< Romans 4 >

1 What then will we say to have discovered Abraham the (ancestor *N+KO) of us according to [the] flesh?
Ǹjẹ́ kín ni àwa ó ha wí nípa Abrahamu, baba wa ti o ṣàwárí èyí? Májẹ̀mú láéláé jẹ́rìí sí i wí pé, a gba Abrahamu là nípa ìgbàgbọ́.
2 If for Abraham by works was justified, he has ground of boasting but not toward God.
Nítorí bí a bá dá Abrahamu láre nípa iṣẹ́, ó ní ohun ìṣògo; ṣùgbọ́n kì í ṣe níwájú Ọlọ́run.
3 What for the Scripture says? Believed then Abraham in God, and it was reckoned to him for righteousness.
Ìwé Mímọ́ ha ti wí? “Abrahamu gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.”
4 To the [one] now working the reward not is reckoned according to grace but according to debt;
Ǹjẹ́ fún ẹni tí ó ṣiṣẹ́, a kò ka èrè náà sí oore-ọ̀fẹ́ bí kò ṣe sí ẹ̀tọ́ rẹ̀.
5 To the [one] however not working, believing however on the [One] justifying the ungodly, is reckoned the faith of him for righteousness.
Ṣùgbọ́n fún ẹni tí kò ṣiṣẹ́, tí ó sì ń gba ẹni tí ó ń dá ènìyàn búburú láre gbọ́, a ka ìgbàgbọ́ rẹ̀ sí òdodo.
6 just as also David declares the blessedness of the man to whom God credits righteousness apart from works:
Gẹ́gẹ́ bí Dafidi pẹ̀lú ti pe olúwa rẹ̀ náà ní ẹni ìbùkún, ẹni tí Ọlọ́run ka òdodo fún láìsí ti iṣẹ́.
7 Blessed [are] they of whom are forgiven the lawless deeds and of whom are covered the sins;
Wí pé, “Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí a dárí ìrékọjá wọn jì, tí a sì bo ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀.
8 blessed [is] [the] man (of whom *N+kO) certainly not may reckon [the] Lord sin.
Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà ẹni tí Olúwa kò ka ẹ̀ṣẹ̀ sí lọ́rùn.”
9 [Is] the blessing then this on the circumcision or also on the uncircumcision? We are saying for (that: *k) was credited to Abraham the faith as righteousness.
Ìbùkún yìí ha jẹ́ ti àwọn akọlà nìkan, tàbí ti àwọn aláìkọlà pẹ̀lú? Nítorí tí a wí pé, Abrahamu gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.
10 How then was it credited? In circumcision being or in uncircumcision? Not in circumcision but in uncircumcision;
Báwo ni a ṣe kà á sí i? Nígbà tí ó wà ní ìkọlà tàbí ní àìkọlà? Kì í ṣe ni ìkọlà, ṣùgbọ́n ní àìkọlà ni.
11 And [the] sign he received of circumcision, a seal of the righteousness of the faith that [he had] [while] in the uncircumcision; for the to be him father of all those believing in uncircumcision, for to be credited also to them the righteousness,
Ó sì gbé àmì ìkọlà àti èdìdì òdodo ìgbàgbọ́ tí ó ní nígbà tí ó wà ní àìkọlà kí ó lè ṣe baba gbogbo àwọn tí ó gbàgbọ́, bí a kò tilẹ̀ kọ wọ́n ní ilà kí a lè ka òdodo sí wọn pẹ̀lú.
12 and father of circumcision to those not of circumcision only but also to those walking in the steps during (the *k) uncircumcision (of the *k) faith of the father of us Abraham.
Àti baba àwọn tí ìkọlà tí kì í ṣe pé a kàn kọlà fún nìkan, ṣùgbọ́n tiwọn ń tẹ̀lé àpẹẹrẹ ìgbàgbọ́ tí baba wa Abrahamu ní, kí a tó kọ ọ́ nílà.
13 Not for through [the] Law [was] the promise to Abraham or to the descendants of him that heir he being (of the *k) world but through [the] righteousness of faith.
Ìlérí fún Abrahamu àti fún irú-ọmọ rẹ̀, ni pé, wọn ó jogún ayé, kì í ṣe nípa òfin bí kò ṣe nípa òdodo ti ìgbàgbọ́.
