀kẹrin, Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀karùnún
11 Next was Attai. Next was Eliel.
Attai ẹlẹ́ẹ̀kẹfà, Elieli èkeje,
12 Next was Johanan. Next was Elzabad.
Johanani ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ Elsabadi ẹlẹ́ẹ̀kẹsàn-án
13 Next was [another man whose name was] Jeremiah. The last was Macbannai.
Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀kẹwàá àti Makbannai ẹlẹ́ẹ̀kọkànlá.
14 Those men from the tribe of Gad were all army officers. Some of them commanded 1,000 soldiers, and some of them commanded 100 soldiers.
Àwọn ará Gadi wọ́n sì jẹ́ olórí ogun; ẹni tí ó kéré jù sì jẹ́ àpapọ̀ ọgọ́rùn-ún, àti fún ẹni tí ó pọ̀jù fún ẹgbẹ̀rún.
15 They crossed [to the west side of] the Jordan [River] during March, [at the time of the year] when the river was flooded. They chased from there all the people who lived in the valleys on both sides of the river.
Àwọn ni ẹni tí ó rékọjá Jordani ní oṣù àkọ́kọ́ nígbà tí ó kún bo gbogbo bèbè rẹ̀, wọ́n sì lé gbogbo àwọn tí ó ń gbé nínú àfonífojì, lọ sí ìlà-oòrùn àti níhà ìwọ̀-oòrùn.
16 Some other men from the tribe of Benjamin and from Judah also came to David in his fortress.
Ìyókù ará Benjamini àti àwọn díẹ̀ ọkùnrin láti Juda lọ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní ibi gíga.
17 David went out [of the cave] to meet them and said to them, “If you have come peacefully to help me, I am eager to have you join with me. But if you have come to enable my enemies to capture me, even though I [SYN] have not done anything to harm you, I hope/wish that the God whom our ancestors (worshiped/belonged to) will see it and condemn/punish you.”
Dafidi sì lọ láti lọ pàdé wọn ó sì wí fún wọn pé, “Tí ẹ bá wá sọ́dọ̀ mi lálàáfíà, láti ràn mí lọ́wọ́ mo ṣetán láti mú un yín wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú mi ṣùgbọ́n tí ẹ bá wá láti dá mi sí fún àwọn ọ̀tá mi nígbà tí ọwọ́ mi bá mọ́ kúrò nínú ìwà agbára, kí Ọlọ́run àwọn baba wa kí ó sì ri kí ó sì ṣe ìdájọ́.”
18 Then [God’s] Spirit came upon Amasai, who was another leader of the thirty [greatest warriors], and he said, “David, we want to be with you; you who are the son of Jesse, we will join you. We know that things will go very well [DOU] for you and for those who are with you, because your God is helping you.”
Nígbà náà Ẹ̀mí Mímọ́ wa sórí Amasai ìjòyè àwọn ọgbọ̀n, ó sì wí pé, “Tìrẹ ni àwa ń ṣe, ìwọ Dafidi! Àwa pẹ̀lú rẹ, ìwọ ọmọ Jese! Àlàáfíà, àlàáfíà fún ọ, àti àlàáfíà fún àwọn tí ó ràn ó lọ́wọ́, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gbà wọ́n ó sì mú wọn jẹ olórí ẹgbẹ́ ogun.
19 So David welcomed those men, and he appointed them to be leaders of his soldiers. Some men from the tribe of Manasseh also joined David when he went with the soldiers of Philistia to fight against Saul’s [army]. But David and his men did not really help the army of Philistia. After the leaders of Philistia talked [about David and his soldiers], they sent David away. They said, “If David joins his master Saul again, we will all be killed {his army will kill all of us}!”
Díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin Manase sì yà sí ọ̀dọ̀ Dafidi nígbà tí ó lọ pẹ̀lú àwọn ará Filistini láti bá Saulu jà. (Òun àti àwọn ọkùnrin rẹ̀ wọn kò sì ran ará Filistini lọ́wọ́ nítorí, lẹ́yìn tiwọn sọ̀rọ̀ papọ̀, àwọn olórí wọn rán wọn jáde, wọ́n sì wí pé, “Yóò jẹ́ ìparun fún wa tí ó bá padà tọ ọ̀gá rẹ̀ Saulu lọ.”)
20 When David went to Ziklag, these were the men from the tribe of Manasseh who went with him: Adnah, Jozabad, Jediael, Michael, [another man whose name was] Jozabad, Elihu, and Zillethai. Each of them had been a commander of 1,000 men [in Saul’s army].
Nígbà tí Dafidi lọ sí Siklagi, àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin ti Manase ẹni tí ó sì yà sọ́dọ̀ rẹ̀. Adina, Josabadi, Jediaeli, Mikaeli, Josabadi, Elihu àti Siletai, àwọn olórí ìrẹ́pọ̀ ti ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní Manase.
21 They were all brave soldiers, and they helped David to fight against the groups of men who roamed throughout the country, robbing people. So those men became commanders in David’s army.
Wọ́n sì ran Dafidi lọ́wọ́ lórí ẹgbẹ́ ogun náà, nítorí gbogbo wọn ni akọni ènìyàn àwọn sì tún ni olórí nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
22 Every day more men joined David’s men, and his army became large, like [SIM] the army of God (OR, a very huge army).
Ọjọ́ dé ọjọ́ ni àwọn ọkùnrin wá láti ran Dafidi lọ́wọ́, títí tí ó fi ní àwọn ológun ńlá, bí ogun Ọlọ́run.
23 These are the numbers of soldiers who were ready for battle who joined David at Hebron [city]. They came to help him to become the king of Israel to replace Saul, as Yahweh had promised would happen.
Àwọn wọ̀nyí sì ni iye ọkùnrin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun àwọn ẹni tí ó wá sọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni láti yí ìjọba Dafidi padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
24 There were 6,800 men from Judah, who carried shields and spears.
Ọkùnrin Juda, tí o ń gbé asà àti ọ̀kọ̀, ẹgbàáta lé lẹ́gbẹ̀rin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun.
25 There were 7,100 men from the tribe of Simeon. They were all strong warriors trained to fight battles.
Àwọn ọkùnrin Simeoni, akọni tó mú fún ogun sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ó lé ọgọ́rùn-ún;
26 There were 4,600 men from the tribe of Levi.
àwọn ọkùnrin Lefi ẹgbàajì ó le ẹgbẹ̀ta,
27 Jehoiada, who was a leader descended from Aaron, was in that group of descendants of Levi, and there were 3,700 men with him.
pẹ̀lú Jehoiada, olórí ìdílé Aaroni pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ènìyàn,
28 Zadok, a strong young soldier, was also in that group, and there were 22 other leaders from his clan who came with him.
àti Sadoku akọni ọ̀dọ́mọkùnrin, pẹ̀lú àwọn méjìlélógún ìjòyè láti ọ̀dọ̀ àwọn ìdílé rẹ̀;
29 There were 3,000 men from the tribe of Benjamin who were Saul’s relatives. Most of them had previously wanted one of Saul’s descendants to be the king.
àwọn arákùnrin Benjamini ìbátan ọkùnrin Saulu ẹgbẹ̀rún mẹ́ta, ọ̀pọ̀ nínú àwọn ẹni tí ó si kù ní olóòtítọ́ sí ilé Saulu títí di ìgbà náà;
30 There were 20,800 men from the tribe of Ephraim who were all brave warriors and trained for fighting battles and famous in their own clans.
àwọn arákùnrin Efraimu, ògbójú akọni, ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n nílé baba wọn ogún ẹgbẹ̀rún ó le ẹgbẹ̀rin;
31 There were 18,000 men from the half of the tribe of Manasseh [that lived west of the Jordan River]. They were all chosen to go and help David become the king.
àwọn ọkùnrin nínú ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, tí a yàn nípa orúkọ láti wá àti láti yan Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba, ẹgbàá mẹ́sàn.