14 If for those of [the] Law [are] heirs, has been made void faith and has been nullified the promise;
Nítorí bí àwọn tí ń ṣe ti òfin bá jẹ ajogún, ìgbàgbọ́ di asán, ìlérí sì di aláìlágbára.
15 For law wrath brings; where (now *N+kO) no there is law, neither [is] transgression.
Nítorí òfin ń ṣiṣẹ́ ìbínú, ṣùgbọ́n ní ibi tí òfin kò bá sí, ìrúfin kò sí níbẹ̀.
16 Therefore it [is] of faith, that [it may be] according to grace, for to be sure the promise to all the seed, not to that of the law only but also to that of [the] faith of Abraham, who is [the] father of all of us —
Nítorí náà ni ó ṣe gbé e ka orí ìgbàgbọ́, kí ìlérí náà bá a lè sinmi lé oore-ọ̀fẹ́, kí a sì lè mú un dá gbogbo irú-ọmọ lójú, kì í ṣe fún àwọn tí ń pa òfin mọ́ nìkan, ṣùgbọ́n bí kò ṣe pẹ̀lú fún àwọn ti ó pín nínú ìgbàgbọ́ Abrahamu, ẹni tí í ṣe baba gbogbo wa pátápátá,
17 even as it has been written that A father of many nations I have made you, before whom he believed God, who is giving life to the dead and calling the [things] not [into] being as existing;
Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Mo ti fi ọ́ ṣe baba orílẹ̀-èdè púpọ̀.” Níwájú Ọlọ́run ẹni tí òun gbàgbọ́, ẹni tí ó sọ òkú di ààyè, tí ó sì pè àwọn ohun tí kò sí bí ẹni pé wọ́n wà.
18 who against hope in hope believed for to become him [the] father of many nations according to that spoken; So will be the offspring of you;
Nígbà tí ìrètí kò sí mọ́, Abrahamu gbàgbọ́ nínú ìrètí bẹ́ẹ̀ ni ó sì di baba orílẹ̀-èdè púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí èyí tí a wí fún un pé, “Báyìí ni irú-ọmọ rẹ̀ yóò rí.”
19 And not having become weak in the faith (not *K) he considered his own body already expired, a hundred years old about being, and the lifelessness of the womb of Sarah,
Ẹni tí kò rẹ̀wẹ̀sì nínú ìgbàgbọ́, nígbà tí ó mọ pe ara òun tìkára rẹ̀ tí ó ti kú tan, nítorí ó tó bí ẹni ìwọ̀n ọgọ́rùn-ún ọdún, àti nígbà tí ó ro ti yíyàgàn inú Sara.
20 About however the promise of God not he did waver through unbelief, but was strengthened in faith, having given glory to God
Kò fi àìgbàgbọ́ ṣiyèméjì nípa ìlérí Ọlọ́run; ṣùgbọ́n ó lágbára sí i nínú ìgbàgbọ́ bí ó ti fi ògo fún Ọlọ́run,
21 and having been fully assured that what He has promised able He is also to do;
pẹ̀lú ìdánilójú kíkún pé, Ọlọ́run lè ṣe ohun tí ó ti ṣe ìlérí rẹ̀.
22 Therefore also it was credited to him unto righteousness.
Nítorí náà ni a sì ṣe kà á sí òdodo fún un.
23 Not it was written now on account of him alone that it was credited to him,
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ náà, “A kà á sí òdodo fún un,” ni a kọ kì í ṣe nítorí tirẹ̀ nìkan.
24 but also on account of us to whom it is about to be credited, to those believing on the [One] having raised Jesus the Lord of us out from [the] dead,
Ṣùgbọ́n nítorí tiwa pẹ̀lú. A ó sì kà á sí fún wa, bí àwa bá gba ẹni tí ó gbé Jesu Olúwa wa dìde kúrò nínú òkú gbọ́.
25 who was delivered over for the trespasses of us and was raised for the justification of us.
Ẹni tí a pa fún ẹ̀ṣẹ̀ wa, tí a sì jí dìde nítorí ìdáláre wa.

< Romans 4 >