32 There were 200 men who were leaders from the tribe of Issachar, along with their relatives. Those leaders always knew what the Israelis should do, and they knew the right time to do it.
Àti ní ti àwọn ọmọ Isakari, àwọn ẹni tí ó ní òye àkókò, láti mọ ohun tí Israẹli ìbá máa ṣe; olórí wọn jẹ́ ìgbà; àti gbogbo àwọn ìbátan wọn ń bẹ ní ìkáwọ́ wọn.
33 There were 55,000 men from the tribe of Zebulun. They were all experienced warriors and knew how to use all kinds of weapons well. They were completely loyal to David.
Àwọn ọkùnrin Sebuluni, àti àwọn jagunjagun tí ó ti nípa ogun múra fún ogun pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ohun èlò ìjà, láti ran Dafidi lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn tí kò fi iyèméjì ṣe ìjólóòótọ́ wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
34 There were 1,000 officers from the tribe of Naphtali. With them were 37,000 soldiers, each carrying shields and spears.
Àwọn ọkùnrin Naftali, ẹgbẹ̀rún ìjòyè àpapọ̀ pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún. Ọkùnrin tí wọ́n gbé asà àti ọ̀kọ̀ wọn.
35 There were 28,600 soldiers from the tribe of Dan, all trained to fight battles.
Àwọn ọkùnrin Dani, tí wọ́n ṣetán fún ogun ẹgbàá mẹ́tàlá.
36 There were 47,000 experienced soldiers from the tribe of Asher, all trained to fight battles.
Àwọn ọkùnrin Aṣeri, àwọn tí ó ti ní ìmọ̀ ogun múra fún ogun ọ̀kẹ́ méjì.
37 There were also 120,000 soldiers from the area east of the Jordan [River who joined David]. They were from the tribes of Reuben, Gad, and the eastern half of the tribe of Manasseh. They had all kinds of weapons.
Láti ìlà-oòrùn Jordani, ọkùnrin Reubeni, Gadi, àti ìdajì ẹ̀yà Manase, dìmọ́ra pẹ̀lú gbogbo onírúurú ohun èlò ìjà ọ̀kẹ́ mẹ́fà.
38 All those men were soldiers who volunteered to be in David’s army. They came to Hebron wanting very much to enable David to be the king of all of the Israeli people.
Gbogbo èyí ni àwọn ọkùnrin ológun tí ó fi ara wọn fún ogun láti ṣe iṣẹ́ fún nínú ẹgbẹ́. Wọ́n wá sí Hebroni tí ó kún fún ìpinnu láti fi Dafidi jẹ́ ọba lórí gbogbo Israẹli. Gbogbo àwọn ìyókù lára àwọn ọmọ Israẹli sì jẹ́ onínú kan láti fi Dafidi jẹ ọba.
39 The men spent three days there with David, eating and drinking, because their families had given them food to take with them.
Àwọn ọkùnrin náà lo ọjọ́ mẹ́ta níbẹ̀ pẹ̀lú Dafidi, wọ́n jẹ, wọ́n sì ń mu, nítorí ìdílé wọn ti pèsè oúnjẹ fún wọn.
40 Also, their fellow Israelis came from as far away as the area where the tribes of Issachar, Zebulun, and Naphtali lived, bringing food on donkeys, camels, mules, and oxen. They brought a lot of flour, fig cakes, raisins, wine, [olive] oil, cattle and sheep. And throughout Israel, the people were very joyful.
Àwọn aládùúgbò láti ọ̀nà jíjìn gẹ́gẹ́ bí Isakari, Sebuluni àti Naftali gbé oúnjẹ wá lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, lórí ràkunmí, àti lórí ìbáaka àti lórí màlúù, àní oúnjẹ ti ìyẹ̀fun, èso àjàrà gbígbẹ, èso ọ̀pọ̀tọ́, àkàrà dídùn, ọtí wáìnì, òróró, màlúù àti àgùntàn, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ayọ̀ wà ní Israẹli.

< 1 Chronicles 12 >